< 2 Samuel 5 >

1 Gbogbo ẹ̀yà Israẹli sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa ń í ṣe.
Entonces todas las tribus de Israel vinieron a David en Hebrón y dijeron: En verdad, somos tu hueso y tu carne.
2 Àti nígbà àtijọ́, nígbà tí Saulu fi jẹ ọba lórí wa, ìwọ ni ẹni tí ó máa ń kó Israẹli jáde, ìwọ sì ni ó máa ń mú wọn bọ̀ wá ilé: Olúwa sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò ṣe olùṣọ́ Israẹli àwọn ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún Israẹli.’”
En el pasado, cuando Saúl era rey sobre nosotros, eras tú a la cabeza de Israel cuando salían o entraban. Y el Señor te dijo: Tú debes ser el guardián de mi pueblo, Israel y su gobernante.
3 Gbogbo àgbàgbà Israẹli sì tọ ọba wá ní Hebroni, Dafidi ọba sì bá wọn ṣe àdéhùn kan ní Hebroni, níwájú Olúwa: wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba Israẹli.
Entonces todos los responsables de Israel vinieron al rey en Hebrón; y el rey David llegó a un acuerdo con ellos en Hebrón delante del Señor; y lo ungieron a David y lo hicieron rey sobre Israel.
4 Dafidi sì jẹ́ ẹni ọgbọ̀n ọdún nígbà tí ó jẹ ọba; ó sì jẹ ọba ní ogójì ọdún.
David tenía treinta años cuando comenzó a reinar, y fue rey durante cuarenta años.
5 Ó jẹ ọba ní Hebroni ní ọdún méje àti oṣù mẹ́fà lórí Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lórí gbogbo Israẹli àti Juda.
Fue rey sobre Judá en Hebrón durante siete años y seis meses, y en Jerusalén, sobre todo Israel y Judá, durante treinta y tres años.
6 Àti ọba àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ àwọn ará Jebusi, àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà; àwọn tí ó sì ti wí fún Dafidi pé, “Bí kò ṣe pé ìwọ bá mú àwọn afọ́jú àti àwọn arọ kúrò, ìwọ kì yóò wọ ìhín wá.” Wọ́n sì wí pé, “Dafidi kì yóò lè wá síyìn-ín.”
Y el rey y sus hombres fueron a Jerusalén contra los jebuseos, la gente de la tierra; y dijeron a David: No entrarás aquí; sino que los ciegos y los cojos te mantendrán fuera; porque dijeron: David no podrá entrar aquí.
7 Ṣùgbọ́n Dafidi fi agbára gba ìlú odi Sioni: èyí náà ni í ṣe ìlú Dafidi.
Pero David tomó el lugar fuerte de Sión, que es el pueblo de David.
8 Dafidi sọ lọ́jọ́ náà pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọlu àwọn ará Jebusi, jẹ́ kí ó gba ojú àgbàrá, kí o sí kọlu àwọn arọ, àti àwọn afọ́jú tí ọkàn Dafidi kórìíra.” Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí pé, “Afọ́jú àti arọ wà níbẹ̀, kì yóò lè wọlé.”
Y aquel día, David dijo: Quien haga un ataque a los jebuseos, déjalo subir por la tubería y mata a todos los ciegos y cojos que son odiados por David. Y es por eso que dicen: Los ciegos y los cojos pies débiles pueden no entrar al templo del Señor.
9 Dafidi sì jókòó ní ilé àwọn ọmọ-ogun tí ó ní odi, a sì ń pè é ní ìlú Dafidi. Dafidi mọ ògiri yí i ká láti Millo wá, ó sì kọ́ ilé nínú rẹ̀.
Entonces David tomó la torre fuerte para su lugar de vida, y la llamó pueblo de David. Y David construyó murallas alrededor, desde él milo hacia adentro.
10 Dafidi sì ń pọ̀ sí i, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Y David se hizo cada vez más grande; porque el Señor, el Dios de los ejércitos, estaba con él.
11 Hiramu ọba Tire sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, àti igi kedari, àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àti àwọn tí ń gbẹ́ òkúta, wọ́n kọ́ ilé kan fún Dafidi.
E Hiram, rey de Tiro, envió hombres a David, con cedros, carpinteros y canteros; y construyeron el palacio de David.
12 Dafidi sì kíyèsi i pé, Olúwa ti fi ìdí òun múlẹ̀ láti jẹ ọba lórí Israẹli, àti pé, ó gbé ìjọba rẹ̀ ga nítorí Israẹli àwọn ènìyàn rẹ̀.
Y David vio que él Señor había salvado su posición de rey sobre Israel, y que había engrandecido su reino en atención a su pueblo Israel.
13 Dafidi sì tún mú àwọn àlè àti aya sí i láti Jerusalẹmu wá, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti Hebroni bọ̀, wọ́n sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin fún Dafidi.
Después de que él viniera de Hebrón, David tomó más mujeres y esposas en Jerusalén, y tuvo más hijos e hijas.
14 Èyí sì ni orúkọ àwọn tí a bí fún un ní Jerusalẹmu; Ṣammua, Ṣobabu, Natani àti Solomoni.
Estos son los nombres de aquellos cuyo nacimiento tuvo lugar en Jerusalén: Samúa y Sobab y Natán y Salomón,
15 Àti Ibhari, àti Eliṣua, àti Nefegi, àti Jafia.
E Ibhar, Elisua, Nefeg, y Jafia,
16 Àti Eliṣama, àti Eliada, àti Elifeleti.
Y Elisama, Eliada y Elifelet.
17 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Filistini gbọ́ pé, wọ́n ti fi Dafidi jẹ ọba lórí Israẹli, gbogbo àwọn Filistini sì gòkè wá láti wá Dafidi; Dafidi sì gbọ́, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìlú olódi.
Y cuando los filisteos tuvieron noticias de que David había sido hecho rey sobre Israel, todos subieron en busca de David; y David, oyéndolo, descendió a la fortaleza.
18 Àwọn Filistini sì wá, wọ́n sì tẹ ara wọn ní àfonífojì Refaimu.
Y cuando llegaron los filisteos, fueron en todas direcciones en el valle de Refaim.
19 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Kí èmi ó gòkè tọ àwọn Filistini bí? Ìwọ ó fi wọ́n lé mi lọ́wọ́ bí?” Olúwa sì wí fún Dafidi pé, “Gòkè lọ, nítorí pé dájúdájú èmi ó fi àwọn Filistini lé ọ lọ́wọ́.”
Y David, deseando instrucciones del Señor, dijo: ¿Debo subir contra los filisteos? ¿Los entregarás en mis manos? Y el Señor dijo: Sube, porque ciertamente entregaré a los filisteos en tus manos.
20 Dafidi sì dé Baali-Perasimu, Dafidi sì pa wọ́n níbẹ̀, ó sì wí pé, “Olúwa ti ya lu àwọn ọ̀tá mi níwájú mi, gẹ́gẹ́ bí omi ti ń ya.” Nítorí náà ni òun ṣe pe orúkọ ibẹ̀ náà ni Baali-Perasimu.
Entonces David fue a Baal-perazim y los venció allí; y él dijo: El Señor ha dejado que las fuerzas que luchan contra mí se rompan ante mí como se rompe un muro por las aguas que corren. Así que ese lugar se llamaba Baal-perazim.
21 Wọ́n sì fi òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì kó wọn.
Y cuando los filisteos huyeron, no se llevaron sus imágenes con ellos, y David y sus hombres se los llevaron.
22 Àwọn Filistini sì tún gòkè wá, wọ́n sì tan ara wọn kalẹ̀ ní àfonífojì Refaimu.
Y volvieron los filisteos otra vez, y se fueron en todas direcciones en el valle de Refaim.
23 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òun sì wí pé, “Má ṣe gòkè lọ; ṣùgbọ́n bù wọ́n lẹ́yìn, kí o sì kọlù wọ́n níwájú àwọn igi Baka.
Y cuando David fue en dirección al Señor, él le dijo: No debes subir contra ellos delante de ellos; pero haz un círculo alrededor de ellos desde la parte posterior y ven sobre ellos frente a los árboles de especias.
24 Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá gbọ́ ìró ẹsẹ̀ lórí àwọn igi Baka náà, nígbà náà ni ìwọ yóò sì yára, nítorí pé nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ níwájú rẹ láti kọlù ogun àwọn Filistini.”
Luego, al oír un ruido como de pasos en las copas de los árboles, avanza rápidamente, porque el Señor ha salido delante de ti para vencer al ejército de los filisteos.
25 Dafidi sì ṣe bẹ́ẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un; ó sì kọlu àwọn Filistini láti Geba títí dé Geseri.
E hizo David como él Señor le había dicho; y venció a los filisteos, atacándolos desde Gabaón hasta cerca de Gezer.

< 2 Samuel 5 >