< 2 Timothy 1 >

1 Paulu, aposteli ti Jesu Kristi nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìlérí ìyè ti ń bẹ nínú Kristi Jesu,
Paul, apôtre de Jésus-Christ par la volonté de Dieu, — pour annoncer la promesse de la vie qui est en Jésus-Christ, —
2 Sí Timotiu, ọmọ mi olùfẹ́ ọ̀wọ́n: Oore-ọ̀fẹ́, àánú àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa, àti Kristi Jesu Olúwa wa.
à Timothée, mon enfant bien-aimé. Que la grâce, la miséricorde et la paix te soient données de la part de Dieu, le Père, et de Jésus-Christ, notre Seigneur!
3 Mo dá ọpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run, ẹni tí èmi ń sìn pẹ̀lú ẹ̀rí ọkàn mímọ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba mi ti í ṣe, pé ni àìsimi lọ́sàn án àti lóru ni mo ń ṣe ìrántí rẹ nínú àdúrà mi.
Je rends grâces à Dieu que je sers, comme mes ancêtres l'ont fait, avec une conscience pure, faisant mention de toi sans cesse, nuit et jour, dans mes prières.
4 Bí mo ti rántí omijé rẹ, bẹ́ẹ̀ ni mo ń fẹ́ láti rí ọ kí èmi kí ó lè kún fún ayọ̀.
Car je me souviens de tes larmes, et j'ai un grand désir de te voir, afin d'être rempli de joie.
5 Nígbà ti mo bá rántí ìgbàgbọ́ àìṣẹ̀tàn rẹ, èyí ti ó kọ́kọ́ ń bẹ nínú Loisi ìyá ńlá rẹ, àti nínú Eunike ìyá rẹ̀ àti, èyí tí ó dá mi lójú pé ó ń gbé inú rẹ̀ pẹ̀lú.
Je garde aussi le souvenir de ta foi sincère, la foi qui demeura d'abord en Lois, ton aïeule, et en Eunice, ta mère, et qui, j'en suis persuadé, demeure aussi en toi.
6 Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe ń ran ọ létí pé kí ó máa rú ẹ̀bùn Ọlọ́run sókè èyí ti ń bẹ nínú rẹ nípa ìgbọ́wọ́lé mi.
C'est pourquoi, je te recommande de rallumer le don de Dieu, que tu as reçu par l'imposition de mes mains.
7 Nítorí pé Ọlọ́run kò fún wa ni ẹ̀mí ìbẹ̀rù, bí kò ṣe ti agbára, àti ti ìfẹ́, àti ti ìsẹ́ra-ẹni ti ó yè kooro.
Car Dieu ne nous a pas donné un esprit de timidité, mais un esprit de force, d'amour et de prudence.
8 Nítorí náà, má ṣe tijú láti jẹ́rìí nípa Olúwa wa, tàbí èmi òǹdè rẹ̀; ṣùgbọ́n kí ìwọ ṣe alábápín nínú ìpọ́njú ìyìnrere nípa agbára Ọlọ́run,
N'aie donc pas honte du témoignage que tu dois rendre à notre Seigneur, ni de moi, qui suis son prisonnier; mais souffre avec moi pour l'Évangile, par la force que Dieu donne.
9 ẹni ti ó gbà wá là, ti ó si pè wá sínú ìwà mímọ́—kì í ṣe nípa iṣẹ́ tí a ṣe ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ète àti oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀. Oore-ọ̀fẹ́ yìí ni a fi fún wa nínú Kristi Jesu láti ìpìlẹ̀ ayérayé, (aiōnios g166)
C'est lui qui nous a sauvés et qui nous a appelés, par une vocation sainte, non pas selon nos oeuvres, mais selon son propre dessein, selon la grâce qui nous a été donnée en Jésus-Christ avant tous les siècles, (aiōnios g166)
10 ṣùgbọ́n tí a fihàn nísinsin yìí nípa ìfarahàn Jesu Kristi Olùgbàlà wa, ẹni ti ó pa ikú run, tí ó sì mú ìyè àti àìkú wá sí ìmọ́lẹ̀ nípasẹ̀ ìyìnrere.
et qui a été maintenant manifestée par l'apparition de notre Sauveur Jésus-Christ, lequel a détruit la mort et mis en évidence la vie et l'immortalité par l'Évangile.
11 Fún ti ìyìnrere tí a yàn mi láti jẹ oníwàásù àti aposteli àti olùkọ́.
C'est pour cet Évangile que j'ai été établi prédicateur, apôtre et docteur;
12 Nítorí ìdí èyí ní èmi ṣe ń jìyà wọ̀nyí pẹ̀lú. Ṣùgbọ́n ojú kò tì mí, nítorí èmi mọ ẹni tí èmi gbàgbọ́, ó sì dá mi lójú pé, òun lè pa ohun ti mo fi lé e lọ́wọ́ mọ́ títí di ọjọ́ náà.
et telle est la cause des maux que j'endure. Mais je n'en ai point honte; car je sais en qui j'ai cru, et je suis persuadé qu'il a la puissance de garder mon dépôt jusqu'au grand jour.
13 Ohun tí ó gbọ́ láti ọ̀dọ̀ mi, pa a mọ́ gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ ẹ̀kọ́ rere nínú ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ Kristi Jesu.
Conserve, dans la foi et dans la charité qui est en Jésus-Christ, le modèle des saines instructions que tu as reçues de moi.
14 Pa ohun rere ti a ti fi lé ọ lọ́wọ́ mọ́ nípa Ẹ̀mí Mímọ́ ti ń gbé inú wa.
Garde le bon dépôt, par le Saint-Esprit qui habite en nous.
15 Èyí ni ìwọ mọ̀ pé, gbogbo àwọn ti ó wà ni agbègbè Asia ti fi mí sílẹ̀, nínú àwọn ẹni tí Figeliu àti Hamogene gbé wà.
Tu sais que tous ceux qui sont en Asie m'ont abandonné; de ce nombre sont Phygelle et Hermogène.
16 Kí Olúwa fi àánú fún ilé Onesiforu; nítorí ti ó máa ń tù mi lára nígbà púpọ̀, ẹ̀wọ̀n mi kò sì tì í lójú.
Que le Seigneur fasse miséricorde à la famille d'Onésiphore; car il m'a souvent réconforté, et il n'a pas eu honte de mes chaînes.
17 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wà ni Romu, ó fi ẹ̀sọ̀ wá mi, ó sì rí mi.
Bien plus, dès son arrivée à Rome, il m'a cherché avec empressement, et il m'a trouvé.
18 Kí Olúwa fi fún un kí ó lè rí àánú lọ́dọ̀ Olúwa ni ọjọ́ náà! Ìwọ tìkára rẹ sá à mọ̀ ọ̀nà gbogbo tí ó gbà ràn mí lọ́wọ́ ni Efesu.
Que le Seigneur lui-même lui donne de trouver miséricorde auprès du Seigneur, au grand jour! Tu sais aussi, mieux que personne, tous les services qu'il m'a rendus à Éphèse.

< 2 Timothy 1 >