< Acts 13 >

1 Àwọn wòlíì àti àwọn olùkọ́ni sì ń bẹ nínú ìjọ ti ó wà ni Antioku; Barnaba àti Simeoni tí a ń pè ni Nigeri, àti Lukiu ará Kirene, àti Manaeni (ẹni tí a tọ́ pọ̀ pẹ̀lú Herodu tetrarki) àti Saulu.
Now there were in Antioch, in the Church there--as Prophets and teachers--barnabas, Symeon surnamed 'the black,' Lucius the Cyrenaean, Manaen (who was Herod the Tetrarch's foster-brother), and Saul.
2 Bí wọn sì ti ń jọ́sìn fún Olúwa, tí wọ́n sì ń gbààwẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ wí pé, “Ẹ ya Barnaba àti Saulu sọ́tọ̀ fún mi fún iṣẹ́ ti mo ti pè wọ́n sí!”
While they were worshipping the Lord and fasting, the Holy Spirit said, "Set apart for Me, now at once, Barnabas and Saul, for the work to which I have called them."
3 Nígbà tí wọ́n sì ti gbààwẹ̀, tí wọn sì ti gbàdúrà, wọ́n gbé ọwọ́ lé wọn, wọ́n sì rán wọn lọ.
So, after fasting and prayer and the laying on of hands, they let them go.
4 Ǹjẹ́ bí Ẹ̀mí Mímọ́ ti rán àwọn méjèèjì lọ, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Seleusia; láti ibẹ̀ wọ́n sì wọ ọkọ̀ ojú omi lọ sí Saipurọsi.
They therefore, being thus sent out by the Holy Spirit, went down to Seleuceia, and from there sailed to Cyprus.
5 Nígbà ti wọ́n sì wà ni Salami, wọ́n ń wàásù ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ní Sinagọgu àwọn Júù. Johanu náà sì wà pẹ̀lú wọn láti ràn wọ́n lọ́wọ́ fún ìránṣẹ́ wọn.
Having reached Salamis, they began to announce God's Message in the synagogues of the Jews. And they had John as their assistant.
6 Nígbà tí wọ́n sì la gbogbo erékùṣù já dé Pafosi, wọ́n rí ọkùnrin oṣó àti wòlíì èké kan ti i ṣe Júù, orúkọ ẹni ti ó ń jẹ́ Bar-Jesu.
When they had gone through the whole length of the island as far as Paphos, they there met with a Jewish magician and false prophet, Bar-Jesus by name,
7 Ó wà lọ́dọ̀ Segiu Paulusi baálẹ̀ ìlú náà tí í ṣe amòye ènìyàn. Òun náà ni ó ránṣẹ́ pe Barnaba àti Saulu, nítorí tí ó fẹ́ gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
who was a friend of the Proconsul Sergius Paulus. The Proconsul was a man of keen intelligence. He sent for Barnabas and Saul, and asked to be told God's Message.
8 Ṣùgbọ́n Elimu oṣó (nítorí bẹ́ẹ̀ ni ìtumọ̀ orúkọ rẹ̀) takò wọ́n, ó ń fẹ́ pa baálẹ̀ ni ọkàn dà kúrò ni ìgbàgbọ́.
But Elymas (or 'the Magician,' for such is the meaning of the name) opposed them, and tried to prevent the Proconsul from accepting the faith.
9 Ṣùgbọ́n Saulu ti a ń pè ni Paulu, ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì tẹjúmọ́ Elimu, ó sì wí pé,
Then Saul, who is also called Paul, was filled with the Holy Spirit, and, fixing his eyes on Elymas,
10 “Ìwọ ti ó kún fún àrékérekè gbogbo, àti fún ìwà ìkà gbogbo, ìwọ ọmọ èṣù, ìwọ ọ̀tá ohun gbogbo, ìwọ kì yóò ha dẹ́kun láti máa yí ọ̀nà òtítọ́ Olúwa po?
said, "You who are full of every kind of craftiness and unscrupulous cunning--you son of the Devil and foe to all that is right--will you never cease to misrepresent the straight paths of the Lord?
11 Ǹjẹ́ nísinsin yìí wò ó, ọwọ́ Olúwa ń bẹ lára rẹ̀, ìwọ ó sì fọjú ìwọ kì yóò rí oòrùn ní sá à kan!” Lójúkan náà, ìkùùkuu àti òkùnkùn sí bò ó; ó sì ń wá ènìyàn kiri láti fa òun lọ́wọ́ lọ.
The Lord's hand is now upon you, and you will be blind for a time and unable to see the light of day." Instantly there fell upon him a mist and a darkness, and, as he walked about, he begged people to lead him by the hand.
12 Nígbà tí baálẹ̀ rí ohun tí ó ṣe, ó gbàgbọ́, ẹnu sì yà á sì ẹ̀kọ́ Olúwa.
Then the Proconsul, seeing what had happened, believed, being struck with amazement at the teaching of the Lord.
13 Nígbà tí Paulu àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ si ṣíkọ̀ ni Pafosi wọ́n wá sí Perga ni Pamfilia: Johanu sì fi wọ́n sílẹ̀, ó sì padà lọ sí Jerusalẹmu.
From Paphos, Paul and his party put out to sea and sailed to Perga in Pamphylia. John, however, left them and returned to Jerusalem.
14 Nígbà ti wọ́n sì là Perga kọjá, wọ́n wá sí Pisidia ní Antioku. Wọ́n sì wọ inú Sinagọgu ní ọjọ́ ìsinmi, wọ́n sì jókòó.
But they themselves, passing through from Perga, came to Antioch in Pisidia. Here, on the Sabbath day, they went into the synagogue and sat down.
15 Lẹ́yìn kíka ìwé òfin àti ìwé àwọn wòlíì, àwọn olórí Sinagọgu ránṣẹ́ sí wọn, pé, “Ará, bí ẹ̀yin bá ni ọ̀rọ̀ ìyànjú kan fún àwọn ènìyàn, ẹ sọ ọ́!”
After the reading of the Law and the Prophets, the Wardens of the synagogue sent word to them. "Brethren," they said, "if you have anything encouraging to say to the people, speak."
16 Paulu sì dìde dúró, ó sì juwọ́ sí wọn, ó ní, “Ẹ̀yin Israẹli, àti ẹ̀yin ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ẹ fi etí sílẹ̀ sí mi!
So Paul rose, and motioning with his hand for silence, said, "Israelites, and you others who fear God, pay attention to me.
17 Ọlọ́run àwọn ènìyàn Israẹli yìí yan àwọn baba wa, ó sì gbé àwọn ènìyàn náà lékè, nígbà tí wọ́n ṣe àtìpó ní ilẹ̀ Ejibiti, pẹ̀lú agbára ńlá ni ó sì fi mú wọn jáde kúrò nínú rẹ̀,
The God of this people of Israel chose our forefathers, and made the people great during their stay in Egypt, until with wondrous power He brought them out from that land.
18 ní ìwọ̀n ìgbà ogójì ọdún ni ó fi mú sùúrù fún ìwà wọn ní ijù,
For a period of about forty years, He fed them, like a nurse, in the Desert.
19 nígbà tí ó sì ti run orílẹ̀-èdè méje ni ilẹ̀ Kenaani, ó sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ni ìní.
Then, after overthrowing seven nations in the land of Canaan, He divided that country among them as their inheritance for about four hundred and fifty years;
20 Gbogbo èyí sì ṣẹlẹ̀ fún ìwọ̀n àádọ́ta lé ní irinwó ọdún. “Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run fi onídàájọ́ fún wọn, títí ó fi di ìgbà Samuẹli wòlíì.
and afterwards He gave them judges down to the time of the Prophet Samuel.
21 Lẹ́yìn náà ni wọ́n sì béèrè ọba; Ọlọ́run sì fún wọn ní Saulu ọmọ Kiṣi, ọkùnrin kan nínú ẹ̀yà Benjamini, fún ogójì ọdún.
Next they asked for a king, and God gave them Saul the son of Kish, a Benjamite, who reigned forty years.
22 Nígbà ti ó sì mú Saulu kúrò, ó gbé Dafidi dìde ní ọba fún wọn, ẹni tí ó sì jẹ́rìí rẹ̀ pé, ‘Mo rí Dafidi ọmọ Jese ẹni bí ọkàn mi, ti yóò ṣe gbogbo ìfẹ́ mi.’
After removing him, He raised up David to be their king, to whom He also bore witness when He said, "'I have found David the son of Jesse, a man I love, who will obey all My commands.'
23 “Láti inú irú-ọmọ ọkùnrin yìí ni Ọlọ́run ti gbé Jesu Olùgbàlà dìde fún Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìlérí.
"It is from among David's descendants that God, in fulfilment of His promise, has raised up a Saviour for Israel, even Jesus.
24 Ṣáájú wíwá Jesu ni Johanu ti wàásù bamitiisi ìrònúpìwàdà fún gbogbo ènìyàn Israẹli.
Before the coming of Jesus, John had proclaimed to all the people of Israel a baptism of repentance.
25 Bí Johanu sì ti ńlá ipa tirẹ̀ já, ó ni, ‘Ta ni ẹ̀yin ṣe bí èmi jẹ́? Èmi kì í ṣe òun. Ṣùgbọ́n ẹ kíyèsi í, ẹnìkan ń bọ̀ lẹ́yìn mi, bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó tú.’
But John, towards the end of his career, repeatedly asked the people, "'What do you suppose me to be? I am not the Christ. But there is One coming after me whose sandal I am not worthy to unfasten.'
26 “Ará, ẹ̀yin ọmọ ìran Abrahamu, àti ẹ̀yin ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, àwa ni a rán ọ̀rọ̀ ìgbàlà yìí sí.
"Brethren, descendants of the family of Abraham, and all among you who fear God, to us has this Message of salvation been sent.
27 Nítorí àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu, àti àwọn olórí wọn, nítorí tiwọn kò mọ̀ Jesu, tí wọn kò sì ní òye ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì, tí a ń kà ní ọjọọjọ́ ìsinmi fún wọn, kò yé wọn, wọ́n mú ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì yìí ṣẹ nípa dídá a lẹ́bi.
For the people of Jerusalem and their rulers, by the judgement they pronounced on Jesus, have actually fulfilled the predictions of the Prophets which are read Sabbath after Sabbath, through ignorance of those predictions and of Him.
28 Àti bí wọn kò tilẹ̀ ti rí ọ̀ràn ikú sí i, síbẹ̀ wọn rọ Pilatu láti pa á.
Without having found Him guilty of any capital offence they urged Pilate to have Him put to death;
29 Bí wọ́n ti mú nǹkan gbogbo ṣẹ ti a kọ̀wé nítorí rẹ̀, wọn sì sọ̀ ọ́ kalẹ̀ kúrò lórí igi, wọ́n sì tẹ́ ẹ sí ibojì.
and when they had carried out everything which had been written about Him, they took Him down from the cross and laid Him in a tomb.
30 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí i dìde kúrò nínú òkú,
"But God raised Him from the dead.
31 o sì farahàn lọ́jọ́ púpọ̀ fún àwọn tí ó bá a gòkè láti Galili wá sí Jerusalẹmu, àwọn tí í ṣe ẹlẹ́rìí rẹ̀ nísinsin yìí fún àwọn ènìyàn.
And, after a few days, He appeared to the people who had gone up with Him from Galilee to Jerusalem and are now witnesses concerning Him to the Jews.
32 “Àwa sì mú ìyìnrere wá fún yín pé, ìlérí èyí tí Ọlọ́run ti ṣe fún àwọn baba wa,
And we bring you the Good News about the promise made to our forefathers,
33 èyí ni Ọlọ́run ti mú ṣẹ fún àwa ọmọ wọn, nípa gbígbé Jesu dìde, bí a sì ti kọ̀wé rẹ̀ nínú Saamu kejì pé, “‘Ìwọ ni Ọmọ mi; lónìí ni mo bí ọ.’
that God has amply fulfilled it to our children in raising up Jesus; as it is also written in the second Psalm, 'Thou art My Son: to-day I have become Thy Father.'
34 Àti ni tí pé Ọlọ́run jí i dìde kúrò nínú òkú, ẹni tí kì yóò tún padà sí ìbàjẹ́ mọ́, ó wí báyìí pé: “‘Èmi ó fún yín ní ọ̀rẹ́ mímọ́ Dafidi, tí ó dájú.’
And as to His having raised Him from among the dead, never again to be in the position of one soon to return to decay, He speaks thus: 'I will give you the holy and trustworthy promises made to David.'
35 Nítorí ó sì wí nínú Saamu mìíràn pẹ̀lú pé, “‘Ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́.’
Because in another Psalm also He says, 'Thou wilt not give up Thy Holy One to undergo decay.'
36 “Nítorí lẹ́yìn ìgbà ti Dafidi ti sin ìran rẹ tan nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, ó sùn, a sì tẹ́ ẹ ti àwọn baba rẹ̀, ara rẹ̀ sì rí ìdíbàjẹ́.
For David, after having been useful to his own generation in accordance with God's purpose, did fall asleep, was gathered to his forefathers, and did undergo decay.
37 Ṣùgbọ́n ẹni tí Ọlọ́run jí dìde kò rí ìdíbàjẹ́.
But He whom God raised to life underwent no decay.
38 “Ǹjẹ́ kí ó yé yín, ará pé nípasẹ̀ Jesu yìí ni a ń wàásù ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ fún yín.
"Understand therefore, brethren, that through this Jesus forgiveness of sins is announced to you;
39 Nípa rẹ̀ ni a ń dá olúkúlùkù ẹni tí ó gbàgbọ́ láre kúrò nínú ohun gbogbo, tí a kò lè dá yín láre rẹ̀ nínú òfin Mose.
and in Him every believer is absolved from all offences, from which you could not be absolved under the Law of Moses.
40 Nítorí náà, ẹ kíyèsára, kí èyí tí a ti sọ nínú ìwé àwọn wòlíì má ṣe dé bá yín pé:
Beware, then, lest what is spoken in the Prophets should come true of you:
41 “‘Ẹ wò ó, ẹ̀yin ẹlẹ́gàn, kí ẹnu sì yà yín, kí a sì fẹ́ yín kù; nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín, tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́, bí a tilẹ̀ sọ fún yin.’”
'Behold, you despisers, be astonished and perish, because I am carrying on a work in your time--a work which you will utterly refuse to believe, though it be fully declared to you.'"
42 Bí Paulu àti Barnaba sì ti ń jáde láti inú Sinagọgu, wọ́n bẹ̀bẹ̀ pé kí a sọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí i fún wọn lọ́jọ́ ìsinmi tí ń bọ̀.
As Paul and Barnabas were leaving the synagogue, the people earnestly begged to have all this repeated to them on the following Sabbath.
43 Nígbà tí wọn sì jáde nínú Sinagọgu, ọ̀pọ̀ nínú àwọn Júù àti nínú àwọn olùfọkànsìn aláwọ̀ṣe Júù tẹ̀lé Paulu àti Barnaba, àwọn ẹni tí ó bá wọn sọ̀rọ̀ tí wọ́n sì rọ̀ wọ́n láti dúró nínú oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
And, when the congregation had broken up, many of the Jews and of the devout converts from heathenism continued with Paul and Barnabas, who talked to them and urged them to hold fast to the grace of God.
44 Ní ọjọ́ ìsinmi kejì, gbogbo ìlú sí fẹ́rẹ̀ péjọ tan láti gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
On the next Sabbath almost the whole population of the city came together to hear the Lord's Message.
45 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Júù rí ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, wọ́n kún fún owú, wọ́n ń sọ̀rọ̀-òdì sí ohun ti Paulu ń sọ.
Seeing the crowds, the Jews, filled with angry jealousy, opposed Paul's statements and abused him.
46 Paulu àti Barnaba sì dá wọn lóhùn láìbẹ̀rù pé, “Ẹ̀yin ni ó tọ́ sí pé ki a kọ́kọ́ sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún yín, ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin ti ta á nù, tí ẹ sì ka ara yín sí aláìyẹ fún ìyè àìnípẹ̀kun, wò ó, àwa yípadà sọ́dọ̀ àwọn aláìkọlà. (aiōnios g166)
Then, throwing off all reserve, Paul and Barnabas said, "We were bound to proclaim God's Message to you first. But since you spurn it and judge yourselves to be unworthy of the Life of the Ages--well, we turn to the Gentiles. (aiōnios g166)
47 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ṣa ti pàṣẹ fún wa pé: “‘Mo ti gbé ọ kalẹ̀ láti tan ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà, kí ìwọ lè mú ìgbàlà wá títí dé òpin ayé.’”
For such is the Lord's command to us. "'I have placed Thee,' He says of Christ, 'as a light to the Gentiles, in order that Thou mayest be a Saviour as far as the remotest parts of the earth.'"
48 Nígbà tí àwọn aláìkọlà sì gbọ́ èyí, wọ́n sì yín ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lógo: gbogbo àwọn tí a yàn sí ìyè àìnípẹ̀kun sì gbàgbọ́. (aiōnios g166)
The Gentiles listened with delight and extolled the Lord's Message; and all who were pre-destined to the Life of the Ages believed. (aiōnios g166)
49 A sí tan ọ̀rọ̀ Olúwa ká gbogbo agbègbè náà.
So the Lord's Message spread through the whole district.
50 Ṣùgbọ́n àwọn Júù rú àwọn obìnrin olùfọkànsìn àti ọlọ́lá sókè àti àwọn àgbà ìlú náà, wọ́n sì gbé inúnibíni dìde sí Paulu àti Barnaba, wọ́n sì le wọn kúrò ni agbègbè wọn.
But the Jews influenced the gentlewomen of rank who worshipped with them, and also the leading men in the city, and stirred up persecution against Paul and Barnabas and drove them out of the district.
51 Ṣùgbọ́n wọ́n gbọn eruku ẹsẹ̀ wọn sí wọn, wọn sì wá sí Ikoniomu.
But they shook off the dust from their feet as a protest against them and came to Iconium;
52 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn si kún fún ayọ̀ àti fún Ẹ̀mí Mímọ́.
and as for the disciples, they were more and more filled with joy and with the Holy Spirit.

< Acts 13 >