< 2 Samuel 5 >

1 Gbogbo ẹ̀yà Israẹli sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa ń í ṣe.
Nivotrak’ amy Davide e Kebrone amy zao ze fifokoa’ Israele iaby nanao ty hoe: Oniño te taola’o naho nofo’o zahay.
2 Àti nígbà àtijọ́, nígbà tí Saulu fi jẹ ọba lórí wa, ìwọ ni ẹni tí ó máa ń kó Israẹli jáde, ìwọ sì ni ó máa ń mú wọn bọ̀ wá ilé: Olúwa sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò ṣe olùṣọ́ Israẹli àwọn ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún Israẹli.’”
Ie omale naho fakomale-bey le nimpanjaka’ay t’i Saole naho ihe ty niaolo vaho nampipoly Israele; le hoe t’Iehovà ama’o, Ho fahana’o ondatiko Israeleo naho ihe ty hifelek’ Israele.
3 Gbogbo àgbàgbà Israẹli sì tọ ọba wá ní Hebroni, Dafidi ọba sì bá wọn ṣe àdéhùn kan ní Hebroni, níwájú Olúwa: wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba Israẹli.
Aa le niheo mb’ amy mpanjakay e Kebrone mb’eo o roandria’ Israeleo; le nifañina am’ iereo t’i Davide mpanjaka e Kebrone ao añatrefa’ Iehovà; vaho noriza’ iareo ho mpanjaka’ Israele t’i Davide.
4 Dafidi sì jẹ́ ẹni ọgbọ̀n ọdún nígbà tí ó jẹ ọba; ó sì jẹ ọba ní ogójì ọdún.
Telopolo taoñe t’i Davide te niorotse nifehe; le nifeleke efapolo taoñe,
5 Ó jẹ ọba ní Hebroni ní ọdún méje àti oṣù mẹ́fà lórí Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lórí gbogbo Israẹli àti Juda.
nifehe Iehoda e Kebrone ao fito taoñe tsi-enem-bolañe re naho nifeleke Israele naho Iehoda e Ierosa­laime ao telopolo taoñe telo’ amby.
6 Àti ọba àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ àwọn ará Jebusi, àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà; àwọn tí ó sì ti wí fún Dafidi pé, “Bí kò ṣe pé ìwọ bá mú àwọn afọ́jú àti àwọn arọ kúrò, ìwọ kì yóò wọ ìhín wá.” Wọ́n sì wí pé, “Dafidi kì yóò lè wá síyìn-ín.”
Nomb’e Ierosalaime mb’eo i mpanjakay rekets’ ondati’eo, haname o nte Iebosìo, o mpimo­neñe amy taneio, ze nanao amy Davide ty hoe: Ndra ty goa naho i kepekey ty hampiamboho azo tsy himoak’ atoy; ie natao’ iereo te tsy hahafizilik’ ao t’i Davide.
7 Ṣùgbọ́n Dafidi fi agbára gba ìlú odi Sioni: èyí náà ni í ṣe ìlú Dafidi.
Fe rinambe’ i Davide ty rova’ i Tsione; i atao rova’ i Davidey.
8 Dafidi sọ lọ́jọ́ náà pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọlu àwọn ará Jebusi, jẹ́ kí ó gba ojú àgbàrá, kí o sí kọlu àwọn arọ, àti àwọn afọ́jú tí ọkàn Dafidi kórìíra.” Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí pé, “Afọ́jú àti arọ wà níbẹ̀, kì yóò lè wọlé.”
Fa hoe t’i Davide amy andro zay: Ia ty mahafandafa o nte-Iebosy am-pionjonañe amy firoroñan-dranoy, ie mongore’e heike ze o kepeke naho goa heje’ ty tro’ i Davide zao—ie atao’ iereo ty hoe: Ndra ty goa naho i kepekey tsy hahafimoaha’e añ’ anjomba atoy.
9 Dafidi sì jókòó ní ilé àwọn ọmọ-ogun tí ó ní odi, a sì ń pè é ní ìlú Dafidi. Dafidi mọ ògiri yí i ká láti Millo wá, ó sì kọ́ ilé nínú rẹ̀.
Nimoneñe amy rovay t’i Davide vaho natao’e ty hoe Rova’ i Davide. Namboatse mb’eo mb’eo boake Milò mb’añate’e ao t’i Davide.
10 Dafidi sì ń pọ̀ sí i, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Nitoabotse erike t’i Davide amy te nindre ama’e t’Iehovà Andrianañahare’ i Màroy.
11 Hiramu ọba Tire sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, àti igi kedari, àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àti àwọn tí ń gbẹ́ òkúta, wọ́n kọ́ ilé kan fún Dafidi.
Aa le nañitrifa’ i Kirame nte-Tsore ìrake t’i Davide naho mendoraveñe naho mpandranjy naho mpamboatse am-bato, le nandranjia’ iereo anjom­ba t’i Davide.
12 Dafidi sì kíyèsi i pé, Olúwa ti fi ìdí òun múlẹ̀ láti jẹ ọba lórí Israẹli, àti pé, ó gbé ìjọba rẹ̀ ga nítorí Israẹli àwọn ènìyàn rẹ̀.
Nioni’ i Davide t’ie noriza’ Iehovà ho mpanjaka’ Israele; naho nonjone’e am’ ondati’e Israeleo ty fifehea’e.
13 Dafidi sì tún mú àwọn àlè àti aya sí i láti Jerusalẹmu wá, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti Hebroni bọ̀, wọ́n sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin fún Dafidi.
Mbe nañenga sakeza naho valy boake Ierosalaime t’i Davide ie fa nivotrake boake Kebrone añe; teo ka te nahasamake ana-dahy naho anak’ ampela t’i Davide.
14 Èyí sì ni orúkọ àwọn tí a bí fún un ní Jerusalẹmu; Ṣammua, Ṣobabu, Natani àti Solomoni.
Zao ty añara’ o nasama’e e Ierosalaimeo: i Samoa naho Sobabe naho Natane naho i Selomò,
15 Àti Ibhari, àti Eliṣua, àti Nefegi, àti Jafia.
naho Iebkare naho Elisoa naho Nèfege naho Iafià,
16 Àti Eliṣama, àti Eliada, àti Elifeleti.
naho i Elisamà naho Eliadà vaho i Elifelete.
17 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Filistini gbọ́ pé, wọ́n ti fi Dafidi jẹ ọba lórí Israẹli, gbogbo àwọn Filistini sì gòkè wá láti wá Dafidi; Dafidi sì gbọ́, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìlú olódi.
Aa ie jinanji’ o nte-Pilistio te norizañe ho mpanjaka’ Israele iaby t’i Davide, le fonga nionjomb’eo o nte-Pilistio hi­tsoeke i Davide. Ie jinanji’ i Davide, le nigodañe am-pipalirañe fatratse ao.
18 Àwọn Filistini sì wá, wọ́n sì tẹ ara wọn ní àfonífojì Refaimu.
Nimb’ am-bavatane’ i Refaime ey ka o nte’ Pilistio vaho nivelatse.
19 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Kí èmi ó gòkè tọ àwọn Filistini bí? Ìwọ ó fi wọ́n lé mi lọ́wọ́ bí?” Olúwa sì wí fún Dafidi pé, “Gòkè lọ, nítorí pé dájúdájú èmi ó fi àwọn Filistini lé ọ lọ́wọ́.”
Aa le nañontane Iehovà t’i Davide ami’ty hoe: Hionjoñe mb’amo nte-Pilistio hao iraho? Hatolo’o an-tanako hao? Le hoe t’Iehovà amy Davide, Mionjona, fa tsy mete tsy hatoloko am-pità’o o nte-Pilistio.
20 Dafidi sì dé Baali-Perasimu, Dafidi sì pa wọ́n níbẹ̀, ó sì wí pé, “Olúwa ti ya lu àwọn ọ̀tá mi níwájú mi, gẹ́gẹ́ bí omi ti ń ya.” Nítorí náà ni òun ṣe pe orúkọ ibẹ̀ náà ni Baali-Perasimu.
Nimb’e Baale-peratsime mb’eo t’i Davide naho zinama’e iereo vaho nanao ty hoe: Niboroboñak’ amo rafelahikoo t’Iehovà manahake ty fisorotombahan-drano. Aa le natao’e ty hoe Baal-peratsime i toetsey.
21 Wọ́n sì fi òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì kó wọn.
Napo’ iareo eo o sampo­sampo’ iareoo le sinodo’ i Davide naho ondati’eo.
22 Àwọn Filistini sì tún gòkè wá, wọ́n sì tan ara wọn kalẹ̀ ní àfonífojì Refaimu.
Niheo mb’eo in­draike o nte-Pilistio vaho nihanak’ am-bavatane Refaime ey.
23 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òun sì wí pé, “Má ṣe gòkè lọ; ṣùgbọ́n bù wọ́n lẹ́yìn, kí o sì kọlù wọ́n níwájú àwọn igi Baka.
Aa ie nañontane Iehovà t’i Davide, le hoe re: Ko mionjomb’eo fa miaria mb’am-boho’ iareo tandrife o sohihio,
24 Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá gbọ́ ìró ẹsẹ̀ lórí àwọn igi Baka náà, nígbà náà ni ìwọ yóò sì yára, nítorí pé nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ níwájú rẹ láti kọlù ogun àwọn Filistini.”
aa ie mahajanjiñe ty feom-pangidigidiñañe andigiligi’ o sohihio le mionjona amy te hiaoloa’ Iehovà nahareo handafa i valobohòn-te-Pilistiy.
25 Dafidi sì ṣe bẹ́ẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un; ó sì kọlu àwọn Filistini láti Geba títí dé Geseri.
Aa le nanoe’ i Davide i nandilia’ Iehovày vaho zinevo’e boake Gebà pake Gezere o nte-Pilistìo.

< 2 Samuel 5 >