< Acts 10 >
1 Ọkùnrin kan sì wà ni Kesarea ti a ń pè ní Korneliu, balógun ọ̀rún ti ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí a ń pè ni Itali.
Na rĩrĩ, kũu Kaisarea nĩ kwarĩ mũndũ wetagwo Korinelio, ũrĩa warĩ mũnene-wa-thigari-igana rĩmwe cia mbũtũ ĩrĩa yoĩkaine ta Mbũtũ ya Italia.
2 Olùfọkànsìn, àti ẹni ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run tilétilé rẹ̀ gbogbo, ẹni tí ó ń tọrẹ àánú púpọ̀ fún àwọn ènìyàn, tí ó sì ń gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run nígbà gbogbo.
Mũndũ ũcio na andũ othe a nyũmba yake nĩmeyamũrĩire Ngai na makamwĩtigagĩra; nake nĩaheanaga indo ciake na ũtaana kũrĩ andũ arĩa maarĩ abatari na nĩahooyaga Ngai kaingĩ.
3 Níwọ́n wákàtí kẹsànán ọjọ́, ó rí nínú ìran kedere angẹli Ọlọ́run kan wọlé tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Korneliu!”
Mũthenya ũmwe ta thaa kenda cia mĩaraho-rĩ, akĩona kĩoneki. Akĩona mũraika wa Ngai wega, ũrĩa wokire harĩ we na akĩmwĩra atĩrĩ, “Korinelio!”
4 Nígbà tí ó sì tẹjúmọ́ ọn, ti ẹ̀rù sì bà á, ó ní, “Kín ni, Olúwa?” Ó sì wí fún un pé, “Àdúrà rẹ àti ọrẹ-àánú, tìrẹ gòkè lọ síwájú Ọlọ́run fún ìrántí.
Korinelio akĩmũrora aiyũrĩtwo nĩ guoya, akĩũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ Mwathani?” Nake mũraika akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mahooya maku na indo iria ũheete andũ arĩa athĩĩni nĩikinyĩte igũrũ kũrĩ Ngai rĩrĩ iruta rĩa kũririkanwo.
5 Sì rán ènìyàn nísinsin yìí lọ sí Joppa, kí wọn sì pe Simoni wá, ẹni ti àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Peteru.
Na rĩrĩ, tũma andũ mathiĩ Jopa magĩĩre mũndũ wĩtagwo Simoni, na nowe wĩtagwo Petero.
6 Ó wọ̀ sí ilé Simoni aláwọ, tí ilé rẹ̀ wà létí Òkun; òun ni yóò sọ fún ọ bí ìwọ ó ti ṣe.”
Araikara gwa Simoni ũria mũtanduki wa njũũa, o ũrĩa nyũmba yake ĩrĩ rũtere-inĩ rwa iria.”
7 Nígbà tí angẹli náà tí ó bá Korneliu sọ̀rọ̀ sì fi i sílẹ̀ lọ ó pe méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ ilé rẹ̀, àti ọmọ-ogun olùfọkànsìn kan, nínú àwọn ti ó máa ń dúró tì í nígbà gbogbo.
Rĩrĩa mũraika ũcio wamwarĩirie aathiire, Korinelio agĩĩta ndungata ciake igĩrĩ na mũthigari ũmwe weamũrĩire Ngai, na aarĩ ũmwe wa andũ arĩa maamũtungatagĩra.
8 Nígbà tí ó sì tí ṣàlàyé ohun gbogbo fún wọn, ó rán wọn lọ sí Joppa.
Akĩmeera ũrĩa wothe kwahanĩte agĩcooka akĩmatũma Jopa.
9 Ni ọjọ́ kejì bí wọ́n ti ń lọ lọ́nà àjò wọn, tí wọ́n sì súnmọ́ ilé náà, Peteru gun òkè ilé lọ láti gbàdúrà ni ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́,
Mũthenya ũcio ũngĩ warũmĩrĩire ta thaa thita cia mũthenya marĩ njĩra-inĩ makuhĩrĩirie itũũra rĩu-rĩ, Petero akĩhaica nyũmba-igũrũ nĩgeetha akahooe Ngai.
10 ebi sì pa á gidigidi, ó sì ń fẹ́ láti jẹun, ó bọ́ sí ojúran.
Nake akĩigua aahũũta na akĩbatario nĩ kĩndũ gĩa kũrĩa, na rĩrĩa irio ciarugagwo-rĩ, akĩgocerera.
11 Ó sì rí ọ̀run ṣí, ohun èlò kan si sọ̀kalẹ̀ bí gọgọwú ńlá, tí a ti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, sọ̀kalẹ̀ sí ilẹ̀.
Nake akĩona igũrũ rĩhingũrĩtwo na kĩndũ gĩatariĩ ta gĩtama kĩnene gĩkĩharũrũkio thĩ kĩnyiitĩtwo mĩthia ĩna.
12 Nínú rẹ̀ ni onírúurú ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin wà, àti ohun tí ń rákò ni ayé àti ẹyẹ ojú ọ̀run.
Nakĩo kĩarĩ na nyamũ cia mĩthemba yothe ya iria irĩ magũrũ mana, o na nyamũ iria itaambaga thĩ, o na nyoni cia rĩera-inĩ.
13 Ohùn kan si fọ̀ sí i pe, “Dìde, Peteru; máa pa kí o sì máa jẹ.”
Hĩndĩ ĩyo mũgambo ũkĩmwĩra atĩrĩ, “Petero, ũkĩra. Thĩnja na ũrĩe.”
14 Ṣùgbọ́n Peteru dáhùn pé, “Rara, Olúwa; nítorí èmi kò jẹ ohun èèwọ̀ àti aláìmọ́ kan rí.”
Petero agĩcookia atĩrĩ, “Aca, Mwathani! Ndirĩ ndarĩa kĩndũ gĩtarĩ kĩamũre, kana kĩndũ kĩrĩ thaahu.”
15 Ohùn kan sì tún fọ̀ sí i lẹ́ẹ̀méjì pé, “Ohun tí Ọlọ́run bá ti wẹ̀mọ́, ìwọ má ṣe pè é ní èèwọ̀ mọ́.”
Mũgambo ũkĩmwarĩria riita rĩa keerĩ ũkĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũkanoige kĩndũ o na kĩrĩkũ kĩrĩa Ngai atheretie atĩ ti kĩamũre.”
16 Èyí sì ṣe lẹ́ẹ̀mẹ́ta; lójúkan náà a sì gbé ohun èlò náà padà lọ sókè ọ̀run.
Ũndũ ũyũ wekĩkire maita matatũ, na o rĩmwe gĩtama kĩu gĩgĩcookio na igũrũ.
17 Bí Peteru sì ti ń dààmú nínú ara rẹ̀ bí òun bá ti mọ̀ ìran tí òun ri yìí sí, si wò ó, àwọn ọkùnrin tí a rán wá láti ọ̀dọ̀ Korneliu dé. Wọ́n ń béèrè ilé Simoni, wọ́n dúró ní ẹnu-ọ̀nà.
Na rĩrĩa Petero eeyũragia gĩtũmi gĩa kĩoneki kĩu oonete-rĩ, andũ arĩa maatũmĩtwo nĩ Korinelio makĩona harĩa nyũmba ya Simoni yarĩ, na makĩrũgama hau kĩhingo-inĩ.
18 Wọn nahùn béèrè bí Simoni tí a ń pè ní Peteru, wọ̀ níbẹ̀.
Magĩĩtana, makĩũria kana Simoni ũrĩa wĩtagwo Petero aaikaraga kũu.
19 Bí Peteru sì ti ń ronú ìran náà, Ẹ̀mí wí fún un pé, “Wò ó, àwọn ọkùnrin mẹ́ta ń wá ọ.
Na rĩrĩa Petero eeciiragia ũhoro wa kĩoneki kĩu, Roho akĩmwĩra atĩrĩ, “Simoni, harĩ na andũ atatũ maragũcaria.
20 Ǹjẹ́ dìde, sọ̀kalẹ̀ kí ó sì bá wọn lọ, má ṣe kó ara ró láti bá wọn lọ, nítorí èmi ni ó rán wọn.”
Nĩ ũndũ ũcio, ũkĩra ũikũrũke, ũthiĩ nao na ndũkagĩe na nganja nĩgũkorwo nĩ niĩ ndĩmatũmĩte.”
21 Nígbà náà ni Peteru sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn ọkùnrin náà tí a rán, ó sì wí pé, “Wò ó, èmi ni ẹni tí ẹ̀yin ń wá, kín ni ìdí rẹ̀ ti ẹ fi wá?”
Petero agĩikũrũka, akĩĩra andũ acio atĩrĩ, “Nĩ niĩ mũndũ ũcio mũracaria. Mũũkĩte nĩkĩ?”
22 Wọ́n sì wí pé, “Korneliu balógun ọ̀rún, ọkùnrin olóòtítọ́, àti ẹni ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó sì ní orúkọ rere lọ́dọ̀ gbogbo orílẹ̀-èdè àwọn Júù, òun ni a ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run kọ́ nípasẹ̀ angẹli mímọ́, láti ránṣẹ́ pè ọ́ wá sí ilé rẹ̀ àti láti gbọ́ ọ̀rọ̀ lẹ́nu rẹ.”
Nao andũ acio magĩcookia atĩrĩ, “Tuumĩte gwa Korinelio, ũrĩa mũnene-wa-thigari-igana rĩmwe. Nĩ mũndũ mũthingu na mwĩtigĩri-Ngai, na nĩatĩĩtwo nĩ Ayahudi othe. Mũraika mũtheru aramwĩrire atũmane ũthiĩ gwake mũciĩ nĩgeetha aigue ũrĩa ũrenda kuuga.”
23 Nígbà náà ni Peteru pè wọ́n wọlé, ó gbà wọ́n lálejò. Ní ọjọ́ kejì, ó sì dìde, ó bá wọn lọ, díẹ̀ nínú àwọn ti o ti gbàgbọ́ ní Joppa sì bá a lọ pẹ̀lú.
Hĩndĩ ĩyo Petero akĩĩra andũ acio matoonye nyũmba matuĩke ageni aake. Mũthenya ũyũ ũngĩ warũmĩrĩire Petero agĩthiĩ nao, na ariũ a Ithe witũ amwe kuuma Jopa magĩthiĩ nake.
24 Lọ́jọ́ kejì wọ́n sì wọ Kesarea, Korneliu sì ti ń retí wọn, ó sì ti pe àwọn ìbátan àti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ jọ.
Naguo mũthenya ũcio ũngĩ warũmĩrĩire magĩkinya Kaisarea. Korinelio agĩkorwo ametereire na eetĩte andũ a nyũmba yake na arata a hakuhĩ.
25 Ó sì ṣe bí Peteru ti ń wọlé, Korneliu pàdé rẹ̀, ó wólẹ̀ lẹ́sẹ̀ rẹ̀, ó sì foríbalẹ̀ fún un.
Na rĩrĩa Petero aatoonyaga nyũmba, Korinelio akĩmũtũnga na akĩĩgũithia magũrũ-inĩ make amwĩnyiihĩrie.
26 Ṣùgbọ́n Peteru gbé e dìde, ó ni, “Dìde ènìyàn ni èmi tìkára mi pẹ̀lú.”
No Petero akĩmũũkĩria, akĩmwĩra atĩrĩ, “Rũgama, niĩ ndĩ o mũndũ o na niĩ.”
27 Bí ó sì ti ń bá a sọ̀rọ̀, ó wọlé ó sì rí àwọn ènìyàn púpọ̀ tí wọ́n péjọ.
O makĩaragia-rĩ, Petero agĩtoonya thĩinĩ na agĩkora gĩkundi kĩnene kĩa andũ.
28 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin mọ̀ bí ó ti jẹ́ èèwọ̀ fún ẹni tí ó jẹ́ Júù, láti bá ẹni tí ó jẹ́ ará ilẹ̀ mìíràn kẹ́gbẹ́, tàbí láti tọ̀ ọ́ wá; ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fihàn mi pé, ki èmi má ṣe pé ẹnikẹ́ni ni èèwọ̀ tàbí aláìmọ́.
Akĩmeera atĩrĩ: “Inyuĩ nĩmũũĩ wega atĩ Mũyahudi ndetĩkĩrĩtio nĩ watho kũgwatanĩra na mũndũ wa Ndũrĩrĩ o na kana kũmũceerera. No Ngai nĩanyonetie atĩ ndiagĩrĩirwo nĩ kuuga atĩ mũndũ o na ũrĩkũ ti mwamũre kana atĩ arĩ na thaahu.
29 Nítorí náà ni mo sì ṣe wá ní àìjiyàn, bí a ti ránṣẹ́ pè mi, ǹjẹ́ mo béèrè, nítorí kín ní ẹ̀yin ṣe ránṣẹ́ pè mi?”
Nĩ ũndũ ũcio rĩrĩa ndĩratũmanĩirwo, ndĩrokire itegũkararia. Njĩtĩkĩria ngũũrie kĩrĩa kĩratũmire ũndũmanĩre?”
30 Korneliu sì dáhùn pé, “Ní ìjẹrin, mo ń ṣe àdúrà wákàtí kẹsànán ọjọ́ ni ilé mi títí di idayìí, sì wò ó, ọkùnrin kan aláṣọ, àlà dúró níwájú mi.
Nake Korinelio akĩmũcookeria atĩrĩ: “Matukũ mana mahĩtũku, ndaarĩ thĩinĩ wa nyũmba yakwa ngĩhooya ithaa-inĩ ta rĩĩrĩ rĩa thaa kenda cia mĩaraho. Mũndũ warĩ na nguo ciahenagia akĩrũgama o rĩmwe mbere yakwa,
31 Ó sì wí pé, ‘Korneliu, a gbọ́ àdúrà rẹ, ọrẹ-àánú rẹ̀ sì wà ni ìrántí níwájú Ọlọ́run.
akĩnjĩĩra atĩrĩ, ‘Korinelio, Ngai nĩaiguĩte mahooya maku, na nĩaririkanĩte iheo ciaku iria wanahe athĩĩni.
32 Ǹjẹ́ ránṣẹ́ lọ sí Joppa, kí ó sì pe Simoni wá, ẹni ti àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Peteru; ó wọ̀ ní ilé Simoni aláwọ létí òkun.’
Nĩ ũndũ ũcio tũmana Jopa wĩtĩrwo Simoni ũrĩa wĩtagwo Petero, nake nĩ mũgeni gwa Simoni ũrĩa mũtanduki wa njũũa, ũrĩa ũikaraga rũtere-inĩ rwa iria.’
33 Nítorí náà ni mo sì ṣe ránṣẹ́ sì ọ lójúkan náà, ìwọ sì ṣeun tí ó fi wá. Gbogbo wa pé níwájú Ọlọ́run nísinsin yìí, láti gbọ́ ohun gbogbo, ti a pàṣẹ fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.”
Nĩ ũndũ ũcio nĩndagũtũmanĩire o hĩndĩ ĩyo, na nĩ weka wega nĩ ũndũ wa gũũka. Rĩu ithuĩ ithuothe tũrĩ haha mbere ya Ngai nĩgeetha tũthikĩrĩrie ũrĩa wothe Mwathani agwathĩte ũtwĩre.”
34 Peteru sì ya ẹnu rẹ, ó sì wí pé, “Nítòótọ́ mo wòye pé, Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn.
Nake Petero akĩambĩrĩria kwaria, akiuga atĩrĩ: “Rĩu nĩndamenya kũna ũrĩa arĩ ma atĩ Ngai ndarĩ mũthutũkanio.
35 Ṣùgbọ́n ni gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá bẹ̀rù rẹ̀, ti ó sì ń ṣiṣẹ́ òdodo, ẹni ìtẹ́wọ́gbà ni lọ́dọ̀ rẹ̀.
no atĩ nĩetĩkagĩra andũ kuuma ndũrĩrĩ-inĩ ciothe arĩa mamwĩtigagĩra na mageeka ũrĩa kwagĩrĩire.
36 Ẹyin mọ ọrọ̀ tí Ọlọ́run rán sí àwọn ọmọ Israẹli láti kéde ìròyìn ayọ̀ àlàáfíà nípasẹ̀ Jesu Kristi, ẹni ti ṣe Olúwa ohun gbogbo.
Inyuĩ nĩmũũĩ ndũmĩrĩri ĩrĩa Ngai aatũmĩire andũ a Isiraeli, akĩaria ũhoro mwega wa thayũ na ũndũ wa Jesũ Kristũ, ũrĩa arĩ we Mwathani wa andũ othe.
37 Ẹ̀yin náà mọ ọ̀rọ̀ náà tí a kéde rẹ̀ yíká gbogbo Judea, tí a bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ láti Galili, lẹ́yìn bamitiisi ti Johanu wàásù rẹ̀.
Inyuĩ nĩmũũĩ ũrĩa gwekĩkire kũu Judea guothe, kwambĩrĩria Galili thuutha wa ũbatithio ũrĩa Johana aahunjagia,
38 Àní Jesu ti Nasareti, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti da Ẹ̀mí Mímọ́ àti agbára le lórí; ẹni tí ó ń kiri ṣe oore, ó ń ṣe ìmúláradá gbogbo àwọn tí èṣù sì ń pọ́n lójú; nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
ũrĩa Ngai aaitĩrĩire Jesũ wa Nazarethi Roho Mũtheru o na hinya, na ũrĩa aathiiaga agĩĩkaga wega na akĩhonagia andũ arĩa maahatĩrĩirio nĩ hinya wa mũcukani, tondũ Ngai aarĩ hamwe nake.
39 “Àwa sì ni ẹlẹ́rìí gbogbo ohun tí ó ṣe, ní ilẹ̀ àwọn Júù, àti ni Jerusalẹmu. Ẹni tí wọ́n pa nípa gbígbékọ́ sí orí igi.
“Ithuĩ tũrĩ aira a maũndũ marĩa mothe eekire thĩinĩ wa bũrũri wa Ayahudi o na Jerusalemu. Nĩmamũũragire na njĩra ya kũmwamba mũtĩ-igũrũ.
40 Òun ni Ọlọ́run jí dìde ni ọjọ́ kẹta ó sì fi i hàn gbangba.
No mũthenya wa gatatũ Ngai akĩmũriũkia kuuma kũrĩ arĩa akuũ na agĩtũma onekane kũrĩ andũ.
41 Kì í ṣe fún gbogbo ènìyàn ni o ri, bí kò ṣe fún àwa ti a jẹ́ ẹlẹ́rìí ti a ti ọwọ́ Ọlọ́run yàn tẹ̀lé, ti a bá a jẹ, ti a sì bá à mu lẹ́yìn ìgbà ti ó jíǹde kúrò nínú òkú.
We ndonirwo nĩ andũ othe, o tiga aira arĩa Ngai aathuurĩte: akĩonwo nĩ ithuĩ, o ithuĩ twarĩĩanĩire na tũkĩnyuuanĩra nake aarĩkia kũriũka kuuma kũrĩ arĩa akuũ.
42 Ó sì pàṣẹ fún wa láti wàásù fún àwọn ènìyàn, àti láti jẹ́rìí pé, òun ni a ti ọwọ́ Ọlọ́run yàn ṣe onídàájọ́ ààyè àti òkú.
Nĩatwathire tũhunjĩrie andũ na tũrute ũira atĩ we nĩ we Ngai aamũrire atuĩke mũtuanĩri-ciira wa andũ arĩa marĩ muoyo na arĩa makuĩte.
43 Òun ni gbogbo àwọn wòlíì jẹ́rìí sì pé, ẹnikẹ́ni ti ó bá gbà á gbọ́ yóò rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ gbà nípa orúkọ rẹ̀.”
Anabii othe nĩmaheanaga ũira wa ũhoro wake atĩ mũndũ ũrĩa wothe ũkaamwĩtĩkia nĩakamũkĩra ũrekeri wa mehia na ũndũ wa rĩĩtwa rĩake.”
44 Bí Peteru sì ti ń sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí lẹ́nu, Ẹ̀mí Mímọ́ bà lé gbogbo àwọn ti ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà.
Na Petero o akĩaragia ciugo icio-rĩ, Roho Mũtheru agĩikũrũkĩra andũ arĩa othe maiguire ndũmĩrĩri ĩyo.
45 Ẹnu sì yà àwọn onígbàgbọ́ ti a ti kọ nílà tí wọ́n bá Peteru wá, nítorí ti a tu ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ sórí àwọn aláìkọlà pẹ̀lú.
Nao andũ arĩa meetĩkĩtie, a thiritũ ya arĩa maruaga, arĩa mokĩte na Petero makĩgega mona atĩ kĩheo kĩa Roho Mũtheru nĩgĩaitĩrĩirio andũ-a-Ndũrĩrĩ o nao.
46 Nítorí wọ́n gbọ́, wọ́n ń fọ onírúurú èdè, wọn sì yin Ọlọ́run lógo. Nígbà náà ni Peteru dáhùn wí pé,
Nĩgũkorwo nĩmamaiguire makĩaria na thiomi makĩgoocaga Ngai. Hĩndĩ ĩyo Petero akĩũria atĩrĩ,
47 “Ẹnikẹ́ni ha lè ṣòfin pe, kí a má bamitiisi àwọn wọ̀nyí tí wọ́n gba Ẹ̀mí Mímọ́ bí àwa?”
“Harĩ mũndũ ũngĩgiria andũ aya mabatithio na maaĩ? Andũ aya nĩmamũkĩra Roho Mũtheru o ta ithuĩ.”
48 Ó sì pàṣẹ kí a bamitiisi wọn ni orúkọ Jesu Kristi. Nígbà náà ni wọ́n bẹ̀ ẹ́ kí ó dúró ni ọjọ́ mélòó kan.
Nĩ ũndũ ũcio agĩathana mabatithio thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩa Jesũ Kristũ. Magĩcooka makĩũria Petero aikaranie nao ihinda rĩa mĩthenya mĩnini.