< Acts 11 >

1 Àwọn aposteli àti àwọn arákùnrin ti ó wà ni Judea sì gbọ́ pé àwọn aláìkọlà pẹ̀lú ti gba ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
itthaM bhinnadeshIyalokA apIshvarasya vAkyam agR^ihlan imAM vArttAM yihUdIyadeshasthapreritA bhrAtR^igaNashcha shrutavantaH|
2 Nígbà tí Peteru sì gòkè wá sí Jerusalẹmu, àwọn ti ìkọlà ń bá a wíjọ́
tataH pitare yirUshAlamnagaraM gatavati tvakChedino lokAstena saha vivadamAnA avadan,
3 wí pé, “Ìwọ wọlé tọ àwọn ènìyàn aláìkọlà lọ, ó sì bá wọn jẹun.”
tvam atvakChedilokAnAM gR^ihaM gatvA taiH sArddhaM bhuktavAn|
4 Ṣùgbọ́n Peteru bẹ̀rẹ̀ sí là á yé wọn lẹ́sẹẹsẹ, wí pé,
tataH pitara AditaH kramashastatkAryyasya sarvvavR^ittAntamAkhyAtum ArabdhavAn|
5 “Èmi wà ni ìlú Joppa, mo ń gbàdúrà, mo rí ìran kan lójúran. Ohun èlò kan sọ̀kalẹ̀ bí ewé tákàdá ńlá, tí a ti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá; ó sì wá títí de ọ̀dọ̀ mi.
yAphonagara ekadAhaM prArthayamAno mUrchChitaH san darshanena chaturShu koNeShu lambanamAnaM vR^ihadvastramiva pAtramekam AkAshadavaruhya mannikaTam AgachChad apashyam|
6 Mo tẹjúmọ́ ọn, mo sì fiyèsí i, mo sí rí ẹran ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin, àti ẹranko igbó, àti ohun tí ń rákò, àti ẹyẹ ojú ọ̀run.
pashchAt tad ananyadR^iShTyA dR^iShTvA vivichya tasya madhye nAnAprakArAn grAmyavanyapashUn urogAmikhecharAMshcha dR^iShTavAn;
7 Mo sì gbọ́ ohùn kan ti ó fọ̀ sí mi pé, ‘Dìde, Peteru: máa pa, kí ó sì máa jẹ.’
he pitara tvamutthAya gatvA bhuMkShva mAM sambodhya kathayantaM shabdamekaM shrutavAMshcha|
8 “Ṣùgbọ́n mo dáhùn wí pé, ‘Rara Olúwa! Nítorí ohun èèwọ̀ tàbí ohun aláìmọ́ kan kò wọ ẹnu mi rí láéláé.’
tatohaM pratyavadaM, he prabho netthaM bhavatu, yataH ki nchana niShiddham ashuchi dravyaM vA mama mukhamadhyaM kadApi na prAvishat|
9 “Ṣùgbọ́n ohùn kan dáhùn nígbà ẹ̀ẹ̀kejì láti ọ̀run wá pé, ‘Ohun tí Ọlọ́run bá ti wẹ̀mọ́, kí ìwọ má ṣe pè é ní àìmọ́.’
aparam Ishvaro yat shuchi kR^itavAn tanniShiddhaM na jAnIhi dvi rmAmpratIdR^ishI vihAyasIyA vANI jAtA|
10 Èyí sì ṣẹlẹ̀ nígbà mẹ́ta; a sì tún fa gbogbo rẹ̀ sókè ọ̀run.
triritthaM sati tat sarvvaM punarAkAsham AkR^iShTaM|
11 “Sì wò ó, lójúkan náà ọkùnrin mẹ́ta dúró níwájú ilé ti a gbé wà, ti a rán láti Kesarea sí mi.
pashchAt kaisariyAnagarAt trayo janA mannikaTaM preShitA yatra niveshane sthitohaM tasmin samaye tatropAtiShThan|
12 Ẹ̀mí sì wí fún mi pé, kí èmi bá wọn lọ, ki èmi má ṣe kọminú ohunkóhun. Àwọn arákùnrin mẹ́fà wọ̀nyí sì bá mi lọ, a sì wọ ilé ọkùnrin náà.
tadA niHsandehaM taiH sArddhaM yAtum AtmA mAmAdiShTavAn; tataH paraM mayA sahaiteShu ShaDbhrAtR^iShu gateShu vayaM tasya manujasya gR^ihaM prAvishAma|
13 Ó sì sọ fún wa bí òun ti rí angẹli kan tí ó dúró ní ilé rẹ̀, tí ó sì wí pé, ‘Ránṣẹ́ lọ sí Joppa, kí ó sì pe Simoni tí àpèlé rẹ̀ jẹ́ Peteru;
sosmAkaM nikaTe kathAmetAm akathayat ekadA dUta ekaH pratyakShIbhUya mama gR^ihamadhye tiShTan mAmityAj nApitavAn, yAphonagaraM prati lokAn prahitya pitaranAmnA vikhyAtaM shimonam AhUyaya;
14 ẹni tí yóò sọ ọ̀rọ̀ fún ọ, nípa èyí tí a ó fi gba ìwọ àti gbogbo ilé rẹ là.’
tatastava tvadIyaparivArANA ncha yena paritrANaM bhaviShyati tat sa upadekShyati|
15 “Bí mo sì ti bẹ̀rẹ̀ sì sọ, Ẹ̀mí Mímọ́ sì bà lé wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti bà lé wa ni àtètèkọ́ṣe.
ahaM tAM kathAmutthApya kathitavAn tena prathamam asmAkam upari yathA pavitra AtmAvarUDhavAn tathA teShAmapyupari samavarUDhavAn|
16 Nígbà náà ni mo rántí ọ̀rọ̀ Olúwa, bí ó ti wí pé, ‘Johanu fi omi bamitiisi nítòótọ́; ṣùgbọ́n a ó fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi yín.’
tena yohan jale majjitavAn iti satyaM kintu yUyaM pavitra Atmani majjitA bhaviShyatha, iti yadvAkyaM prabhuruditavAn tat tadA mayA smR^itam|
17 Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run sì ti fi irú ẹ̀bùn kan náà fún wọn bí ó ti fi fún àwa pẹ̀lú nígbà tí a gba Jesu Kristi Olúwa gbọ́, ta ni èmi tí n ó fi rò pé mo le è de Ọlọ́run ní ọ̀nà?”
ataH prabhA yIshukhrIShTe pratyayakAriNo ye vayam asmabhyam Ishvaro yad dattavAn tat tebhyo lokebhyopi dattavAn tataH kohaM? kimaham IshvaraM vArayituM shaknomi?
18 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì pa ẹnu wọn mọ́, wọ́n sì yin Ọlọ́run ògo wí pé, “Ǹjẹ́ Ọlọ́run fi ìrònúpìwàdà sí ìyè fún àwọn aláìkọlà pẹ̀lú!”
kathAmetAM shruvA te kShAntA Ishvarasya guNAn anukIrttya kathitavantaH, tarhi paramAyuHprAptinimittam IshvaronyadeshIyalokebhyopi manaHparivarttanarUpaM dAnam adAt|
19 Nítorí náà àwọn tí a sì túká kiri nípasẹ̀ inúnibíni tí ó dìde ní ti Stefanu, wọ́n rìn títí de Fonisia, àti Saipurọsi, àti Antioku, wọn kò sọ ọ̀rọ̀ náà fún ẹnìkan bí kò ṣe fún kìkì àwọn Júù.
stiphAnaM prati upadrave ghaTite ye vikIrNA abhavan tai phainIkIkuprAntiyakhiyAsu bhramitvA kevalayihUdIyalokAn vinA kasyApyanyasya samIpa Ishvarasya kathAM na prAchArayan|
20 Ṣùgbọ́n àwọn kan ń bẹ nínú wọn tí ó jẹ́ ará Saipurọsi àti Kirene; nígbà tí wọ́n dé Antioku, wọ́n sọ̀rọ̀ fún àwọn Helleni pẹ̀lú, wọ́n ń wàásù ìròyìn ayọ̀ nípa Jesu Olúwa.
aparaM teShAM kuprIyAH kurInIyAshcha kiyanto janA AntiyakhiyAnagaraM gatvA yUnAnIyalokAnAM samIpepi prabhoryIshoH kathAM prAchArayan|
21 Ọwọ́ Olúwa sì wà pẹ̀lú wọn, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì gbàgbọ́, wọ́n sì yípadà sí Olúwa.
prabhoH karasteShAM sahAya AsIt tasmAd aneke lokA vishvasya prabhuM prati parAvarttanta|
22 Ìròyìn nípa wọn sì dé etí ìjọ ti ó wà ni Jerusalẹmu; wọ́n sì rán Barnaba lọ títí dé Antioku;
iti vArttAyAM yirUshAlamasthamaNDalIyalokAnAM karNagocharIbhUtAyAm AntiyakhiyAnagaraM gantu te barNabbAM prairayan|
23 Nígbà ti ó dé ti ó sì rí ẹ̀rí oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run, ó yọ̀, ó sì gba gbogbo wọn níyànjú pé, pẹ̀lú ìpinnu ọkàn ni kí wọn fi ara mọ́ Olúwa.
tato barNabbAstatra upasthitaH san IshvarasyAnugrahasya phalaM dR^iShTvA sAnando jAtaH,
24 Nítorí òun jẹ́ ènìyàn rere, ó sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àti fún ìgbàgbọ́; ènìyàn púpọ̀ ni a sì kà kún Olúwa.
sa svayaM sAdhu rvishvAsena pavitreNAtmanA cha paripUrNaH san ganoniShTayA prabhAvAsthAM karttuM sarvvAn upadiShTavAn tena prabhoH shiShyA aneke babhUvuH|
25 Barnaba sì jáde lọ sí Tarsu láti wá Saulu,
sheShe shaulaM mR^igayituM barNabbAstArShanagaraM prasthitavAn| tatra tasyoddeshaM prApya tam AntiyakhiyAnagaram Anayat;
26 nígbà tí ó sì rí i, ó mú un wá sí Antioku. Fún ọdún kan gbáko ni wọ́n fi ń bá ìjọ péjọpọ̀, tí wọ́n sì kọ́ ènìyàn púpọ̀. Ní Antioku ni a sì kọ́kọ́ ti pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ni “Kristiani.”
tatastau maNDalIsthalokaiH sabhAM kR^itvA saMvatsaramekaM yAvad bahulokAn upAdishatAM; tasmin AntiyakhiyAnagare shiShyAH prathamaM khrIShTIyanAmnA vikhyAtA abhavan|
27 Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni àwọn wòlíì sì ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ wá sí Antioku.
tataH paraM bhaviShyadvAdigaNe yirUshAlama AntiyakhiyAnagaram Agate sati
28 Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn, ti a ń pè ni Agabu sí dìde, ó ti ipa Ẹ̀mí sọ pé, ìyàn ńlá yóò mú yíká gbogbo ilẹ̀ Romu. (Èyí sì ṣẹlẹ̀ nígbà ìṣèjọba Kilaudiu.)
AgAbanAmA teShAmeka utthAya AtmanaH shikShayA sarvvadeshe durbhikShaM bhaviShyatIti j nApitavAn; tataH klaudiyakaisarasyAdhikAre sati tat pratyakSham abhavat|
29 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì pinnu, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí agbára rẹ̀ ti tó, láti rán ìrànlọ́wọ́ sí àwọn arákùnrin tí ó wà ní Judea.
tasmAt shiShyA ekaikashaH svasvashaktyanusArato yihUdIyadeshanivAsinAM bhratR^iNAM dinayApanArthaM dhanaM preShayituM nishchitya
30 Wọn sì ṣe bẹ́ẹ̀, wọn sì fi ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí àwọn àgbà láti ọwọ́ Barnaba àti Saulu.
barNabbAshaulayo rdvArA prAchInalokAnAM samIpaM tat preShitavantaH|

< Acts 11 >