< Acts 10 >
1 Ọkùnrin kan sì wà ni Kesarea ti a ń pè ní Korneliu, balógun ọ̀rún ti ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí a ń pè ni Itali.
ⲁ̅ⲚⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚⲔⲈⲤⲀⲢⲒⲀ ⲈⲠⲈϤⲢⲀⲚ ⲔⲞⲢⲚⲎⲖⲒⲞⲤ ⲈⲞⲨⲈⲔⲀⲦⲞⲚⲦⲀⲢⲬⲞⲤ ⲠⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲤⲠⲨⲢⲀ ⲈϢⲀⲨⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞⲤ ϪⲈ ϮϨⲨⲆⲀⲖⲒⲔⲎ.
2 Olùfọkànsìn, àti ẹni ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run tilétilé rẹ̀ gbogbo, ẹni tí ó ń tọrẹ àánú púpọ̀ fún àwọn ènìyàn, tí ó sì ń gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run nígbà gbogbo.
ⲃ̅ⲈⲞⲨⲈⲨⲤⲈⲂⲎⲤ ⲠⲈ ⲈϤⲈⲢϨⲞϮ ϦⲀⲦϨⲎ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲈⲘ ⲠⲈϤⲎⲒ ⲦⲎⲢϤ ⲈϤⲒⲢⲒ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲘⲘⲈⲐⲚⲀⲎⲦ ⲘⲠⲒⲖⲀⲞⲤ ⲦⲎⲢϤ ⲈϤⲦⲰⲂϨ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲤⲎⲞⲨ ⲚⲒⲂⲈⲚ.
3 Níwọ́n wákàtí kẹsànán ọjọ́, ó rí nínú ìran kedere angẹli Ọlọ́run kan wọlé tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Korneliu!”
ⲅ̅ⲀϤⲚⲀⲨ ϦⲈⲚⲞⲨϨⲞⲢⲀⲘⲀ ϦⲈⲚⲞⲨⲞⲚϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲞⲨⲀⲄⲄⲈⲖⲞⲤ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲀϤϢⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ϢⲀⲢⲞϤ ϦⲈⲚⲪⲚⲀⲨ ⲚⲀϪⲠ ⲐⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲔⲞⲢⲚⲎⲖⲒⲈ.
4 Nígbà tí ó sì tẹjúmọ́ ọn, ti ẹ̀rù sì bà á, ó ní, “Kín ni, Olúwa?” Ó sì wí fún un pé, “Àdúrà rẹ àti ọrẹ-àánú, tìrẹ gòkè lọ síwájú Ọlọ́run fún ìrántí.
ⲇ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤⲤⲞⲘⲤ ⲈⲢⲞϤ ⲈⲦⲀϤϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲞⲨϨⲞϮ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈⲦϢⲞⲠ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲆⲈ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲚⲈⲔⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲎ ⲚⲈⲘ ⲚⲈⲔⲘⲈⲐⲚⲀⲎⲦ ⲀⲨⲒ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲞⲨⲈⲢⲪⲘⲈⲨⲒ ⲘⲠⲈⲘⲐⲞ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ.
5 Sì rán ènìyàn nísinsin yìí lọ sí Joppa, kí wọn sì pe Simoni wá, ẹni ti àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Peteru.
ⲉ̅ϮⲚⲞⲨ ⲞⲨⲚ ⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚϨⲀⲚⲢⲰⲘⲒ ⲈⲒⲞⲠⲠⲎ ⲘⲀⲢⲞⲨⲘⲞⲨϮ ⲈⲞⲨⲀⲒ ϪⲈ ⲤⲒⲘⲰⲚ ⲪⲎ ⲈⲦⲞⲨⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ.
6 Ó wọ̀ sí ilé Simoni aláwọ, tí ilé rẹ̀ wà létí Òkun; òun ni yóò sọ fún ọ bí ìwọ ó ti ṣe.”
ⲋ̅ⲪⲀⲒ ϤϪⲀⲖⲎⲞⲨⲦ ⲈⲞⲨⲀⲒ ϪⲈ ⲤⲒⲘⲰⲚ ⲠⲒⲂⲀⲔϢⲀⲢ ⲪⲀⲒ ⲈⲦⲈ ⲠⲈϤⲎⲒ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲪⲒⲞⲘ.
7 Nígbà tí angẹli náà tí ó bá Korneliu sọ̀rọ̀ sì fi i sílẹ̀ lọ ó pe méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ ilé rẹ̀, àti ọmọ-ogun olùfọkànsìn kan, nínú àwọn ti ó máa ń dúró tì í nígbà gbogbo.
ⲍ̅ⲈⲦⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲠⲒⲀⲄⲄⲈⲖⲞⲤ ⲈⲦⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲀϤⲘⲞⲨϮ ⲈⲂⲰⲔ ⲂⲚⲦⲀϤ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲘⲀⲦⲞⲒ ⲚⲈⲨⲤⲈⲂⲎⲤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲎ ⲈⲐⲘⲎⲚ ⲈⲢⲞϤ.
8 Nígbà tí ó sì tí ṣàlàyé ohun gbogbo fún wọn, ó rán wọn lọ sí Joppa.
ⲏ̅ⲈⲦⲀϤϪⲈ ϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ϦⲀⲦⲞⲦⲞⲨ ⲀϤⲞⲨⲞⲢⲠⲞⲨ ⲈⲒⲞⲠⲠⲎ.
9 Ni ọjọ́ kejì bí wọ́n ti ń lọ lọ́nà àjò wọn, tí wọ́n sì súnmọ́ ilé náà, Peteru gun òkè ilé lọ láti gbàdúrà ni ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́,
ⲑ̅ⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲆⲈ ⲈⲨⲘⲞϢⲒ ϨⲒ ⲠⲒⲘⲰⲒⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨϦⲰⲚⲦ ⲈϮⲠⲞⲖⲒⲤ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲒϪⲈⲚⲈⲪⲰⲢ ⲈⲈⲢⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬ ⲈⲤⲐⲈ ⲘⲪⲚⲀⲨ ⲚⲀϪⲠ.
10 ebi sì pa á gidigidi, ó sì ń fẹ́ láti jẹun, ó bọ́ sí ojúran.
ⲓ̅ⲚⲈ ⲀϤϨⲔⲞ ⲆⲈ ⲠⲈ ⲚⲀϤⲞⲨⲰϢ ⲈⲞⲨⲰⲘ ⲈⲨⲤⲞⲂϮ ⲆⲈ ⲚⲀϤ ⲀϤⲒ ⲚϪⲈⲞⲨⲦⲰⲘⲦ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰϤ.
11 Ó sì rí ọ̀run ṣí, ohun èlò kan si sọ̀kalẹ̀ bí gọgọwú ńlá, tí a ti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, sọ̀kalẹ̀ sí ilẹ̀.
ⲓ̅ⲁ̅ⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲦⲪⲈ ⲈⲤⲞⲨⲎⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲤⲔⲈⲨⲞⲤ ⲈⲨⲬⲰ ⲘⲘⲞϤ ⲈϦⲢⲎⲒ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϨⲂⲰⲤ ⲚⲒⲀⲨ ⲚⲆ ⲚⲀⲢⲬⲎ.
12 Nínú rẹ̀ ni onírúurú ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin wà, àti ohun tí ń rákò ni ayé àti ẹyẹ ojú ọ̀run.
ⲓ̅ⲃ̅ⲈⲨⲬⲎ ⲚϨⲢⲎⲒ ⲚϦⲎⲦϤ ⲚϪⲈⲚⲒϤⲦⲈⲪⲀⲦ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲒϬⲀⲦϤⲒ ⲚⲦⲈⲠⲔⲀϨⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲒϨⲀⲖⲀϮ ⲚⲦⲈⲦⲪⲈ.
13 Ohùn kan si fọ̀ sí i pe, “Dìde, Peteru; máa pa kí o sì máa jẹ.”
ⲓ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲞⲨⲤⲘⲎ ϪⲈ ⲦⲰⲚⲔ ⲠⲈⲦⲢⲈ ϢⲰⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲰⲘ.
14 Ṣùgbọ́n Peteru dáhùn pé, “Rara, Olúwa; nítorí èmi kò jẹ ohun èèwọ̀ àti aláìmọ́ kan rí.”
ⲓ̅ⲇ̅ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲘⲪⲰⲢ ⲠϬⲞⲒⲤ ϪⲈ ⲘⲠⲒⲞⲨⲈⲘ ϨⲖⲒ ⲚⲈⲚⲬⲀⲒ ⲈⲚⲈϨ ⲈϤϬⲀϦⲈⲘ ⲒⲈ ⲈϤⲤⲞϤ.
15 Ohùn kan sì tún fọ̀ sí i lẹ́ẹ̀méjì pé, “Ohun tí Ọlọ́run bá ti wẹ̀mọ́, ìwọ má ṣe pè é ní èèwọ̀ mọ́.”
ⲓ̅ⲉ̅ⲠⲀⲖⲒⲚ ⲞⲚ ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈϮⲤⲘⲎ ⲘⲪⲘⲀϨⲤⲞⲠⲂ ϪⲈ ⲚⲎ ⲈⲦⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲦⲞⲨⲂⲰⲞⲨ ⲚⲐⲞⲔ ⲆⲈ ⲘⲠⲈⲢϬⲀϦⲘⲞⲨ.
16 Èyí sì ṣe lẹ́ẹ̀mẹ́ta; lójúkan náà a sì gbé ohun èlò náà padà lọ sókè ọ̀run.
ⲓ̅ⲋ̅ⲪⲀⲒ ⲆⲈ ⲀϤϢⲰⲠⲒ ϢⲀ ⲄⲚⲤⲞⲠ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲰⲖⲒ ⲘⲠⲒⲤⲔⲈⲨⲞⲤ ⲈⲠϢⲰⲒ ⲈⲦⲪⲈ.
17 Bí Peteru sì ti ń dààmú nínú ara rẹ̀ bí òun bá ti mọ̀ ìran tí òun ri yìí sí, si wò ó, àwọn ọkùnrin tí a rán wá láti ọ̀dọ̀ Korneliu dé. Wọ́n ń béèrè ilé Simoni, wọ́n dúró ní ẹnu-ọ̀nà.
ⲓ̅ⲍ̅ϨⲰⲤ ⲆⲈ ⲈϤⲘⲈⲨⲒ ⲚϪⲈⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲚϦⲢⲎ ⲒⲚϦⲎⲦϤ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈ ⲠⲒϨⲞⲢⲀⲘⲀ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞϤ ϨⲎⲠⲠⲈ ⲒⲤ ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲈⲦⲀϤⲞⲨⲞⲢⲠⲞⲨ ⲚϪⲈⲔⲞⲢⲚⲎⲖⲒⲞⲤ ⲈⲀⲨϢⲒⲚⲒ ⲚⲤⲀⲠⲎⲒ ⲚⲤⲒⲘⲰⲚ ⲀⲨⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦⲞⲨ ϨⲒⲢⲈⲚ ⲠⲒⲠⲨⲖⲰⲚ
18 Wọn nahùn béèrè bí Simoni tí a ń pè ní Peteru, wọ̀ níbẹ̀.
ⲓ̅ⲏ̅ⲈⲦⲀⲨⲘⲞⲨϮ ⲚⲀⲨϢⲒⲚⲒ ⲠⲈ ϪⲈ ⲀⲚ ⲤⲒⲘⲰⲚ ⲪⲎ ⲈⲦⲞⲨⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ϤϪⲀⲖⲎⲞⲨⲦ ⲈⲠⲀⲒⲘⲀ.
19 Bí Peteru sì ti ń ronú ìran náà, Ẹ̀mí wí fún un pé, “Wò ó, àwọn ọkùnrin mẹ́ta ń wá ọ.
ⲓ̅ⲑ̅ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲆⲈ ⲈϤⲤⲞϬⲚⲒ ⲚϦⲢⲎⲒ ⲚϦⲎⲦϤ ⲈⲐⲂⲈ ⲠⲒϨⲞⲢⲀⲘⲀ ⲠⲈϪⲈ ⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲆⲈ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲒⲤ ⲄⲚⲢⲰⲘⲒ ⲤⲈⲔⲰϮ ⲚⲤⲰⲔ.
20 Ǹjẹ́ dìde, sọ̀kalẹ̀ kí ó sì bá wọn lọ, má ṣe kó ara ró láti bá wọn lọ, nítorí èmi ni ó rán wọn.”
ⲕ̅ⲀⲖⲖⲀ ⲦⲰⲚⲔ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲞϢⲒ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ ⲚⲔⲞⲒ ⲚϨⲎⲦ ⲂⲀⲚ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ ⲈⲦⲀⲒⲞⲨⲞⲢⲠⲞⲨ.
21 Nígbà náà ni Peteru sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn ọkùnrin náà tí a rán, ó sì wí pé, “Wò ó, èmi ni ẹni tí ẹ̀yin ń wá, kín ni ìdí rẹ̀ ti ẹ fi wá?”
ⲕ̅ⲁ̅ⲈⲦⲀϤⲒ ⲆⲈ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ⲚϪⲈⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ϢⲀ ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ϨⲎⲠⲠⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲔⲰϮ ⲚⲤⲰⲒ ⲠⲒϨⲰⲂ ⲞⲨ ⲠⲈ ⲈⲦⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲒ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ.
22 Wọ́n sì wí pé, “Korneliu balógun ọ̀rún, ọkùnrin olóòtítọ́, àti ẹni ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó sì ní orúkọ rere lọ́dọ̀ gbogbo orílẹ̀-èdè àwọn Júù, òun ni a ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run kọ́ nípasẹ̀ angẹli mímọ́, láti ránṣẹ́ pè ọ́ wá sí ilé rẹ̀ àti láti gbọ́ ọ̀rọ̀ lẹ́nu rẹ.”
ⲕ̅ⲃ̅ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲔⲞⲢⲚⲎⲖⲒⲞⲤ ⲠⲒⲈⲔⲀⲦⲞⲚⲦⲀⲢⲬⲞⲤ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲚⲐⲘⲎⲒ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤⲈⲢϨⲞϮ ϦⲀⲦϨⲎ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲨⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϦⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲠⲒϢⲖⲞⲖ ⲦⲎⲢϤ ⲚⲦⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲀⲨⲦⲀⲘⲞϤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲞⲨⲀⲄⲄⲈⲖⲞⲤ ⲈϤⲞⲨⲀⲂ ⲈⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚⲤⲰⲔ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲈϤⲎⲒ ⲈⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈϨⲀⲚⲤⲀϪⲒ ⲚⲦⲞⲦⲔ.
23 Nígbà náà ni Peteru pè wọ́n wọlé, ó gbà wọ́n lálejò. Ní ọjọ́ kejì, ó sì dìde, ó bá wọn lọ, díẹ̀ nínú àwọn ti o ti gbàgbọ́ ní Joppa sì bá a lọ pẹ̀lú.
ⲕ̅ⲅ̅ⲀϤⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲀϤϢⲞⲠⲞⲨ ⲈⲢⲞϤ ⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲆⲈ ⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲔⲈⲤⲚⲎⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲒⲞⲠⲠⲎ.
24 Lọ́jọ́ kejì wọ́n sì wọ Kesarea, Korneliu sì ti ń retí wọn, ó sì ti pe àwọn ìbátan àti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ jọ.
ⲕ̅ⲇ̅ⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲆⲈ ⲀⲨⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲔⲈⲤⲀⲢⲒⲀ ⲔⲞⲢⲚⲎⲖⲒⲞⲤ ⲆⲈ ⲚⲀϤⲤⲞⲘⲤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲀϪⲰⲞⲨ ⲈⲦⲀϤⲘⲞⲨϮ ⲆⲈ ⲈⲚⲈϤⲤⲨⲄⲄⲈⲚⲎⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲈϤϢⲪⲎ ⲢⲚⲀⲚⲀⲄⲔⲈⲞⲚ.
25 Ó sì ṣe bí Peteru ti ń wọlé, Korneliu pàdé rẹ̀, ó wólẹ̀ lẹ́sẹ̀ rẹ̀, ó sì foríbalẹ̀ fún un.
ⲕ̅ⲉ̅ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲚϪⲈⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲀϤϮⲘⲀϮ ⲈⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲔⲞⲢⲚⲎⲖⲒⲞⲤ ⲀϤϨⲒⲦϤ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ϦⲀⲢⲀⲦⲞⲨ ⲚⲚⲈϤϬⲀⲖⲀⲨϪ ⲀϤⲞⲨⲰϢⲦ.
26 Ṣùgbọ́n Peteru gbé e dìde, ó ni, “Dìde ènìyàn ni èmi tìkára mi pẹ̀lú.”
ⲕ̅ⲋ̅ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲆⲈ ⲀϤⲦⲞⲨⲚⲞⲤϤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲦⲰⲚⲔ ⲀⲚⲞⲔ ϨⲰ ⲀⲚⲞⲔ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ.
27 Bí ó sì ti ń bá a sọ̀rọ̀, ó wọlé ó sì rí àwọn ènìyàn púpọ̀ tí wọ́n péjọ.
ⲕ̅ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲀϤⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϪⲒⲘⲒ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲈⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ.
28 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin mọ̀ bí ó ti jẹ́ èèwọ̀ fún ẹni tí ó jẹ́ Júù, láti bá ẹni tí ó jẹ́ ará ilẹ̀ mìíràn kẹ́gbẹ́, tàbí láti tọ̀ ọ́ wá; ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fihàn mi pé, ki èmi má ṣe pé ẹnikẹ́ni ni èèwọ̀ tàbí aláìmọ́.
ⲕ̅ⲏ̅ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲦⲈⲦⲈⲚⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲞⲨⲂⲞϮ ⲠⲈ ⲚⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲚⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲈⲦⲞⲘϤ ⲒⲈ ⲈⲘⲞϢⲒ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲀⲖⲖⲞⲪⲨⲖⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲞⲔ ⲀⲪⲚⲞⲨϮ ⲦⲀⲘⲞⲒ ⲈϢⲦⲈⲘϪⲞⲤ ⲚϨⲖⲒ ⲚⲢⲰⲘⲒ ϪⲈ ϤϬⲀϦⲈⲘ ⲒⲈ ϤⲤⲞϤ.
29 Nítorí náà ni mo sì ṣe wá ní àìjiyàn, bí a ti ránṣẹ́ pè mi, ǹjẹ́ mo béèrè, nítorí kín ní ẹ̀yin ṣe ránṣẹ́ pè mi?”
ⲕ̅ⲑ̅ⲈⲐⲂⲈⲪⲀⲒ ⲀⲒⲒ ⲈⲦⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚⲤⲰⲒ ⲘⲠⲒⲈⲢⲀⲚⲦⲒⲖⲈⲄⲒⲚ ϮϢⲒⲚⲒ ⲞⲨⲚ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈ ⲀϢ ⲚϨⲰⲂ ⲀⲦⲈⲦⲈⲚⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚⲤⲰⲒ.
30 Korneliu sì dáhùn pé, “Ní ìjẹrin, mo ń ṣe àdúrà wákàtí kẹsànán ọjọ́ ni ilé mi títí di idayìí, sì wò ó, ọkùnrin kan aláṣọ, àlà dúró níwájú mi.
ⲗ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲈ ⲔⲞⲢⲚⲎⲖⲒⲞⲤ ϪⲈ ⲒⲤ ϤⲦⲞⲨ ⲪⲞⲞⲨ ϢⲀ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲦⲀⲒⲞⲨⲚⲞⲨ ⲚⲀⲒⲦⲰⲂϨ ⲘⲪⲚⲀⲨ ⲚⲀϪⲠ ⲐϮ ϦⲈⲚⲠⲀⲎⲒ ϨⲎⲠⲠⲈ ⲒⲤ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲀϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲘⲠⲀⲘⲐⲞ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲞⲨϨⲈⲂⲤⲰ ⲈⲤⲞⲨⲞⲂϢ.
31 Ó sì wí pé, ‘Korneliu, a gbọ́ àdúrà rẹ, ọrẹ-àánú rẹ̀ sì wà ni ìrántí níwájú Ọlọ́run.
ⲗ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲔⲞⲢⲚⲎⲖⲒⲈ ⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲦⲈⲔⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲎ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲔⲘⲈⲐⲚⲀⲎⲦ ⲀⲨⲈⲢⲠⲞⲨⲘⲈⲨⲒ ⲘⲠⲈⲘⲐⲞ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ.
32 Ǹjẹ́ ránṣẹ́ lọ sí Joppa, kí ó sì pe Simoni wá, ẹni ti àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Peteru; ó wọ̀ ní ilé Simoni aláwọ létí òkun.’
ⲗ̅ⲃ̅ⲞⲨⲰⲢⲠ ⲞⲨⲚ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲒⲞⲠⲠⲎ ⲘⲀⲢⲞⲨⲘⲞⲨϮ ⲈⲤⲒⲘⲰⲚ ⲪⲎ ⲈⲦⲞⲨⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲪⲀⲒ ϤϪⲀⲖⲎⲞⲨⲦ ⲈⲠⲎⲒ ⲚⲤⲒⲘⲰⲚ ⲠⲒⲂⲀⲔϢⲀⲢ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲪⲒⲞⲘ.
33 Nítorí náà ni mo sì ṣe ránṣẹ́ sì ọ lójúkan náà, ìwọ sì ṣeun tí ó fi wá. Gbogbo wa pé níwájú Ọlọ́run nísinsin yìí, láti gbọ́ ohun gbogbo, ti a pàṣẹ fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.”
ⲗ̅ⲅ̅ⲚϮⲚⲞⲨ ⲞⲨⲚ ⲀⲒⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚⲤⲰⲔ ⲚⲐⲞⲔ ⲆⲈ ⲔⲀⲖⲰⲤ ⲀⲔⲀⲒⲤ ⲈⲦⲀⲔⲒ ϮⲚⲞⲨ ⲀⲚⲞⲚ ⲦⲎⲢⲈⲚ ⲦⲈⲚⲘⲠⲀⲒⲘⲀ ⲈⲚⲬⲎ ⲘⲠⲈⲘⲐⲞ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲚⲎ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲈⲦⲀ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲐⲀϢⲞⲨ ⲚⲀⲔ.
34 Peteru sì ya ẹnu rẹ, ó sì wí pé, “Nítòótọ́ mo wòye pé, Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn.
ⲗ̅ⲇ̅ⲈⲦⲀϤⲞⲨⲰⲚ ⲆⲈ ⲚⲢⲰϤ ⲚϪⲈⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ϮⲚⲀⲨ ϪⲈ ⲞⲨⲢⲈϤϬⲒϨⲞ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲪⲚⲞⲨϮ.
35 Ṣùgbọ́n ni gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá bẹ̀rù rẹ̀, ti ó sì ń ṣiṣẹ́ òdodo, ẹni ìtẹ́wọ́gbà ni lọ́dọ̀ rẹ̀.
ⲗ̅ⲉ̅ⲀⲖⲖⲀ ⲚϨⲢⲎⲒ ϦⲈⲚϢⲖⲰⲖ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲈⲢϨⲞϮ ϦⲀⲦⲈϤϨⲎ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲈⲢϨⲰⲂ ⲈϮⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ϤϢⲎⲠ ⲚⲀϨⲢⲀϤ.
36 Ẹyin mọ ọrọ̀ tí Ọlọ́run rán sí àwọn ọmọ Israẹli láti kéde ìròyìn ayọ̀ àlàáfíà nípasẹ̀ Jesu Kristi, ẹni ti ṣe Olúwa ohun gbogbo.
ⲗ̅ⲋ̅ⲀϤⲞⲨⲰⲢⲠ ⲘⲠⲈϤⲤⲀϪⲒ ⲚⲚⲈⲚϢⲎⲢⲒ ⲘⲠⲒⲤⲖ ⲈϤϨⲒϢⲈⲚⲚⲞⲨϤⲒ ⲚⲞⲨϨⲒⲢⲎⲚⲎ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲚⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ.
37 Ẹ̀yin náà mọ ọ̀rọ̀ náà tí a kéde rẹ̀ yíká gbogbo Judea, tí a bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ láti Galili, lẹ́yìn bamitiisi ti Johanu wàásù rẹ̀.
ⲗ̅ⲍ̅ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲈⲦⲀϤϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚϮⲒⲞⲨⲆⲈⲀ ⲦⲎⲢⲤ ⲈⲀϤⲈⲢϨⲎ ⲦⲤ ⲒⲤϪⲈⲚ ϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ⲘⲈⲚⲈⲚⲤⲀ ⲠⲒⲰⲘⲤ ⲈⲦⲀϤϨⲒⲰⲒϢ ⲘⲘⲞϤ ⲚϪⲈⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ.
38 Àní Jesu ti Nasareti, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti da Ẹ̀mí Mímọ́ àti agbára le lórí; ẹni tí ó ń kiri ṣe oore, ó ń ṣe ìmúláradá gbogbo àwọn tí èṣù sì ń pọ́n lójú; nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
ⲗ̅ⲏ̅ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲒⲢⲈⲘⲚⲀⲌⲀⲢⲈⲐ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲀϤⲐⲀϨⲤϤ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ϦⲈⲚⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈϤⲞⲨⲀⲂ ⲚⲈⲘ ⲞⲨϪⲞⲘ ⲪⲀⲒ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈⲈⲢⲠⲈⲐⲚⲀⲚⲈϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤⲦⲀⲖϬⲞ ⲚⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲀ ⲠⲒⲆⲒⲀⲂⲞⲖⲞⲤ ϪⲈⲘϪⲞⲘ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰϤ ϪⲈ ⲚⲀⲢⲈ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲬⲎ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲠⲈ.
39 “Àwa sì ni ẹlẹ́rìí gbogbo ohun tí ó ṣe, ní ilẹ̀ àwọn Júù, àti ni Jerusalẹmu. Ẹni tí wọ́n pa nípa gbígbékọ́ sí orí igi.
ⲗ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲞⲚ ⲦⲈⲚⲞⲒ ⲘⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲀϤⲀⲒⲦⲞⲨ ϦⲈⲚⲦⲬⲰⲢⲀ ⲚⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲚⲈⲘ ϦⲈⲚⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ⲪⲎ ⲈⲦⲀⲨϦⲞⲐⲂⲈϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲀϢϤ ⲈϪⲈⲚ ⲞⲨϢⲈ.
40 Òun ni Ọlọ́run jí dìde ni ọjọ́ kẹta ó sì fi i hàn gbangba.
ⲙ̅ⲪⲀⲒ ⲀⲪⲚⲞⲨϮ ⲦⲞⲨⲚⲞⲤϤ ϦⲈⲚⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲘⲘⲀϨⲄ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲎⲒϤ ⲈⲐⲢⲈϤⲞⲨⲞⲚϨϤ ⲈⲂⲞⲖ
41 Kì í ṣe fún gbogbo ènìyàn ni o ri, bí kò ṣe fún àwa ti a jẹ́ ẹlẹ́rìí ti a ti ọwọ́ Ọlọ́run yàn tẹ̀lé, ti a bá a jẹ, ti a sì bá à mu lẹ́yìn ìgbà ti ó jíǹde kúrò nínú òkú.
ⲙ̅ⲁ̅ⲘⲠⲒⲖⲀⲞⲤ ⲦⲎⲢϤ ⲀⲚ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲚⲒⲘⲈⲐⲢⲈⲨ ⲚⲎ ⲈⲦⲀϤⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲚⲤⲞⲦⲠⲞⲨ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲦⲈ ⲀⲚⲞⲚ ⲠⲈ ϦⲀ ⲚⲎ ⲈⲦⲀⲚⲞⲨⲰⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲤⲰ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲘⲈⲚⲈⲚⲤⲀ ⲈⲦⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲎ ⲈⲐⲘⲰⲞⲨⲦ.
42 Ó sì pàṣẹ fún wa láti wàásù fún àwọn ènìyàn, àti láti jẹ́rìí pé, òun ni a ti ọwọ́ Ọlọ́run yàn ṣe onídàájọ́ ààyè àti òkú.
ⲙ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϨⲞⲚϨⲈⲚ ⲚⲀⲚ ⲈϨⲒⲰⲒϢ ⲘⲠⲒⲖⲀⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϪⲈ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲈⲦⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲐⲀϢϤ ⲚⲢⲈϤϮϨⲀⲠ ⲈⲚⲎ ⲈⲦⲞⲚϦ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲐⲘⲰⲞⲨⲦ.
43 Òun ni gbogbo àwọn wòlíì jẹ́rìí sì pé, ẹnikẹ́ni ti ó bá gbà á gbọ́ yóò rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ gbà nípa orúkọ rẹ̀.”
ⲙ̅ⲅ̅ⲪⲀⲒ ⲈⲦⲈ ⲚⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϦⲀⲢⲞϤ ⲈⲐⲢⲞⲨϬⲒ ⲘⲠⲬⲰ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲦⲈⲚⲞⲨⲚⲞⲂⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦϤ ⲘⲠⲈϤⲢⲀⲚ ⲚϪⲈⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲐⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ.
44 Bí Peteru sì ti ń sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí lẹ́nu, Ẹ̀mí Mímọ́ bà lé gbogbo àwọn ti ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà.
ⲙ̅ⲇ̅ⲈⲦⲒ ⲈϤⲤⲀϪⲒ ⲚϪⲈⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲚⲚⲀⲒⲤⲀϪⲒ ⲀϤⲒ ⲚϪⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈⲐⲞⲨⲀⲂ ⲈϪⲈⲚ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲠⲒⲤⲀϪⲒ.
45 Ẹnu sì yà àwọn onígbàgbọ́ ti a ti kọ nílà tí wọ́n bá Peteru wá, nítorí ti a tu ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ sórí àwọn aláìkọlà pẹ̀lú.
ⲙ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲦⲰⲘⲦ ⲚϪⲈⲚⲒⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲤⲈⲂⲒ ⲚⲒⲠⲒⲤⲦⲞⲤ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲚⲈⲘ ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ϪⲈ Ⲁ- ϮⲆⲰⲢⲈⲀ ⲚⲦⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈⲐⲞⲨⲀⲂ ⲀⲤⲪⲰⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲚⲒⲔⲈⲈⲐⲚⲞⲤ.
46 Nítorí wọ́n gbọ́, wọ́n ń fọ onírúurú èdè, wọn sì yin Ọlọ́run lógo. Nígbà náà ni Peteru dáhùn wí pé,
ⲙ̅ⲋ̅ⲚⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲄⲀⲢ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲠⲈ ⲈⲨⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲖⲀⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲨϬⲒⲤⲒ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲦⲞⲦⲈ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲠⲈⲦⲢⲞⲤ
47 “Ẹnikẹ́ni ha lè ṣòfin pe, kí a má bamitiisi àwọn wọ̀nyí tí wọ́n gba Ẹ̀mí Mímọ́ bí àwa?”
ⲙ̅ⲍ̅ϪⲈ ⲘⲎⲦⲒ ⲞⲨⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲚⲦⲈϨⲖⲒ ⲦⲀϨⲚⲞ ⲘⲠⲒⲘⲰⲞⲨ ⲈϢⲦⲈⲘⲐⲢⲈ ⲚⲀⲒ ϬⲒⲰⲘⲤ ⲚⲀⲒ ⲈⲦⲀⲨϬⲒ ⲘⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈⲐⲞⲨⲀⲂ ⲘⲠⲈⲚⲢⲎϮ ϨⲰⲚ.
48 Ó sì pàṣẹ kí a bamitiisi wọn ni orúkọ Jesu Kristi. Nígbà náà ni wọ́n bẹ̀ ẹ́ kí ó dúró ni ọjọ́ mélòó kan.
ⲙ̅ⲏ̅ⲀϤⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲆⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲈⲐⲢⲞⲨⲞⲘⲤⲞⲨ ϦⲈⲚⲪⲢⲀⲚ ⲚⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲦⲞⲦⲈ ⲀⲨϮϨⲞ ⲈⲢⲞϤ ⲈⲐⲢⲈϤϢⲰⲠⲒ ϦⲀⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚϨⲀⲚⲈϨⲞⲞⲨ.