< 2 Samuel 7 >
1 Ó sì ṣe, nígbà tí ọba ń gbé ní ilé rẹ̀, tí Olúwa sì fún un ní ìsinmi yíkákiri kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.
И като се настани царят в къщата си, и Господ беше го успокоил от всичките неприятели около него,
2 Ọba sì wí fún Natani wòlíì pé, “Sá wò ó, èmi ń gbé inú ilẹ̀ tí a fi kedari kọ́, ṣùgbọ́n àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ń gbé inú ibi tí a fi aṣọ gé.”
царят каза на пророк Натана: Виж сега, аз живея в кедрова къща, а Божият ковчег стои под завеси.
3 Natani sì wí fún ọba pé, “Lọ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn rẹ, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
И Натан каза на царя: Иди, стори всичко, което е в сърцето ти; защото Господ е с тебе.
4 Ó sì ṣe ní òru náà, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Natani wá pé,
Но през същата нощ Господното слово дойде на Натана и рече:
5 “Lọ, sọ fún ìránṣẹ́ mi, fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ó ha kọ́ ilé fún mi tí èmi yóò gbé.
Иди кажи на слугата Ми Давида: Така говори Господ: Ти ли ще Ми построиш дом, в който да обитавам?
6 Nítorí pé, èmi kò ì ti gbé inú ilé kan láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ọmọ Israẹli gòkè ti ilẹ̀ Ejibiti wá, títí di òní yìí, ṣùgbọ́n èmi ti ń rìn nínú àgọ́, fún ibùgbé mi.
Защото от деня, когато изведох израилтяните от Египет дори до днес, не съм обитавал в дом, но съм ходил в шатър и в скиния.
7 Ní ibi gbogbo tí èmi ti ń rìn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ǹjẹ́ èmi ti bá ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli, tí èmi pa àṣẹ fún láti máa bọ́ àwọn ènìyàn mi àní Israẹli, sọ̀rọ̀ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi kedari kọ́ ilé fún mi.”’
Където и да съм ходил с всичките израилтяни, говорих ли някога на някое от Израилевите племена, на което заповядах да пасе людете Ми Израиля, да кажа: Защо не Ми построихте кедров дом?
8 “Ǹjẹ́, nítorí náà, báyìí ni ìwọ yóò sì wí fún ìránṣẹ́ mi àní Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, Èmi ti mú ìwọ kúrò láti inú agbo àgùntàn wá láti má tẹ̀lé àwọn àgùntàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli.
Сега, прочее, така да кажеш на слугата Ми Давида: Така казва Господ на Силите: Аз те взех от кошарата, от подир стадото, за да бъдеш вожд на людете Ми, на Израиля;
9 Èmi sì wà pẹ̀lú rẹ níbikíbi tí ìwọ ń lọ, èmi sá à gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ, èmi sì ti sọ orúkọ rẹ di ńlá, gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá tí ó wà ní ayé.
и съм бил с тебе навсякъде, гдето си ходил и изтребил всичките ти неприятели пред тебе, и направих името ти велико, както името на великите, които са на земята.
10 Èmi ó sì yan ibìkan fún àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi ó sì gbìn wọ́n, wọn ó sì má gbé bí ibùjókòó tiwọn, wọn kì yóò sì sípò padà mọ́; àwọn ọmọ ènìyàn búburú kì yóò sì pọ́n wọn lójúmọ́, bí ìgbà àtijọ́.
И ще определя място за людете Си Израиля и ще ги насадя, та ще обитават на свое собствено място, и няма да се преместват вече; и тези които, вършат нечестие няма вече да ги притесняват, както по-напред,
11 Àti gẹ́gẹ́ bí àkókò ìgbà tí èmi ti fi àṣẹ fún àwọn onídàájọ́ lórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi fi ìsinmi fún ọ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ. “‘Olúwa sì wí fún ọ pé Olúwa yóò kọ ilé kan fún ọ.
и както от деня, когато поставих съдии над людете Си Израиля; и ще те успокоя от всичките ти неприятели. При това, Господ ти явява, че Господ ще ти съгради дом.
12 Nígbà tí ọjọ́ rẹ bá pé, tí ìwọ ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ, èmi yóò sì gbé irú-ọmọ rẹ lékè lẹ́yìn rẹ, èyí tí ó ti inú rẹ jáde wá, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀.
Когато се навършат дните ти и заспиш с бащите си, ще въздигна потомеца ти подир тебе, който ще излезе из чреслата ти, и ще утвърдя царството му.
13 Òun ó sì kọ́ ilé fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀ láéláé.
Той ще построи дом за името Ми; и Аз ще утвърдя престола на царството му до века.
14 Èmi ó máa ṣe baba fún un, òun yóò sì máa jẹ́ ọmọ mi. Bí òun bá dẹ́ṣẹ̀, èmi yóò sì fi ọ̀pá ènìyàn nà án, àti ìnà àwọn ọmọ ènìyàn.
Аз ще му бъда Отец, и той ще Ми бъде син: ако стори беззаконие, ще го накажа с тояга каквато е за мъже и с биения каквито са за човешкия род;
15 Ṣùgbọ́n àánú mi kì yóò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú un kúrò lọ́dọ̀ Saulu, tí èmi ti mú kúrò níwájú rẹ.
но Моята милост няма да го остави, както я отнех от Саула, когото отмахнах от пред тебе.
16 A ó sì fi ìdílé rẹ àti ìjọba rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ títí láé, a ó sì fi ìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ títí láé.’”
И домът ти и царството ти ще се утвърдят пред тебе до века.
17 Gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, àti gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìran yìí, bẹ́ẹ̀ ni Natani sì sọ fún Dafidi.
И Натан говори на Давида точно според тия думи и напълно според това видение.
18 Dafidi ọba sì wọlé lọ, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, “Olúwa Olódùmarè, ta ni èmi, àti kí sì ni ìdílé mi, tí ìwọ fi mú mi di ìsinsin yìí?
Тогава цар Давид влезе та седна пред Господа и рече: Кой съм аз, Господи Иеова, и какъв е моят дом, та си ме довел до това положение?
19 Nǹkan kékeré ni èyí sá à jásí lójú rẹ, Olúwa Olódùmarè; ìwọ sì ti sọ nípa ìdílé ìránṣẹ́ rẹ pẹ̀lú ní ti àkókò tí o jìnnà. Èyí ha ṣe ìwà ènìyàn bí, Olúwa Olódùmarè?
Но даже и това бе малко пред очите Ти, Господи Иеова; а Ти си говорил още за едно дълго бъдеще за дома на слугата Си, и даваш това като закон на човеците, Господи Иеова!
20 “Àti kín ní ó tún kù tí Dafidi ìbá tún máa wí fún ọ? Ìwọ, Olúwa Olódùmarè mọ̀ ìránṣẹ́ rẹ.
И какво повече може да Ти рече Давид? защото Ти, Господи Иеова, познаваш слугата Си.
21 Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni ìwọ ṣe ṣe gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí, kí ìránṣẹ́ rẹ lè mọ̀.
Заради Своето слово и според Своето сърце Ти си сторил всички тия велики дела, за да ги явиш на слугата Си.
22 “Ìwọ sì tóbi, Olúwa Olódùmarè! Kò sì sí ẹni tí ó dàbí rẹ, kò sì sí Ọlọ́run kan lẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí àwa fi etí wá gbọ́.
Затова Ти си велик, Господи Боже; защото няма подобен на Тебе, нито има бог освен Тебе, според всичко, що сме чули с ушите си.
23 Orílẹ̀-èdè kan wo ni ó sì ń bẹ ní ayé tí ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli, àwọn tí Ọlọ́run lọ rà padà láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ̀, àti láti sọ wọ́n ní orúkọ, àti láti ṣe nǹkan ńlá fún un yín, àti nǹkan ìyanu fún ilé rẹ̀, níwájú àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ ti rà padà fún ara rẹ láti Ejibiti wá, àní àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn òrìṣà wọn.
И кой друг народ на света е както Твоите люде, както Израил, при когото Бог дойде да го откупи за Свои люде, да ги направи именити и да извърши за тях велики дела, и страшни дела за земята Ти, пред Твоите люде, които Ти си откупил за Себе Си от Египет, от народите, и от боговете им?
24 Ìwọ sì fi ìdí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli kalẹ̀ fún ara rẹ láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ títí láé; ìwọ Olúwa sì wá di Ọlọ́run fún wọn.
Защото Ти си утвърдил людете Си Израиля за Себе Си, за да Ти бъдат люде до века; и Ти, Господи, им стана Бог.
25 “Ǹjẹ́, Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà tí ìwọ sọ ní ti ìránṣẹ́ rẹ, àti ní ti ìdílé rẹ̀, kí ó dúró títí láé, kí ó sí ṣe bí ìwọ ti wí.
И сега, Господи Боже, утвърди до века думата, която си говорил на слугата Си, и за дома му, и стори както си говорил.
26 Jẹ́ kí orúkọ rẹ ó ga títí láé, pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run lórí Israẹli!’ Sì jẹ́ kí a fi ìdílé Dafidi ìránṣẹ́ rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ.
И нека възвеличат името Ти до века, като казват: Господ на Силите е Бог над Израиля; и нека бъде утвърден пред Тебе домът на слугата Ти Давида,
27 “Nítorí pé ìwọ, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli ti sọ létí ìránṣẹ́ rẹ, pé, ‘Èmí ó kọ́ ilé kan fún ọ.’ Nítorí náà ni ìránṣẹ́ rẹ sì ṣe ní i lọ́kàn rẹ̀ láti gbàdúrà yìí sí ọ.
Защото Ти, Господи на Силите, Боже Израилев, откри на слугата Си, като каза: Ще ти съградя дом: затова слугата Ти намери сърцето си разположено да Ти се помоли с тая молитва.
28 Ǹjẹ́, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni Ọlọ́run náà, àwọn ọ̀rọ̀ rẹ sì jásí òtítọ́, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ nǹkan rere yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
И Сега, Господи Иеова, Ти си Бог, и думите Ти са истинни, и Ти си обещал тия блага на слугата Си;
29 Ǹjẹ́, jẹ́ kí ó wù ọ́ láti bùkún ìdílé ìránṣẹ́ rẹ, kí ó wà títí láé níwájú rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa Olódùmarè, ni ó ti sọ ọ́: sì jẹ́ kí ìbùkún wà ní ìdílé ìránṣẹ́ rẹ títí láé, nípasẹ̀ ìbùkún rẹ.”
сега, прочее, благоволи да благословиш дома на слугата Си, за да пребъдва пред Тебе до века; защото Ти, Господи Иеова, Си говорил тия неща, и под Твоето благоволение нека бъде благословен до века дома на слугата Ти.