< Acts 11 >
1 Àwọn aposteli àti àwọn arákùnrin ti ó wà ni Judea sì gbọ́ pé àwọn aláìkọlà pẹ̀lú ti gba ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
Namtom rhoek loh Pathen kah olka a doe uh te Judea ah aka om caeltueih rhoek neh manuca rhoek loh a yaak uh.
2 Nígbà tí Peteru sì gòkè wá sí Jerusalẹmu, àwọn ti ìkọlà ń bá a wíjọ́
Tedae Peter loh Jerusalem la a caeh vaengah tah anih te yahvinrhetnah dongkah rhoek loh a boelhkhoeh uh.
3 wí pé, “Ìwọ wọlé tọ àwọn ènìyàn aláìkọlà lọ, ó sì bá wọn jẹun.”
“Pumdul la aka om hlang rhoek taengla na kun tih amih te na vael puei,” a ti nah.
4 Ṣùgbọ́n Peteru bẹ̀rẹ̀ sí là á yé wọn lẹ́sẹẹsẹ, wí pé,
Te dongah Peter loh amih taengah tuek tuek a saep pahoi tih,
5 “Èmi wà ni ìlú Joppa, mo ń gbàdúrà, mo rí ìran kan lójúran. Ohun èlò kan sọ̀kalẹ̀ bí ewé tákàdá ńlá, tí a ti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá; ó sì wá títí de ọ̀dọ̀ mi.
“Kai loh Joppa khopuei kah ka thangthui vaengah ka muei ka mang neh ka om tih mangthui ka hmuh. Te vaengah himbai len bangla kil pali aka om hno pakhat te vaan lamloh ha colh tih, kai taengla ha pawk.
6 Mo tẹjúmọ́ ọn, mo sì fiyèsí i, mo sí rí ẹran ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin, àti ẹranko igbó, àti ohun tí ń rákò, àti ẹyẹ ojú ọ̀run.
Te te ka hmaitang tih ka hmat hatah diklai rhamsa neh satlung khaw, rhulcai neh vaan kah vaa khaw ka hmuh.
7 Mo sì gbọ́ ohùn kan ti ó fọ̀ sí mi pé, ‘Dìde, Peteru: máa pa, kí ó sì máa jẹ.’
Te phoeiah ol ka yaak bal tih, 'Peter, thoo, ngawn lamtah ca,’a ti.
8 “Ṣùgbọ́n mo dáhùn wí pé, ‘Rara Olúwa! Nítorí ohun èèwọ̀ tàbí ohun aláìmọ́ kan kò wọ ẹnu mi rí láéláé.’
Tedae, 'Moenih boeipa, tanghnong tangaih neh rhalawt tah ka ka la a kun noek moenih,’ ka ti nah.
9 “Ṣùgbọ́n ohùn kan dáhùn nígbà ẹ̀ẹ̀kejì láti ọ̀run wá pé, ‘Ohun tí Ọlọ́run bá ti wẹ̀mọ́, kí ìwọ má ṣe pè é ní àìmọ́.’
Tedae vaan lamkah a pabae ol loh, 'Pathen loh a ciim tangtae te nang loh poeih boeh,’ a ti.
10 Èyí sì ṣẹlẹ̀ nígbà mẹ́ta; a sì tún fa gbogbo rẹ̀ sókè ọ̀run.
Te tlam te a om phoeikah a pathum dongah tah vaan la boeih a doek koep.
11 “Sì wò ó, lójúkan náà ọkùnrin mẹ́ta dúró níwájú ilé ti a gbé wà, ti a rán láti Kesarea sí mi.
Te vaengah Kaiserea lamloh kai taengla han tueih hlang pathum tah ka om nah im ah pakcak ha pai uh pahoi.
12 Ẹ̀mí sì wí fún mi pé, kí èmi bá wọn lọ, ki èmi má ṣe kọminú ohunkóhun. Àwọn arákùnrin mẹ́fà wọ̀nyí sì bá mi lọ, a sì wọ ilé ọkùnrin náà.
Mueihla long khaw kai taengah, 'Boelhkhoeh kolla amih te puei laeh,’ a ti. Te dongah manuca parhuk he kamah neh kan lo puei tih hlang im khuila ka kun uh.
13 Ó sì sọ fún wa bí òun ti rí angẹli kan tí ó dúró ní ilé rẹ̀, tí ó sì wí pé, ‘Ránṣẹ́ lọ sí Joppa, kí ó sì pe Simoni tí àpèlé rẹ̀ jẹ́ Peteru;
Anih long khaw a im ah a pai vaengah puencawn a hmuh tih, Joppa ah hlang tueih lamtah Peter la a khue Simon te tah laeh.
14 ẹni tí yóò sọ ọ̀rọ̀ fún ọ, nípa èyí tí a ó fi gba ìwọ àti gbogbo ilé rẹ là.’
Anih loh nang taengkah a thui ol dongah namah neh na imko boeih khaw khang la na om ni,’ a ti nah te kaimih taengah ha puen bal.
15 “Bí mo sì ti bẹ̀rẹ̀ sì sọ, Ẹ̀mí Mímọ́ sì bà lé wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti bà lé wa ni àtètèkọ́ṣe.
A cuek ca vaengkah mamih soah a tlak vanbangla thui hamla ka tong vaengah amih te Mueihla Cim loh a tlak thil coeng.
16 Nígbà náà ni mo rántí ọ̀rọ̀ Olúwa, bí ó ti wí pé, ‘Johanu fi omi bamitiisi nítòótọ́; ṣùgbọ́n a ó fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi yín.’
Te vaengah Boeipa kah ol, 'Johan loh tui ah n'nuem. Tedae nangmih tah Mueihla Cim ah n'nuem ni,’ a ti te ka poek.
17 Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run sì ti fi irú ẹ̀bùn kan náà fún wọn bí ó ti fi fún àwa pẹ̀lú nígbà tí a gba Jesu Kristi Olúwa gbọ́, ta ni èmi tí n ó fi rò pé mo le è de Ọlọ́run ní ọ̀nà?”
Te dongah mamih van bangla Boeipa Jesuh Khrih dongah aka tangnah tah Pathen loh amih te vanat la kutdoe a paek atah kai metlam ka om tih Pathen te ka kang thai eh,” a ti.
18 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì pa ẹnu wọn mọ́, wọ́n sì yin Ọlọ́run ògo wí pé, “Ǹjẹ́ Ọlọ́run fi ìrònúpìwàdà sí ìyè fún àwọn aláìkọlà pẹ̀lú!”
A yaak uh vaengah sap duem uh tih Pathen te a thangpom uh. Te dongah, “Hingnah ham yutnah te Pathen loh namtom taengah khaw a paek coeng,” a ti uh.
19 Nítorí náà àwọn tí a sì túká kiri nípasẹ̀ inúnibíni tí ó dìde ní ti Stefanu, wọ́n rìn títí de Fonisia, àti Saipurọsi, àti Antioku, wọn kò sọ ọ̀rọ̀ náà fún ẹnìkan bí kò ṣe fún kìkì àwọn Júù.
Phacip phabaem loh Stephen te a pai thil dongah amih khaw palang uh tih Phoiniki, Kupros neh Antiok la cet uh. Tedae Judah bueng pawt atah u taengah khaw ol thui uh pawh.
20 Ṣùgbọ́n àwọn kan ń bẹ nínú wọn tí ó jẹ́ ará Saipurọsi àti Kirene; nígbà tí wọ́n dé Antioku, wọ́n sọ̀rọ̀ fún àwọn Helleni pẹ̀lú, wọ́n ń wàásù ìròyìn ayọ̀ nípa Jesu Olúwa.
Te vaengah amih khuiah khaw Kuporos neh Kurena hlang rhoek khaw bet om van. Amih tah Antiok la cet uh tih Hellenist rhoek taengah khaw a thui uh vaengah Boeipa Jesuh ni a thui uh.
21 Ọwọ́ Olúwa sì wà pẹ̀lú wọn, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì gbàgbọ́, wọ́n sì yípadà sí Olúwa.
Amih te Boeipa kut loh a om puei dongah Boeipa taengla aka bal tih aka tangnah hlangmi long khaw ping uh.
22 Ìròyìn nípa wọn sì dé etí ìjọ ti ó wà ni Jerusalẹmu; wọ́n sì rán Barnaba lọ títí dé Antioku;
Amih kawng te Jerusalem kah aka om hlangboel kah a hna ah olthang la a yaak uh. Te dongah Antiok la caeh ham Barnabas te a tueih uh.
23 Nígbà ti ó dé ti ó sì rí ẹ̀rí oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run, ó yọ̀, ó sì gba gbogbo wọn níyànjú pé, pẹ̀lú ìpinnu ọkàn ni kí wọn fi ara mọ́ Olúwa.
Anih a pha vaengah Pathen kah lungvatnah aka hmuh rhoek tah omngaih uh tih thinko mangtaengnah he Boeipa dongah rhaeh rhong ham boeih thaphoh uh thae.
24 Nítorí òun jẹ́ ènìyàn rere, ó sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àti fún ìgbàgbọ́; ènìyàn púpọ̀ ni a sì kà kún Olúwa.
Anih te hlang then pakhat la om tih Mueihla Cim neh tangnah nen khaw baetawt. Te dongah hlangping loh Boeipa taengah muep tomthap la om.
25 Barnaba sì jáde lọ sí Tarsu láti wá Saulu,
Te phoeiah Saul tlap hamla Tarsus ah cet.
26 nígbà tí ó sì rí i, ó mú un wá sí Antioku. Fún ọdún kan gbáko ni wọ́n fi ń bá ìjọ péjọpọ̀, tí wọ́n sì kọ́ ènìyàn púpọ̀. Ní Antioku ni a sì kọ́kọ́ ti pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ni “Kristiani.”
A hmuh phoeiah Antiok la a khuen. A pha vaengah amih te kum khat puet hlangboel khuiah tingtun uh tih hlangping te yet te a thuituen. Te dongah hnukbang rhoek te Khrihca rhoek tila Antiok ah a khue lamhma cuek.
27 Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni àwọn wòlíì sì ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ wá sí Antioku.
Te vaeng tue ah te tonghma rhoek tah Jerusalem lamkah Antiok la cet uh.
28 Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn, ti a ń pè ni Agabu sí dìde, ó ti ipa Ẹ̀mí sọ pé, ìyàn ńlá yóò mú yíká gbogbo ilẹ̀ Romu. (Èyí sì ṣẹlẹ̀ nígbà ìṣèjọba Kilaudiu.)
Te vaengah amih khuikah pakhat, a ming ah Agabus loh thoo tih lunglai pum ah om ham aka cai khokha tung te mueihla neh a phoe. Te te Klaudius tue vaengah thoeng coeng.
29 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì pinnu, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí agbára rẹ̀ ti tó, láti rán ìrànlọ́wọ́ sí àwọn arákùnrin tí ó wà ní Judea.
Te dongah hnukbang rhoek tah pakhat rhip loh amah kah a noeng bangla Judea kah manuca khosa rhoek taengah bomnah pat ham a hmoel uh.
30 Wọn sì ṣe bẹ́ẹ̀, wọn sì fi ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí àwọn àgbà láti ọwọ́ Barnaba àti Saulu.
Te tlam te a saii phoeiah Barnabas neh Sual kut ah patong rhoek taengla a pat uh.