< 2 Timothy 2 >
1 Nítorí náà ìwọ ọmọ mi, jẹ́ alágbára nínú oore-ọ̀fẹ́ ti ń bẹ nínú Kristi Jesu.
Tvou silou, můj synu, ať je Kristova moc.
2 Àwọn ohun ti ìwọ ti gbọ́ lọ́dọ̀ mi níwájú ẹlẹ́rìí púpọ̀, àwọn náà ni kí ìwọ fi lé àwọn olóòtítọ́ ènìyàn lọ́wọ́, àwọn ti yóò lè máa kọ́ àwọn ẹlòmíràn pẹ̀lú.
Co jsi se naučil ode mne, předávej spolehlivým a schopným lidem, kteří budou šířit pravdu dál.
3 Ṣe alábápín pẹ̀lú mi nínú ìpọ́njú, bí ọmọ-ogun rere Jesu Kristi.
Jako řádný bojovník Ježíše Krista ochotně snášej nepohodlí a útrapy.
4 Kò sí ẹni tí ń jagun ti ń fi ohun ayé yìí dí ara rẹ̀ lọ́wọ́, kí ó lè mú inú ẹni tí ó yàn ni ọmọ-ogun dùn.
Kdo stojí v boji, nemá čas na soukromé záležitosti, nechce-li upadnout v nelibost u velitele.
5 Ní ọ̀nà kan náà, bí ẹnikẹ́ni bá sì ń díje bí olùdíje, a kì í dé e ládé, bí kò ṣe bí ó bá parí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà
I sportovec musí dodržovat pravidla, nemá-li být diskvalifikován.
6 Àgbẹ̀ ti ó ń ṣe làálàá ni ó yẹ láti kọ́kọ́ mu nínú àwọn èso.
Pracuj pilně jako rolník, který sklidí úrodu jen tehdy, když ji zaléval svým potem.
7 Ronú lórí ohun ti èmi ń sọ; nítorí Olúwa yóò fún ọ lóye nínú ohun gbogbo.
Přemýšlej, co tím chci říci. Pán ti jistě pomůže zaujmout ke všemu správný postoj.
8 Rántí Jesu Kristi, ti ó jíǹde kúrò nínú òkú, láti inú irú-ọmọ Dafidi gẹ́gẹ́ bí ìyìnrere mi.
Nikdy nezapomeň, že Ježíš Kristus jako člověk pochází z královského Davidova rodu. Zároveň však svým zmrtvýchvstáním dokázal, že je Bohem.
9 Nínú èyí tí èmi ń rí ìpọ́njú títí dé inú ìdè bí arúfin; ṣùgbọ́n a kò de ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
Jenom proto, že jsem tyto velké pravdy hlásal, jsem teď přikován ve vězení jako nějaký zločinec. Ale Boží slovo nikdo neuváže na řetěz jako mne.
10 Nítorí náà mo ń faradà ohun gbogbo nítorí àwọn àyànfẹ́; kí àwọn náà pẹ̀lú lè ní ìgbàlà tí ń bẹ nínú Kristi Jesu pẹ̀lú ògo ayérayé. (aiōnios )
A tak to s radostí snáším pro ty, kterým chce Bůh dát záchranu a věčnou slávu v Kristu Ježíši. (aiōnios )
11 Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ náà, bi àwa bá bá a kú, àwa yóò yè pẹ̀lú rẹ̀.
Utěšuje mne vědomí, že trpět a zemřít pro Krista znamená taky žít s ním na věčnosti,
12 Bí àwa bá faradà, àwa ó sì bá a jẹ ọba. Bí àwa bá sẹ́ ẹ, òun náà yóò sì sẹ́ wa.
a kdo vydrží s ním všechna utrpení zde, bude s ním jednou vládnout. Kdo se ho však tady zřekne, toho se zřekne i on.
13 Bí àwa kò bá gbàgbọ́, òun dúró ni olóòtítọ́, nítorí òun kò lè sẹ́ ara rẹ̀.
Ale i když my zklameme jeho důvěru, on nám věrně stojí po boku, protože neumí být nevěrný.
14 Nǹkan wọ̀nyí ni ki ó máa rán wọn létí. Máa kìlọ̀ fún wọn níwájú Olúwa pé, ki wọn ó yẹra kúrò nínú jíjiyàn ọ̀rọ̀ tí kò léèrè, bí kò ṣe ìparun fún àwọn tí ń gbọ́.
Připomínej to vždycky znovu a v Boží autoritě umlčuj hádky o slovíčka; nepřispívají k ničemu, leda ke zmatku u posluchačů.
15 Ṣaápọn láti fi ara rẹ̀ hàn níwájú Ọlọ́run bi ẹni tí ó yege àti òṣìṣẹ́ tí kò ní láti tijú, tí ó ń pín ọ̀rọ̀ òtítọ́ bí ó ti yẹ.
Snaž se být užitečným Božím pracovníkem, Boží pravdy hlásej čistě a jasně, abys mohl své dílo odevzdat bez obav, že propadne.
16 Yà kúrò nínú ọ̀rọ̀ asán, nítorí tiwọn máa síwájú nínú àìwà-bí-Ọlọ́run.
Vyhýbej se lidem, kteří si libují v planých diskusích a tím odvádějí od Boha.
17 Ọ̀rọ̀ wọn yóò sì máa fẹ́ bí egbò kíkẹ̀; nínú àwọn ẹni tí Himeneu àti Filetu wà;
Jejich bludy působí zhoubně jako rakovina. Patří k nim i Hymenaios a Filétos,
18 àwọn ẹni tí ó ti ṣìnà kúrò nínú òtítọ́, tí ń wí pé àjíǹde ti kọjá ná; tí wọ́n sì ń bi ìgbàgbọ́ àwọn mìíràn ṣubú.
kteří řadu křesťanů pomátli učením, že vzkříšení mrtvých už nastalo.
19 Ṣùgbọ́n ìpìlẹ̀ Ọlọ́run tí ó dájú dúró ṣinṣin, ó ní èdìdì yìí, pé, “Olúwa mọ àwọn tí í ṣe tirẹ̀.” Àti pẹ̀lú, “Kí olúkúlùkù ẹni tí ń pé orúkọ Olúwa kúrò nínú àìṣòdodo.”
Ale Boží pravda stojí pevně jako skála, kterou nic neotřese, jako základní kámen, na němž je napsáno: „Bůh zná ty, kdo mu patří“a „Kdo vyznává Boha, odvrať se od bezbožností“.
20 Ṣùgbọ́n nínú ilé ńlá, kì í ṣe kìkì ohun èlò wúrà àti ti fàdákà nìkan ni ń bẹ, ṣùgbọ́n ti igi àti amọ̀ pẹ̀lú; àti òmíràn sí ọlá, àti òmíràn sí àìlọ́lá.
V zámožných domácnostech bývá zlaté a stříbrné nádobí pro slavnostní příležitosti; dřevěné a hliněné se užívá jen v kuchyni nebo na odpadky.
21 Bí ẹnikẹ́ni bá wẹ ara rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìwọ̀nyí, òun yóò jẹ́ ohun èlò sí ọlá, tí a yà sọ́tọ̀, tí ó sì yẹ fún ìlò baálé, tí a sì ti pèsè sílẹ̀ fún iṣẹ́ rere gbogbo.
Když si s těmi bludaři nezadáš, zůstaneš vzácnou nádobou, kterou bude sám Kristus moci použít pro své vznešené účely.
22 Máa sá fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ èwe, sì máa lépa òdodo, ìgbàgbọ́, ìfẹ́, àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn tí ń ké pe Olúwa láti inú ọkàn funfun wá.
Buď na stráži před nebezpečími, která obkličují mladého člověka. Pěstuj v sobě víru a lásku ve společenství s těmi, kdo Pána milují z čistého srdce.
23 Ìbéèrè òmùgọ̀ àti aláìní ẹ̀kọ́ nínú ni kí o kọ̀, bí o ti mọ̀ pe wọn máa dá ìjà sílẹ̀.
Znovu ti připomínám, nepouštěj se do takových debat, které lidi jen rozeštvávají.
24 Ìránṣẹ́, Olúwa kò sì gbọdọ̀ jà; bí kò ṣe kí ó jẹ́ ẹni pẹ̀lẹ́ sí ènìyàn gbogbo ẹni tí ó lè kọ́ni, àti onísùúrù.
Kristův služebník se nesmí hádat; musí být taktní a trpělivě
25 Ẹni tí yóò máa kọ́ àwọn alátakò pẹ̀lú ìwà tútù, ní ìrètí pé Ọlọ́run lè fún wọn ní ìrònúpìwàdà sí ìmọ̀ òtítọ́,
poučovat toho, kdo se mýlí. Když ti někdo odporuje, zůstaň přesto vlídný;
26 wọn ó sì lè bọ́ kúrò nínú ìdẹ̀kùn èṣù, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti mú wọn láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
možná, že ho tím s Boží pomocí snáze přesvědčíš o jeho omylu a on unikne z ďábelské léčky.