< 2 Samuel 5 >

1 Gbogbo ẹ̀yà Israẹli sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa ń í ṣe.
Andin keyin Israilning barliⱪ ⱪǝbililiri Ⱨebronƣa Dawutning ⱪexiƣa kelip: Ⱪarisila, biz ɵzlirining ǝt-sɵngǝkliridurmiz!
2 Àti nígbà àtijọ́, nígbà tí Saulu fi jẹ ọba lórí wa, ìwọ ni ẹni tí ó máa ń kó Israẹli jáde, ìwọ sì ni ó máa ń mú wọn bọ̀ wá ilé: Olúwa sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò ṣe olùṣọ́ Israẹli àwọn ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún Israẹli.’”
Burun Saul bizning üstimizdǝ sǝltǝnǝt ⱪilƣandimu Israil hǝlⱪigǝ jǝnggǝ qiⱪip-kirixkǝ yolbaxqi bolƣan ɵzliri idila; Pǝrwǝrdigar siligǝ: Sǝn Mening hǝlⱪim Israilning padiqisi bolup, ularni baⱪisǝn, Israilning ǝmiri bolisǝn, degǝnidi — dedi.
3 Gbogbo àgbàgbà Israẹli sì tọ ọba wá ní Hebroni, Dafidi ọba sì bá wọn ṣe àdéhùn kan ní Hebroni, níwájú Olúwa: wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba Israẹli.
Xuning bilǝn Israilning ⱨǝmmǝ aⱪsaⱪalliri Ⱨebronƣa padixaⱨning ⱪexiƣa kǝldi; Dawut padixaⱨ Ⱨebronda, Pǝrwǝrdigarning aldida ular bilǝn ǝⱨdǝ tüzüxti. Andin ular Dawutni Israilƣa padixaⱨ boluxⱪa mǝsiⱨ ⱪildi.
4 Dafidi sì jẹ́ ẹni ọgbọ̀n ọdún nígbà tí ó jẹ ọba; ó sì jẹ ọba ní ogójì ọdún.
Dawut padixaⱨ bolƣanda ottuz yaxⱪa kirgǝn bolup, ⱪiriⱪ yil sǝltǝnǝt ⱪildi.
5 Ó jẹ ọba ní Hebroni ní ọdún méje àti oṣù mẹ́fà lórí Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lórí gbogbo Israẹli àti Juda.
U Ⱨebronda Yǝⱨudaning üstidǝ yǝttǝ yil altǝ ay sǝltǝnǝt ⱪilip, Yerusalemda pütkül Israil bilǝn Yǝⱨudaning üstidǝ ottuz üq yil sǝltǝnǝt ⱪildi.
6 Àti ọba àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ àwọn ará Jebusi, àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà; àwọn tí ó sì ti wí fún Dafidi pé, “Bí kò ṣe pé ìwọ bá mú àwọn afọ́jú àti àwọn arọ kúrò, ìwọ kì yóò wọ ìhín wá.” Wọ́n sì wí pé, “Dafidi kì yóò lè wá síyìn-ín.”
Padixaⱨ ɵz adǝmliri bilǝn Yerusalemƣa qiⱪip, xu zeminda turƣan Yǝbusiylar bilǝn jǝng ⱪilƣili bardi. Ular Dawutⱪa: Sǝn bu yǝrgǝ kirǝlmǝysǝn, bǝlki ⱨǝtta korlar bilǝn aⱪsaⱪlar seni qekindüridu! — dedi. Qünki ular: «Dawut bu yǝrgǝ ⱪǝt’iy kirǝlmǝydu», dǝp oylaytti.
7 Ṣùgbọ́n Dafidi fi agbára gba ìlú odi Sioni: èyí náà ni í ṣe ìlú Dafidi.
Lekin Dawut Zion ⱪorƣinini aldi (bu yǝr Dawutning xǝⱨiri dǝp atilidu).
8 Dafidi sọ lọ́jọ́ náà pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọlu àwọn ará Jebusi, jẹ́ kí ó gba ojú àgbàrá, kí o sí kọlu àwọn arọ, àti àwọn afọ́jú tí ọkàn Dafidi kórìíra.” Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí pé, “Afọ́jú àti arọ wà níbẹ̀, kì yóò lè wọlé.”
Dawut u küni: Kimki Yǝbusiylarni uray desǝ sünggüq bilǝn qiⱪixi kerǝk, andin u Dawut ⱪin-ⱪinidin ɵq kɵridiƣan bu kor, aⱪsaⱪlar bilǝn [ⱨesablixalaydu], dedi. Xuning bilǝn «Ⱪorlar ya aⱪsaⱪlar ɵygǝ kirmisun» dǝydiƣan maⱪal pǝyda boldi.
9 Dafidi sì jókòó ní ilé àwọn ọmọ-ogun tí ó ní odi, a sì ń pè é ní ìlú Dafidi. Dafidi mọ ògiri yí i ká láti Millo wá, ó sì kọ́ ilé nínú rẹ̀.
Xundaⱪ ⱪilip Dawut ⱪorƣanda turdi wǝ u yǝrni «Dawutning xǝⱨiri» dǝp atidi. Dawut xǝⱨǝrning ǝtrapiƣa Millodin tartip iq tǝrǝpkiqǝ imarǝt saldi.
10 Dafidi sì ń pọ̀ sí i, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Dawut barƣanseri ⱪudrǝt tapti; samawiy ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Huda Pǝrwǝrdigar uning bilǝn billǝ idi.
11 Hiramu ọba Tire sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, àti igi kedari, àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àti àwọn tí ń gbẹ́ òkúta, wọ́n kọ́ ilé kan fún Dafidi.
Turning padixaⱨi Ⱨiram Dawutning ⱪexiƣa ǝlqilǝrni ǝwǝtti wǝ ular bilǝn ⱪoxup, kedir yaƣaqliri, yaƣaqqilar wǝ taxqilarni ǝwǝtti; ular Dawut üqün bir orda yasap bǝrdi.
12 Dafidi sì kíyèsi i pé, Olúwa ti fi ìdí òun múlẹ̀ láti jẹ ọba lórí Israẹli, àti pé, ó gbé ìjọba rẹ̀ ga nítorí Israẹli àwọn ènìyàn rẹ̀.
Dawut Pǝrwǝrdigarning ɵzini Israilƣa padixaⱨ tiklǝp, ɵz hǝlⱪi Israil üqün ɵzining padixaⱨliⱪini güllǝndürgǝnlikini bilip yǝtti.
13 Dafidi sì tún mú àwọn àlè àti aya sí i láti Jerusalẹmu wá, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti Hebroni bọ̀, wọ́n sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin fún Dafidi.
Dawut Ⱨebrondin kǝlgǝndin keyin Yerusalemdin yǝnǝ ayallarni wǝ kenizǝklǝrni aldi; xuning bilǝn Dawutⱪa yǝnǝ kɵp oƣul-ⱪizlar tuƣuldi.
14 Èyí sì ni orúkọ àwọn tí a bí fún un ní Jerusalẹmu; Ṣammua, Ṣobabu, Natani àti Solomoni.
Yerusalemda uningdin tuƣulƣanlarning isimliri mana mundaⱪ idi: Xammua, Xobab, Natan, Sulayman,
15 Àti Ibhari, àti Eliṣua, àti Nefegi, àti Jafia.
Ibⱨar, Elixua, Nǝfǝg, Yafiya,
16 Àti Eliṣama, àti Eliada, àti Elifeleti.
Elixama, Eliada wǝ Elifǝlǝt.
17 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Filistini gbọ́ pé, wọ́n ti fi Dafidi jẹ ọba lórí Israẹli, gbogbo àwọn Filistini sì gòkè wá láti wá Dafidi; Dafidi sì gbọ́, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìlú olódi.
Filistiylǝr Dawutning Israilƣa padixaⱨ boluxⱪa mǝsiⱨlǝnginini angliƣanda, ular ⱨǝmmisi Dawutni tutⱪili qiⱪti, Dawut buni anglapla, ⱪorƣanƣa qüxti.
18 Àwọn Filistini sì wá, wọ́n sì tẹ ara wọn ní àfonífojì Refaimu.
Filistiylǝr kelip «Rǝfayim jilƣisi»da yeyilip turdi;
19 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Kí èmi ó gòkè tọ àwọn Filistini bí? Ìwọ ó fi wọ́n lé mi lọ́wọ́ bí?” Olúwa sì wí fún Dafidi pé, “Gòkè lọ, nítorí pé dájúdájú èmi ó fi àwọn Filistini lé ọ lọ́wọ́.”
Dawut Pǝrwǝrdigardin yol sorap: Filistiylǝrgǝ ⱪarxi atlinaymu? Ularni ⱪolumƣa tapxurarsǝnmu? — dedi. Pǝrwǝrdigar Dawutⱪa: Qiⱪⱪin! Qünki, Mǝn Filistiylǝrni jǝzmǝn ⱪolungƣa tapxurimǝn — dedi.
20 Dafidi sì dé Baali-Perasimu, Dafidi sì pa wọ́n níbẹ̀, ó sì wí pé, “Olúwa ti ya lu àwọn ọ̀tá mi níwájú mi, gẹ́gẹ́ bí omi ti ń ya.” Nítorí náà ni òun ṣe pe orúkọ ibẹ̀ náà ni Baali-Perasimu.
U waⱪitta Dawut Baal-Pǝrazimƣa bardi. U yǝrdǝ Dawut ularni tarmar ⱪildi. U: — «Pǝrwǝrdigar mening aldimda düxmǝnlirim üstigǝ huddi kǝlkün yarni elip kǝtkǝndǝk bɵsüp kirdi» — dedi. Xuning bilǝn u yǝrni «Baal-Pǝrazim» dǝp atidi.
21 Wọ́n sì fi òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì kó wọn.
Filistiylǝr u yǝrdǝ ɵz mǝbudlirini taxlap kǝtti; Dawut bilǝn adǝmliri ularni elip kǝtti.
22 Àwọn Filistini sì tún gòkè wá, wọ́n sì tan ara wọn kalẹ̀ ní àfonífojì Refaimu.
Əmdi Filistiylǝr yǝnǝ qiⱪip «Rǝfayim jilƣisi»da yeyilip turdi.
23 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òun sì wí pé, “Má ṣe gòkè lọ; ṣùgbọ́n bù wọ́n lẹ́yìn, kí o sì kọlù wọ́n níwájú àwọn igi Baka.
Dawut Pǝrwǝrdigardin yol soridi. Pǝrwǝrdigar: Sǝn u yǝrgǝ qiⱪmay, bǝlki ularning kǝynidin aylinip ɵtüp üjmǝ dǝrǝhlirining udulidin ⱨujum ⱪilƣin — dedi,
24 Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá gbọ́ ìró ẹsẹ̀ lórí àwọn igi Baka náà, nígbà náà ni ìwọ yóò sì yára, nítorí pé nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ níwájú rẹ láti kọlù ogun àwọn Filistini.”
Xundaⱪ boliduki, sǝn üjmǝ dǝrǝhlikining üstidin ayaƣ tiwixini anglixing bilǝnla dǝrⱨal atlan; qünki xu tapta Pǝrwǝrdigar Filistiylǝrning ⱪoxuniƣa ⱨujumƣa qiⱪⱪan bolidu, — dedi.
25 Dafidi sì ṣe bẹ́ẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un; ó sì kọlu àwọn Filistini láti Geba títí dé Geseri.
Dawut Pǝrwǝrdigarning uningƣa ǝmr ⱪilƣinidǝk ⱪilip, Filistiylǝrni Gibeondin Gǝzǝrgiqǝ ⱪoƣlap ⱪirdi.

< 2 Samuel 5 >