< Acts 10 >

1 Ọkùnrin kan sì wà ni Kesarea ti a ń pè ní Korneliu, balógun ọ̀rún ti ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí a ń pè ni Itali.
Na i Hiharia tetahi tangata, ko Koroniria te ingoa, he keneturio no te pu i kiia nei ko to Itari;
2 Olùfọkànsìn, àti ẹni ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run tilétilé rẹ̀ gbogbo, ẹni tí ó ń tọrẹ àánú púpọ̀ fún àwọn ènìyàn, tí ó sì ń gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run nígbà gbogbo.
He tangata karakia ia, e wehi ana i te Atua, ratou ko tona whare katoa, he maha ana mahi atawhai ki te iwi, me te inoi tonu ki te Atua.
3 Níwọ́n wákàtí kẹsànán ọjọ́, ó rí nínú ìran kedere angẹli Ọlọ́run kan wọlé tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Korneliu!”
I kite nui ia, he whakarehu, i te mea ka tata ki te iwa o nga haora o te ra, i tetahi anahera a te Atua, e haere mai ana ki a ia, e mea ana hoki ki a ia, E Koroniria.
4 Nígbà tí ó sì tẹjúmọ́ ọn, ti ẹ̀rù sì bà á, ó ní, “Kín ni, Olúwa?” Ó sì wí fún un pé, “Àdúrà rẹ àti ọrẹ-àánú, tìrẹ gòkè lọ síwájú Ọlọ́run fún ìrántí.
Na ka titiro matatau atu ia ki a ia, ka wehi, ka mea, he aha, e te Ariki? Ka ki tera ki a ia, Kua puta ake au inoi me au mahi atawhai, hei whakamahara ki te aroaro o te Atua.
5 Sì rán ènìyàn nísinsin yìí lọ sí Joppa, kí wọn sì pe Simoni wá, ẹni ti àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Peteru.
Na tonoa aianei he tangata ki Hopa, ki te tiki i a Haimona, ko te rua nei o ona ingoa ko Pita.
6 Ó wọ̀ sí ilé Simoni aláwọ, tí ilé rẹ̀ wà létí Òkun; òun ni yóò sọ fún ọ bí ìwọ ó ti ṣe.”
He manuhiri ia na Haimona kaimahi hiako, i te taha nei o te moana tona whare.
7 Nígbà tí angẹli náà tí ó bá Korneliu sọ̀rọ̀ sì fi i sílẹ̀ lọ ó pe méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ ilé rẹ̀, àti ọmọ-ogun olùfọkànsìn kan, nínú àwọn ti ó máa ń dúró tì í nígbà gbogbo.
A, no te rironga atu o te anahera i korero nei ki a ia, ka karangatia e ia tokorua o ana pononga tane, me tetahi hoia karakia no te hunga e mahi tonu ana ki a ia;
8 Nígbà tí ó sì tí ṣàlàyé ohun gbogbo fún wọn, ó rán wọn lọ sí Joppa.
A, ka oti nga mea katoa te korero ki a ratou, ka tonoa ratou e ia ki Hopa.
9 Ni ọjọ́ kejì bí wọ́n ti ń lọ lọ́nà àjò wọn, tí wọ́n sì súnmọ́ ilé náà, Peteru gun òkè ilé lọ láti gbàdúrà ni ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́,
Na i te aonga ake, i a ratou e haere ana, e whakatata atu ana ki te pa, ka kake a Pita ki runga ki te tuanui, i te ono o nga haora, ki te inoi:
10 ebi sì pa á gidigidi, ó sì ń fẹ́ láti jẹun, ó bọ́ sí ojúran.
Na ka pa ki a ia te matekai, ka mea ki te kai: otira i a ratou e taka mai ana, ka tau iho te wairua matakite ki a ia;
11 Ó sì rí ọ̀run ṣí, ohun èlò kan si sọ̀kalẹ̀ bí gọgọwú ńlá, tí a ti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, sọ̀kalẹ̀ sí ilẹ̀.
Na ka kite ia i te rangi kua tuwhera, me tetahi mea e heke iho ana, he mea tuku iho ma nga pito e wha, ki te whenua:
12 Nínú rẹ̀ ni onírúurú ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin wà, àti ohun tí ń rákò ni ayé àti ẹyẹ ojú ọ̀run.
I roto i taua mea nga momo kararehe waewae wha katoa, nga mea ngokingoki katoa o te whenua, me nga manu o te rangi.
13 Ohùn kan si fọ̀ sí i pe, “Dìde, Peteru; máa pa kí o sì máa jẹ.”
I reira ka puta mai he reo ki a ia, Whakatika, e Pita; patua, kainga.
14 Ṣùgbọ́n Peteru dáhùn pé, “Rara, Olúwa; nítorí èmi kò jẹ ohun èèwọ̀ àti aláìmọ́ kan rí.”
Ko Pita ia i mea, Kahore, e te Ariki; kiano ahau i kai i te mea noa, i te mea poke ranei.
15 Ohùn kan sì tún fọ̀ sí i lẹ́ẹ̀méjì pé, “Ohun tí Ọlọ́run bá ti wẹ̀mọ́, ìwọ má ṣe pè é ní èèwọ̀ mọ́.”
Ka puta mai ano he reo ki a ia, ka tuaruatia, Ko a te Atua i mea ai kia ma, kaua e whakanoatia e koe.
16 Èyí sì ṣe lẹ́ẹ̀mẹ́ta; lójúkan náà a sì gbé ohun èlò náà padà lọ sókè ọ̀run.
E toru meatanga o tenei: a i reira tonu ka tangohia atu taua mea ki te rangi.
17 Bí Peteru sì ti ń dààmú nínú ara rẹ̀ bí òun bá ti mọ̀ ìran tí òun ri yìí sí, si wò ó, àwọn ọkùnrin tí a rán wá láti ọ̀dọ̀ Korneliu dé. Wọ́n ń béèrè ilé Simoni, wọ́n dúró ní ẹnu-ọ̀nà.
I taua wa tonu, i a Pita e whakaaroaro ana i roto i a ia ki te tikanga o tenei whakakitenga, na, ko nga tangata i tonoa mai ra e Koroniria, tera kua uiui ki te whare o Haimona, tu ana i mua i te kuwaha,
18 Wọn nahùn béèrè bí Simoni tí a ń pè ní Peteru, wọ̀ níbẹ̀.
Karanga ana mai, ui ana, kei reira ranei e noho ana a Pita, te rua nei o ona ingoa ko Haimona.
19 Bí Peteru sì ti ń ronú ìran náà, Ẹ̀mí wí fún un pé, “Wò ó, àwọn ọkùnrin mẹ́ta ń wá ọ.
A, i a Pita e whakaaro ana mo taua whakakitenga, ka mea te Wairua ki a ia, Nana, tokotoru enei tangata e rapu ana i a koe.
20 Ǹjẹ́ dìde, sọ̀kalẹ̀ kí ó sì bá wọn lọ, má ṣe kó ara ró láti bá wọn lọ, nítorí èmi ni ó rán wọn.”
Na whakatika, heke atu, haere tahi koutou, kei ruarua; naku hoki ratou i tono mai.
21 Nígbà náà ni Peteru sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn ọkùnrin náà tí a rán, ó sì wí pé, “Wò ó, èmi ni ẹni tí ẹ̀yin ń wá, kín ni ìdí rẹ̀ ti ẹ fi wá?”
Na ka heke atu a Pita ki aua tangata, ka mea, Na, ko ahau tenei e rapu nei koutou: he aha te take o ta koutou haere mai?
22 Wọ́n sì wí pé, “Korneliu balógun ọ̀rún, ọkùnrin olóòtítọ́, àti ẹni ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó sì ní orúkọ rere lọ́dọ̀ gbogbo orílẹ̀-èdè àwọn Júù, òun ni a ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run kọ́ nípasẹ̀ angẹli mímọ́, láti ránṣẹ́ pè ọ́ wá sí ilé rẹ̀ àti láti gbọ́ ọ̀rọ̀ lẹ́nu rẹ.”
Na ka mea ratou, Ko Koroniria ra, he keneturio, he tangata tika, e wehi ana i te Atua, e korerotia paitia ana e te iwi katoa o nga Hurai, kua whakamaharatia ia e te Atua na tetahi anahera tapu kia tikina atu koe ki tona whare, kia rongo ia ki et ahi kupu i a koe.
23 Nígbà náà ni Peteru pè wọ́n wọlé, ó gbà wọ́n lálejò. Ní ọjọ́ kejì, ó sì dìde, ó bá wọn lọ, díẹ̀ nínú àwọn ti o ti gbàgbọ́ ní Joppa sì bá a lọ pẹ̀lú.
Na karanga ana ia i a ratou ki roto hei manuhiri mana. A, i te aonga ake, ka whakatika ia ka haere atu me ratou, a ko etahi o nga teina no Hopa i haere tahi me ia.
24 Lọ́jọ́ kejì wọ́n sì wọ Kesarea, Korneliu sì ti ń retí wọn, ó sì ti pe àwọn ìbátan àti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ jọ.
A ao ake ka tomo ratou ki Hiharia. Na ko Koronira e tatari mai ana ki a ratou, he mea karanga nana kia huihui mai ona whanaunga me ona hoa tupu.
25 Ó sì ṣe bí Peteru ti ń wọlé, Korneliu pàdé rẹ̀, ó wólẹ̀ lẹ́sẹ̀ rẹ̀, ó sì foríbalẹ̀ fún un.
A, no ka tomo atu a Pita, ka tutaki a Koroniria ki a ia, ka hinga ki ona waewae, ka koropiko ki a ia.
26 Ṣùgbọ́n Peteru gbé e dìde, ó ni, “Dìde ènìyàn ni èmi tìkára mi pẹ̀lú.”
Otira ka whakaara ake a Pita i a ia, ka mea, E tu ki runga; he tangata nei ano ahau.
27 Bí ó sì ti ń bá a sọ̀rọ̀, ó wọlé ó sì rí àwọn ènìyàn púpọ̀ tí wọ́n péjọ.
Na i a ia e korero ana ki a ia, ka tomo atu ia ki roto, ka kite i te menenga tokomaha,
28 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin mọ̀ bí ó ti jẹ́ èèwọ̀ fún ẹni tí ó jẹ́ Júù, láti bá ẹni tí ó jẹ́ ará ilẹ̀ mìíràn kẹ́gbẹ́, tàbí láti tọ̀ ọ́ wá; ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fihàn mi pé, ki èmi má ṣe pé ẹnikẹ́ni ni èèwọ̀ tàbí aláìmọ́.
Ka mea atu ki a ratou, E matau ana koutou e kore e tika kia huihui te tangata o nga Hurai, kia haere atu ranei ki te tangata iwi ke: otiia kua whakakitea e te Atua ki ahau kia kaua e kiia tetahi tangata he noa, he poke.
29 Nítorí náà ni mo sì ṣe wá ní àìjiyàn, bí a ti ránṣẹ́ pè mi, ǹjẹ́ mo béèrè, nítorí kín ní ẹ̀yin ṣe ránṣẹ́ pè mi?”
Koia ahau i haere mai ai, kihai i aha i te tikinga ake i ahau. Na ka ui nei ahau, he aha te take i tikina ake ai ahau?
30 Korneliu sì dáhùn pé, “Ní ìjẹrin, mo ń ṣe àdúrà wákàtí kẹsànán ọjọ́ ni ilé mi títí di idayìí, sì wò ó, ọkùnrin kan aláṣọ, àlà dúró níwájú mi.
Ka mea a Koroniria, Ka wha nga ra inaianei tae mai ki tenei haora, e whakarite ana ahau i te inoinga o te iwa o nga haora i roto i toku whare; na, ko te tangata e tu ana i toku aroaro, kanapa tonu te kakahu,
31 Ó sì wí pé, ‘Korneliu, a gbọ́ àdúrà rẹ, ọrẹ-àánú rẹ̀ sì wà ni ìrántí níwájú Ọlọ́run.
E mea ana, E Koroniria, kua rangona tau inoi, a e maharatia ana au mahi atawhai i te aroaro o te Atua.
32 Ǹjẹ́ ránṣẹ́ lọ sí Joppa, kí ó sì pe Simoni wá, ẹni ti àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Peteru; ó wọ̀ ní ilé Simoni aláwọ létí òkun.’
Na, tonoa he tangata ki Hopa, ka karanga ki a koe i a Haimona, te rua nei o ona ingoa ko Pita: he manuhiri ia i roto i te whare o Haimona kaimahi hiako, i te taha moana.
33 Nítorí náà ni mo sì ṣe ránṣẹ́ sì ọ lójúkan náà, ìwọ sì ṣeun tí ó fi wá. Gbogbo wa pé níwájú Ọlọ́run nísinsin yìí, láti gbọ́ ohun gbogbo, ti a pàṣẹ fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.”
I reira tonu ka tono tangata atu ahau ki a koe; na he pai rawa tou haerenga mai. No reira kei konei katoa matou kei te aroaro o te Atua, whakarongo ai ki nga mea katoa kua whakahaua e te Ariki ki a koe.
34 Peteru sì ya ẹnu rẹ, ó sì wí pé, “Nítòótọ́ mo wòye pé, Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn.
Na ka puaki te mangai o Pita, ka mea, he pono ka kite ahau kahore a te Atua whakapai kanohi:
35 Ṣùgbọ́n ni gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá bẹ̀rù rẹ̀, ti ó sì ń ṣiṣẹ́ òdodo, ẹni ìtẹ́wọ́gbà ni lọ́dọ̀ rẹ̀.
Otiia i roto i nga tini iwi ko te tangata e wehi ana ki a ia, a e mahi ana i te tika, ka paingia e ia.
36 Ẹyin mọ ọrọ̀ tí Ọlọ́run rán sí àwọn ọmọ Israẹli láti kéde ìròyìn ayọ̀ àlàáfíà nípasẹ̀ Jesu Kristi, ẹni ti ṣe Olúwa ohun gbogbo.
Ko te kupu i tukua mai e ia ki nga tamariki a Iharaira, he kauwhau i te rongopai o te rangimarie na Ihu Karaiti: ko ia nei te Ariki o te katoa:
37 Ẹ̀yin náà mọ ọ̀rọ̀ náà tí a kéde rẹ̀ yíká gbogbo Judea, tí a bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ láti Galili, lẹ́yìn bamitiisi ti Johanu wàásù rẹ̀.
Ko taua kupu, kei te mohio koutou, i kauwhautia ra puta noa i Huria katoa, i timata mai i Kariri, i muri o te iriiri i kauwhautia e Hoani;
38 Àní Jesu ti Nasareti, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti da Ẹ̀mí Mímọ́ àti agbára le lórí; ẹni tí ó ń kiri ṣe oore, ó ń ṣe ìmúláradá gbogbo àwọn tí èṣù sì ń pọ́n lójú; nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
Ara ko Ihu o Nahareta, ta te Atua whakawahinga i a ia ki te Wairua Tapu, ki te kaha: a haereere ana ia ki te mahi i te pai, ki te whakaora i te hunga katoa i pehia e te rewera; no te mea i a ia te Atua.
39 “Àwa sì ni ẹlẹ́rìí gbogbo ohun tí ó ṣe, ní ilẹ̀ àwọn Júù, àti ni Jerusalẹmu. Ẹni tí wọ́n pa nípa gbígbékọ́ sí orí igi.
Ko matou hoki nga kaiwhakaatu o nga mea katoa i mea ai ia ki te whenua o nga Hurai, ki Hiruharama hoki: a whakamatea ana ia e ratou, he mea whakairi ki runga ki te rakau.
40 Òun ni Ọlọ́run jí dìde ni ọjọ́ kẹta ó sì fi i hàn gbangba.
Na ko ia i whakaarahia ake e te Atua i te toru o nga ra, a meinga ana ia kia kitea nuitia,
41 Kì í ṣe fún gbogbo ènìyàn ni o ri, bí kò ṣe fún àwa ti a jẹ́ ẹlẹ́rìí ti a ti ọwọ́ Ọlọ́run yàn tẹ̀lé, ti a bá a jẹ, ti a sì bá à mu lẹ́yìn ìgbà ti ó jíǹde kúrò nínú òkú.
Ehara i te mea e te iwi katoa, engari e te hunga i whiriwhiria i mua e te Atua, ara e matou, i kai tahi nei, i inu tahi nei me ia, i muri i tona aranga ake i te hunga mate.
42 Ó sì pàṣẹ fún wa láti wàásù fún àwọn ènìyàn, àti láti jẹ́rìí pé, òun ni a ti ọwọ́ Ọlọ́run yàn ṣe onídàájọ́ ààyè àti òkú.
I whai kupu hoki ia ki a matou kia kauwhau ki te iwi, kia whakaatu, ko ia ta te Atua i whakarite ai hei kaiwhakawa mo nga tangata ora, mo nga tangata mate.
43 Òun ni gbogbo àwọn wòlíì jẹ́rìí sì pé, ẹnikẹ́ni ti ó bá gbà á gbọ́ yóò rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ gbà nípa orúkọ rẹ̀.”
He kaiwhakaatu nga poropiti katoa mona, ara ma tona ingoa ka whiwhi ai ki te murunga hara nga tangata katoa e whakarongo ana ki a ia.
44 Bí Peteru sì ti ń sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí lẹ́nu, Ẹ̀mí Mímọ́ bà lé gbogbo àwọn ti ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà.
I a Pita ano e korero ana i enei kupu, ka tau iho te Wairua Tapu ki te hunga katoa e whakarongo ana ki te kupu.
45 Ẹnu sì yà àwọn onígbàgbọ́ ti a ti kọ nílà tí wọ́n bá Peteru wá, nítorí ti a tu ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ sórí àwọn aláìkọlà pẹ̀lú.
A, ko te hunga o te kotinga i whakapono nei, ko nga mea i haere tahi mai me Pita, miharo ana no te mea kua ringihia tahitia iho te Wairua Tapu ki nga Tauiwi.
46 Nítorí wọ́n gbọ́, wọ́n ń fọ onírúurú èdè, wọn sì yin Ọlọ́run lógo. Nígbà náà ni Peteru dáhùn wí pé,
I rongo hoki ratou ki nga reo i korero ai ratou, i whakanui ai i te Atua. I reira ka whakahoki a Pita,
47 “Ẹnikẹ́ni ha lè ṣòfin pe, kí a má bamitiisi àwọn wọ̀nyí tí wọ́n gba Ẹ̀mí Mímọ́ bí àwa?”
E ahei ranei te whakakahore e tetahi te wai, kei iriiria enei kua whiwhi tahi nei me tatou ki te Wairua Tapu?
48 Ó sì pàṣẹ kí a bamitiisi wọn ni orúkọ Jesu Kristi. Nígbà náà ni wọ́n bẹ̀ ẹ́ kí ó dúró ni ọjọ́ mélòó kan.
Na ka whakahau ia kia iriiria ratou i runga i te ingoa o Ihu Karaiti. I reira ka tohe ratou ki a ia kia noho mo etahi ra.

< Acts 10 >