< 2 Timothy 4 >
1 Nítorí náà mo pàṣẹ fún ọ níwájú Ọlọ́run, àti Kristi Jesu, ẹni tí yóò ṣe ìdájọ́ alààyè àti òkú, àti nítorí ìfarahàn rẹ̀ àti ìjọba rẹ̀.
Te ordeno delante de Dios y de Cristo Jesús, que será juez de vivos y muertos, y de su revelación de su reino;
2 Wàásù ọ̀rọ̀ náà, ṣe àìsimi ní àkókò tí ó wọ̀, àti àkókò ti kò wọ̀; bá ni wí, ṣe ìtọ́ni, gbani níyànjú pẹ̀lú ìpamọ́ra àti ẹ̀kọ́ gbogbo.
Que Prediques la palabra en todo tiempo, en todo lugar; redarguye, reprende, da consuelo, con paciencia y enseñanza;
3 Nítorí pé ìgbà yóò dé, tí wọn kì yóò lè gba ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro, ṣùgbọ́n bí wọ́n ti jẹ́ ẹni tí etí ń rin, wọn ó lọ kó olùkọ́ jọ fún ara wọn nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara wọn.
Porque vendrá tiempo cuando no tomarán la verdadera enseñanza; pero, movidos por sus deseos, obtendrán para sí mismos una gran cantidad de maestros que solo les enseñen lo que ellos quieran oír;
4 Wọ́n ó sì yí etí wọn padà kúrò nínú òtítọ́, wọn ó sì yípadà sí ìtàn asán.
Y cerrando los oídos a lo que es verdad, y harán caso a toda clase de historias necias.
5 Ṣùgbọ́n máa faradà ìpọ́njú, ṣe iṣẹ́ efangelisti, ṣe iṣẹ́ rẹ láṣepé.
Pero tú siempre conserva el buen juicio en todas las cosas, soporta las aflicciones, continúa predicando las buenas nuevas, completando el trabajo que se te ha encomendado.
6 Nítorí à ń fi mi rú ẹbọ nísinsin yìí, àtilọ mi sì súnmọ́ etílé.
Porque ahora mismo soy un sacrificio vivo, y mi fin está cerca.
7 Èmi ti ja ìjà rere, èmi tí parí iré-ìje mi, èmi ti pa ìgbàgbọ́ mọ́.
He hecho una buena batalla, he llegado al final de mi viaje, he guardado la fe:
8 Láti ìsinsin yìí lọ a fi adé òdodo lélẹ̀ fún mi, tí Olúwa onídàájọ́ òdodo, yóò fífún mi ni ọjọ́ náà kì í sì í ṣe kìkì èmi nìkan ṣùgbọ́n pẹ̀lú fún gbogbo àwọn tí ó ti fẹ́ ìfarahàn rẹ̀.
A partir de ahora, la corona de justicia se ha preparado para mí, que el Señor, el juez recto, dará a mi en ese día, y no solo a mí, sino a todos aquellos que con amor esperan que él vuelva.
9 Sa ipá rẹ láti tètè tọ̀ mí wá.
Haz lo mejor que puedas para venir a verme enseguida:
10 Nítorí Dema ti kọ̀ mí sílẹ̀, nítorí ó ń fẹ́ ayé yìí, ó sì lọ sí Tẹsalonika; Kreskeni sí Galatia, Titu sí Dalimatia. (aiōn )
Porque Demas se ha alejado de mí, por amor a esta vida presente, y se ha ido a Tesalónica: Crescente ha ido a Galacia, Tito a Dalmacia. (aiōn )
11 Luku nìkan ni ó wà pẹ̀lú mi, mú Marku wá pẹ̀lú rẹ: nítorí ó wúlò fún mi fún iṣẹ́ ìránṣẹ́.
Sólo Lucas está conmigo. Busca a Marcos y tráelo contigo; porque él me es útil en el trabajo.
12 Mo rán Tikiku ní iṣẹ́ lọ sí Efesu.
Tíquico lo envié a Efeso.
13 Aṣọ òtútù tí mo fi sílẹ̀ ní Troasi lọ́dọ̀ Karpu, nígbà tí ìwọ bá ń bọ̀ mú un wa, àti àwọn ìwé, pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ìwé-awọ.
Cuando vengas tráeme la capa que dejé en Troas y que está en casa de Carpo, y los libros, especialmente los pergaminos.
14 Aleksanderu alágbẹ̀dẹ bàbà ṣe mi ni ibi púpọ̀: Olúwa yóò san án fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.
Alejandro el herrero me hizo mucho daño: el Señor le dará la recompensa de sus obras;
15 Lọ́dọ̀ ẹni tí kí ìwọ máa ṣọ́ra pẹ̀lú, nítorí tí ó kọ ojú ìjà sí ìwàásù wa púpọ̀.
Pero está atento a él, porque fue violento en sus ataques a nuestras enseñanzas.
16 Ní àkọ́kọ́ jẹ́ ẹjọ́ mi, kò sí ẹni tí ó ba mi gba ẹjọ́ rò ṣùgbọ́n gbogbo ènìyàn ni o kọ̀ mi sílẹ̀, àdúrà mi ni kí a má ṣe kà á sí wọn lọ́rùn.
En mi primera reunión con mis jueces, nadie tomó mi parte, pero todos se alejaron de mi. Espero que Dios no se los tome en cuenta.
17 Ṣùgbọ́n Olúwa gba ẹjọ́ mi rò, ó sì fún mi lágbára; pé nípasẹ̀ mi kí a lè wàásù náà ní àwàjálẹ̀, àti pé kí gbogbo àwọn aláìkọlà lè gbọ́; a sì gbà mí kúrò lẹ́nu kìnnìún náà.
Pero el Señor estaba a mi lado y me dio fuerzas; para que por mí se divulguen las noticias en toda su plenitud, y todos los gentiles puedan prestar oído; y yo fui sacado de la boca del león.
18 Olúwa yóò yọ mí kúrò nínú iṣẹ́ búburú gbogbo, yóò sì mu mí dé inú ìjọba ọ̀run. Ẹni ti ògo wà fún láé àti láéláé. Àmín. (aiōn )
El Señor me salvará de toda obra mala y me salvará en su reino en el cielo: a él sea la gloria por los siglos de los siglos. Que así sea. (aiōn )
19 Kí Priska àti Akuila, àti ilé Onesiforu.
Dale mi amor a Prisca y Aquila y a los de la casa de Onesíforo.
20 Erastu wà ní Kọrinti: ṣùgbọ́n mo fi Tirofimu sílẹ̀ ni Miletu nínú àìsàn.
Erasto se quedó en Corinto; pero Trófimo, cuando lo vi por última vez estaba en Mileto, enfermo.
21 Sa ipá rẹ láti tètè wá ṣáájú ìgbà òtútù. Eubulu kí ọ, àti Pudeni, àti Linu, Klaudia, àti gbogbo àwọn arákùnrin.
Haz tu mejor esfuerzo para venir antes del invierno. Te mandan saludos Eubulo, te manda saludos Pudente y Lino, Claudia, y todos los hermanos.
22 Kí Olúwa wà pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ kí oore-ọ̀fẹ́ wà pẹ̀lú yín.
El Señor Jesucristo esté con ustedes, y que Dios derrame su gracia sobre todos ustedes.