< 2 Samuel 8 >

1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn èyí, Dafidi sì kọlu àwọn Filistini, ó sì tẹrí wọn ba, Dafidi sì gba Metegamima lọ́wọ́ àwọn Filistini.
I stało się potem, że poraził Dawid Filistyny, i poniżył je; a wziął Dawid Meteg Amma z rąk Filistyńskich.
2 Dafidi sì kọlu Moabu, ó sì fi okùn títa kan dì wọ́n, ó sì dá wọn dùbúlẹ̀; ó sì ṣe òsùwọ̀n okùn méjì ni iye àwọn tí yóò dá sí. Àwọn ará Moabu sì ń sin Dafidi, wọn a sì máa mú ẹ̀bùn wá.
Poraził też i Moabity, które pomierzył sznurem, zrównawszy je z ziemią, i wymierzył ich dwa sznury na zabicie, a cały sznur na zachowanie przy żywocie; i byli Moabitowie sługami Dawidowymi, przynosząc mu podatki.
3 Dafidi sì kọlu Hadadeseri ọmọ Rehobu, ọba Soba, bí òun sì ti ń lọ láti mú agbára rẹ̀ bọ̀ sípò ni odò Eufurate.
Poraził też Dawid Hadadezera, syna Rochobowego, króla Soby, gdy wyjechał, aby rozprzestrzenił granice swe nad rzeką Eufrates.
4 Dafidi sì gba ẹgbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ẹlẹ́ṣin, àti ogún ẹgbẹ̀rún àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀. Dafidi sì já gbogbo àwọn ẹṣin kẹ̀kẹ́ wọn ní pàtì, ṣùgbọ́n ó dá ọgọ́rùn-ún kẹ̀kẹ́ sí nínú wọn.
I pojmał z nich Dawid tysiąc i siedm set jezdnych, a dwadzieście tysięcy ludu pieszego. I poderznął Dawid żyły wszystkim woźnikom, zachowawszy koni do sta wozów.
5 Nígbà tí àwọn ará Siria ti Damasku sì wá láti ran Hadadeseri ọba Soba lọ́wọ́, Dafidi sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ènìyàn nínú àwọn ará Siria.
Przyciągnął tedy Syryjczyk z Damaszku na pomoc Hadadezerowi, królowi Soby, i poraził Dawid Syryjczyków dwadzieścia i dwa tysiące mężów.
6 Dafidi sì fi àwọn ológun sí Siria ti Damasku, àwọn ará Siria sì wá sin Dafidi, wọn a sì máa mú ẹ̀bùn wá, Olúwa sì pa Dafidi mọ́ níbikíbi tí o ń lọ.
I osadził Dawid żołnierzem Syryją Damaską. A tak Syryjczycy byli sługami Dawidowymi, przynosząc mu podatki; i bronił Pan Dawida wszędzie gdziekolwiek się obrócił.
7 Dafidi sì gba àṣà wúrà tí ó wà lára àwọn ìránṣẹ́ Hadadeseri, ó sì gbé wọn wá sí Jerusalẹmu.
Pobrał też Dawid tarcze złote, które mieli słudzy Hadadezerowi, i wniósł je do Jeruzalemu.
8 Láti Beta, àti láti Berotai, àwọn ìlú Hadadeseri, ọba Dafidi kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ idẹ wá.
Przytem z Betachu i z Berotu, miast Hadadezerowych, przyniósł król Dawid bardzo wiele miedzi.
9 Nígbà tí Tou ọba Hamati sì gbọ́ pé Dafidi ti pa gbogbo ogun Hadadeseri.
To usłyszawszy Tohy, król Emat, iż poraził Dawid wszystko wojsko Hadadezerowe,
10 Toi sì rán Joramu ọmọ rẹ̀ sí Dafidi ọba, láti kí i, àti láti súre fún un, nítorí pé ó tí bá Hadadeseri jagun, ó sì ti pa á, nítorí tí Hadadeseri sá à ti bá Toi jagun. Joramu sì ni ohun èlò fàdákà, àti ohun èlò wúrà, àti ohun èlò idẹ ní ọwọ́ rẹ̀.
Posłał Tohy Jorama, syna swego, do króla Dawida, aby go pozdrowił w pokoju, i winszował mu, przeto że zwalczył Hadadezera, i poraził go, (albowiem walczył z Tohym Hadadezer, ) i przyniósł z sobą naczynia srebrne, i naczynia złote, i naczynia miedziane.
11 Dafidi ọba sì fi wọ́n fún Olúwa pẹ̀lú fàdákà, àti wúrà tí ó yà sí mímọ́, èyí tí ó ti gbà lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ti ṣẹ́gun.
Które też rzeczy poświęcił król Dawid Panu z innem srebrem i złotem, które był poświęcił, pobrawszy od wszystkich narodów, które sobie podbił.
12 Lọ́wọ́ Siria àti lọ́wọ́ Moabu àti lọ́wọ́ àwọn ọmọ Ammoni, àti lọ́wọ́ àwọn Filistini, àti lọ́wọ́ Amaleki, àti nínú ìkógun Hadadeseri ọmọ Rehobu ọba Soba.
Jako od Syryjczyków, i od Moabczyków, i od synów Ammonowych, i od Filistynów, i od Amalekitów, i z łupów Hadadezera, syna Rochobowego, króla Soby.
13 Dafidi sì ní òkìkí gidigidi nígbà tí ó padà wá ilé láti ibi pípa àwọn ará Siria ní àfonífojì Iyọ̀, àwọn tí o pa jẹ́ ẹgbàá mẹ́sàn ènìyàn.
A tak uczynił sobie Dawid imię, gdy się wrócił poraziwszy Syryjczyki w dolinie solnej, gdzie pobił ośmnaście tysięcy ludu.
14 Ó sì fi àwọn ológun sí Edomu; àti ní gbogbo Edomu yíká ni òun sì fi ológun sí, gbogbo àwọn tí ó wà ní Edomu sì wá sin Dafidi, Olúwa sì fún Dafidi ní ìṣẹ́gun níbikíbi tí ó ń lọ.
Postanowił też straż w Edom, wszystkę ziemię Edomską osadziwszy żołnierzami; i byli wszyscy Edomczycy sługami Dawidowymi, a bronił Pan Dawida wszędzie, gdzie się obrócił.
15 Dafidi sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli; Dafidi sì ṣe ìdájọ́ àti òtítọ́ fún àwọn ènìyàn rẹ̀.
I królował Dawid nad wszystkim Izraelem, i czynił sąd i sprawiedliwość wszystkiemu ludowi swemu.
16 Joabu ọmọ Seruiah ni ó sì ń ṣe olórí ogun; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì ń ṣe akọ̀wé.
A Joab, syn Sarwii, był nad wojskiem, a Jozafat syn Ahiluda, kanclerzem.
17 Sadoku ọmọ Ahitubu, àti Ahimeleki ọmọ Abiatari, ni àwọn àlùfáà; Seraiah a sì máa ṣe akọ̀wé.
A Sadok, syn Achitoba, i Achimelech, syn Abijatara, byli kapłanami, a Saraja pisarzem.
18 Benaiah ọmọ Jehoiada ni ó sì ń ṣe olórí àwọn Kereti, àti àwọn Peleti; àwọn ọmọ Dafidi sì jẹ́ aláṣẹ.
Banajas też, syn Jojada, nad Cheretczykami i Feletczykami, a synowie Dawidowi byli książętami.

< 2 Samuel 8 >