< Acts 12 >

1 Ní àkókò ìgbà náà ni Herodu ọba sì nawọ́ rẹ̀ mú àwọn kan nínú ìjọ, pẹ̀lú èrò láti pọ́n wọn lójú.
ⲁ̅⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲥⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲁ Ⲏ̇ⲣⲱⲇⲏⲥ ⳿ⲡⲟⲩⲣⲟ ⲁϥ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥϫⲓϫ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓ⳿ⲁ ⳿ⲉϯ⳿ⲙⲕⲁϩ ⲛⲱⲟⲩ.
2 Ó sì fi idà pa Jakọbu arákùnrin Johanu.
ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϧⲱⲧⲉⲃ ⳿ⲛⲒⲁⲕⲱⲃⲟⲥ ⳿ⲡⲥⲟⲛ ⳿ⲛⲒⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⳿ⲛ⳿ⲧⲥⲏϥⲓ.
3 Nígbà tí ó sì rí pé èyí dùn mọ́ àwọn Júù nínú, ó sì nawọ́ mú Peteru pẹ̀lú. Ó sì jẹ́ ìgbà àjọ àìwúkàrà.
ⲅ̅⳿ⲉⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⲇⲉ ϫⲉ ⲡⲓϩⲱⲃ ⲣⲁⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ ⲁϥⲟⲩⲁϩⲧⲟⲧϥ ⳿ⲉϭⲱⲡⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡⲕⲉⲠⲉⲧⲣⲟⲥ ⲛⲉ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲇⲉ ⲛⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲁⲧⲕⲱⲃ.
4 Nígbà tí o sì mú un, ó fi i sínú túbú, ó fi lé àwọn ẹ̀ṣọ́ mẹ́rin ti ọmọ-ogun lọ́wọ́ láti máa ṣọ́ ọ. Herodu ń rò láti mú un jáde fún àwọn ènìyàn lẹ́yìn ìrékọjá fún ìdájọ́.
ⲇ̅ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲧⲁϥϭⲟⲡϥ ⲁϥⲭⲁϥ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ϣⲧⲉⲕⲟ ⳿ⲉⲁϥⲧⲏⲓϥ ⳿ⲉⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲇ̅ ⳿ⲛϣⲱⲡ ⳿ⲙⲙⲁⲧⲟⲓ ⲉⲑⲣⲟⲩ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲉϥⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲉ⳿ⲉⲛϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲡⲓⲡⲁⲥⲭⲁ.
5 Nítorí náà wọn fi Peteru pamọ́ sínú túbú; ṣùgbọ́n ìjọ ń fi ìtara gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run fún un.
ⲉ̅Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲙⲉⲛ ⲟⲩⲛ ⲛⲁⲩ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ϣⲧⲉⲕⲟ ⲛⲁⲥⲉⲣⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲉⲥⲑⲉ ⲇⲉ ⲉⲑⲃⲏⲧϥ ⳿ⲉⲙⲁϣⲱ ϩⲁ Ⲫϯ ⳿ⲛϫⲉ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓ⳿ⲁ.
6 Ní òru náà gan an ti Herodu ìbá sì mú un jáde, Peteru ń sùn láàrín àwọn ọmọ-ogun méjì, a fi ẹ̀wọ̀n méjì dè é, ẹ̀ṣọ́ sí wà ní ẹnu-ọ̀nà, wọ́n ń ṣọ́ túbú náà.
ⲋ̅ϩⲟⲧⲉ ⲇⲉ ⲉϥⲛⲁ⳿ⲉⲛϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲛϫⲉ Ⲏ̇ⲣⲱⲇⲏⲥ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϫⲱⲣϩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲛⲁϥⲉⲛⲕⲟⲧ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲟⲩⲧⲉ ⲙⲁⲧⲟⲓ ⲃ̅ ⲉϥⲙⲏⲣ ⳿ⲛϩⲁⲗⲩⲥⲓⲥ ⲃ̅ϯ ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ⲁⲣⲉϩ ⲇⲉ ϩⲓⲣⲉⲛ ⲛⲓⲣⲱⲟⲩ ⲉⲩ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲡⲓ⳿ϣⲧⲉⲕⲟ.
7 Sì wò ó, angẹli Olúwa farahàn, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ nínú túbú; ó sì lu Peteru pẹ́pẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́, ó jí i, ó ni, “Dìde kánkán!” Ẹ̀wọ̀n sí bọ́ sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ Peteru.
ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲓⲥ ⲟⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ⲁϥ⳿ⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱⲓⲛⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲏⲓ ⳿ⲉⲧⲁϥⲕⲓⲙ ⲇⲉ ⳿ⲉ⳿ⲡ⳿ⲥⲫⲓⲣ ⳿ⲙⲠⲉⲧⲣⲟⲥ ⲁϥⲧⲟⲩⲛⲟⲥϥ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲧⲱⲛⲕ ⳿ⲛⲭⲱⲗⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϩⲉⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓϩⲁⲗⲩⲥⲓⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲉϥϫⲓϫ.
8 Angẹli náà sì wí fún un pé, “Di àmùrè rẹ̀, kí ó sì wọ sálúbàtà rẹ!” Peteru sì ṣe bẹ́ẹ̀. Ó sì wí fún un pé, “Da aṣọ rẹ́ bora, ki ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn!”
ⲏ̅ⲡⲉϫⲉ ⲡⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲇⲉ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲙⲟⲣⲕ ⲟⲩⲟϩ ⲙⲁ ⲡⲉⲕⲥⲩⲛⲇⲁⲗⲓⲟⲛ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲕ ⲁϥ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ϫⲟⲗϩⲕ ⳿ⲙⲡⲉⲕ⳿ϩⲃⲱⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲥⲱⲓ.
9 Peteru sì jáde, ó ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn; kò sí mọ̀ pé ohun tí a ṣe láti ọwọ́ angẹli náà jẹ́ òtítọ́, ṣùgbọ́n ó ṣe bí òun wà lójú ìran.
ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲛⲁϥⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲟⲩⲙⲏⲓ ⲡⲉⲧⲉ ⲛⲁϥϣⲟⲡ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲛⲁϥⲙⲉⲩⲓ ⲇⲉ ϫⲉ ⲟⲩϩⲟⲣⲁⲙⲁ ⲡⲉⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
10 Nígbà tí wọ́n kọjá ìṣọ́ èkínní àti èkejì, wọ́n dé ẹnu-ọ̀nà ìlẹ̀kùn irin tí ó lọ sí ìlú. Ó sí tìkára rẹ̀ ṣí sílẹ̀ fún wọn: wọ́n sì jáde, wọ́n ń gba ọ̀nà ìgboro kan lọ; lójúkan náà angẹli náà sì fi í sílẹ̀ lọ.
ⲓ̅⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲓⲛⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲓⲙⲁ ⳿ⲛ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲛϩⲟⲩⲓⲧ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲙⲁϩⲃ̅ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉϯⲡⲩⲗⲏ⳿ⲙⲃⲉⲛⲓⲡⲓ ⲑⲏⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉϯⲡⲟⲗⲓⲥ ⲑⲁⲓ ⲁⲥⲟⲩⲱⲛ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲟⲩⲁⲧⲥ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲩⲥⲉⲛ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲛⲓϧⲓⲣ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲁⲧⲟⲧϥ ⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁⲣⲟϥ.
11 Nígbà tí ojú Peteru sì wálẹ̀, ó ní, “Nígbà yìí ni mo tó mọ̀ nítòótọ́ pé, Olúwa rán angẹli rẹ̀, ó sì gbà mi lọ́wọ́ Herodu àti gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn Júù ń retí!”
ⲓ̅ⲁ̅Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲁ ⲡⲉϥϩⲏⲧ ⳿ⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ϯⲛⲟⲩ ⲁⲓ⳿ⲉⲙⲓ ⲧⲁ⳿ⲫⲙⲏϫⲉ ⳿ⲁ Ⲡ⳪ ⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲙⲡⲉϥⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲛⲁϩⲙⲉⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⳿ⲧϫⲓϫ ⳿ⲛⲎ̇ⲣⲱⲇⲏⲥ ⲛⲉⲙ ⳿ⲡⲥⲟⲙⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲧⲏⲣϥ ⳿ⲙⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ.
12 Nígbà tó sì rò ó, ó lọ sí ilé Maria ìyá Johanu, tí àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Marku; níbi tí àwọn ènìyàn púpọ̀ péjọ sí, tí wọn ń gbàdúrà.
ⲓ̅ⲃ̅⳿ⲉⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⲇⲉ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ⲡⲏⲓ ⳿ⲙⲘⲁⲣⲓ⳿ⲁ ⳿ⲑⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲒⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲫⲏ⳿⳿ⲉⲧⲟⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⲙⲁⲣⲕⲟⲥ ⲡⲓⲙⲁ ⳿ⲉⲛⲁⲩⲑⲟⲩⲏⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲉⲩⲉⲣⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲉⲥⲑⲉ.
13 Bí ó sì ti kan ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà, ọmọbìnrin kan tí a n pè ní Roda wá láti dáhùn.
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲉⲧⲁϥⲕⲱⲗϩ ⲇⲉ ϩⲓⲣⲉⲛ ⳿ⲫⲣⲟ ⳿ⲙⲡⲓⲡⲩⲗⲱⲛ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲁⲥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⳿ⲙⲃⲱⲕⲓ ⳿ⲉⲉⲣⲟⲩⲱ ⲛⲁϥ ⳿ⲉⲡⲉⲥⲣⲁⲛ ⲡⲉ ⲣⲱⲇⲏ.
14 Nígbà tí ó sì ti mọ ohùn Peteru, kò ṣí ìlẹ̀kùn nítorí tí ayọ̀ kún ọkàn rẹ̀ gidigidi, ṣùgbọ́n ó súré wọ ilé, ó sísọ pé, Peteru dúró ní ẹnu-ọ̀nà.
ⲓ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲥⲥⲟⲩⲉⲛ ⳿ⲧ⳿ⲥⲙⲏ ⳿ⲙⲠⲉⲧⲣⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲓⲣⲁϣⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲥⲟⲩⲱⲛ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ϣⲑⲱⲙ ⳿ⲉⲧⲁⲥϭⲟϫⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⲁⲥⲧⲁⲙⲱⲟⲩ ϫⲉ Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ϩⲓⲣⲉⲛ ⲡⲓⲡⲩⲗⲱⲛ.
15 Wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ ń ṣe òmùgọ̀!” Ṣùgbọ́n ó tẹnumọ́ ọn gidigidi pé bẹ́ẹ̀ ni sẹ́. Wọn sì wí pé, “Angẹli rẹ̀ ni!”
ⲓ̅ⲉ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⲁⲣⲉⲗⲟⲃⲓ ⳿ⲛⲑⲟⲥ ⲇⲉ ⲛⲁⲥⲧⲁϫⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲥ ⲡⲉ ϫⲉ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲡⲉⲧϣⲟⲡ ⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲡⲉϥⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲡⲉ.
16 Ṣùgbọ́n Peteru ń kànkùn síbẹ̀, nígbà tí wọn sì ṣí ìlẹ̀kùn, wọ́n rí i, ẹnu sì yá wọ́n.
ⲓ̅ⲋ̅Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲇⲉ ⲛⲁϥⲙⲏⲛ ⲉϥⲕⲱⲗϩ ⲡⲉ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲟⲩⲱⲛ ⲇⲉ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲁⲩⲧⲱⲙⲧ.
17 Ṣùgbọ́n ó juwọ́ sí wọn pé kí wọn dákẹ́, ó sì ròyìn fún wọn bí Olúwa ti mú òun jáde kúrò nínú túbú. Ó sì wí pé, “Ẹ ro èyí fún Jakọbu àti àwọn arákùnrin yòókù!” Ó sì jáde, ó lọ sí ibòmíràn.
ⲓ̅ⲍ̅ⲁϥϭⲱⲣⲉⲙ ⲇⲉ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉϥϫⲓϫ ϫⲉ ⲭⲁⲣⲱⲧⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲥⲁϫⲓ ϧⲁⲧⲟⲧⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲛⲁϣ ⳿ⲛⲣⲏϯ ⳿ⲁ Ⲡ⳪ ⳿ⲉⲛϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ϣⲧⲉⲕⲟ ⲡⲉϫⲁϥ ⲇⲉ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲙⲁⲧⲁⲙⲉ Ⲓⲁⲕⲱⲃⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲛⲁⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁϥϣⲉ ⳿ⲉⲕⲉⲙⲁ.
18 Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ìrúkèrúdò díẹ̀ kọ́ ni ó wà láàrín àwọn ọmọ-ogun nípa ohun tí ó dé bá Peteru.
ⲓ̅ⲏ̅ⲉⲧⲁ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲇⲉ ϣⲱⲡⲓ ⲁϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩ⳿ϣⲑⲟⲣⲧⲉⲣ ⳿ⲛⲟⲩⲕⲟⲩϫⲓ ⲁⲛ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲙⲁⲧⲟⲓ ϫⲉ ⲟⲩ ϩⲁⲣⲁ ⲡⲉⲧⲁϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲠⲉⲧⲣⲟⲥ.
19 Nígbà tí Herodu sì wá a kiri, tí kò sì rí i, ó wádìí àwọn ẹ̀ṣọ́, ó pàṣẹ pé, kí a pa wọ́n. Herodu sì sọ̀kalẹ̀ láti Judea lọ sí Kesarea, ó sì wà níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀.
ⲓ̅ⲑ̅Ⲏ̇ⲣⲱⲇⲏⲥ ⳿ⲉⲧⲁϥⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲉϥϫⲉⲙϥ ⲁϥϯ⳿ⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛⲛⲓⲣⲉϥ⳿ⲁⲣⲉϩ ⲁϥⲟⲩⲁϩⲥⲁϩⲛⲓ ⳿ⲉϧⲟⲑⲃⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ϯⲒⲟⲩⲇⲉ⳿ⲁ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲔⲉⲥⲁⲣⲓ⳿ⲁ ⲁϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
20 Herodu sí ń bínú gidigidi sí àwọn ará Tire àti Sidoni; ṣùgbọ́n wọ́n fi ìmọ̀ ṣọ̀kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀, nígbà tí wọn sì ti tu Bilasitu ìwẹ̀fà ọba lójú, wọn ń bẹ̀bẹ̀ fún àlàáfíà, nítorí pé ìlú ọba náà ni ìlú tí wọ́n ti ń gba oúnjẹ.
ⲕ̅ⲛⲁϥϣⲟⲡ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲙⲃⲟⲛ ⲉϥϯ ⲟⲩⲃⲉ ⲛⲁ Ⲧⲩⲣⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⳿ⲧⲤⲓⲇⲱⲛ ⲁⲩ⳿ⲓ ⲇⲉ ⲉⲩⲥⲟⲡ ϣⲁⲣⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲑⲉⲧ ⳿ⲡϩⲏⲧ ⳿ⲙ⳿ⲡⲗⲁⲥⲧⲟⲥ ⲫⲏⲉⲧⲭⲏ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓⲕⲟⲓⲧⲱⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲟⲩⲣⲟ ⲛⲁⲩⲉⲣ⳿ⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲛⲟⲩϩⲓⲣⲏⲛⲏⲉⲑⲃⲉ ϫⲉ ⲛⲁⲩϣⲁⲛϣ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲭⲱⲣⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧⲥ ⳿ⲛⲧⲉϥⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ.
21 Ni ọjọ́ àfiyèsí kan, Herodu sì wà nínú aṣọ ìgúnwà rẹ̀, ni orí ìtẹ́ rẹ̀, ó sì ń bá àwọn àjọ ènìyàn sọ̀rọ̀ ní gbangba.
ⲕ̅ⲁ̅⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲉϥⲑⲏϣ ⳿ⲁ Ⲏ̇ⲣⲱⲇⲏⲥ ϯ ϩⲓⲱⲧϥ ⳿ⲛⲟⲩϩⲉⲃⲥⲱ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲟ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓⲃⲏⲙⲁ ⲛⲁϥⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ.
22 Àwọn ènìyàn sì hó wí pé, “Ohùn ọlọ́run ni èyí, kì í sì í ṣe ti ènìyàn!”
ⲕ̅ⲃ̅ⲡⲓⲙⲏϣ ⲇⲉ ⲛⲁϥⲱϣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲩ⳿ⲥⲙⲏ ⳿ⲛⲛⲟⲩϯ ⲧⲉ ⲑⲁⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲑⲁ ⲣⲱⲙⲓ ⲁⲛ ⲧⲉ.
23 Lójúkan náà, nítorí ti Herodu kò fi ògo fún Ọlọ́run, angẹli Olúwa lù ú, ó sì kú, ìdin sì jẹ ẹ́.
ⲕ̅ⲅ̅ⲥⲁⲧⲟⲧϥ ⲇⲉ ⳿ⲁ ⲟⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ⲁϥϣⲁⲣⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲉ⳿ⲫⲙⲁ ϫⲉ ⳿ⲙⲡⲉϥϯ⳿ⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲪϯ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲉⲣϭⲓϥⲉⲛⲧ ⲁϥⲙⲟⲩ.
24 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run gbilẹ̀, ó sì bí sí i.
ⲕ̅ⲇ̅ⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⲁϥⲁⲓⲁⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛ⳿ⲁϣⲁⲓ.
25 Barnaba àti Saulu sì padà wá láti Jerusalẹmu, nígbà ti wọ́n sì parí iṣẹ́ ìránṣẹ́ wọn, wọn sì mú Johanu ẹni tí àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Marku wá pẹ̀lú wọn.
ⲕ̅ⲉ̅ⲃⲁⲣⲛⲁⲃⲁⲥ ⲇⲉ ⲛⲉⲙ ⲥⲁⲩⲗⲟⲥ ⲁⲩⲕⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ Ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⳿ⲛϯⲇⲓ⳿ⲁⲕⲟⲛⲓⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉⲁⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡⲕⲉⲒⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩϯⲣⲉⲛϥ ϫⲉ ⲙⲁⲣⲕⲟⲥ.

< Acts 12 >