< 2 Samuel 3 >

1 Ogun náà sì pẹ́ títí láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi: agbára Dafidi sì ń pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n ìdílé Saulu ń rẹ̀yìn sí i.
I była długa wojna między domem Saulowym i między domem Dawidowym. Wszakże Dawid postępował, i zmacniał się; ale dom Saulów schodził i niszczał.
2 Dafidi sì bí ọmọkùnrin ní Hebroni: Amnoni ni àkọ́bí rẹ̀ tí Ahinoamu ará Jesreeli bí fún un.
I narodziło się Dawidowi w Hebronie synów. A był pierworodny jego Amnon z Achinoamy Jezreelitki;
3 Èkejì rẹ̀ sì ni Kileabu, tí Abigaili aya Nabali ará Karmeli bí fún un; ẹ̀kẹta sì ni Absalomu ọmọ tí Maaka ọmọbìnrin Talmai ọba Geṣuri bí fún un.
Wtóry po nim był Helijab z Abigaili, żony przedtem Nabalowej z Karmelu, a trzeci Absalom, syn Moachy, córki Tolmaja króla Giessur;
4 Ẹ̀kẹrin sì ni Adonijah ọmọ Haggiti; àti ẹ̀karùnún ni Ṣefatia ọmọ Abitali;
A czwarty Adonijasz, syn Hagity, a piąty Sefatyjasz, syn Abitali;
5 Ẹ̀kẹfà sì ni Itreamu, tí Egla aya Dafidi bí fún un. Wọ̀nyí ni a bí fún Dafidi ni Hebroni.
A szósty Jetraam z Egli, żony Dawidowej. Cić się urodzili Dawidowi w Hebronie.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí ogun wà láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi, Abneri sì dì alágbára ní ìdílé Saulu.
I stało się, gdy była wojna między domem Saulowym i między domem Dawidowym, a Abner się mężnie zastawiał o dom Saulowy.
7 Saulu ti ní àlè kan, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Rispa, ọmọbìnrin Aiah: Iṣboṣeti sì bi Abneri léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wọlé tọ àlè baba mi lọ.”
(A Saul miał założnicę, której imię było Resfa, córka Aje, ) że rzekł Izboset do Abnera: Czemuś wszedł do założnicy ojca mojego?
8 Abneri sì bínú gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ti Iṣboṣeti sọ fún un, ó sì wí pé, “Èmi jẹ́ bí orí ajá ti Juda bí? Di òní yìí ni mo ṣàánú fún ìdílé Saulu baba rẹ, àti fún àwọn arákùnrin rẹ̀, àti fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, tí èmi kò sì fi ọ́ lé Dafidi lọ́wọ́, ìwọ sì kà ẹ̀ṣẹ̀ sí mí lọ́rùn nítorí obìnrin yìí lónìí?
I rozgniewał się Abner bardzo o one słowa Izbosetowe, i rzekł: Izalim ja psia głowa, którym przeciw Judzie dziś uczynił miłosierdzie nad domem Saula, ojca twego, i nad bracią jego, i nad przyjaciółmi jego, i nie wydałem cię w rękę Dawidowę, a ty d ziś szukasz na mnie nieprawości tej niewiasty?
9 Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe Abneri, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí Olúwa ti búra fún Dafidi, bí èmi kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ fún un.
To niech uczyni Bóg Abnerowi, i to niech mu przyczyni, jeźliże, jako przysiągł Pan Dawidowi, nie pomogę do tego.
10 Láti mú ìjọba náà kúrò ní ìdílé Saulu, àti láti gbé ìtẹ́ Dafidi kalẹ̀ lórí Israẹli, àti lórí Juda, láti Dani títí ó fi dé Beerṣeba.”
Aby przeniesione było królestwo od domu Saulowego, a wystawiona stolica Dawidowa nad Izraelem, i nad Judą od Dan aż do Beerseba.
11 Òun kò sì lè dá Abneri lóhùn kan nítorí tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
I nie mógł nic więcej odpowiedzieć Abnerowi, przeto że się go bał.
12 Abneri sì rán àwọn oníṣẹ́ sí Dafidi nítorí rẹ̀ wí pé, “Ti ta ni ilẹ̀ náà ń ṣe? Bá mi ṣe àdéhùn, èmi yóò si kó gbogbo Israẹli tọ̀ ọ́ wá.”
A tak wyprawił Abner posły do Dawida od siebie, mówiąc: Czyjaż jest ziemia? i żeby mówili: Uczyń przymierze twoje ze mną, a oto ręka moja będzie z tobą, aby obrócon był do ciebie wszystek Izrael.
13 Òun sì wí pé, “Ó dára, èmi ó bá ọ ṣe àdéhùn, ṣùgbọ́n ohun kan ni èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, èyí ni pé, ìwọ kì yóò rí ojú mi, àfi bí ìwọ bá kọ́ mú Mikali ọmọbìnrin Saulu wá, nígbà tí ìwọ bá wá, láti rí ojú mi.”
Któremu odpowiedział: Dobrze, uczynię z tobą przymierze. A wszakże o jedno cię proszę, mianowicie, abyś nie przychodził przed oblicze moje, aż mi pierwej przywiedziesz Michol, córkę Saulowę, gdy będziesz chciał przyjść, abyś widział twarz moję.
14 Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Iṣboṣeti ọmọ Saulu pé, “Fi Mikali obìnrin mi lé mi lọ́wọ́, ẹni tí èmi ti fi ọgọ́rùn-ún awọ iwájú orí àwọn Filistini fẹ́.”
I wyprawił Dawid posły do Izboseta syn Saulowego, mówiąc: Wydaj mi żonę moję Michol, którąm sobie poślubił stem nieobrzezek Filistyńskich.
15 Iṣboṣeti sì ránṣẹ́, ó sì gbà á lọ́wọ́ ọkùnrin tí a ń pè ní Paltieli ọmọ Laiṣi.
Przetoż posłał Izboset, i wziął ją od męża, od Faltejela, syna Laisowego.
16 Ọkọ rẹ̀ sì ń bà a lọ, ó ń rìn, ó sì ń sọkún lẹ́yìn rẹ̀ títí ó fi dé Bahurimu Abneri sì wí fún un pé, “Padà sẹ́yìn!” Òun sì padà.
Tedy szedł z nią mąż jej, a idąc za nią, płakał jej aż do Bachurym; i rzekł do niego Abner: Idź, a wróć się; i wrócił się.
17 Abneri sì bá àwọn àgbàgbà Israẹli sọ̀rọ̀ pé, “Ẹ̀yin ti ń ṣe àfẹ́rí Dafidi ní ìgbà àtijọ́, láti jẹ ọba lórí yín.
Uczynił potem Abner rzecz do starszych Izraelskich mówiąc: Przeszłych czasów szukaliście Dawida, aby był królem nad wami.
18 Ǹjẹ́ ẹ ṣe, nítorí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi pé, ‘Láti ọwọ́ Dafidi ìránṣẹ́ mi lé mi ó gba Israẹli ènìyàn mi là kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a wọn.’”
Przetoż teraz uczyńcie tak; bo Pan rzekł o Dawidzie, mówiąc: Przez rękę Dawida, sługi mego, wybawię lud mój Izraelski z ręki Filistyńskiej, i z ręki wszystkich nieprzyjaciół jego.
19 Abneri sì sọ̀rọ̀ létí Benjamini: Abneri sì lọ sọ létí Dafidi ní Hebroni, gbogbo èyí tí ó dára lójú Israẹli, àti lójú gbogbo ilé Benjamini.
To też mówił Abner i do Benjamińczyków. Potem odszedł Abner, aby mówił z Dawidem w Hebronie wszystko, co dobrego było w oczach Izraela, i w oczach wszystkiego domu Benjaminowego.
20 Abneri sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, ogún ọmọkùnrin sì lọ pẹ̀lú rẹ̀ Dafidi sì ṣe àsè fún Abneri àti fún àwọn ọmọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀.
Gdy tedy przeszedł Abner do Dawida do Hebronu, a z nim dwadzieścia mężów, sprawił Dawid na Abnera, i na męże, którzy z nim byli, ucztę.
21 Abneri sì wí fún Dafidi pé, “Èmi ó dìde, èmi ó sì lọ, èmi ó sì kó gbogbo Israẹli jọ sọ́dọ̀ ọba olúwa mi, wọn ó sì bá a ṣe àdéhùn, ìwọ ó sì jẹ ọba gbogbo wọn bí ọkàn rẹ ti ń fẹ́.” Dafidi sì rán Abneri lọ; òun sì lọ ní àlàáfíà.
I rzekł Abner do Dawida: Wstanę, a pójdę, abym zebrał do króla, pana mego, wszystkiego Izraela, którzy z tobą uczynią przymierze; a będziesz królował nad wszystkimi, jako żąda dusza twoja. A tak odprawił Dawid Abnera, który odszedł w pokoju.
22 Sì wò ó, àwọn ìránṣẹ́ Dafidi àti Joabu sì ti ibi ìlépa ẹgbẹ́ ogun kan bọ̀, wọ́n sì mú ìkógun púpọ̀ bọ̀; ṣùgbọ́n Abneri kò sí lọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni; nítorí tí òun ti rán an lọ, òun sì ti lọ ní àlàáfíà.
A oto, słudzy Dawidowi i Joab wracali się z wojny, korzyści wielkie z sobą prowadząc, ale Abnera już nie było u Dawida w Hebronie: bo go był odprawił, i odszedł był w pokoju.
23 Nígbà tí Joabu àti gbogbo ogun tí ó pẹ̀lú rẹ̀ sì dé, wọ́n sì sọ fún Joabu pé Abneri, ọmọ Neri ti tọ ọba wá, òun sì ti rán an lọ, ó sì ti lọ ní àlàáfíà.
Joab tedy i wszystko wojsko, które z nim było, przyszli tam; i dano znać Joabowi, mówiąc: Był tu Abner, syn Nera, u króla; ale go odprawił, i odszedł w pokoju.
24 Joabu sì tọ ọba wá, ó sì sọ pé, “Kí ni ìwọ ṣe yìí? Wò ó, Abneri tọ̀ ọ́ wá; èéha ti ṣe tí ìwọ sì fi rán an lọ? Òun sì ti lọ.
Przetoż wszedłszy Joab do króla, rzekł: Cóżeś uczynił? Oto, przyszedł był Abner do ciebie; przeczżeś go puścił, aby zaś odszedł.
25 Ìwọ mọ Abneri ọmọ Neri, pé ó wá láti tàn ọ́ jẹ ni, àti láti mọ ìjáde lọ rẹ, àti wíwọlé rẹ́ àti láti mọ gbogbo èyí tí ìwọ ń ṣe.”
Znasz Abnera, syna Nerowego, gdyż przyszedł, aby cię zdradził, i żeby wiedział wyjście twoje, i wejście twoje, aby się wywiedział o wszystkiem, co ty czynisz.
26 Nígbà tí Joabu sì jáde kúrò lọ́dọ̀ Dafidi, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ láti lépa Abneri, wọ́n sì pè é padà láti ibi kànga Sira, Dafidi kò sì mọ̀.
Tedy odszedłszy Joab od Dawida, wyprawił posły za Abnerem, którzy go wrócili od studni Syra, o czem Dawid nie wiedział.
27 Abneri sì padà sí Hebroni, Joabu sì bá a tẹ̀ láàrín ojú ọ̀nà láti bá a sọ̀rọ̀ ní àlàáfíà, ó sì gún un níbẹ̀ lábẹ́ inú, ó sì kú, nítorí ẹ̀jẹ̀ Asaheli arákùnrin rẹ̀.
A gdy się wrócił Abner do Hebronu, odwiódł go Joab w pośród bramy, aby z nim po cichu (osobno) mówił, i przebił go tam pod piąte żebro, że umarł dla krwi Asaela, brata swego.
28 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi sì gbọ́ ọ, ó sì wí pé, “Èmi àti ìjọba mi sì jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú Olúwa títí láé, ní ti ẹ̀jẹ̀ Abneri ọmọ Neri,
Co gdy potem usłyszał Dawid, rzekł: Nie jestem winien, ani królestwo moje, przed Panem aż na wieki krwi Abnera, syna Nerowego.
29 jẹ́ kí ó wà ní orí Joabu, àti ní orí gbogbo ìdílé baba rẹ̀; kí a má sì fẹ́ ẹni ó tí ní ààrùn ìsun, tàbí adẹ́tẹ̀, tàbí ẹni tí ń tẹ ọ̀pá, tàbí ẹni tí a ó fi idà pa, tàbí ẹni tí ó ṣe aláìní oúnjẹ kù ní ilé Joabu.”
Niechaj przyjdzie na głowę Joabowę, i na wszystek dom ojca jego, i niech nie ustaje z domu Joabowego płynienie nasienia cierpiący, i trędowaty, i o kiju chodzący, i od miecza upadający, i nie mający chleba.
30 (Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì pa Abneri, nítorí pé òun ti pa Asaheli arákùnrin wọn ní Gibeoni ní ogun.)
A tak Joab i Abisaj, brat jego, zabili Abnera, przeto iż on też był zabił Asaela, brata ich, w bitwie u Gabaona.
31 Dafidi sì wí fún Joabu àti fún gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ fa aṣọ yín ya, kí ẹ̀yin sì mú aṣọ ọ̀fọ̀, kí ẹ̀yin sì sọkún níwájú Abneri.” Dafidi ọba tìkára rẹ̀ sì tẹ̀lé pósí rẹ̀.
Rzekł potem Dawid do Joaba i do wszystkiego ludu, który był z nim: Porozdzierajcie odzienia wasze a opaszcie się w wory, i płaczcie nad Abnerem. A król Dawid szedł za marami.
32 Wọ́n sì sin Abneri ní Hebroni, ọba sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì sọkún ní ibojì Abneri; gbogbo àwọn ènìyàn náà sì sọkún.
A gdy pogrzebli Abnera w Hebronie, podniósł król głos swój, i płakał nad grobem Abnerowym; płakał też wszystek lud.
33 Ọba sì sọkún lórí Abneri, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ Abneri ó yẹ kí ó kú bí aṣiwèrè?
A tak lamentując król nad Abnerem, rzekł: Izali tak miał umrzeć Abner, jako umiera nikczemnik?
34 A kò sá à dè ọ́ lọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò kan ẹsẹ̀ rẹ ní àbà. Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń ṣubú níwájú àwọn ìkà ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ ṣubú.” Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì tún sọkún lórí rẹ̀.
Ręce twoje nie były związane, a nogi twoje nie były pętami obciążone; poległeś jako ten, który pada przed synami niezbożnymi. Tedy tem więcej wszystek lud płakał nad nim.
35 Nígbà tí gbogbo ènìyàn sì wá láti gba Dafidi ní ìyànjú kí ó jẹun, nígbà tí ọjọ́ sì ń bẹ, Dafidi sì búra wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí èmi yóò bá tọ́ oúnjẹ wò, tàbí nǹkan mìíràn títí oòrùn yóò fi wọ̀!”
Potem przyszedł wszystek lud prosić Dawida, aby jadł chleb, gdy jeszcze był jasny dzień: ale przysiągł Dawid, mówiąc: To mi niech uczyni Bóg, i to niech przyczyni, jeźli przed zajściem słońca skosztuję chleba, albo czego innego.
36 Gbogbo àwọn ènìyàn sì kíyèsi i, ó sì dára lójú wọn, gbogbo èyí tí ọba ṣe sì dára lójú gbogbo àwọn ènìyàn náà.
Co gdy wszystek lud obaczył, podobało się im to; a wszystko cokolwiek czynił król, podobało się w oczach wszystkiego ludu.
37 Gbogbo àwọn ènìyàn náà àti gbogbo Israẹli sì mọ̀ lọ́jọ́ náà pé, kì í ṣe ìfẹ́ ọba láti pa Abneri ọmọ Neri.
I poznał wszystek Izrael dnia onego, że nie z naprawy królewskiej zabity był Abner, syn Nera.
38 Ọba sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ pé olórí àti ẹni ńlá kan ni ó ṣubú lónìí ní Israẹli.
I rzekł król do sług swoich: Azaż nie wiecie, że hetman, a bardzo wielki, poległ dziś w Izraelu?
39 Èmi sì ṣe aláìlágbára lónìí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi èmi jẹ ọba; àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ọmọ Seruiah sì le jù mí lọ: Olúwa ni yóò san án fún ẹni tí ó ṣe ibi gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀!”
A ja dziś jako nowy, i dopiero pomazany król; ci zasię mężowie, synowie Sarwii, srożsi są niżli ja; niechże odda Pan czyniącemu złe według złości jego.

< 2 Samuel 3 >