< 2 Samuel 9 >

1 Dafidi sì béèrè pé, ọ̀kan nínú àwọn ẹni tí ń ṣe ìdílé Saulu kù síbẹ̀ bí? Kí èmi lè ṣe oore fún un nítorí Jonatani.
Jonathan koe pahrennae ka kamnue sak nahanelah, Sawl imthungnaw dawk hoi kaawm rae ao maw telah Devit ni ati.
2 Ìránṣẹ́ kan sì ti wà ní ìdílé Saulu, orúkọ rẹ̀ sí ń jẹ́ Ṣiba, wọ́n sì pè é wá sọ́dọ̀ Dafidi, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ìwọ ni Ṣiba bí?” Ó sì dáhùn wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni.”
Sawl e sannaw thung e tami buet touh, a min Ziba ao teh Devit koe cei hanelah a kaw awh. Siangpahrang ni nang teh Ziba maw telah atipouh boteh, ahni ni, bokheiyah, na san kai doeh telah atipouh.
3 Ọba sì wí pé, “Kò ha sí ọ̀kan nínú ìdílé Saulu síbẹ̀, kí èmi ṣe oore Ọlọ́run fún un?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Jonatani ní ọmọ kan síbẹ̀ tó ya arọ.”
Siangpahrang ni Cathut lungpatawnae ka kamnue sak nahan Sawl imthungnaw thung dawk e kaawm rae awm hoeh na maw telah atipouh. Ziba ni, Jonathan ni capa buet touh a tawn teh a khokkhem telah atipouh.
4 Ọba sì wí fún un pé, “Níbo ni ó gbé wà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, òun wà ní ilé Makiri, ọmọ Ammieli, ní Lo-Debari.”
Siangpahrang ni nâmaw ao telah a pacei. Ziba ni khenhaw! Lodebar kho e Ammiel capa Makhir im vah ao telah atipouh.
5 Dafidi ọba sì ránṣẹ́, ó sì mú un láti ilé Makiri ọmọ Ammieli láti Lo-Debari wá.
Hattoteh siangpahrang Devit ni tami a patoun teh, Lodebar kho e Ammiel capa Makhir im hoi ahni teh a thokhai awh.
6 Mefiboṣeti ọmọ Jonatani ọmọ Saulu sì tọ Dafidi wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì bú ọlá fún un. Dafidi sì wí pé, “Mefiboṣeti!” Òun sì dáhùn wí pé, “Wò ó, ìránṣẹ́ rẹ!”
Sawl capa Jonathan e capa Mephibosheth teh Devit koe a tho teh, a minhmai talai dawk tabei laihoi a tabut. Devit ni Mephibosheth telah a kaw, na san kai teh hivah ka o telah atipouh.
7 Dafidi sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé nítòótọ́ èmi ó ṣe oore fún ọ nítorí Jonatani baba rẹ, èmi ó sì tún fi gbogbo ilé Saulu baba rẹ fún ọ, ìwọ ó sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.”
Devit ni na lungpuen hanh, na pa Jonathan kecu dawk na pahren hanelah, Sawl ni a tawn e pueng kai ni bout na poe han. Kaie caboi dawk bu pou na ven han toe telah atipouh.
8 Mefiboṣeti sì tẹríba, ó sì wí pé, “Kí ni ìránṣẹ́ rẹ jásí, tí ìwọ ó fi máa wo òkú ajá bí èmi.”
A lûsaling teh kai ui ro patet e na san kai heh banglamaw khuek na pouk telah ati.
9 Ọba sì pe Ṣiba ìránṣẹ́ Saulu, ó sì wí fún un pé, “Gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Saulu, àti gbogbo èyí tí í ṣe ti ìdílé rẹ̀ ni èmi fi fún ọmọ olúwa rẹ.
Siangpahrang ni Sawl e a san Ziba hah ama koe a kaw teh, Sawl hoi a imthung e hnopai pueng hah na bawipa e capa he ka poe toe.
10 Ìwọ, àti àwọn ọmọ rẹ, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni yóò sì máa ro ilẹ̀ náà fún un, ìwọ ni yóò sì máa mú ìkórè wá, ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa rí oúnjẹ jẹ, ṣùgbọ́n Mefiboṣeti ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.” (Ṣiba sì ní ọmọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́kùnrin.)
Nama hoi na capa, na sannaw hoi lai na thawn pouh vaiteh, na bawi capa ni a ca hane kawi ao thai nahan, na tawk e a pawhik hah na tho khai han. Hateiteh, na bawipa e capa Mephibosheth ni ka caboi dawk bu pou a ven han telah atipouh. Ziba ni a ca 15 touh hoi a san 20 touh a tawn.
11 Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa mi ọba ti pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ náà ni ìránṣẹ́ rẹ ó ṣe.” Ọba sì wí pé, “Ní ti Mefiboṣeti, yóò máa jẹun ní ibi oúnjẹ mi, gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọba.”
Ziba ni siangpahrang koevah, siangpahrang ka bawipa ni na san koe kâ na poe e patetlah na san ni ka sak han telah ati. Siangpahrang ni Mephibosheth teh ka caboi dawk siangpahrang capa buet touh patetlah bu pou a ca han toe telah ati.
12 Mefiboṣeti sì ní ọmọ kékeré kan, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika. Gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilé Ṣiba ni ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Mefiboṣeti.
Mephibosheth ni capa cahnoung Mika a min phung e buet touh a tawn. Ziba im dawk kaawm e pueng teh Mephibosheth e san lah ao awh.
13 Mefiboṣeti sì ń gbé ní Jerusalẹmu, òun a sì máa jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ ọba; òun sì yarọ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì.
Mephibosheth teh, Jerusalem kho dawk ao teh, hnintangkuem siangpahrang e caboi dawk bu a ven, a khok kahni touh hoi a khem.

< 2 Samuel 9 >