< Acts 13 >

1 Àwọn wòlíì àti àwọn olùkọ́ni sì ń bẹ nínú ìjọ ti ó wà ni Antioku; Barnaba àti Simeoni tí a ń pè ni Nigeri, àti Lukiu ará Kirene, àti Manaeni (ẹni tí a tọ́ pọ̀ pẹ̀lú Herodu tetrarki) àti Saulu.
ⲁ̅ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ϩⲁⲛ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⲇⲉ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ϧⲉⲛ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲧⲁⲛ ϯⲟⲭⲓ⳿ⲁ ⲃⲁⲣⲛⲁⲃⲁⲥ ⲛⲉⲙ Ⲥⲓⲙⲱⲛ ⲫⲏ⳿⳿ⲉⲧⲟⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⲛⲓⲕⲉⲣ ⲛⲉⲙ ⲗⲟⲩⲕⲓⲟⲥ ⲡⲓⲔⲩⲣⲓⲛⲛⲉⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲙⲁⲛⲁⲏⲡⲓ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲛϣⲁⲛϣ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲏ̇ⲣⲱⲇⲏⲥ ⲡⲓⲧⲉⲧⲣⲁⲁⲣⲭⲏⲥ ⲛⲉⲙ ⲥⲁⲩⲗⲟⲥ.
2 Bí wọn sì ti ń jọ́sìn fún Olúwa, tí wọ́n sì ń gbààwẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ wí pé, “Ẹ ya Barnaba àti Saulu sọ́tọ̀ fún mi fún iṣẹ́ ti mo ti pè wọ́n sí!”
ⲃ̅ⲉⲩϣⲉⲙϣⲓ ⲇⲉ ⳿ⲙⲠ⳪ ⲉⲩⲉⲣⲛⲏⲥⲧⲉⲩⲓⲛ ⲡⲉϫⲉ ⲡⲠⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ϫⲉ ⲫⲱⲣϫ ⲛⲏⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲃⲁⲣⲛⲁⲃⲁⲥ ⲛⲉⲙ ⲥⲁⲩⲗⲟⲥ ⳿ⲉⲡⲓϩⲱⲃ ⳿ⲉⲧⲁⲓⲑⲁϩⲙⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
3 Nígbà tí wọ́n sì ti gbààwẹ̀, tí wọn sì ti gbàdúrà, wọ́n gbé ọwọ́ lé wọn, wọ́n sì rán wọn lọ.
ⲅ̅ⲧⲟⲧⲉ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲉⲣⲛⲏⲥⲧⲉⲩⲓⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲧⲱⲃϩ ⲁⲩⲭⲁϫⲓϫ ⳿ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲭⲁⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
4 Ǹjẹ́ bí Ẹ̀mí Mímọ́ ti rán àwọn méjèèjì lọ, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Seleusia; láti ibẹ̀ wọ́n sì wọ ọkọ̀ ojú omi lọ sí Saipurọsi.
ⲇ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲙⲉⲛ ⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲟⲩⲟⲣⲡⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲠⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲥⲉⲗⲉⲩⲕⲓ⳿ⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲁⲩⲉⲣϩⲱⲧ ⳿ⲉⲕⲩⲡⲣⲟⲥ.
5 Nígbà ti wọ́n sì wà ni Salami, wọ́n ń wàásù ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ní Sinagọgu àwọn Júù. Johanu náà sì wà pẹ̀lú wọn láti ràn wọ́n lọ́wọ́ fún ìránṣẹ́ wọn.
ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲥⲁⲗⲁⲙⲓⲛⲏⲛⲁⲩϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ ⲛⲁⲣⲉ ⳿ⲡⲕⲉⲒⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲇⲉ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⲉϥⲟⲓ ⳿ⲛⲣⲉϥϣⲉⲙϣⲓ.
6 Nígbà tí wọ́n sì la gbogbo erékùṣù já dé Pafosi, wọ́n rí ọkùnrin oṣó àti wòlíì èké kan ti i ṣe Júù, orúkọ ẹni ti ó ń jẹ́ Bar-Jesu.
ⲋ̅⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲉⲛ ϯⲛⲏⲥⲟⲥ ⲇⲉ ⲧⲏⲣⲥ ϣⲁ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲡⲁⲫⲟⲩ ⲁⲩϫⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲁⲭⲱ ⳿ⲙⲯⲉⲇⲟ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⳿ⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲡⲉ ⲃⲁⲣⲓⲏⲥⲟⲩ.
7 Ó wà lọ́dọ̀ Segiu Paulusi baálẹ̀ ìlú náà tí í ṣe amòye ènìyàn. Òun náà ni ó ránṣẹ́ pe Barnaba àti Saulu, nítorí tí ó fẹ́ gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
ⲍ̅ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲛⲁϥⲭⲏ ⲛⲉⲙ ⲡⲓ⳿ⲁⲛⲑⲩⲡⲁⲧⲟⲥ ⲥⲉⲣⲅⲓⲟⲥ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲕⲁⲧϩⲏ ⲧ ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ⲁϥⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲃⲁⲣⲛⲁⲃⲁⲥ ⲛⲉⲙ ⲥⲁⲩⲗⲟⲥ ⲛⲁϥⲕⲱϯ ⳿ⲉⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
8 Ṣùgbọ́n Elimu oṣó (nítorí bẹ́ẹ̀ ni ìtumọ̀ orúkọ rẹ̀) takò wọ́n, ó ń fẹ́ pa baálẹ̀ ni ọkàn dà kúrò ni ìgbàgbọ́.
ⲏ̅ⲛⲁϥϯ ⲇⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲁⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲉⲗⲩⲙⲁⲥ ⲡⲓⲁⲭⲱ ⳿ⲉϣⲁⲩⲟⲩⲁϩⲉⲙ ⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲉϥⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲫⲉⲛϩ ⲡⲓ⳿ⲁⲛⲑⲩⲡⲁⲧⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⳿ⲫⲛⲁϩϯ.
9 Ṣùgbọ́n Saulu ti a ń pè ni Paulu, ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì tẹjúmọ́ Elimu, ó sì wí pé,
ⲑ̅ⲥⲁⲩⲗⲟⲥ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲉ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲡⲉ ⳿ⲉⲧⲁϥⲙⲟϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲠⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ.
10 “Ìwọ ti ó kún fún àrékérekè gbogbo, àti fún ìwà ìkà gbogbo, ìwọ ọmọ èṣù, ìwọ ọ̀tá ohun gbogbo, ìwọ kì yóò ha dẹ́kun láti máa yí ọ̀nà òtítọ́ Olúwa po?
ⲓ̅ⲡⲉϫⲁϥ ⳿ⲱ ⲫⲏⲉⲑⲙⲉϩ ⳿ⲛ⳿ⲭⲣⲟϥ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲇⲓ⳿ⲁⲃⲟⲗⲟⲥ ⲡⲓϫⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲑⲙⲏⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲛ⳿ⲕⲭⲱ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲛ ⲉⲕⲫⲱⲛϩ ⳿ⲛⲛⲓⲙⲱⲓⲧ ⲉⲧⲥⲟⲩⲧⲱⲛ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪.
11 Ǹjẹ́ nísinsin yìí wò ó, ọwọ́ Olúwa ń bẹ lára rẹ̀, ìwọ ó sì fọjú ìwọ kì yóò rí oòrùn ní sá à kan!” Lójúkan náà, ìkùùkuu àti òkùnkùn sí bò ó; ó sì ń wá ènìyàn kiri láti fa òun lọ́wọ́ lọ.
ⲓ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ϯⲛⲟⲩ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲓⲥ ⳿ⲧϫⲓϫ ⳿ⲙⲠ⳪ ⲉⲥ⳿ⲉ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲱⲕ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲕ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲉⲕⲟⲓ ⳿ⲙⲃⲉⲗⲗⲉ ⳿ⲛ⳿ⲭⲛⲁⲩ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏⲁⲛ ϣⲁ ⲟⲩⲥⲏⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲁⲧⲟⲧϥ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲱϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩ⳿ϩⲗⲟⲗ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲭⲁⲕⲓ ⲛⲁϥⲕⲱϯ ⲉϥϣⲓⲛⲓ ⳿ⲛⲥⲁ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϯⲧⲟⲧϥ.
12 Nígbà tí baálẹ̀ rí ohun tí ó ṣe, ó gbàgbọ́, ẹnu sì yà á sì ẹ̀kọ́ Olúwa.
ⲓ̅ⲃ̅ⲧⲟⲧⲉ ⳿ⲉⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓ⳿ⲁⲛⲑⲩⲡⲁⲧⲟⲥ ⳿ⲉⲫⲏ⳿ⲉⲧⲁϥϣⲱⲡⲓ ⲁϥⲛⲁϩϯ ⲁϥⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪.
13 Nígbà tí Paulu àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ si ṣíkọ̀ ni Pafosi wọ́n wá sí Perga ni Pamfilia: Johanu sì fi wọ́n sílẹ̀, ó sì padà lọ sí Jerusalẹmu.
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲁⲫⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲁ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲡⲁⲣⲛⲁⲃⲁⲥ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲡⲉⲣⲅⲏ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲡⲁⲙⲫⲓⲗⲓ⳿ⲁ Ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲇⲉ ⲁϥⲫⲱⲣϫ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲁϥⲕⲟⲧϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲒⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅.
14 Nígbà ti wọ́n sì là Perga kọjá, wọ́n wá sí Pisidia ní Antioku. Wọ́n sì wọ inú Sinagọgu ní ọjọ́ ìsinmi, wọ́n sì jókòó.
ⲓ̅ⲇ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲉⲣⲅⲏⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ⲧⲁⲛϯⲟⲭⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲡⲓⲥⲓⲇⲓ⳿ⲁ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉϯⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲏ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ⲁⲩϩⲉⲙⲥⲓ.
15 Lẹ́yìn kíka ìwé òfin àti ìwé àwọn wòlíì, àwọn olórí Sinagọgu ránṣẹ́ sí wọn, pé, “Ará, bí ẹ̀yin bá ni ọ̀rọ̀ ìyànjú kan fún àwọn ènìyàn, ẹ sọ ọ́!”
ⲓ̅ⲉ̅ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲡⲓⲱϣ ⲇⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⲁⲩⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲁⲣⲭⲏⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲟⲥ ϩⲁⲣⲱⲟⲩ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲛⲉⲛ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲛⲟⲙϯ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϣⲁ ⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ⳿ⲁϫⲟϥ.
16 Paulu sì dìde dúró, ó sì juwọ́ sí wọn, ó ní, “Ẹ̀yin Israẹli, àti ẹ̀yin ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ẹ fi etí sílẹ̀ sí mi!
ⲓ̅ⲋ̅⳿ⲉⲧⲁϥⲧⲱⲛϥ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥϭⲱⲣⲉⲙ ⳿ⲛⲧⲉϥϫⲓϫ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓ⳿ⲥⲣⲁⲏⲗⲓⲧⲏⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲉⲣϩⲟϯ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲙⲪϯ ⲥⲱⲧⲉⲙ.
17 Ọlọ́run àwọn ènìyàn Israẹli yìí yan àwọn baba wa, ó sì gbé àwọn ènìyàn náà lékè, nígbà tí wọ́n ṣe àtìpó ní ilẹ̀ Ejibiti, pẹ̀lú agbára ńlá ni ó sì fi mú wọn jáde kúrò nínú rẹ̀,
ⲓ̅ⲍ̅ⲫϯ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲗⲁⲟⲥ Ⲡⲓ̅ⲥ̅ⲗ̅ ⲁϥⲥⲱⲧⲡ ⳿ⲛⲛⲉⲛⲓⲟϯ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϭⲓⲥⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ϧⲉⲛ ϯⲡⲁⲣⲟⲓⲕⲓ⳿ⲁ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⳿ⲛⲬⲏⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ϧⲉⲛ ⲟⲩϣⲱⲃϣ ⲉϥϭⲟⲥⲓ ⲁϥ⳿ⲉⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ⳿ⲛⲏⲧϥ.
18 ní ìwọ̀n ìgbà ogójì ọdún ni ó fi mú sùúrù fún ìwà wọn ní ijù,
ⲓ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϣⲁⲛⲟⲩϣⲟⲩ ⳿ⲛⲙ̅ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ ⳿ⲛⲥⲏⲟⲩ ϩⲓ ⳿ⲡϣⲁϥⲉ.
19 nígbà tí ó sì ti run orílẹ̀-èdè méje ni ilẹ̀ Kenaani, ó sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ni ìní.
ⲓ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲣⲱϧⲧ ⳿ⲛⲍ̅ ⳿ⲛ⳿ϣⲗⲱⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⳿ⲛⲭⲁⲛⲁⲁⲛ ⲁϥ⳿ⲑⲣⲟⲩⲉⲣ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲡⲟⲩⲕⲁϩⲓ.
20 Gbogbo èyí sì ṣẹlẹ̀ fún ìwọ̀n àádọ́ta lé ní irinwó ọdún. “Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run fi onídàájọ́ fún wọn, títí ó fi di ìgbà Samuẹli wòlíì.
ⲕ̅⳿ⲛⲩ̅ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲛⲁⲓ ⲁϥϯ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ⲕⲣⲓⲧⲏⲥ ϣⲁ ⲥ⳿ⲁⲙⲟⲩⲏⲗ ⲡⲓ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ.
21 Lẹ́yìn náà ni wọ́n sì béèrè ọba; Ọlọ́run sì fún wọn ní Saulu ọmọ Kiṣi, ọkùnrin kan nínú ẹ̀yà Benjamini, fún ogójì ọdún.
ⲕ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲁⲩⲉⲣ⳿ⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲩⲣⲟ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϯ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ Ⲫϯ ⳿ⲛⲥⲁⲟⲩⲗ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲕⲓⲥ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲩⲗⲏ⳿ⲙⲃⲉⲛⲓ⳿ⲁⲙⲓⲛ ⳿ⲛⲙ̅ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ.
22 Nígbà ti ó sì mú Saulu kúrò, ó gbé Dafidi dìde ní ọba fún wọn, ẹni tí ó sì jẹ́rìí rẹ̀ pé, ‘Mo rí Dafidi ọmọ Jese ẹni bí ọkàn mi, ti yóò ṣe gbogbo ìfẹ́ mi.’
ⲕ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲟⲩⲟⲑⲃⲉϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁϥⲧⲟⲩⲛⲟⲥ Ⲇⲁⲩⲓⲇ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲟ ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲧⲁϥⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⲉⲑⲃⲏⲧϥ ⳿ⲉⲁϥϫⲟⲥ ϫⲉ ⲁⲓϫⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲆⲁⲩⲓⲇ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲓⲉⲥⲥⲉ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲁϩⲏⲧ ⲫⲁⲓ ⲉⲑⲛⲁ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲉϩⲛⲏⲓ.
23 “Láti inú irú-ọmọ ọkùnrin yìí ni Ọlọ́run ti gbé Jesu Olùgbàlà dìde fún Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìlérí.
ⲕ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⳿ⲡ⳿ϫⲣⲟϫ ⳿ⲙⲫⲁⲓ ⳿ⲁ Ⲫϯ ⲕⲁⲧⲁ ⲟⲩⲱϣ ⲁϥ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲠⲓ̅ⲥ̅ⲗ̅ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲱⲧⲏⲣ Ⲓⲏ̅ⲥ̅.
24 Ṣáájú wíwá Jesu ni Johanu ti wàásù bamitiisi ìrònúpìwàdà fún gbogbo ènìyàn Israẹli.
ⲕ̅ⲇ̅⳿ⲉⲁϥⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛϩⲓⲱⲓϣ ϧⲁϫⲉⲛ ⲡⲉϥⲙⲱⲓⲧ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲙⲥ ⳿ⲙⲙⲉⲧⲁⲛⲟⲓ⳿ⲁ ⳿ⲙⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ⲧⲏⲣϥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲓ̅ⲥ̅ⲗ̅.
25 Bí Johanu sì ti ńlá ipa tirẹ̀ já, ó ni, ‘Ta ni ẹ̀yin ṣe bí èmi jẹ́? Èmi kì í ṣe òun. Ṣùgbọ́n ẹ kíyèsi í, ẹnìkan ń bọ̀ lẹ́yìn mi, bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó tú.’
ⲕ̅ⲉ̅ⲉⲧⲁ Ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲇⲉ ϫⲱⲕ ⳿ⲙⲡⲉϥ⳿ⲇⲣⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲛⲁϥⲭⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲩⲓ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲛⲓⲙ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ⲡⲉ ⲁⲗⲗⲁ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲉϥⲛⲏⲟⲩ ⲙ⳿ⲉⲛⲉⲛⲥⲱⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲛϯ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⲁⲛ ⳿ⲉϯⲟⲩ⳿ⲱ ⳿ⲙⲡⲓⲑⲱⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲉϥϭⲁⲗⲁⲩϫ.
26 “Ará, ẹ̀yin ọmọ ìran Abrahamu, àti ẹ̀yin ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, àwa ni a rán ọ̀rọ̀ ìgbàlà yìí sí.
ⲕ̅ⲋ̅ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲛⲉⲛ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⲛⲓϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲅⲉⲛⲟⲥ ⳿ⲛⲀⲃⲣⲁⲁⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲉⲣϩⲟϯ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲙⲪϯ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲟⲩⲱⲣⲡ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓⲟⲩϫⲁⲓ ⲫⲁⲓ.
27 Nítorí àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu, àti àwọn olórí wọn, nítorí tiwọn kò mọ̀ Jesu, tí wọn kò sì ní òye ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì, tí a ń kà ní ọjọọjọ́ ìsinmi fún wọn, kò yé wọn, wọ́n mú ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì yìí ṣẹ nípa dídá a lẹ́bi.
ⲕ̅ⲍ̅ⲛⲏⲅⲁⲣ ⲉⲧϣⲟⲡ ϧⲉⲛ Ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲛⲉⲙ ⲛⲟⲩⲕⲉⲁⲣⲭⲱⲛ ⲫⲁⲓ ⲁⲩⲉⲣⲁⲧ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲕⲉ⳿ⲥⲙⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⲛⲁⲓ ⲉⲧⲟⲩⲱϣ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲕⲁⲧⲁ ⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉⲁⲩϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲁⲩϫⲟⲕⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
28 Àti bí wọn kò tilẹ̀ ti rí ọ̀ràn ikú sí i, síbẹ̀ wọn rọ Pilatu láti pa á.
ⲕ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲟⲩϫⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛⲗⲱⲓϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲫⲙⲟⲩ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲁⲩⲉⲣ⳿ⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲙⲠⲓⲗⲁⲧⲟⲥ ⳿ⲉϧⲟⲑⲃⲉϥ.
29 Bí wọ́n ti mú nǹkan gbogbo ṣẹ ti a kọ̀wé nítorí rẹ̀, wọn sì sọ̀ ọ́ kalẹ̀ kúrò lórí igi, wọ́n sì tẹ́ ẹ sí ibojì.
ⲕ̅ⲑ̅⳿ⲉⲧⲁⲩϫⲱⲕ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ⲉⲑⲃⲏⲧϥ ⲁⲩⲭⲁϥ ⳿ⲉⲡⲉⲥⲏⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓϣⲉ ⲁⲩⲭⲁϥ ⳿ⲛϧⲟⲩⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲙϩⲁⲩ.
30 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí i dìde kúrò nínú òkú,
ⲗ̅ⲫϯ ⲇⲉ ⲁϥⲧⲟⲩⲛⲟⲥϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲑⲙⲱⲟⲩⲧ.
31 o sì farahàn lọ́jọ́ púpọ̀ fún àwọn tí ó bá a gòkè láti Galili wá sí Jerusalẹmu, àwọn tí í ṣe ẹlẹ́rìí rẹ̀ nísinsin yìí fún àwọn ènìyàn.
ⲗ̅ⲁ̅ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲧⲁϥⲟⲩⲟⲛϩϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⲛⲉⲙⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ϯⲄⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲒⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲛⲁⲓ ϯⲛⲟⲩ ⲉⲧⲟⲓ ⳿ⲙⲙⲉⲑⲣⲉ ⲛⲁϥ ϣⲁ ⲡⲓⲗⲁⲟⲥ.
32 “Àwa sì mú ìyìnrere wá fún yín pé, ìlérí èyí tí Ọlọ́run ti ṣe fún àwọn baba wa,
ⲗ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲧⲉⲛϩⲓϣⲉⲛⲛⲟⲩϥⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲓⲱϣ ⳿ⲉⲧⲁϥϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲓⲟϯ.
33 èyí ni Ọlọ́run ti mú ṣẹ fún àwa ọmọ wọn, nípa gbígbé Jesu dìde, bí a sì ti kọ̀wé rẹ̀ nínú Saamu kejì pé, “‘Ìwọ ni Ọmọ mi; lónìí ni mo bí ọ.’
ⲗ̅ⲅ̅ϫⲉ ⲫⲁⲓ ⳿ⲁ Ⲫϯ ϫⲟⲕϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲛⲓϣⲏⲣⲓ ⳿ⲉⲧⲁϥⲧⲟⲩⲛⲟⲥ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲙⲁϩⲃ̅ ⳿ⲙⲯⲁⲗⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲡⲉ ⲡⲁϣⲏⲣⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲁⲓ⳿ϫⲫⲟⲕ ⳿ⲙⲫⲟⲟⲩ.
34 Àti ni tí pé Ọlọ́run jí i dìde kúrò nínú òkú, ẹni tí kì yóò tún padà sí ìbàjẹ́ mọ́, ó wí báyìí pé: “‘Èmi ó fún yín ní ọ̀rẹ́ mímọ́ Dafidi, tí ó dájú.’
ⲗ̅ⲇ̅ⲟⲧⲓ ⲇⲉ ϫⲉ ⲁϥⲧⲟⲩⲛⲟⲥϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲑⲙⲱⲟⲩⲧ ⳿ϥⲛⲁⲧⲁⲥⲑⲟ ⲁⲛ ϫⲉ ⳿ⲉ⳿ⲡⲧⲁⲕⲟ ⲁϥϫⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ϫⲉ ⲉⲓ⳿ⲉϯ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲇⲁⲩⲓⲇ ⳿ⲉⲧⲉⲛϩⲟⲧ.
35 Nítorí ó sì wí nínú Saamu mìíràn pẹ̀lú pé, “‘Ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́.’
ⲗ̅ⲉ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲫⲁⲓ ⲟⲛ ⳿ϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϧⲉⲛ ⲕⲉⲙⲁ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲉⲕϯ ⳿ⲙⲡⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⳿ⲛⲧⲁⲕ ⳿ⲉⲛⲁⲩ ⳿ⲉ⳿ⲡⲧⲁⲕⲟ.
36 “Nítorí lẹ́yìn ìgbà ti Dafidi ti sin ìran rẹ tan nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, ó sùn, a sì tẹ́ ẹ ti àwọn baba rẹ̀, ara rẹ̀ sì rí ìdíbàjẹ́.
ⲗ̅ⲋ̅Ⲇⲁⲩⲓⲇ ⲙⲉⲛ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲧⲉϥⲅ⳿ⲉⲛⲉ⳿ⲁ ⲛⲁϥϣⲉⲙϣⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲟϭⲛⲓ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⲁϥⲉⲛⲕⲟⲧ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲭⲁϥ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲛⲉϥⲓⲟϯ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉ⳿ⲡⲧⲁⲕⲟ.
37 Ṣùgbọ́n ẹni tí Ọlọ́run jí dìde kò rí ìdíbàjẹ́.
ⲗ̅ⲍ̅ⲫⲏ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲁ Ⲫϯ ⲧⲟⲩⲛⲟⲥϥ ⳿ⲙⲡⲉϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉ⳿ⲡⲧⲁⲕⲟ.
38 “Ǹjẹ́ kí ó yé yín, ará pé nípasẹ̀ Jesu yìí ni a ń wàásù ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ fún yín.
ⲗ̅ⲏ̅ⲙⲁⲣⲉ ⲡⲓϩⲱⲃ ⲟⲩⲛ ⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲛⲉⲛ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⲫⲁⲓ ⲥⲉϩⲓⲱⲓϣ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙ⳿ⲡⲭⲱ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛⲛⲟⲃⲓ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲁ ⲛⲏⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛ⳿ϣϫⲉⲙϫⲟⲙ ⳿ⲉⲑⲁⲙⲓⲟ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲙⲘⲱ⳿ⲩⲥⲏⲥ.
39 Nípa rẹ̀ ni a ń dá olúkúlùkù ẹni tí ó gbàgbọ́ láre kúrò nínú ohun gbogbo, tí a kò lè dá yín láre rẹ̀ nínú òfin Mose.
ⲗ̅ⲑ̅ϧⲉⲛ ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁϩϯ ⲥⲉⲛⲁ⳿ⲑⲙⲁⲓⲟϥ.
40 Nítorí náà, ẹ kíyèsára, kí èyí tí a ti sọ nínú ìwé àwọn wòlíì má ṣe dé bá yín pé:
ⲙ̅⳿ⲁⲛⲁⲩ ⲟⲩⲛ ⲙⲏ ⲡⲱⲥ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲁϥϫⲟϥ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ.
41 “‘Ẹ wò ó, ẹ̀yin ẹlẹ́gàn, kí ẹnu sì yà yín, kí a sì fẹ́ yín kù; nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín, tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́, bí a tilẹ̀ sọ fún yin.’”
ⲙ̅ⲁ̅ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲁⲩ ⲛⲓⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲟⲛⲓⲧⲏⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲣⲓ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲙⲁⲕⲉⲧ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϫⲉ ϯⲛⲁ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲟⲩϩⲱⲃ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲟⲩϩⲱⲃ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲁⲛ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲁⲣⲉϣⲁⲛ ⲟⲩⲁⲓ ⲫ⳿⳿ⲓⲣⲓ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
42 Bí Paulu àti Barnaba sì ti ń jáde láti inú Sinagọgu, wọ́n bẹ̀bẹ̀ pé kí a sọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí i fún wọn lọ́jọ́ ìsinmi tí ń bọ̀.
ⲙ̅ⲃ̅ⲉⲩⲛⲏⲟⲩ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲛⲁⲩⲉⲣ⳿ⲁⲝⲓⲟⲓⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉⲥⲁϫⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲕⲉⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ⲉⲑⲛⲏⲟⲩ.
43 Nígbà tí wọn sì jáde nínú Sinagọgu, ọ̀pọ̀ nínú àwọn Júù àti nínú àwọn olùfọkànsìn aláwọ̀ṣe Júù tẹ̀lé Paulu àti Barnaba, àwọn ẹni tí ó bá wọn sọ̀rọ̀ tí wọ́n sì rọ̀ wọ́n láti dúró nínú oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
ⲙ̅ⲅ̅ⲉⲧⲁⲥⲃⲱⲗ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ϯⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲏ ⲁⲩⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲥⲁ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲃⲁⲣⲛⲁⲃⲁⲥ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲉⲣⲥⲉⲃⲉⲥⲑⲉ ϧⲉⲛ ⲛⲓϣⲉⲙⲙⲱⲟⲩ ⲉⲩⲑⲱⲧ ⳿ⲙⲡⲟⲩϩⲏⲧ ⲉⲑⲣⲟⲩϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
44 Ní ọjọ́ ìsinmi kejì, gbogbo ìlú sí fẹ́rẹ̀ péjọ tan láti gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
ⲙ̅ⲇ̅⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲕⲉⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲥⲭⲉⲇⲟⲛ ⳿ⲁ ϯⲡⲟⲗⲓⲥ ⲧⲏⲣⲥ ⲑⲱⲟⲩϯ ⳿ⲉⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
45 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Júù rí ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, wọ́n kún fún owú, wọ́n ń sọ̀rọ̀-òdì sí ohun ti Paulu ń sọ.
ⲙ̅ⲉ̅⳿ⲉⲧⲁⲩⲛⲁⲩ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ ⳿ⲉⲛⲓⲙⲏϣ ⲁⲩⲙⲟϩ ⳿ⲛⲭⲟϩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩϯ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲉⲛ ⲛⲏ⳿ⲉⲛⲁⲣⲉ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ϫⲱ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲉⲩϫⲉⲟⲩ⳿ⲁ.
46 Paulu àti Barnaba sì dá wọn lóhùn láìbẹ̀rù pé, “Ẹ̀yin ni ó tọ́ sí pé ki a kọ́kọ́ sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún yín, ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin ti ta á nù, tí ẹ sì ka ara yín sí aláìyẹ fún ìyè àìnípẹ̀kun, wò ó, àwa yípadà sọ́dọ̀ àwọn aláìkọlà. (aiōnios g166)
ⲙ̅ⲋ̅⳿ⲉⲧⲁⲩⲟⲩⲟⲛϩⲟⲩ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲃⲁⲣⲛⲁⲃⲁⲥ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲛⲉ ⲟⲩⲁⲛⲁⲅⲕⲉⲟⲛ ⲡⲉ ⳿ⲉⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⲉⲡⲓⲇⲏⲧⲉⲧⲉⲛϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲱⲡ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ ⳿ⲉⲉⲣ⳿ⲡⲉⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲙⲡⲓⲱⲛϧ ⳿ⲛ⳿⳿ⲉⲛⲉϩ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲧⲉⲛⲛⲁⲕⲟⲧⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲛⲓⲉⲑⲛⲟⲥ. (aiōnios g166)
47 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ṣa ti pàṣẹ fún wa pé: “‘Mo ti gbé ọ kalẹ̀ láti tan ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà, kí ìwọ lè mú ìgbàlà wá títí dé òpin ayé.’”
ⲙ̅ⲍ̅ⲫⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ ⳿ⲙⲫⲣⲏϯ ⳿ⲉⲧⲁϥϩⲟⲛϩⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲟⲧⲉⲛ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡ⳪ ϫⲉ ⲁⲓⲭⲁⲕ ⲉⲩⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲉⲑⲛⲟⲥ ⲉⲑⲣⲉⲕϣⲱⲡⲓ ⲉⲩⲟⲩϫⲁⲓ ϣⲁ ⲁⲩⲣⲏϫϥ ⳿ⲙ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ.
48 Nígbà tí àwọn aláìkọlà sì gbọ́ èyí, wọ́n sì yín ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lógo: gbogbo àwọn tí a yàn sí ìyè àìnípẹ̀kun sì gbàgbọ́. (aiōnios g166)
ⲙ̅ⲏ̅⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲉⲑⲛⲟⲥ ⲁⲩⲣⲁϣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩϯ⳿ⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲛⲁϩϯ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲏⲧⲏⲣⲟⲩ ⲉⲧⲑⲏϣ ⳿ⲉⲡⲓⲱⲛϧ ⳿ⲛ⳿⳿ⲉⲛⲉϩ. (aiōnios g166)
49 A sí tan ọ̀rọ̀ Olúwa ká gbogbo agbègbè náà.
ⲙ̅ⲑ̅ⲛⲁⲩⲕⲱϯ ⲇⲉ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ϧⲉⲛ ϯⲭⲱⲣⲁ ⲧⲏⲣⲥ.
50 Ṣùgbọ́n àwọn Júù rú àwọn obìnrin olùfọkànsìn àti ọlọ́lá sókè àti àwọn àgbà ìlú náà, wọ́n sì gbé inúnibíni dìde sí Paulu àti Barnaba, wọ́n sì le wọn kúrò ni agbègbè wọn.
ⲛ̅ⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ ⲇⲉ ⲛⲁⲩϣⲟⲡϣⲉⲡ ⳿ⲛⲛⲓϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ⳿ⲉⲧⲉⲣⲥⲉⲃⲉⲥⲑⲉ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲉⲩⲥⲭⲏⲙⲱⲛ ⲛⲉⲙ ⲛⲓϩⲟⲩⲁϯ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲡⲟⲗⲓⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲧⲟⲩⲛⲟⲥ ⲟⲩⲇⲓⲱⲅⲙⲟⲥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲃⲁⲣⲛⲁⲃⲁⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϩⲓⲧⲟⲩ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲑⲱϣ.
51 Ṣùgbọ́n wọ́n gbọn eruku ẹsẹ̀ wọn sí wọn, wọn sì wá sí Ikoniomu.
ⲛ̅ⲁ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲁⲩⲛⲉϩ ⳿ⲡϣⲱⲓϣ ⳿ⲛⲛⲟⲩ ϭⲁⲗⲁⲩϫ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲓⲕⲟⲛⲓⲟⲛ.
52 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn si kún fún ayọ̀ àti fún Ẹ̀mí Mímọ́.
ⲛ̅ⲃ̅ⲛⲓⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲇⲉ ⲛⲁⲩⲙⲉϩ ⳿ⲛⲣⲁϣⲓ ⲛⲉⲙ ⲡⲠⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ.

< Acts 13 >