< 2 Timothy 2 >

1 Nítorí náà ìwọ ọmọ mi, jẹ́ alágbára nínú oore-ọ̀fẹ́ ti ń bẹ nínú Kristi Jesu.
Ty więc, mój synu, wzmacniaj się w łasce, która jest w Chrystusie Jezusie.
2 Àwọn ohun ti ìwọ ti gbọ́ lọ́dọ̀ mi níwájú ẹlẹ́rìí púpọ̀, àwọn náà ni kí ìwọ fi lé àwọn olóòtítọ́ ènìyàn lọ́wọ́, àwọn ti yóò lè máa kọ́ àwọn ẹlòmíràn pẹ̀lú.
A co słyszałeś ode mnie wobec wielu świadków, to powierz wiernym ludziom, którzy będą zdolni nauczać także innych.
3 Ṣe alábápín pẹ̀lú mi nínú ìpọ́njú, bí ọmọ-ogun rere Jesu Kristi.
Dlatego znoś trudy jak dobry żołnierz Jezusa Chrystusa.
4 Kò sí ẹni tí ń jagun ti ń fi ohun ayé yìí dí ara rẹ̀ lọ́wọ́, kí ó lè mú inú ẹni tí ó yàn ni ọmọ-ogun dùn.
Nikt, kto pełni służbę żołnierską, nie wikła się w sprawy tego życia, aby podobać się temu, który go powołał na żołnierza.
5 Ní ọ̀nà kan náà, bí ẹnikẹ́ni bá sì ń díje bí olùdíje, a kì í dé e ládé, bí kò ṣe bí ó bá parí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà
Również jeśli ktoś staje do zapasów, nie otrzymuje korony, jeżeli nie walczy prawidłowo.
6 Àgbẹ̀ ti ó ń ṣe làálàá ni ó yẹ láti kọ́kọ́ mu nínú àwọn èso.
Rolnik, który pracuje, jako pierwszy powinien korzystać z plonów.
7 Ronú lórí ohun ti èmi ń sọ; nítorí Olúwa yóò fún ọ lóye nínú ohun gbogbo.
Rozważ, co mówię, a niech Pan ci da zrozumienie we wszystkim.
8 Rántí Jesu Kristi, ti ó jíǹde kúrò nínú òkú, láti inú irú-ọmọ Dafidi gẹ́gẹ́ bí ìyìnrere mi.
Pamiętaj, że Jezus Chrystus, potomek Dawida, powstał z martwych według mojej ewangelii;
9 Nínú èyí tí èmi ń rí ìpọ́njú títí dé inú ìdè bí arúfin; ṣùgbọ́n a kò de ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
Dla której znoszę cierpienia jak złoczyńca, aż do więzów, ale słowo Boże nie jest związane.
10 Nítorí náà mo ń faradà ohun gbogbo nítorí àwọn àyànfẹ́; kí àwọn náà pẹ̀lú lè ní ìgbàlà tí ń bẹ nínú Kristi Jesu pẹ̀lú ògo ayérayé. (aiōnios g166)
Dlatego wszystko znoszę przez wzgląd na wybranych, aby i oni dostąpili zbawienia, które jest w Chrystusie Jezusie wraz z wieczną chwałą. (aiōnios g166)
11 Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ náà, bi àwa bá bá a kú, àwa yóò yè pẹ̀lú rẹ̀.
Wiarygodne to słowa. Jeśli bowiem z nim umarliśmy, z nim też będziemy żyć.
12 Bí àwa bá faradà, àwa ó sì bá a jẹ ọba. Bí àwa bá sẹ́ ẹ, òun náà yóò sì sẹ́ wa.
Jeśli cierpimy, z nim też będziemy królować, jeśli się go wyprzemy, i on się nas wyprze.
13 Bí àwa kò bá gbàgbọ́, òun dúró ni olóòtítọ́, nítorí òun kò lè sẹ́ ara rẹ̀.
Jeśli jesteśmy niewierni, on pozostaje wierny, bo samego siebie wyprzeć się nie może.
14 Nǹkan wọ̀nyí ni ki ó máa rán wọn létí. Máa kìlọ̀ fún wọn níwájú Olúwa pé, ki wọn ó yẹra kúrò nínú jíjiyàn ọ̀rọ̀ tí kò léèrè, bí kò ṣe ìparun fún àwọn tí ń gbọ́.
To wszystko przypominaj, zaklinając [ich] przed Panem, aby się nie wdawali w spory o słowa, bo to niczemu nie służy, tylko [prowadzi] do zguby słuchaczy.
15 Ṣaápọn láti fi ara rẹ̀ hàn níwájú Ọlọ́run bi ẹni tí ó yege àti òṣìṣẹ́ tí kò ní láti tijú, tí ó ń pín ọ̀rọ̀ òtítọ́ bí ó ti yẹ.
Staraj się, abyś stanął przed Bogiem jako wypróbowany pracownik, który nie ma się czego wstydzić [i] który dobrze rozkłada słowo prawdy.
16 Yà kúrò nínú ọ̀rọ̀ asán, nítorí tiwọn máa síwájú nínú àìwà-bí-Ọlọ́run.
Unikaj zaś pospolitej, czczej gadaniny, bo prowadzi ona do [coraz] większej bezbożności.
17 Ọ̀rọ̀ wọn yóò sì máa fẹ́ bí egbò kíkẹ̀; nínú àwọn ẹni tí Himeneu àti Filetu wà;
A ich mowa szerzy się jak gangrena. Do nich należą Hymenajos i Filetos;
18 àwọn ẹni tí ó ti ṣìnà kúrò nínú òtítọ́, tí ń wí pé àjíǹde ti kọjá ná; tí wọ́n sì ń bi ìgbàgbọ́ àwọn mìíràn ṣubú.
Którzy pobłądzili w [sprawie] prawdy, mówiąc, że zmartwychwstanie już nastąpiło, i wywracają wiarę niektórych.
19 Ṣùgbọ́n ìpìlẹ̀ Ọlọ́run tí ó dájú dúró ṣinṣin, ó ní èdìdì yìí, pé, “Olúwa mọ àwọn tí í ṣe tirẹ̀.” Àti pẹ̀lú, “Kí olúkúlùkù ẹni tí ń pé orúkọ Olúwa kúrò nínú àìṣòdodo.”
Mimo to fundament Boży stoi niewzruszony, mając taką pieczęć: Zna Pan tych, którzy należą do niego, oraz: Niech odstąpi od nieprawości każdy, kto wzywa imienia Chrystusa.
20 Ṣùgbọ́n nínú ilé ńlá, kì í ṣe kìkì ohun èlò wúrà àti ti fàdákà nìkan ni ń bẹ, ṣùgbọ́n ti igi àti amọ̀ pẹ̀lú; àti òmíràn sí ọlá, àti òmíràn sí àìlọ́lá.
W wielkim zaś domu znajdują się nie tylko naczynia złote i srebrne, lecz także drewniane i gliniane, niektóre do [użytku] zaszczytnego, a inne do niezaszczytnego.
21 Bí ẹnikẹ́ni bá wẹ ara rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìwọ̀nyí, òun yóò jẹ́ ohun èlò sí ọlá, tí a yà sọ́tọ̀, tí ó sì yẹ fún ìlò baálé, tí a sì ti pèsè sílẹ̀ fún iṣẹ́ rere gbogbo.
Jeśli więc ktoś oczyści samego siebie z tego [wszystkiego], będzie naczyniem do [użytku] zaszczytnego, uświęconym i użytecznym dla Pana, przygotowanym do każdego dobrego czynu.
22 Máa sá fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ èwe, sì máa lépa òdodo, ìgbàgbọ́, ìfẹ́, àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn tí ń ké pe Olúwa láti inú ọkàn funfun wá.
Uciekaj też od młodzieńczych pożądliwości, a zabiegaj o sprawiedliwość, wiarę, miłość, pokój wraz z tymi, którzy wzywają Pana z czystego serca.
23 Ìbéèrè òmùgọ̀ àti aláìní ẹ̀kọ́ nínú ni kí o kọ̀, bí o ti mọ̀ pe wọn máa dá ìjà sílẹ̀.
Unikaj zaś głupich i niedouczonych rozmów, wiedząc, że rodzą kłótnie.
24 Ìránṣẹ́, Olúwa kò sì gbọdọ̀ jà; bí kò ṣe kí ó jẹ́ ẹni pẹ̀lẹ́ sí ènìyàn gbogbo ẹni tí ó lè kọ́ni, àti onísùúrù.
A sługa Pana nie powinien wdawać się w kłótnie, lecz ma być uprzejmy względem wszystkich, zdolny do nauczania, cierpliwie znoszący złych;
25 Ẹni tí yóò máa kọ́ àwọn alátakò pẹ̀lú ìwà tútù, ní ìrètí pé Ọlọ́run lè fún wọn ní ìrònúpìwàdà sí ìmọ̀ òtítọ́,
Łagodnie nauczający tych, którzy się sprzeciwiają; może kiedyś Bóg da im pokutę, aby uznali prawdę;
26 wọn ó sì lè bọ́ kúrò nínú ìdẹ̀kùn èṣù, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti mú wọn láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
Oprzytomnieli i [wyrwali się] z sideł diabła, przez którego zostali schwytani do pełnienia jego woli.

< 2 Timothy 2 >