< 2 Samuel 1 >
1 Lẹ́yìn ikú Saulu, Dafidi ti ibi tí ó ti ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki bọ̀, ó sì dúró ní Siklagi ní ọjọ́ méjì.
Po śmierci Saula, gdy Dawid po rozgromieniu Amalekitów wrócił i zatrzymał się w Siklag przez dwa dni;
2 Ní ọjọ́ kẹta, ọkùnrin kan dé láti ibi ibùdó Saulu, pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ tí ó ti ya; àti erùpẹ̀ ní orí rẹ̀. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ Dafidi, ó wólẹ̀ fún un láti bu ọlá fún un.
Trzeciego dnia pewien człowiek przybył z obozu Saula z podartymi szatami i z prochem na głowie. Gdy przyszedł do Dawida, padł na ziemię i pokłonił [mu] się.
3 Dafidi sì béèrè pé, “Ibo ni ìwọ ti wá?” “Èmi sá láti ibùdó àwọn ọmọ Israẹli.”
Dawid zapytał go: Skąd przybywasz? Odpowiedział mu: Uciekłem z obozu Izraela.
4 Dafidi béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” “Sọ fún mi.” Ó wí pé, “Àwọn ọkùnrin náà sá láti ojú ogun. Ọ̀pọ̀ wọn ṣubú, wọ́n sì kú. Saulu àti ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Jonatani sì kú pẹ̀lú.”
Dawid znowu zapytał: Co się stało? Proszę, powiedz mi. Odpowiedział: Lud uciekł z pola bitwy, a wielu ludzi padło i poległo, także Saul i jego syn Jonatan polegli.
5 Nígbà náà, ní Dafidi sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Báwo ni o ṣe mọ̀ pé Saulu àti ọmọkùnrin rẹ̀ Jonatani ti kú.”
Wtedy Dawid zapytał młodzieńca, który mu to powiedział: Skąd wiesz, że Saul i jego syn Jonatan umarli?
6 Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sọ pé, “Mo wà ní orí òkè Gilboa níbẹ̀ ni Saulu fi ara tí ọkọ̀ rẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin sì ń lépa rẹ̀.
Młodzieniec, który mu to oznajmił, odpowiedział: Przypadkiem znalazłem się na górze Gilboa, a oto Saul opierał się na swojej włóczni, a rydwany i jeźdźcy doganiali go.
7 Nígbà tí ó wò yíká, tí ó rí mí, ó pè mi, mo sì wí pé, ‘Kí ni mo lè ṣe?’
Kiedy obejrzał się i zobaczył mnie, zawołał na mnie. Odpowiedziałem: Oto jestem.
8 “Ó bi mí wí pé, ‘Ta ni ìwọ?’ “Mo dáhùn pé, ‘Ará a Amaleki.’
I zapytał mnie: Kim jesteś? Odpowiedziałem mu: Jestem Amalekitą.
9 “Nígbà náà ó wí fún mi pé, ‘Dúró lórí ì mi kí o sì pa mí! Èmi wà nínú ìrora ikú, ṣùgbọ́n mo wà láààyè.’
Wtedy powiedział mi: Stań, proszę, nade mną i zabij mnie, bo ogarnęła mnie udręka, a moje życie [jest] jeszcze we mnie.
10 “Nígbà náà, mo dúró lórí i rẹ̀, mo sì pa á nítorí mo mọ̀ wí pé, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣubú, kò le è yè mọ́. Mo sì mú adé tí ó wà lórí rẹ̀, idẹ tí ó wà ní apá a rẹ̀, mo sì kó wọn wá síbí fún olúwa mi.”
Stanąłem więc nad nim i zabiłem go, bo wiedziałem, że nie przeżyje po swoim upadku. Potem wziąłem koronę, która [była] na jego głowie, oraz naramiennik, który [miał] na ramieniu, i przyniosłem je tutaj do swojego pana.
11 Nígbà náà ni, Dafidi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, di aṣọ wọn mú, wọ́n sì fà á ya.
Wtedy Dawid chwycił swoje szaty i rozdarł je, [tak uczynili] również wszyscy ludzie, którzy z nim byli.
12 Wọ́n ṣọ̀fọ̀, wọ́n sì sọkún, wọ́n sì gbààwẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́ fún Saulu àti ọmọ rẹ̀ Jonatani àti fún àwọn ọmọ-ogun Olúwa, àti fún àwọn ilé Israẹli, nítorí wọ́n ti ṣubú nípa idà.
Lamentowali i płakali, i pościli aż do wieczora po Saulu i jego synu Jonatanie, po ludzie PANA i po domu Izraela, że padli od miecza.
13 Dafidi sọ fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Níbo ni ó ti wá?” O dáhùn pé, “Ọmọ àlejò ni mo jẹ́, ará Amaleki.”
I Dawid zapytał młodzieńca, który mu [to] powiedział: Skąd jesteś? Odpowiedział: Jestem synem przybysza, Amalekity.
14 Dafidi béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ kò fi bẹ̀rù láti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè láti fi pa ẹni àmì òróró Olúwa?”
Dawid znowu zapytał go: Jakże nie bałeś się wyciągnąć swej ręki, aby zabić pomazańca PANA?
15 Nígbà náà Dafidi pe ọ̀kan nínú ọkùnrin, ó sì wí pé, “Lọ, gbé e lulẹ̀!” Nígbà náà ó gbé e lulẹ̀, ó sì kú.
Następnie Dawid zawołał jednego ze sług i rozkazał: Podejdź i zabij go. Ten uderzył go [tak], że umarł.
16 Nítorí Dafidi wí fún un pé, “Ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò wà lórí ara rẹ, nítorí ẹnu ara rẹ ni o fi sọ pé, ‘Mo pa ẹni àmì òróró Olúwa.’”
Dawid powiedział do niego: Twoja krew na twoją głowę, bo twoje usta świadczyły przeciw tobie, gdy mówiły: Zabiłem pomazańca PANA.
17 Dafidi sì fi orin ọ̀fọ̀ yìí ṣọ̀fọ̀ lórí Saulu àti lórí Jonatani ọmọ rẹ̀,
Wtedy Dawid podniósł lament nad Saulem i jego synem Jonatanem;
18 Ó sì pàṣẹ pé kí a kọ́ àwọn ọkùnrin Juda ní orin arò yìí tí ó jẹ́ ti ọrun (a kọ ọ́ sí inú ìwé Jaṣari):
Polecił także, aby synów Judy uczono [strzelać] z łuku. Oto co napisane jest w księdze Jaszara:
19 “Ògo rẹ, Israẹli ni a pa ní òkè gíga rẹ. Wò bí àwọn alágbára ṣe ń ṣubú!
Piękno Izraela poległo na twoich wzgórzach. Jakże padli mocarze!
20 “Ẹ má ṣe sọ ọ́ ní Gati, ẹ má ṣe kéde rẹ̀ ní òpópónà Aṣkeloni, kí àwọn ọmọbìnrin Filistini má bá à yọ̀, kí àwọn ọmọbìnrin aláìkọlà má ba à dunnú.
Nie opowiadajcie o tym w Gat ani nie rozgłaszajcie [tego] po ulicach w Aszkelonie, aby się nie cieszyły córki Filistynów, by się nie radowały córki nieobrzezanych.
21 “Ẹ̀yin òkè Gilboa, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe rí ìrì tàbí òjò, tàbí oko tí ó mú èso ọrẹ wá. Nítorí ibẹ̀ ni asà alágbára ti ṣègbé, asà Saulu, bí ẹni pé a kò fi òróró yàn án.
O góry Gilboa! Niech nie [pada] na was ani rosa, ani deszcz i niech tam nie [będzie] pól żyznych. Tam bowiem została skalana tarcza mocarzy, tarcza Saula, [jakby] nie była namaszczona oliwą.
22 “Ọrun Jonatani kì í padà bẹ́ẹ̀ ni idà Saulu kì í padà lásán, láì kan ẹ̀jẹ̀ àwọn tí a pa, àti ẹran àwọn alágbára.
Od krwi zabitych, od tłuszczu mocarzy nie cofał się łuk Jonatana, a miecz Saula nie wracał daremnie.
23 Saulu àti Jonatani— ní ọjọ́ ayé, wọ́n fẹ́ràn ara, wọn sì dùn, ní ikú, wọn kò sì yà ara wọ́n. Wọ́n yára ju idì lọ, wọ́n lágbára ju kìnnìún lọ.
Saul i Jonatan, ukochani i mili za życia, a w śmierci nie byli rozdzieleni, szybsi od orłów, silniejsi od lwów.
24 “Ẹ̀yin ọmọbìnrin Israẹli, ẹ sọkún lórí Saulu, ẹni tí ó fi aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára wọ̀ yín, ẹni tí ó fi wúrà sí ara aṣọ yín.
Córki Izraela, płaczcie nad Saulem, który was przyodziewał w piękny szkarłat i który włożył złote klejnoty na wasze szaty.
25 “Wò ó bí alágbára ti ṣubú ní ojú ogun! Jonatani, ìwọ tí a pa ní òkè gíga.
Jakże padli mocarze pośród bitwy! Jonatanie, na twych wzgórzach zostałeś zabity.
26 Ọkàn mi gbọgbẹ́ fún ọ Jonatani arákùnrin mi; ìwọ ṣọ̀wọ́n fún mi. Ìfẹ́ rẹ sí mi jẹ́ ìyanu, ó jẹ́ ìyanu ju ti obìnrin lọ.
Żal mi ciebie, mój bracie, Jonatanie. Byłeś mi bardzo miły. Twoja miłość była dla mnie cenniejsza niż miłość kobiety.
27 “Wò ó bí alágbára ti ṣubú! Ohun ìjà sì ti ṣègbé!”
Jakże padli mocarze i przepadły narzędzia wojny!