< 3 John 1 >

1 Alàgbà, Sì Gaiusi, olùfẹ́, ẹni tí mo fẹ́ nínú òtítọ́.
Starszy do umiłowanego Gajusa, którego miłuję w prawdzie.
2 Olùfẹ́, èmi ń gbàdúrà pé nínú ohun gbogbo kí o lè máa dára fún ọ, kí o sì máa wà ni ìlera, àní bí o tí dára fún ọkàn rẹ.
Umiłowany, pragnę przede wszystkim, aby ci się dobrze powodziło i abyś był zdrowy, tak jak dobrze się powodzi twojej duszy.
3 Nítorí mo yọ̀ gidigidi, nígbà tí àwọn arákùnrin dé tí wọn sì jẹ́rìí sí ìwà òtítọ́ inú rẹ̀, àní bí ìwọ tí ń rìn nínú òtítọ́.
Uradowałem się bowiem bardzo, gdy przyszli bracia i dali świadectwo o prawdzie w tobie, jak postępujesz w prawdzie.
4 Èmi ni ayọ̀ tí ó tayọ, láti máa gbọ́ pé, àwọn ọmọ mi ń rìn nínú òtítọ́.
Nie ma dla mnie większej radości od tej, gdy słyszę, że moje dzieci postępują w prawdzie.
5 Olùfẹ́, ìwọ ń ṣe olóòtítọ́ nínú iṣẹ́ tí ìwọ ń ṣe fún àwọn tí ń ṣe ará, àti pàápàá fún àwọn tí ń ṣe àlejò.
Umiłowany, wiernie wykonujesz wszystko, co robisz dla braci oraz dla obcych.
6 Tí wọn ń jẹ́rìí sí ìfẹ́ rẹ̀ níwájú ìjọ, bí ìwọ bá ń pèsè fún wọn ní ọ̀nà àjò wọn gẹ́gẹ́ bí ó tí yẹ nínú Ọlọ́run.
Dali oni świadectwo przed kościołem o twojej miłości. Dobrze też zrobisz, jeśli ich wyprawisz, jak przystoi przed Bogiem.
7 Nítorí pé, nítorí iṣẹ́ Kristi ni wọ́n ṣe jáde lọ, láìgba ohunkóhun lọ́wọ́ àwọn aláìkọlà.
Wyruszyli bowiem dla jego imienia, nie biorąc niczego od pogan.
8 Nítorí náà, ó yẹ kí àwa fi inú rere gba irú àwọn wọ̀nyí, kí àwa lè jẹ́ alábáṣiṣẹ́pọ̀ pẹ̀lú òtítọ́.
Powinniśmy więc takich przyjmować, abyśmy się stali współpracownikami dla prawdy.
9 Èmi kọ̀wé sí ìjọ ṣùgbọ́n Diotirefe, ẹni tí ó fẹ́ láti jẹ́ ẹni pàtàkì jùlọ, kò gbà wá.
Napisałem do kościoła, lecz Diotrefes, który chce być pierwszym wśród nich, nie przyjmuje nas.
10 Nítorí náà bí mo bá dé, èmi yóò mú iṣẹ́ rẹ̀ tí ó ṣe wá sì ìrántí rẹ, tí ó ń sọ ọ̀rọ̀ búburú àti ìsọkúsọ sí wa, èyí kò sì tún tẹ́ ẹ lọ́rùn, síbẹ̀ òun fúnra rẹ̀ kọ̀ láti gba àwọn ará, àwọn tí ó sì ń fẹ́ gbà wọ́n, ó ń dá wọn lẹ́kun, ó sì ń lé wọn kúrò nínú ìjọ.
Dlatego, jeśli przybędę, przypomnę jego uczynki, których się dopuszcza, gdy nas obmawia złośliwymi słowami. A nie poprzestając na tym, sam braci nie przyjmuje, a nawet zabrania tym, którzy chcą ich [przyjąć], i wyrzuca ich z kościoła.
11 Olùfẹ́, má ṣe ṣe àfarawé ohun tí í ṣe ibi bí kò ṣe ohun tí ṣe rere. Ẹni tí ó bá ń ṣe rere ti Ọlọ́run ni; ẹni tí ó ba ń ṣe búburú kò rí Ọlọ́run.
Umiłowany, nie naśladuj tego, co złe, lecz to, co dobre. Kto czyni dobrze, jest z Boga, kto zaś czyni źle, nie widział Boga.
12 Demetriusi ní ẹ̀rí rere lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn àti ní ti òtítọ́ fúnra rẹ̀ pẹ̀lú; nítòótọ́, àwa pẹ̀lú sì gba ẹ̀rí rẹ̀ jẹ́; ẹ̀yin sì mọ̀ pé, òtítọ́ ni ẹ̀rí wa.
Demetriuszowi wystawili [dobre] świadectwo wszyscy, nawet sama prawda. My również dajemy [o nim] świadectwo, a wiecie, że nasze świadectwo jest prawdziwe.
13 Èmí ní ohun púpọ̀ láti kọ sínú ìwé sí ọ, ṣùgbọ́n èmi kò fẹ́ fi kálàmù àti tawada kọ wọ́n sínú ìwé.
Wiele miałem do napisania, ale nie chcę posługiwać się atramentem i piórem.
14 Mo ni ìrètí láti rí ọ láìpẹ́, tí àwa yóò sì sọ̀rọ̀ lójúkojú. Àlàáfíà fún ọ. Àwọn ọ̀rẹ́ wa tó wà níbí kí ọ. Kí àwọn ọ̀rẹ́ wa tó wà lọ́dọ̀ rẹ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
Mam bowiem nadzieję, że zobaczę cię wkrótce, a [wtedy] porozmawiamy osobiście. Pokój tobie. Pozdrawiają cię przyjaciele. [Ty też] pozdrów przyjaciół imiennie.

< 3 John 1 >