< 2 Samuel 3 >
1 Ogun náà sì pẹ́ títí láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi: agbára Dafidi sì ń pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n ìdílé Saulu ń rẹ̀yìn sí i.
There was then long warre betweene the house of Saul and the house of Dauid: but Dauid waxed stronger, and the house of Saul waxed weaker.
2 Dafidi sì bí ọmọkùnrin ní Hebroni: Amnoni ni àkọ́bí rẹ̀ tí Ahinoamu ará Jesreeli bí fún un.
And vnto Dauid were children borne in Hebron: and his eldest sonne was Amnon of Ahinoam the Izreelite,
3 Èkejì rẹ̀ sì ni Kileabu, tí Abigaili aya Nabali ará Karmeli bí fún un; ẹ̀kẹta sì ni Absalomu ọmọ tí Maaka ọmọbìnrin Talmai ọba Geṣuri bí fún un.
And his seconde, was Chileab of Abigail the wife of Nabal the Carmelite: and the third, Absalom the sonne of Maacah the daughter of Talmai the King of Geshur,
4 Ẹ̀kẹrin sì ni Adonijah ọmọ Haggiti; àti ẹ̀karùnún ni Ṣefatia ọmọ Abitali;
And the fourth, Adoniiah the sonne of Haggith, and the fifth, Shephatiah the sonne of Abital,
5 Ẹ̀kẹfà sì ni Itreamu, tí Egla aya Dafidi bí fún un. Wọ̀nyí ni a bí fún Dafidi ni Hebroni.
And the sixt, Ithream by Eglah Dauids wife: these were borne to Dauid in Hebron.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí ogun wà láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi, Abneri sì dì alágbára ní ìdílé Saulu.
Nowe while there was warre betweene the house of Saul and the house of Dauid, Abner made all his power for the house of Saul.
7 Saulu ti ní àlè kan, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Rispa, ọmọbìnrin Aiah: Iṣboṣeti sì bi Abneri léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wọlé tọ àlè baba mi lọ.”
And Saul had a concubine named Rizpah, the daughter of Aiiah. And Ish-bosheth sayde to Abner, Wherefore hast thou gone in to my fathers concubine?
8 Abneri sì bínú gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ti Iṣboṣeti sọ fún un, ó sì wí pé, “Èmi jẹ́ bí orí ajá ti Juda bí? Di òní yìí ni mo ṣàánú fún ìdílé Saulu baba rẹ, àti fún àwọn arákùnrin rẹ̀, àti fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, tí èmi kò sì fi ọ́ lé Dafidi lọ́wọ́, ìwọ sì kà ẹ̀ṣẹ̀ sí mí lọ́rùn nítorí obìnrin yìí lónìí?
Then was Abner very wroth for the words of Ish-bosheth, and said, Am I a dogges head, which against Iudah do shew mercie this day vnto the house of Saul thy father, to his brethren, and to his neighbours, and haue not deliuered thee into the hande of Dauid, that thou chargest me this day with a fault concerning this woman?
9 Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe Abneri, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí Olúwa ti búra fún Dafidi, bí èmi kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ fún un.
So doe God to Abner, and more also, except, as the Lord hath sworne to Dauid, euen so I doe to him,
10 Láti mú ìjọba náà kúrò ní ìdílé Saulu, àti láti gbé ìtẹ́ Dafidi kalẹ̀ lórí Israẹli, àti lórí Juda, láti Dani títí ó fi dé Beerṣeba.”
To remoue the kingdome from the house of Saul, that the throne of Dauid may be stablished ouer Israel, and ouer Iudah, euen from Dan to Beer-sheba.
11 Òun kò sì lè dá Abneri lóhùn kan nítorí tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
And he durst no more answere to Abner: for he feared him.
12 Abneri sì rán àwọn oníṣẹ́ sí Dafidi nítorí rẹ̀ wí pé, “Ti ta ni ilẹ̀ náà ń ṣe? Bá mi ṣe àdéhùn, èmi yóò si kó gbogbo Israẹli tọ̀ ọ́ wá.”
Then Abner sent messengers to Dauid on his behalfe, saying, Whose is the lande? who should also say, Make couenant with me, and beholde, mine hande shalbe with thee, to bring all Israel vnto thee.
13 Òun sì wí pé, “Ó dára, èmi ó bá ọ ṣe àdéhùn, ṣùgbọ́n ohun kan ni èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, èyí ni pé, ìwọ kì yóò rí ojú mi, àfi bí ìwọ bá kọ́ mú Mikali ọmọbìnrin Saulu wá, nígbà tí ìwọ bá wá, láti rí ojú mi.”
Who saide, Well, I will make a couenant with thee: but one thing I require of thee, that is, that thou see not my face except thou bring Michal Sauls daughter when thou commest to see me.
14 Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Iṣboṣeti ọmọ Saulu pé, “Fi Mikali obìnrin mi lé mi lọ́wọ́, ẹni tí èmi ti fi ọgọ́rùn-ún awọ iwájú orí àwọn Filistini fẹ́.”
Then Dauid sent messengers to Ish-bosheth Sauls sonne, saying, Deliuer me my wife Michal, which I marryed for an hundreth foreskinnes of the Philistims.
15 Iṣboṣeti sì ránṣẹ́, ó sì gbà á lọ́wọ́ ọkùnrin tí a ń pè ní Paltieli ọmọ Laiṣi.
And Ish-bosheth sent, and tooke her from her husband Phaltiel the sonne of Laish.
16 Ọkọ rẹ̀ sì ń bà a lọ, ó ń rìn, ó sì ń sọkún lẹ́yìn rẹ̀ títí ó fi dé Bahurimu Abneri sì wí fún un pé, “Padà sẹ́yìn!” Òun sì padà.
And her husband went with her, and came weeping behinde her, vnto Bahurim: then saide Abner vnto him, Go, and returne. So he returned.
17 Abneri sì bá àwọn àgbàgbà Israẹli sọ̀rọ̀ pé, “Ẹ̀yin ti ń ṣe àfẹ́rí Dafidi ní ìgbà àtijọ́, láti jẹ ọba lórí yín.
And Abner had communication with the Elders of Israel, saying, Ye sought for Dauid in times past, that he might be your King.
18 Ǹjẹ́ ẹ ṣe, nítorí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi pé, ‘Láti ọwọ́ Dafidi ìránṣẹ́ mi lé mi ó gba Israẹli ènìyàn mi là kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a wọn.’”
Nowe then doe it: for the Lord hath spoken of Dauid, saying, By the hand of my seruant Dauid I will saue my people Israel out of the handes of the Philistims, and out of the handes of all their enemies.
19 Abneri sì sọ̀rọ̀ létí Benjamini: Abneri sì lọ sọ létí Dafidi ní Hebroni, gbogbo èyí tí ó dára lójú Israẹli, àti lójú gbogbo ilé Benjamini.
Also Abner spake to Beniamin, and afterward Abner went to speake with Dauid in Hebron, concerning all that Israel was content with, and the whole house of Beniamin.
20 Abneri sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, ogún ọmọkùnrin sì lọ pẹ̀lú rẹ̀ Dafidi sì ṣe àsè fún Abneri àti fún àwọn ọmọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀.
So Abner came to Dauid to Hebron, hauing twentie men with him, and Dauid made a feast vnto Abner, and to the men that were with him.
21 Abneri sì wí fún Dafidi pé, “Èmi ó dìde, èmi ó sì lọ, èmi ó sì kó gbogbo Israẹli jọ sọ́dọ̀ ọba olúwa mi, wọn ó sì bá a ṣe àdéhùn, ìwọ ó sì jẹ ọba gbogbo wọn bí ọkàn rẹ ti ń fẹ́.” Dafidi sì rán Abneri lọ; òun sì lọ ní àlàáfíà.
Then Abner sayde vnto Dauid, I will rise vp, and goe gather all Israel vnto my lorde the King, that they may make a couenant with thee, and that thou mayest reigne ouer all that thine heart desireth. Then Dauid let Abner depart, who went in peace.
22 Sì wò ó, àwọn ìránṣẹ́ Dafidi àti Joabu sì ti ibi ìlépa ẹgbẹ́ ogun kan bọ̀, wọ́n sì mú ìkógun púpọ̀ bọ̀; ṣùgbọ́n Abneri kò sí lọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni; nítorí tí òun ti rán an lọ, òun sì ti lọ ní àlàáfíà.
And beholde, the seruants of Dauid and Ioab came from the campe, and brought a great pray with them (but Abner was not with Dauid in Hebron: for he had sent him away, and he departed in peace)
23 Nígbà tí Joabu àti gbogbo ogun tí ó pẹ̀lú rẹ̀ sì dé, wọ́n sì sọ fún Joabu pé Abneri, ọmọ Neri ti tọ ọba wá, òun sì ti rán an lọ, ó sì ti lọ ní àlàáfíà.
When Ioab, and all the hoste that was with him were come, men tolde Ioab, saying, Abner the sonne of Ner came to the King, and he hath sent him away, and he is gone in peace.
24 Joabu sì tọ ọba wá, ó sì sọ pé, “Kí ni ìwọ ṣe yìí? Wò ó, Abneri tọ̀ ọ́ wá; èéha ti ṣe tí ìwọ sì fi rán an lọ? Òun sì ti lọ.
Then Ioab came to the King, and saide, What hast thou done? beholde, Abner came vnto thee, why hast thou sent him away, and he is departed?
25 Ìwọ mọ Abneri ọmọ Neri, pé ó wá láti tàn ọ́ jẹ ni, àti láti mọ ìjáde lọ rẹ, àti wíwọlé rẹ́ àti láti mọ gbogbo èyí tí ìwọ ń ṣe.”
Thou knowest Abner the sonne of Ner: for he came to deceiue thee, and to knowe thy outgoing and ingoing, and to knowe all that thou doest.
26 Nígbà tí Joabu sì jáde kúrò lọ́dọ̀ Dafidi, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ láti lépa Abneri, wọ́n sì pè é padà láti ibi kànga Sira, Dafidi kò sì mọ̀.
And when Ioab was gone out from Dauid, he sent messengers after Abner, which brought him againe from the well of Siriah vnknowing to Dauid.
27 Abneri sì padà sí Hebroni, Joabu sì bá a tẹ̀ láàrín ojú ọ̀nà láti bá a sọ̀rọ̀ ní àlàáfíà, ó sì gún un níbẹ̀ lábẹ́ inú, ó sì kú, nítorí ẹ̀jẹ̀ Asaheli arákùnrin rẹ̀.
And when Abner was come againe to Hebron, Ioab tooke him aside in the gate to speake with him peaceably, and smote him vnder the fift ryb, that he dyed, for the blood of Asahel his brother.
28 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi sì gbọ́ ọ, ó sì wí pé, “Èmi àti ìjọba mi sì jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú Olúwa títí láé, ní ti ẹ̀jẹ̀ Abneri ọmọ Neri,
And when afterwarde it came to Dauids eare, he saide, I and my kingdome are giltlesse before the Lord for euer, concerning the blood of Abner the sonne of Ner.
29 jẹ́ kí ó wà ní orí Joabu, àti ní orí gbogbo ìdílé baba rẹ̀; kí a má sì fẹ́ ẹni ó tí ní ààrùn ìsun, tàbí adẹ́tẹ̀, tàbí ẹni tí ń tẹ ọ̀pá, tàbí ẹni tí a ó fi idà pa, tàbí ẹni tí ó ṣe aláìní oúnjẹ kù ní ilé Joabu.”
Let the blood fall on the head of Ioab, and on all his fathers house, that the house of Ioab be neuer without some that haue running issues, or leper, or that leaneth on a staffe, or that doeth fall on the sworde, or that lacketh bread.
30 (Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì pa Abneri, nítorí pé òun ti pa Asaheli arákùnrin wọn ní Gibeoni ní ogun.)
(So Ioab and Abishai his brother slewe Abner, because he had slaine their brother Asahel at Gibeon in battel)
31 Dafidi sì wí fún Joabu àti fún gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ fa aṣọ yín ya, kí ẹ̀yin sì mú aṣọ ọ̀fọ̀, kí ẹ̀yin sì sọkún níwájú Abneri.” Dafidi ọba tìkára rẹ̀ sì tẹ̀lé pósí rẹ̀.
And Dauid said to Ioab, and to al the people that were with him, Rent your clothes, and put on sackecloth, and mourne before Abner: and King Dauid him selfe followed the beare.
32 Wọ́n sì sin Abneri ní Hebroni, ọba sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì sọkún ní ibojì Abneri; gbogbo àwọn ènìyàn náà sì sọkún.
And when they had buryed Abner in Hebron, the King lift vp his voyce, and wept beside the sepulchre of Abner, and all the people wept.
33 Ọba sì sọkún lórí Abneri, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ Abneri ó yẹ kí ó kú bí aṣiwèrè?
And the King lamented ouer Abner, and sayde, Dyed Abner as a foole dyeth?
34 A kò sá à dè ọ́ lọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò kan ẹsẹ̀ rẹ ní àbà. Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń ṣubú níwájú àwọn ìkà ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ ṣubú.” Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì tún sọkún lórí rẹ̀.
Thine handes were not bounde, nor thy feete tyed in fetters of brasse: but as a man falleth before wicked men, so diddest thou fall. And all the people wept againe for him.
35 Nígbà tí gbogbo ènìyàn sì wá láti gba Dafidi ní ìyànjú kí ó jẹun, nígbà tí ọjọ́ sì ń bẹ, Dafidi sì búra wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí èmi yóò bá tọ́ oúnjẹ wò, tàbí nǹkan mìíràn títí oòrùn yóò fi wọ̀!”
Afterwarde all the people came to cause Dauid eate meate while it was yet day, but Dauid sware, saying, So doe God to me and more also, if I taste bread, or ought els till the sunne be downe.
36 Gbogbo àwọn ènìyàn sì kíyèsi i, ó sì dára lójú wọn, gbogbo èyí tí ọba ṣe sì dára lójú gbogbo àwọn ènìyàn náà.
And all the people knewe it, and it pleased them: as whatsoeuer the King did, pleased all the people.
37 Gbogbo àwọn ènìyàn náà àti gbogbo Israẹli sì mọ̀ lọ́jọ́ náà pé, kì í ṣe ìfẹ́ ọba láti pa Abneri ọmọ Neri.
For all the people and all Israel vnderstoode that day, howe that it was not the Kings deede that Abner the sonne of Ner was slaine.
38 Ọba sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ pé olórí àti ẹni ńlá kan ni ó ṣubú lónìí ní Israẹli.
And the King said vnto his seruants, Know ye not, that there is a prince and a great man falle this day in Israel?
39 Èmi sì ṣe aláìlágbára lónìí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi èmi jẹ ọba; àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ọmọ Seruiah sì le jù mí lọ: Olúwa ni yóò san án fún ẹni tí ó ṣe ibi gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀!”
And I am this day weake and newly anoynted King: and these men the sonnes of Zeruiah be too harde for me: the Lord rewarde the doer of euill according to his wickednesse.