< 2 Samuel 4 >

1 Nígbà tí ọmọ Saulu sì gbọ́ pé, Abneri kú ní Hebroni, ọwọ́ rẹ̀ sì rọ, gbogbo Israẹli sì rẹ̀wẹ̀sì.
Quand le fils de Saül eut appris qu’Abner était mort à Hébron, les bras lui tombèrent; tout Israël aussi fut consterné.
2 Ọmọ Saulu sì ní ọkùnrin méjì tí í ṣe olórí ẹgbẹ́ ogun: a ń pe orúkọ ọ̀kan ní Baanah, àti orúkọ èkejì ní Rekabu, àwọn ọmọ Rimoni ará Beeroti ti àwọn ọmọ Benjamini (nítorí pé a sì ka Beeroti pẹ̀lú Benjamini).
Parmi les chefs de bande du fils de Saül se trouvaient deux hommes ayant nom l’un Baana, l’autre Rêkhab, deux Benjamites, fils de Rimmon le Beérotite; car Beérot aussi était attribué à Benjamin.
3 Àwọn ará Beeroti sì ti sálọ sí Gittaimu, wọ́n sì ṣe àtìpó níbẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ òní yìí.
Les Beérotites s’étaient réfugiés à Ghittayim, où ils ont résidé jusqu’à ce jour.
4 (Jonatani ọmọ Saulu sì ti bí ọmọkùnrin kan tí ẹsẹ̀ rẹ̀ rọ, òun sì jẹ́ ọdún márùn-ún, nígbà tí ìròyìn dé ní ti Saulu àti Jonatani láti Jesreeli wá, olùtọ́ rẹ̀ sì gbé e, o sì sálọ, ó sì ṣe, bí ó sì ti ń yára láti sálọ, òun sì ṣubú, ó sì ya arọ. Orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Mefiboṣeti.)
(Jonathan, fils de Saül, avait laissé un fils boiteux; ce dernier avait cinq ans lorsqu’arriva, de Jezreël, la nouvelle relative à Saül et à Jonathan; sa nourrice l’emporta en fuyant, le laissa tomber dans sa précipitation, et il devint boiteux; il se nommait Mephiboseth.)
5 Àwọn ọmọ Rimoni, ará Beeroti, Rekabu àti Baanah sì lọ wọ́n sì wá síh ilé Iṣboṣeti ní ọ̀sán gangan, òun sì sinmi lórí ibùsùn kan ní ọjọ́-kanrí.
Or, les fils de Rimmon le Beérotite, Rêkhab et Baana, s’acheminèrent vers la demeure d’Isboseth, où ils arrivèrent au plus chaud de la journée; il était couché, goûtant le repos de midi.
6 Sì wò ó, bí olùṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé náà ti ń gbọn àwọn pàǹtí, ó tòògbé ó sì sùn lọ, wọ́n sì wá sí àárín ilé náà, wọ́n sì ṣe bí ẹni pé wọ́n ń fẹ́ mú alikama; wọ́n sì gún un lábẹ́ inú. Rekabu àti Baanah arákùnrin rẹ̀ sì sálọ.
Rêkhab et son frère Baana pénétrèrent jusque dans l’intérieur de la maison en acheteurs de froment, le frappèrent dans l’aine et se sauvèrent.
7 Nígbà tí wọ́n wọ ilé náà lọ, òun sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀ nínú iyàrá rẹ̀, wọ́n sì pa á, wọ́n sì bẹ́ ẹ lórí, wọ́n gbé orí sálọ, wọ́n sì fi gbogbo òru rìn ni pẹ̀tẹ́lẹ̀ náà.
Ils y étaient entrés comme il reposait sur son lit, dans sa chambre à coucher, l’avaient frappé à mort et lui avaient coupé la tête. Munis de cette tête, ils s’en allèrent par la plaine et marchèrent toute la nuit.
8 Wọ́n sì gbé orí Iṣboṣeti tọ Dafidi wá ní Hebroni, wọ́n sì wí fún ọba pé, “Wò ó, orí Iṣboṣeti ọmọ Saulu ọ̀tá rẹ, tí ó ti ń wá ẹ̀mí rẹ kiri, Olúwa ti gbẹ̀san fún ọba olúwa mi lónìí lára Saulu àti lára irú-ọmọ rẹ̀.”
Ils apportèrent à David, à Hébron, la tête d’lsboseth, et dirent au roi: "Voici la tête d’Isboseth, fils de Saül, ton ennemi, qui en voulait à ta vie. Dieu a vengé en ce jour mon seigneur le roi de Saül et de sa postérité."
9 Dafidi sì dá Rekabu àti Baanah arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Rimoni ará Beeroti lóhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ, ẹni tí ó gba ẹ̀mí mi lọ́wọ́ gbogbo ìpọ́njú.
David répondit à Rêkhab et à Baana, son frère, fils de Rimmon le Beérotite, en ces termes: "Par le Dieu vivant, qui a sauvé ma personne de tous les dangers!
10 Nígbà tí ẹnìkan rò fún mi pé, ‘Wò ó, Saulu ti kú,’ lójú ara rẹ̀ òun sì jásí ẹni tí ó mú ìyìnrere wá, èmi sì mú un, mo sì pa á ní Siklagi, ẹni tí ó ṣe bí òun ó rí nǹkan gbà nítorí ìròyìn rere rẹ̀.
celui qui m’annonça que Saül était mort, se croyant porteur d’une bonne nouvelle, je le fis saisir et tuer à Ciklag, le payant ainsi de sa bonne nouvelle;
11 Mélòó mélòó ni, nígbà tí àwọn ìkà ènìyàn pa olódodo ènìyàn kan ni ilé rẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀—ǹjẹ́ èmi ha sì lè ṣe aláìbéèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ yín bí? Kí èmi sì mú yín kúrò láààyè.”
combien plus, quand des méchants ont fait périr un homme de bien dans sa maison, sur sa couche! Et maintenant, certes, je vous demanderai compte de son sang et vous ferai disparaître du pays."
12 Dafidi sì fi àṣẹ fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ̀, wọ́n sì pa wọ́n, wọ́n sì gé ọwọ́ àti ẹsẹ̀ wọn, a sì fi wọ́n há lórí igi ní Hebroni. Ṣùgbọ́n wọ́n mú orí Iṣboṣeti, wọ́n sì sin ín ní ibojì Abneri ní Hebroni.
Sur l’ordre de David, les serviteurs les mirent à mort, leur coupèrent les mains et les pieds et les pendirent près de l’étang de Hébron; quant à la tête d’Isboseth, ils la prirent pour la déposer dans le sépulcre d’Abner, à Hébron.

< 2 Samuel 4 >