< 2 Samuel 3 >

1 Ogun náà sì pẹ́ títí láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi: agbára Dafidi sì ń pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n ìdílé Saulu ń rẹ̀yìn sí i.
Ⱨalbuki, Saulning jǝmǝti bilǝn Dawutning jǝmǝti ottursidiki jǝng uzun waⱪitⱪiqǝ dawamlaxti; Dawutning jǝmǝti barƣanseri küqǝydi, lekin Saulning jǝmǝti barƣanseri ajizlaxmaⱪta idi.
2 Dafidi sì bí ọmọkùnrin ní Hebroni: Amnoni ni àkọ́bí rẹ̀ tí Ahinoamu ará Jesreeli bí fún un.
Ⱨebronda Dawut bir ⱪanqǝ oƣulluⱪ boldi, uning tunjisi Amnon bolup, Yizrǝǝllik Aⱨinoamdin tuƣuldi;
3 Èkejì rẹ̀ sì ni Kileabu, tí Abigaili aya Nabali ará Karmeli bí fún un; ẹ̀kẹta sì ni Absalomu ọmọ tí Maaka ọmọbìnrin Talmai ọba Geṣuri bí fún un.
ikkinqisi Kileab bolup Karmǝllik Nabalning ayali bolƣan Abigaildin tuƣuldi. Üqinqisi Abxalom idi. U Gǝxorning padixaⱨi Talmayning ⱪizi Maakaⱨdin tuƣulƣanidi,
4 Ẹ̀kẹrin sì ni Adonijah ọmọ Haggiti; àti ẹ̀karùnún ni Ṣefatia ọmọ Abitali;
tɵtinqisi Adoniya bolup Ⱨaggittin tuƣulƣan idi. Bǝxinqisi Xǝfatiya bolup Abitaldin tuƣulƣan idi.
5 Ẹ̀kẹfà sì ni Itreamu, tí Egla aya Dafidi bí fún un. Wọ̀nyí ni a bí fún Dafidi ni Hebroni.
Altinqisi Yitriam bolup Dawutning ayali Əglaⱨdin tuƣuldi. Dawutning bu altǝ oƣlining ⱨǝmmisi Ⱨebronda tuƣuldi.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí ogun wà láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi, Abneri sì dì alágbára ní ìdílé Saulu.
Saulning jǝmǝti bilǝn Dawutning jǝmǝti otturisidiki jǝng dawamida, Abnǝr Saulning jǝmǝtidǝ ɵz ⱨoⱪuⱪini küqǝytti.
7 Saulu ti ní àlè kan, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Rispa, ọmọbìnrin Aiah: Iṣboṣeti sì bi Abneri léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wọlé tọ àlè baba mi lọ.”
Əmdi Saulning bir kiniziki bar idi; u Ayaⱨning ⱪizi bolup, ismi Rizpaⱨ idi. Bir küni Ixboxǝt Abnǝrgǝ: Nemixⱪa atamning keniziki bilǝn billǝ boldung? — dedi.
8 Abneri sì bínú gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ti Iṣboṣeti sọ fún un, ó sì wí pé, “Èmi jẹ́ bí orí ajá ti Juda bí? Di òní yìí ni mo ṣàánú fún ìdílé Saulu baba rẹ, àti fún àwọn arákùnrin rẹ̀, àti fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, tí èmi kò sì fi ọ́ lé Dafidi lọ́wọ́, ìwọ sì kà ẹ̀ṣẹ̀ sí mí lọ́rùn nítorí obìnrin yìí lónìí?
Abnǝr Ixboxǝtning bu sɵzlirigǝ intayin aqqiⱪlinip mundaⱪ dedi: — «Mǝn bügünki kündimu atang Saulning jǝmǝtigǝ, uning uruⱪ-tuƣⱪanliriƣa wǝ dostliriƣa meⱨribanliⱪ kɵrsitip, seni Dawutning ⱪoliƣa tapxurmiƣan tursam, meni Yǝⱨudaƣa tǝwǝ bir itining bexidǝk kɵrüp, bügün bu hotun üqün meni gunaⱨⱪa buyrumaⱪqimusǝn?
9 Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe Abneri, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí Olúwa ti búra fún Dafidi, bí èmi kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ fún un.
Mǝn Pǝrwǝrdigarning Dawutⱪa ⱪǝsǝm bilǝn wǝdǝ ⱪilƣinidǝk ⱪilmisam Huda mǝnki Abnǝrni ⱪattiⱪ ursun wǝ uningdin artuⱪ ursun!
10 Láti mú ìjọba náà kúrò ní ìdílé Saulu, àti láti gbé ìtẹ́ Dafidi kalẹ̀ lórí Israẹli, àti lórí Juda, láti Dani títí ó fi dé Beerṣeba.”
— yǝni, padixaⱨliⱪni Saulning jǝmǝtidin yɵtkǝp, Dawutning tǝhtini Dandin Bǝǝr-Xebaƣiqǝ pütkül Israil bilǝn Yǝⱨudaning üstigǝ tiklimisǝm!».
11 Òun kò sì lè dá Abneri lóhùn kan nítorí tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
Ixboxǝt Abnǝrdin ⱪorⱪup, uningƣa jawabǝn bir eƣiz sɵz ⱪilixⱪimu jür’ǝt ⱪilalmidi.
12 Abneri sì rán àwọn oníṣẹ́ sí Dafidi nítorí rẹ̀ wí pé, “Ti ta ni ilẹ̀ náà ń ṣe? Bá mi ṣe àdéhùn, èmi yóò si kó gbogbo Israẹli tọ̀ ọ́ wá.”
Abnǝr bolsa ɵzi üqün ǝlqilǝrni Dawutning ⱪexiƣa mangdurup uningƣa: Zemin kimningki? Mǝn bilǝn ǝⱨdǝ tüzgin, mening ⱪolum sening tǝripingdǝ bolup, pütkül Israilni sanga mayil ⱪilimǝn — dedi.
13 Òun sì wí pé, “Ó dára, èmi ó bá ọ ṣe àdéhùn, ṣùgbọ́n ohun kan ni èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, èyí ni pé, ìwọ kì yóò rí ojú mi, àfi bí ìwọ bá kọ́ mú Mikali ọmọbìnrin Saulu wá, nígbà tí ìwọ bá wá, láti rí ojú mi.”
Dawut jawab berip: — Bolidu, mǝn sǝn bilǝn ǝⱨdǝ ⱪilay. Pǝⱪǝt birla ixni tǝlǝp ⱪilay; mening ⱪeximƣa kǝlgǝndǝ Saulning ⱪizi Miⱪalni elip kǝlmisǝng, yüzümni kɵrǝlmǝysǝn, dedi.
14 Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Iṣboṣeti ọmọ Saulu pé, “Fi Mikali obìnrin mi lé mi lọ́wọ́, ẹni tí èmi ti fi ọgọ́rùn-ún awọ iwájú orí àwọn Filistini fẹ́.”
Andin Dawut Ixboxǝtning ⱪexiƣa ǝlqilǝrni mangdurup: Mǝn bir yüz Filistiyning hǝtniliki bǝdili bilǝn alƣan ayalim Miⱪalni manga ⱪayturup bǝrgin — dedi.
15 Iṣboṣeti sì ránṣẹ́, ó sì gbà á lọ́wọ́ ọkùnrin tí a ń pè ní Paltieli ọmọ Laiṣi.
Ixboxǝt adǝm ǝwǝtip Miⱪalni uning eridin, yǝni Laixning oƣli Paltiyǝldin elip kǝldi.
16 Ọkọ rẹ̀ sì ń bà a lọ, ó ń rìn, ó sì ń sọkún lẹ́yìn rẹ̀ títí ó fi dé Bahurimu Abneri sì wí fún un pé, “Padà sẹ́yìn!” Òun sì padà.
Lekin uning eri Bahurimƣiqǝ uning kǝynidin yiƣliƣan peti ǝgixip mangdi. Ahir berip Abnǝr uningƣa: — Yenip kǝtkin, dewidi, u ⱪaytip kǝtti.
17 Abneri sì bá àwọn àgbàgbà Israẹli sọ̀rọ̀ pé, “Ẹ̀yin ti ń ṣe àfẹ́rí Dafidi ní ìgbà àtijọ́, láti jẹ ọba lórí yín.
Əmdi Abnǝr Israilning aⱪsaⱪalliriƣa: Silǝr burun Dawut üstimizgǝ padixaⱨ bolsun, degǝn arzu-istǝktǝ boldunglar.
18 Ǹjẹ́ ẹ ṣe, nítorí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi pé, ‘Láti ọwọ́ Dafidi ìránṣẹ́ mi lé mi ó gba Israẹli ènìyàn mi là kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a wọn.’”
Əmdi ⱨazir ⱨǝrikǝt ⱪilinglar; qünki Pǝrwǝrdigar Dawut toƣrisida: — Ⱪul-bǝndǝm Dawutning ⱪoli bilǝn Israil hǝlⱪimni Filistiylǝrning ⱪolidin, xundaⱪla barliⱪ düxmǝnlirining ⱪolidin ⱪutⱪuzimǝn, — degǝnidi.
19 Abneri sì sọ̀rọ̀ létí Benjamini: Abneri sì lọ sọ létí Dafidi ní Hebroni, gbogbo èyí tí ó dára lójú Israẹli, àti lójú gbogbo ilé Benjamini.
Abnǝr yǝnǝ Binyaminlarning ⱪuliⱪiƣimu muxu sɵzlǝrni eytti. Andin Israil bilǝn Binyaminning pütkül jǝmǝtining arzu-istǝklirini Dawutning ⱪuliⱪiƣa eytixⱪa Ⱨebronƣa bardi.
20 Abneri sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, ogún ọmọkùnrin sì lọ pẹ̀lú rẹ̀ Dafidi sì ṣe àsè fún Abneri àti fún àwọn ọmọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀.
xundaⱪ ⱪilip Abnǝr yigirmǝ adǝmning ⱨǝmraⱨliⱪida Ⱨebronƣa Dawutning ⱪexiƣa kǝlgǝndǝ Dawut Abnǝr wǝ uning adǝmlirigǝ bir ziyapǝt tǝyyarlidi.
21 Abneri sì wí fún Dafidi pé, “Èmi ó dìde, èmi ó sì lọ, èmi ó sì kó gbogbo Israẹli jọ sọ́dọ̀ ọba olúwa mi, wọn ó sì bá a ṣe àdéhùn, ìwọ ó sì jẹ ọba gbogbo wọn bí ọkàn rẹ ti ń fẹ́.” Dafidi sì rán Abneri lọ; òun sì lọ ní àlàáfíà.
Abnǝr Dawutⱪa: Mǝn ⱪozƣilip pütkül Israilni ƣojam padixaⱨning aldiƣa jǝm ⱪilay, ular sening bilǝn ǝⱨdǝ ⱪilixsun, andin sǝn ɵz kɵnglüng haliƣanning barliⱪi üstidin sǝltǝnǝt ⱪilalaydiƣan bolisǝn, dedi. Xuning bilǝn Dawut Abnǝrni yolƣa selip ⱪoydi, u aman-esǝn ⱪaytip kǝtti.
22 Sì wò ó, àwọn ìránṣẹ́ Dafidi àti Joabu sì ti ibi ìlépa ẹgbẹ́ ogun kan bọ̀, wọ́n sì mú ìkógun púpọ̀ bọ̀; ṣùgbọ́n Abneri kò sí lọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni; nítorí tí òun ti rán an lọ, òun sì ti lọ ní àlàáfíà.
Mana, xu ǝsnada Dawutning adǝmliri bilǝn Yoab bir yǝrgǝ ⱨujum ⱪilip nurƣun olja elip ⱪaytip kǝldi. Lekin Abnǝr xu qaƣda Ⱨebronda Dawutning ⱪexida yoⱪ idi; qünki Dawutning uzitip ⱪoyuxi bilǝn aman-esǝn ⱪaytip kǝtkǝnidi.
23 Nígbà tí Joabu àti gbogbo ogun tí ó pẹ̀lú rẹ̀ sì dé, wọ́n sì sọ fún Joabu pé Abneri, ọmọ Neri ti tọ ọba wá, òun sì ti rán an lọ, ó sì ti lọ ní àlàáfíà.
Yoab wǝ uning bilǝn bolƣan pütkül ⱪoxun yetip kǝlgǝndǝ, hǝlⱪ uningƣa: Nǝrning oƣli Abnǝr padixaⱨning ⱪexiƣa kǝldi, padixaⱨ uni yolƣa selip ⱪoyuxi bilǝn u aman-esǝn ⱪaytip kǝtti — dedi.
24 Joabu sì tọ ọba wá, ó sì sọ pé, “Kí ni ìwọ ṣe yìí? Wò ó, Abneri tọ̀ ọ́ wá; èéha ti ṣe tí ìwọ sì fi rán an lọ? Òun sì ti lọ.
Andin Yoab padixaⱨning ⱪexiƣa berip: Bu sening nemǝ ⱪilƣining?! Mana, Abnǝr ⱪexingƣa kǝptu! Nemixⱪa uni yolƣa selip ⱪoydung? U ⱨazir ketiptu!
25 Ìwọ mọ Abneri ọmọ Neri, pé ó wá láti tàn ọ́ jẹ ni, àti láti mọ ìjáde lọ rẹ, àti wíwọlé rẹ́ àti láti mọ gbogbo èyí tí ìwọ ń ṣe.”
Sǝn Nǝrning oƣli Abnǝrni bilisǝnƣu! Uning kelixi jǝzmǝn seni aldax üqün, sening qiⱪip-kiridiƣan yolungni, xundaⱪla barliⱪ ix-paaliyitingni biliwelix üqündur, — dedi.
26 Nígbà tí Joabu sì jáde kúrò lọ́dọ̀ Dafidi, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ láti lépa Abneri, wọ́n sì pè é padà láti ibi kànga Sira, Dafidi kò sì mọ̀.
Yoab Dawutning ⱪexidin qiⱪixi bilǝn u hǝwǝrqilǝrni Abnǝrning kǝynidin mangdurdi. Ular uni Siraⱨ ⱪuduⱪining yenidin yandurup elip kǝldi; lekin Dawut bu ixtin bihǝwǝr idi.
27 Abneri sì padà sí Hebroni, Joabu sì bá a tẹ̀ láàrín ojú ọ̀nà láti bá a sọ̀rọ̀ ní àlàáfíà, ó sì gún un níbẹ̀ lábẹ́ inú, ó sì kú, nítorí ẹ̀jẹ̀ Asaheli arákùnrin rẹ̀.
Abnǝr Ⱨebronƣa yenip kǝlgǝndǝ Yoab uni xǝⱨǝr ⱪowuⱪida uqritip, «Sanga dǝydiƣan mǝhpiy sɵzüm bar idi» dǝp uni bir qǝtkǝ ǝkilip u yǝrdǝ inisi Asaⱨǝlning ⱪan ⱪisasini elix üqün ⱪorsiⱪiƣa piqaⱪ saldi, xuning bilǝn u ɵldi.
28 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi sì gbọ́ ọ, ó sì wí pé, “Èmi àti ìjọba mi sì jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú Olúwa títí láé, ní ti ẹ̀jẹ̀ Abneri ọmọ Neri,
Keyin, Dawut bu ixni anglap: Mǝn wǝ padixaⱨliⱪim Pǝrwǝrdigarning aldida Nǝrning oƣli Abnǝrning aⱪⱪan ⱪeni üqün mǝnggü bigunaⱨdurmiz;
29 jẹ́ kí ó wà ní orí Joabu, àti ní orí gbogbo ìdílé baba rẹ̀; kí a má sì fẹ́ ẹni ó tí ní ààrùn ìsun, tàbí adẹ́tẹ̀, tàbí ẹni tí ń tẹ ọ̀pá, tàbí ẹni tí a ó fi idà pa, tàbí ẹni tí ó ṣe aláìní oúnjẹ kù ní ilé Joabu.”
[uning ⱪenini aⱪⱪuzux] gunaⱨi Yoabning bexiƣa wǝ atisining jǝmǝtining bexiƣa ⱪaynam bolup qüxsun; Yoabning ailisidin aⱪma yara kesili, yaki mahaw kesili, yaki ⱨasiƣa tayanƣuqi, ⱪiliqtin ɵlgüqi yaki ax-tülüksizlǝr ɵksümisun! — dedi.
30 (Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì pa Abneri, nítorí pé òun ti pa Asaheli arákùnrin wọn ní Gibeoni ní ogun.)
Xundaⱪ ⱪilip, Abnǝr Gibeondiki jǝngdǝ ularning inisi Asaⱨǝlni ɵltürgini üqün, Yoab bilǝn inisi Abixay uni ɵltürdi.
31 Dafidi sì wí fún Joabu àti fún gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ fa aṣọ yín ya, kí ẹ̀yin sì mú aṣọ ọ̀fọ̀, kí ẹ̀yin sì sọkún níwájú Abneri.” Dafidi ọba tìkára rẹ̀ sì tẹ̀lé pósí rẹ̀.
Dawut Yoabⱪa wǝ uningƣa ǝgǝxkǝn barliⱪ hǝlⱪⱪǝ: Kiyimliringlarni yirtinglar! Bɵz kiyim kiyinglar! Abnǝrning [meyiti] aldida matǝm tutunglar! dedi. Dawut padixaⱨ [Abnǝrning] jinazisining kǝynidin mangdi.
32 Wọ́n sì sin Abneri ní Hebroni, ọba sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì sọkún ní ibojì Abneri; gbogbo àwọn ènìyàn náà sì sọkún.
Ular Abnǝrni Ⱨebronda dǝpnǝ ⱪildi, padixaⱨ Abnǝrning ⱪǝbrisining yenida awazini kɵtürüp yiƣlidi; hǝlⱪning ⱨǝmmisimu yiƣlaxti.
33 Ọba sì sọkún lórí Abneri, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ Abneri ó yẹ kí ó kú bí aṣiwèrè?
Padixaⱨ Abnǝr üqün mǝrsiyǝ oⱪup: — «Abnǝrning ǝhmǝⱪtǝk ɵlgini toƣrimu?
34 A kò sá à dè ọ́ lọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò kan ẹsẹ̀ rẹ ní àbà. Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń ṣubú níwájú àwọn ìkà ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ ṣubú.” Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì tún sọkún lórí rẹ̀.
Ⱪolliring baƣlaƣliⱪ bolmisimu, Putlurung ixkǝllik bolmisimu, Lekin sǝn kixilǝrning rǝzillǝrning ⱪolida yiⱪilƣinidǝk, yiⱪilip ɵlgǝnsǝn!» — dedi. Xuning bilǝn hǝlⱪning ⱨǝmmisi uning üqün yǝnǝ yiƣlaxti.
35 Nígbà tí gbogbo ènìyàn sì wá láti gba Dafidi ní ìyànjú kí ó jẹun, nígbà tí ọjọ́ sì ń bẹ, Dafidi sì búra wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí èmi yóò bá tọ́ oúnjẹ wò, tàbí nǹkan mìíràn títí oòrùn yóò fi wọ̀!”
Andin barliⱪ hǝlⱪ Dawutning yeniƣa kelip, uningƣa kün patⱪuqǝ tamaⱪ yeyixni ɵtündi. Əmma Dawut ⱪǝsǝm iqip: Mǝn kün patmasta ya nan ya baxⱪa ⱨǝrⱪandaⱪ nǝrsini tetisam, Huda meni ursun yaki uningdin artuⱪ jazalisun, — dedi.
36 Gbogbo àwọn ènìyàn sì kíyèsi i, ó sì dára lójú wọn, gbogbo èyí tí ọba ṣe sì dára lójú gbogbo àwọn ènìyàn náà.
Barliⱪ hǝlⱪ buni bayⱪap, bu ixtin razi boldi; ǝmǝliyǝttǝ padixaⱨ ⱪilƣan ⱨǝrbir ix barliⱪ hǝlⱪni razi ⱪilatti.
37 Gbogbo àwọn ènìyàn náà àti gbogbo Israẹli sì mọ̀ lọ́jọ́ náà pé, kì í ṣe ìfẹ́ ọba láti pa Abneri ọmọ Neri.
Xuning bilǝn barliⱪ hǝlⱪ, xundaⱪla pütkül Israil xu küni Nǝrning oƣli Abnǝrning ɵltürülixining padixaⱨning kɵrsǝtmisi ǝmǝslikini bilip yǝtti.
38 Ọba sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ pé olórí àti ẹni ńlá kan ni ó ṣubú lónìí ní Israẹli.
Padixaⱨ ɵz hizmǝtkarliriƣa: Bilǝmsilǝr? Bügün Israilda bir sǝrdar, uluƣ bir zat yiⱪildi!
39 Èmi sì ṣe aláìlágbára lónìí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi èmi jẹ ọba; àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ọmọ Seruiah sì le jù mí lọ: Olúwa ni yóò san án fún ẹni tí ó ṣe ibi gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀!”
Gǝrqǝ mǝn Mǝsiⱨ ⱪilinip padixaⱨ tiklǝngǝn bolsammu, mǝn ajiz bir bǝndimǝn. Bu adǝmlǝr, yǝni Zǝruiyaning oƣullirining wǝⱨxiyilikini mǝn kɵtürǝlmigüdǝkmǝn; Pǝrwǝrdigar rǝzillik ⱪilƣuqining rǝzillikini ɵz bexiƣa ⱪaytursun! — dedi.

< 2 Samuel 3 >