< 2 Samuel 1 >

1 Lẹ́yìn ikú Saulu, Dafidi ti ibi tí ó ti ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki bọ̀, ó sì dúró ní Siklagi ní ọjọ́ méjì.
Après la mort de Saül, David revenait de la tuerie des Amalécites, et il était resté deux jours à Tsiklag.
2 Ní ọjọ́ kẹta, ọkùnrin kan dé láti ibi ibùdó Saulu, pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ tí ó ti ya; àti erùpẹ̀ ní orí rẹ̀. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ Dafidi, ó wólẹ̀ fún un láti bu ọlá fún un.
Le troisième jour, voici qu'un homme sortit du camp de la part de Saül, les vêtements déchirés et de la terre sur la tête. Lorsqu'il arriva à David, il se jeta à terre et lui témoigna du respect.
3 Dafidi sì béèrè pé, “Ibo ni ìwọ ti wá?” “Èmi sá láti ibùdó àwọn ọmọ Israẹli.”
David lui dit: « D'où viens-tu? » Il lui dit: « Je me suis échappé du camp d'Israël. »
4 Dafidi béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” “Sọ fún mi.” Ó wí pé, “Àwọn ọkùnrin náà sá láti ojú ogun. Ọ̀pọ̀ wọn ṣubú, wọ́n sì kú. Saulu àti ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Jonatani sì kú pẹ̀lú.”
David lui dit: « Comment cela s'est-il passé? Dis-le-moi. » Il répondit: « Le peuple a fui la bataille, et beaucoup de gens sont tombés et sont morts. Saül et son fils Jonathan sont morts eux aussi. »
5 Nígbà náà, ní Dafidi sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Báwo ni o ṣe mọ̀ pé Saulu àti ọmọkùnrin rẹ̀ Jonatani ti kú.”
David dit au jeune homme qui lui avait raconté: « Comment sais-tu que Saül et Jonathan, son fils, sont morts? »
6 Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sọ pé, “Mo wà ní orí òkè Gilboa níbẹ̀ ni Saulu fi ara tí ọkọ̀ rẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin sì ń lépa rẹ̀.
Le jeune homme qui le raconta dit: « Comme je me trouvais par hasard sur la montagne de Gilboa, voici que Saül s'appuyait sur sa lance; et voici que les chars et les cavaliers suivaient de près derrière lui.
7 Nígbà tí ó wò yíká, tí ó rí mí, ó pè mi, mo sì wí pé, ‘Kí ni mo lè ṣe?’
Quand il regarda derrière lui, il me vit et m'appela. Je répondis: Me voici!
8 “Ó bi mí wí pé, ‘Ta ni ìwọ?’ “Mo dáhùn pé, ‘Ará a Amaleki.’
Il me dit: « Qui es-tu? Je lui répondis: Je suis un Amalécite.
9 “Nígbà náà ó wí fún mi pé, ‘Dúró lórí ì mi kí o sì pa mí! Èmi wà nínú ìrora ikú, ṣùgbọ́n mo wà láààyè.’
Il me dit: « Mets-toi à côté de moi, je t'en prie, et tue-moi, car l'angoisse s'est emparée de moi, parce que ma vie est encore en moi.
10 “Nígbà náà, mo dúró lórí i rẹ̀, mo sì pa á nítorí mo mọ̀ wí pé, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣubú, kò le è yè mọ́. Mo sì mú adé tí ó wà lórí rẹ̀, idẹ tí ó wà ní apá a rẹ̀, mo sì kó wọn wá síbí fún olúwa mi.”
Je me suis donc tenu à côté de lui et je l'ai tué, car j'étais sûr qu'il ne pourrait pas vivre après sa chute. J'ai pris la couronne qui était sur sa tête et le bracelet qui était à son bras, et je les ai apportés ici à mon seigneur. »
11 Nígbà náà ni, Dafidi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, di aṣọ wọn mú, wọ́n sì fà á ya.
Alors David saisit ses vêtements et les déchira, et tous les hommes qui étaient avec lui firent de même.
12 Wọ́n ṣọ̀fọ̀, wọ́n sì sọkún, wọ́n sì gbààwẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́ fún Saulu àti ọmọ rẹ̀ Jonatani àti fún àwọn ọmọ-ogun Olúwa, àti fún àwọn ilé Israẹli, nítorí wọ́n ti ṣubú nípa idà.
Ils se lamentèrent, pleurèrent et jeûnèrent jusqu'au soir sur Saül et sur Jonathan, son fils, sur le peuple de l'Éternel et sur la maison d'Israël, parce qu'ils étaient tombés par l'épée.
13 Dafidi sọ fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Níbo ni ó ti wá?” O dáhùn pé, “Ọmọ àlejò ni mo jẹ́, ará Amaleki.”
David dit au jeune homme qui lui a parlé: « D'où viens-tu? » Il répondit: « Je suis le fils d'un étranger, un Amalécite. »
14 Dafidi béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ kò fi bẹ̀rù láti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè láti fi pa ẹni àmì òróró Olúwa?”
David lui dit: « Pourquoi n'as-tu pas eu peur d'étendre ta main pour faire périr l'oint de Yahvé? ».
15 Nígbà náà Dafidi pe ọ̀kan nínú ọkùnrin, ó sì wí pé, “Lọ, gbé e lulẹ̀!” Nígbà náà ó gbé e lulẹ̀, ó sì kú.
David appela l'un des jeunes hommes et dit: « Approche, et coupe-le! ». Il le frappa de telle sorte qu'il mourut.
16 Nítorí Dafidi wí fún un pé, “Ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò wà lórí ara rẹ, nítorí ẹnu ara rẹ ni o fi sọ pé, ‘Mo pa ẹni àmì òróró Olúwa.’”
David lui dit: « Que ton sang retombe sur ta tête, car ta bouche a rendu témoignage contre toi, en disant: J'ai tué l'oint de l'Éternel. »
17 Dafidi sì fi orin ọ̀fọ̀ yìí ṣọ̀fọ̀ lórí Saulu àti lórí Jonatani ọmọ rẹ̀,
David se lamenta ainsi sur Saül et sur Jonathan, son fils
18 Ó sì pàṣẹ pé kí a kọ́ àwọn ọkùnrin Juda ní orin arò yìí tí ó jẹ́ ti ọrun (a kọ ọ́ sí inú ìwé Jaṣari):
(et il leur ordonna d'enseigner aux fils de Juda le chant de l'arc; voici, cela est écrit dans le livre de Jashar):
19 “Ògo rẹ, Israẹli ni a pa ní òkè gíga rẹ. Wò bí àwọn alágbára ṣe ń ṣubú!
« Ta gloire, Israël, a été tuée sur tes hauts lieux! Comme les puissants sont tombés!
20 “Ẹ má ṣe sọ ọ́ ní Gati, ẹ má ṣe kéde rẹ̀ ní òpópónà Aṣkeloni, kí àwọn ọmọbìnrin Filistini má bá à yọ̀, kí àwọn ọmọbìnrin aláìkọlà má ba à dunnú.
Ne le dis pas à Gath. Ne le publiez pas dans les rues d'Ashkelon, de peur que les filles des Philistins ne se réjouissent, de peur que les filles des incirconcis ne triomphent.
21 “Ẹ̀yin òkè Gilboa, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe rí ìrì tàbí òjò, tàbí oko tí ó mú èso ọrẹ wá. Nítorí ibẹ̀ ni asà alágbára ti ṣègbé, asà Saulu, bí ẹni pé a kò fi òróró yàn án.
Vous les montagnes de Gilboa, qu'il n'y ait ni rosée ni pluie sur vous, et pas de champs d'offrandes; car c'est là que le bouclier des puissants a été souillé et jeté, le bouclier de Saul n'a pas été oint d'huile.
22 “Ọrun Jonatani kì í padà bẹ́ẹ̀ ni idà Saulu kì í padà lásán, láì kan ẹ̀jẹ̀ àwọn tí a pa, àti ẹran àwọn alágbára.
Du sang des victimes, de la graisse des puissants, L'arc de Jonathan ne s'est pas retourné. L'épée de Saul n'est pas revenue vide.
23 Saulu àti Jonatani— ní ọjọ́ ayé, wọ́n fẹ́ràn ara, wọn sì dùn, ní ikú, wọn kò sì yà ara wọ́n. Wọ́n yára ju idì lọ, wọ́n lágbára ju kìnnìún lọ.
Saül et Jonathan étaient charmants et agréables dans leur vie. Dans leur mort, ils n'ont pas été divisés. Ils étaient plus rapides que les aigles. Ils étaient plus forts que des lions.
24 “Ẹ̀yin ọmọbìnrin Israẹli, ẹ sọkún lórí Saulu, ẹni tí ó fi aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára wọ̀ yín, ẹni tí ó fi wúrà sí ara aṣọ yín.
Filles d'Israël, pleurez sur Saül, qui t'a délicatement vêtu d'écarlate, qui ont mis des ornements d'or sur vos vêtements.
25 “Wò ó bí alágbára ti ṣubú ní ojú ogun! Jonatani, ìwọ tí a pa ní òkè gíga.
Comme les puissants sont tombés au milieu de la bataille! Jonathan a été tué sur vos hauts lieux.
26 Ọkàn mi gbọgbẹ́ fún ọ Jonatani arákùnrin mi; ìwọ ṣọ̀wọ́n fún mi. Ìfẹ́ rẹ sí mi jẹ́ ìyanu, ó jẹ́ ìyanu ju ti obìnrin lọ.
Je suis dans l'angoisse pour toi, mon frère Jonathan. Vous avez été très agréable avec moi. Ton amour pour moi était merveilleux, surpassant l'amour des femmes.
27 “Wò ó bí alágbára ti ṣubú! Ohun ìjà sì ti ṣègbé!”
Comme les puissants sont tombés, et les armes de guerre ont péri! »

< 2 Samuel 1 >