< 2 Samuel 3 >
1 Ogun náà sì pẹ́ títí láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi: agbára Dafidi sì ń pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n ìdílé Saulu ń rẹ̀yìn sí i.
Torej tam je bila dolga vojna med Savlovo hišo in Davidovo hišo, toda David je postajal močnejši in močnejši, Savlova hiša pa je postajala šibkejša in šibkejša.
2 Dafidi sì bí ọmọkùnrin ní Hebroni: Amnoni ni àkọ́bí rẹ̀ tí Ahinoamu ará Jesreeli bí fún un.
Davidu so se v Hebrónu rodili sinovi. Njegov prvorojenec je bil Amnón; od Jezreélke Ahinóam;
3 Èkejì rẹ̀ sì ni Kileabu, tí Abigaili aya Nabali ará Karmeli bí fún un; ẹ̀kẹta sì ni Absalomu ọmọ tí Maaka ọmọbìnrin Talmai ọba Geṣuri bí fún un.
in njegov drugi Kiláb od Abigájile, žene Karmelčana Nabála in tretji Absalom, sin Maáhe, hčere gešurskega kralja Talmája;
4 Ẹ̀kẹrin sì ni Adonijah ọmọ Haggiti; àti ẹ̀karùnún ni Ṣefatia ọmọ Abitali;
in četrti Adoníja, Hagítin sin; in peti Šefatjá, sin Abitále;
5 Ẹ̀kẹfà sì ni Itreamu, tí Egla aya Dafidi bí fún un. Wọ̀nyí ni a bí fún Dafidi ni Hebroni.
in šesti Jitreám od Davidove žene Egle. Ti so bili rojeni Davidu v Hebrónu.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí ogun wà láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi, Abneri sì dì alágbára ní ìdílé Saulu.
Pripetilo se je, medtem ko je bila vojna med Savlovo hišo in Davidovo hišo, da je Abnêr sebe naredil močnega za Savlovo hišo.
7 Saulu ti ní àlè kan, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Rispa, ọmọbìnrin Aiah: Iṣboṣeti sì bi Abneri léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wọlé tọ àlè baba mi lọ.”
Savel je imel priležnico, ki ji je bilo ime Ricpa, Ajájeva hči in Iš Bošet je rekel Abnêrju: »Zakaj si odšel k priležnici mojega očeta?«
8 Abneri sì bínú gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ti Iṣboṣeti sọ fún un, ó sì wí pé, “Èmi jẹ́ bí orí ajá ti Juda bí? Di òní yìí ni mo ṣàánú fún ìdílé Saulu baba rẹ, àti fún àwọn arákùnrin rẹ̀, àti fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, tí èmi kò sì fi ọ́ lé Dafidi lọ́wọ́, ìwọ sì kà ẹ̀ṣẹ̀ sí mí lọ́rùn nítorí obìnrin yìí lónìí?
Potem je bil Abnêr zelo ogorčen zaradi besed Iš Bošeta in je rekel: » Mar sem pasja glava, ko ta dan zoper Juda izkazujem prijaznost hiši tvojega očeta Savla, njegovim bratom in njegovim prijateljem in te nisem izročil v Davidovo roko, da me danes obsojaš s krivdo glede te ženske?
9 Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe Abneri, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí Olúwa ti búra fún Dafidi, bí èmi kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ fún un.
Tako stori Bog Abnêrju in še več, razen če, kakor je Gospod prisegel Davidu, celo tako jaz storim njemu,
10 Láti mú ìjọba náà kúrò ní ìdílé Saulu, àti láti gbé ìtẹ́ Dafidi kalẹ̀ lórí Israẹli, àti lórí Juda, láti Dani títí ó fi dé Beerṣeba.”
da se kraljestvo prestavi od Savlove hiše in da postavi Davidov prestol čez Izraela in čez Juda, od Dana, celo do Beeršébe.«
11 Òun kò sì lè dá Abneri lóhùn kan nítorí tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
In ni mogel Abnêrju ponovno odgovoriti besede, ker se ga je bal.
12 Abneri sì rán àwọn oníṣẹ́ sí Dafidi nítorí rẹ̀ wí pé, “Ti ta ni ilẹ̀ náà ń ṣe? Bá mi ṣe àdéhùn, èmi yóò si kó gbogbo Israẹli tọ̀ ọ́ wá.”
Abnêr pa je v svojem imenu poslal poslance k Davidu, rekoč: »Čigava je ta dežela?« Rekoč tudi: »Skleni zavezo z menoj in glej, moja roka bo s teboj, da k tebi privedem ves Izrael.«
13 Òun sì wí pé, “Ó dára, èmi ó bá ọ ṣe àdéhùn, ṣùgbọ́n ohun kan ni èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, èyí ni pé, ìwọ kì yóò rí ojú mi, àfi bí ìwọ bá kọ́ mú Mikali ọmọbìnrin Saulu wá, nígbà tí ìwọ bá wá, láti rí ojú mi.”
Rekel je: »Dobro. Jaz bom sklenil zavezo s teboj, toda od tebe zahtevam eno stvar, to je: ›Ne boš videl mojega obraza, razen če mi najprej ne pripelješ Savlove hčere Mihále, ko prideš, da vidiš moj obraz.‹«
14 Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Iṣboṣeti ọmọ Saulu pé, “Fi Mikali obìnrin mi lé mi lọ́wọ́, ẹni tí èmi ti fi ọgọ́rùn-ún awọ iwájú orí àwọn Filistini fẹ́.”
David je poslal poslance k Savlovemu sinu Iš Bošetu, rekoč: »Izroči mi mojo ženo Mihálo, ki sem si jo zaročil za sto prednjih kožic Filistejcev.«
15 Iṣboṣeti sì ránṣẹ́, ó sì gbà á lọ́wọ́ ọkùnrin tí a ń pè ní Paltieli ọmọ Laiṣi.
Iš Bošet je poslal in jo vzel od njenega soproga, torej od Lajiševega sina Paltíela.
16 Ọkọ rẹ̀ sì ń bà a lọ, ó ń rìn, ó sì ń sọkún lẹ́yìn rẹ̀ títí ó fi dé Bahurimu Abneri sì wí fún un pé, “Padà sẹ́yìn!” Òun sì padà.
Njen soprog je odšel skupaj z njo, jokajoč za njo, do Bahuríma. Potem mu je Abnêr rekel: »Pojdi, vrni se.« In se je vrnil.
17 Abneri sì bá àwọn àgbàgbà Israẹli sọ̀rọ̀ pé, “Ẹ̀yin ti ń ṣe àfẹ́rí Dafidi ní ìgbà àtijọ́, láti jẹ ọba lórí yín.
Abnêr je imel pogovor z Izraelovimi starešinami, rekoč: »V preteklih časih ste iskali za Davidom, da bi bil kralj nad vami.
18 Ǹjẹ́ ẹ ṣe, nítorí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi pé, ‘Láti ọwọ́ Dafidi ìránṣẹ́ mi lé mi ó gba Israẹli ènìyàn mi là kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a wọn.’”
Sedaj torej to storite, kajti Gospod je govoril o Davidu, rekoč: ›Po roki svojega služabnika Davida bom rešil svoje ljudstvo Izraela iz roke Filistejcev in iz roke vseh njihovih sovražnikov.‹«
19 Abneri sì sọ̀rọ̀ létí Benjamini: Abneri sì lọ sọ létí Dafidi ní Hebroni, gbogbo èyí tí ó dára lójú Israẹli, àti lójú gbogbo ilé Benjamini.
Abnêr je govoril tudi na ušesa Benjamina in Abnêr je odšel, da govori tudi na Davidova ušesa v Hebrónu. Vse to se je zdelo dobro Izraelu in to se je zdelo dobro celotni Benjaminovi hiši.
20 Abneri sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, ogún ọmọkùnrin sì lọ pẹ̀lú rẹ̀ Dafidi sì ṣe àsè fún Abneri àti fún àwọn ọmọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀.
Tako je Abnêr prišel k Davidu v Hebrón in z njim dvajset mož. David je naredil zabavo za Abnêrja in može, ki so bili z njim.
21 Abneri sì wí fún Dafidi pé, “Èmi ó dìde, èmi ó sì lọ, èmi ó sì kó gbogbo Israẹli jọ sọ́dọ̀ ọba olúwa mi, wọn ó sì bá a ṣe àdéhùn, ìwọ ó sì jẹ ọba gbogbo wọn bí ọkàn rẹ ti ń fẹ́.” Dafidi sì rán Abneri lọ; òun sì lọ ní àlàáfíà.
Abnêr je rekel Davidu: »Vstal bom in šel in ves Izrael bom zbral k svojemu gospodu kralju, da bodo lahko s teboj sklenili zavezo in da boš lahko kraljeval nad vsem, kar si tvoje srce želi.« David je poslal Abnêrja proč in ta je odšel v miru.
22 Sì wò ó, àwọn ìránṣẹ́ Dafidi àti Joabu sì ti ibi ìlépa ẹgbẹ́ ogun kan bọ̀, wọ́n sì mú ìkógun púpọ̀ bọ̀; ṣùgbọ́n Abneri kò sí lọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni; nítorí tí òun ti rán an lọ, òun sì ti lọ ní àlàáfíà.
Glej, Davidovi služabniki in Joáb so prišli iz zasledovanja krdela in s seboj prinesli velik plen, toda Abnêr ni bil z Davidom v Hebrónu, kajti poslal ga je proč in ta je odšel v miru.
23 Nígbà tí Joabu àti gbogbo ogun tí ó pẹ̀lú rẹ̀ sì dé, wọ́n sì sọ fún Joabu pé Abneri, ọmọ Neri ti tọ ọba wá, òun sì ti rán an lọ, ó sì ti lọ ní àlàáfíà.
Ko so prišli Joáb in vsa vojska, ki je bila z njim, so Joábu povedali, rekoč: »Nerov sin Abnêr je prišel h kralju in ta ga je poslal proč in je odšel v miru.«
24 Joabu sì tọ ọba wá, ó sì sọ pé, “Kí ni ìwọ ṣe yìí? Wò ó, Abneri tọ̀ ọ́ wá; èéha ti ṣe tí ìwọ sì fi rán an lọ? Òun sì ti lọ.
Potem je Joáb prišel h kralju in rekel: »Kaj si storil? Glej, Abnêr je prišel k tebi. Zakaj je to, da si ga poslal proč in je on popolnoma izginil?
25 Ìwọ mọ Abneri ọmọ Neri, pé ó wá láti tàn ọ́ jẹ ni, àti láti mọ ìjáde lọ rẹ, àti wíwọlé rẹ́ àti láti mọ gbogbo èyí tí ìwọ ń ṣe.”
Ti poznaš Nerovega sina Abnêrja, da je prišel, da te zavede in da spozna tvoja odhajanja in tvoja prihajanja in da spozna vse, kar delaš.«
26 Nígbà tí Joabu sì jáde kúrò lọ́dọ̀ Dafidi, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ láti lépa Abneri, wọ́n sì pè é padà láti ibi kànga Sira, Dafidi kò sì mọ̀.
Ko je Joáb prišel od Davida, je za Abnêrjem poslal poslance, ki so ga ponovno privedli od vodnjaka Sire. Toda David tega ni vedel.
27 Abneri sì padà sí Hebroni, Joabu sì bá a tẹ̀ láàrín ojú ọ̀nà láti bá a sọ̀rọ̀ ní àlàáfíà, ó sì gún un níbẹ̀ lábẹ́ inú, ó sì kú, nítorí ẹ̀jẹ̀ Asaheli arákùnrin rẹ̀.
Ko se je Abnêr vrnil v Hebrón, ga je Joáb vzel na stran, v velika vrata, da bi tiho govoril z njim in ga tam udaril pod petim rebrom, da je umrl zaradi krvi njegovega brata Asaéla.
28 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi sì gbọ́ ọ, ó sì wí pé, “Èmi àti ìjọba mi sì jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú Olúwa títí láé, ní ti ẹ̀jẹ̀ Abneri ọmọ Neri,
Potem ko je David to slišal, je rekel: »Jaz in moje kraljestvo sva brez krivde pred Gospodom na veke pred krvjo Nerovega sina Abnêrja.
29 jẹ́ kí ó wà ní orí Joabu, àti ní orí gbogbo ìdílé baba rẹ̀; kí a má sì fẹ́ ẹni ó tí ní ààrùn ìsun, tàbí adẹ́tẹ̀, tàbí ẹni tí ń tẹ ọ̀pá, tàbí ẹni tí a ó fi idà pa, tàbí ẹni tí ó ṣe aláìní oúnjẹ kù ní ilé Joabu.”
Ta naj počiva na Joábovi glavi in na vsej hiši njegovega očeta in naj iz Joábove hiše ne zmanjka tistega, ki ima izliv ali je gobavec ali se naslanja na palico ali pada na meč ali mu primanjkuje kruha.«
30 (Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì pa Abneri, nítorí pé òun ti pa Asaheli arákùnrin wọn ní Gibeoni ní ogun.)
Tako sta Joáb in njegov brat Abišáj umorila Abnêrja, ker je ubil njunega brata Asaéla v bitki pri Gibeónu.
31 Dafidi sì wí fún Joabu àti fún gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ fa aṣọ yín ya, kí ẹ̀yin sì mú aṣọ ọ̀fọ̀, kí ẹ̀yin sì sọkún níwájú Abneri.” Dafidi ọba tìkára rẹ̀ sì tẹ̀lé pósí rẹ̀.
David je rekel Joábu in vsemu ljudstvu, ki je bilo z njim: »Pretrgajte svoja oblačila in se opašite z vrečevino in žalujte pred Abnêrjem.« In sam kralj David je sledil mrtvaškemu odru.
32 Wọ́n sì sin Abneri ní Hebroni, ọba sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì sọkún ní ibojì Abneri; gbogbo àwọn ènìyàn náà sì sọkún.
Abnêrja so pokopali v Hebrónu. Kralj je povzdignil svoj glas in jokal nad Abnêrjevim grobom in vse ljudstvo je jokalo.
33 Ọba sì sọkún lórí Abneri, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ Abneri ó yẹ kí ó kú bí aṣiwèrè?
Kralj je žaloval nad Abnêrjem in rekel: »Je Abnêr umrl, kakor umira bedak?
34 A kò sá à dè ọ́ lọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò kan ẹsẹ̀ rẹ ní àbà. Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń ṣubú níwájú àwọn ìkà ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ ṣubú.” Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì tún sọkún lórí rẹ̀.
Tvoje roke niso bile zvezane niti tvoja stopala, vklenjena v okove. Kakor mož pada pred zlobneži, tako padaš ti.« In vse ljudstvo je ponovno jokalo nad njim.
35 Nígbà tí gbogbo ènìyàn sì wá láti gba Dafidi ní ìyànjú kí ó jẹun, nígbà tí ọjọ́ sì ń bẹ, Dafidi sì búra wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí èmi yóò bá tọ́ oúnjẹ wò, tàbí nǹkan mìíràn títí oòrùn yóò fi wọ̀!”
Ko je vse ljudstvo prišlo, da povzročijo Davidu, da jé hrano, medtem ko je bil še dan, je David prisegel, rekoč: »Tako naj mi Bog stori in še več, če okusim kruh ali karkoli drugega, dokler sonce ne zaide.«
36 Gbogbo àwọn ènìyàn sì kíyèsi i, ó sì dára lójú wọn, gbogbo èyí tí ọba ṣe sì dára lójú gbogbo àwọn ènìyàn náà.
Vse ljudstvo je to opazilo in to jim je ugajalo, kakor karkoli je kralj storil, je vsemu ljudstvu ugajalo.
37 Gbogbo àwọn ènìyàn náà àti gbogbo Israẹli sì mọ̀ lọ́jọ́ náà pé, kì í ṣe ìfẹ́ ọba láti pa Abneri ọmọ Neri.
Kajti vse ljudstvo in ves Izrael je ta dan razumelo, da to ni bilo od kralja, da umori Nerovega sina Abnêrja.
38 Ọba sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ pé olórí àti ẹni ńlá kan ni ó ṣubú lónìí ní Israẹli.
Kralj je rekel svojim služabnikom: »Ali ne veste, da je ta dan tukaj v Izraelu padel princ in velik mož?
39 Èmi sì ṣe aláìlágbára lónìí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi èmi jẹ ọba; àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ọmọ Seruiah sì le jù mí lọ: Olúwa ni yóò san án fún ẹni tí ó ṣe ibi gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀!”
Jaz sem ta dan šibek, čeprav maziljen kralj in ti možje, Cerújini sinovi, so pretežki zame. Gospod bo hudodelca nagradil glede na njegovo zlobnost.«