< 2 Samuel 24 >

1 Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli, ó sì ti Dafidi sí wọn, pé, “Lọ ka iye Israẹli àti Juda!”
La colère de Yahvé s'enflamma de nouveau contre Israël, et il poussa David contre eux, en disant: « Va, fais le compte d'Israël et de Juda. »
2 Ọba sì wí fún Joabu olórí ogun, tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ ní ìsinsin yìí sí gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba, kí ẹ sì ka iye àwọn ènìyàn, kí èmi lè mọ iye àwọn ènìyàn náà!”
Le roi dit à Joab, chef de l'armée, qui était avec lui: « Maintenant, va et viens dans toutes les tribus d'Israël, depuis Dan jusqu'à Beersheba, et compte le peuple, afin que je connaisse la somme du peuple. »
3 Joabu sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi kún iye àwọn ènìyàn náà, iyekíye tí ó wù kí wọn jẹ́, ní ọ̀rọ̀ọ̀rún, ojú olúwa mi ọba yóò sì rí i, ṣùgbọ́n èétiṣe tí olúwa mi ọba fi fẹ́ nǹkan yìí?”
Joab dit au roi: « Que Yahvé, ton Dieu, ajoute maintenant cent fois au peuple, quel que soit son nombre, et que les yeux de mon seigneur le roi le voient. Mais pourquoi mon seigneur le roi se réjouit-il de cette chose? »
4 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí ti Joabu, àti ti àwọn olórí ogun. Joabu àti àwọn olórí ogun sì jáde lọ kúrò níwájú ọba, láti lọ ka àwọn ènìyàn Israẹli.
Néanmoins, la parole du roi l'emporta sur Joab et sur les chefs de l'armée. Joab et les chefs de l'armée sortirent de la présence du roi pour compter le peuple d'Israël.
5 Wọ́n sì kọjá odò Jordani, wọ́n sì pàgọ́ ní Aroeri, ní ìhà apá ọ̀tún ìlú tí ó wà láàrín àfonífojì Gadi, àti sí ìhà Jaseri.
Ils passèrent le Jourdain et campèrent à Aroër, à droite de la ville qui est au milieu de la vallée de Gad, et jusqu'à Jazer;
6 Wọ́n sì wá sí Gileadi, àti sí ilé Tatimi Hodṣi; wọ́n sì wá sí Dani Jaani àti yíkákiri sí Sidoni.
puis ils vinrent en Galaad et au pays de Tahtim Hodshi; ils vinrent à Dan Jaan et contournèrent Sidon,
7 Wọ́n sì wá sí ìlú olódi Tire, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hifi, àti ti àwọn ará Kenaani, wọ́n sì jáde lọ síhà gúúsù ti Juda, àní sí Beerṣeba.
ils arrivèrent à la forteresse de Tyr et à toutes les villes des Héviens et des Cananéens, et ils sortirent au sud de Juda, à Beer Schéba.
8 Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu ní òpin oṣù kẹsànán àti ogúnjọ́.
Après avoir parcouru tout le pays, ils arrivèrent à Jérusalem au bout de neuf mois et vingt jours.
9 Joabu sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́. Ó sì jẹ́ ogójì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Israẹli, àwọn onídà, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn.
Joab remit au roi le compte du peuple. Il y avait en Israël huit cent mille hommes vaillants tirant l'épée, et en Juda cinq cent mille hommes.
10 Àyà Dafidi sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dafidi sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe, ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jì ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”
Le cœur de David le frappa après qu'il eut compté le peuple. David dit à Yahvé: « J'ai beaucoup péché par ce que j'ai fait. Mais maintenant, Yahvé, efface, je t'en prie, l'iniquité de ton serviteur, car j'ai fait une grande folie. »
11 Dafidi sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gadi wòlíì wá, aríran Dafidi wí pé,
Lorsque David se leva le matin, la parole de Yahvé fut adressée au prophète Gad, le voyant de David, en ces termes:
12 “Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
« Va dire à David: « Yahvé dit: Je te propose trois choses. Choisis l'une d'elles, que je te l'accorde »".
13 Gadi sì tọ Dafidi wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí ààrùn ìparun ọjọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Rò ó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
Gad se rendit auprès de David et lui dit: « Est-ce que sept années de famine t'arriveront dans ton pays? Ou bien fuiras-tu trois mois devant tes ennemis pendant qu'ils te poursuivent? Ou bien y aura-t-il trois jours de peste dans ton pays? Réponds maintenant, et considère quelle réponse je ferai à celui qui m'a envoyé. »
14 Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí a fi ara wa lé Olúwa ní ọwọ́; nítorí pé àánú rẹ̀ pọ̀; kí ó má sì ṣe fi mí lé ènìyàn ní ọwọ́.”
David dit à Gad: « Je suis dans la détresse. Tombons maintenant dans la main de Yahvé, car sa miséricorde est grande. Que je ne tombe pas dans la main de l'homme. »
15 Olúwa sì rán ààrùn ìparun sí Israẹli láti òwúrọ̀ títí dé àkókò tí a dá, ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn sì kú nínú àwọn ènìyàn náà láti Dani títí fi dé Beerṣeba.
Et l'Éternel envoya la peste sur Israël, depuis le matin jusqu'à l'heure fixée, et il mourut soixante-dix mille hommes du peuple, depuis Dan jusqu'à Beersheba.
16 Nígbà tí angẹli náà sì nawọ́ rẹ̀ sí Jerusalẹmu láti pa á run, Olúwa sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì sọ fún angẹli tí ń pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó tó, dá ọwọ́ rẹ dúró wàyí!” Angẹli Olúwa náà sì wà níbi ìpakà Arauna ará Jebusi.
Lorsque l'ange étendit sa main vers Jérusalem pour la détruire, Yahvé se détourna du désastre et dit à l'ange qui détruisait le peuple: « C'est assez. Maintenant, retire ta main. » L'ange de Yahvé était près de l'aire de battage d'Arauna, le Jébusien.
17 Dafidi sì wí fún Olúwa nígbà tí ó rí angẹli tí ń kọlu àwọn ènìyàn pé, “Wò ó, èmi ti ṣẹ̀, èmi sì ti hùwà búburú ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn wọ̀nyí, kín ni wọ́n ha ṣe? Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, kí ó wà lára mi àti ìdílé baba mi.”
David s'adressa à Yahvé lorsqu'il vit l'ange qui frappait le peuple, et il dit: « Voici, j'ai péché et j'ai agi avec perversité; mais ces brebis, qu'ont-elles fait? Je t'en prie, que ta main soit contre moi et contre la maison de mon père. »
18 Gadi sì tọ Dafidi wá ní ọjọ́ náà, ó sì wí fún un pé, “Gòkè, tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.”
Gad vint ce jour-là auprès de David et lui dit: « Monte, bâtis un autel à Yahvé sur l'aire d'Arauna, le Jébusien. »
19 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Gadi, Dafidi sì gòkè lọ bí Olúwa ti pa á ní àṣẹ.
David monta, selon la parole de Gad, comme l'avait ordonné l'Éternel.
20 Arauna sì wò, ó sì rí ọba àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ wá lọ́dọ̀ rẹ̀, Arauna sì jáde, ó sì wólẹ̀ níwájú ọba ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀.
Arauna regarda dehors et vit le roi et ses serviteurs qui venaient vers lui. Alors Arauna sortit et se prosterna devant le roi, le visage contre terre.
21 Arauna sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ọba ṣe tọ ìránṣẹ́ rẹ̀ wá?” Dafidi sì dáhùn pé, “Láti ra ibi ìpakà rẹ lọ́wọ́ rẹ, láti tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa, kí ààrùn ìparun lè dá lára àwọn ènìyàn náà.”
Aravna dit: « Pourquoi le roi mon seigneur est-il venu vers son serviteur? » David dit: « Pour acheter ton aire, pour construire un autel à Yahvé, afin que la peste cesse d'affliger le peuple. »
22 Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba ó mú èyí tí ó dára lójú rẹ̀, kí o sì fi í rú ẹbọ, wò ó, màlúù nìyìí láti fi ṣe ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà, àti ohun èlò mìíràn ti màlúù fún igi.
Arauna dit à David: « Que le roi mon seigneur prenne et offre ce qui lui semble bon. Voici le bétail pour l'holocauste, les traîneaux à battre et les jougs des bœufs pour le bois.
23 Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Arauna fi fún ọba, bí ọba.” Arauna sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ ó gba ọrẹ rẹ.”
Tout cela, ô roi, Arauna le donne au roi. » Aravna dit au roi: « Que Yahvé ton Dieu t'accueille. »
24 Ọba sì wí fún Arauna pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n èmi ó rà á ní iye kan lọ́wọ́ rẹ, bí ó ti wù kí ó ṣe; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi èyí tí èmi kò náwó fún, rú ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run mi.” Dafidi sì ra ibi ìpakà náà, àti àwọn màlúù náà ní àádọ́ta ṣékélì fàdákà.
Le roi dit à Arauna: « Non, mais je veux bien te l'acheter à prix d'or. Je ne veux pas offrir à Yahvé mon Dieu des holocaustes qui ne me coûtent rien. » David acheta donc l'aire et les bœufs pour cinquante sicles d'argent.
25 Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ sí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ti ìlàjà. Olúwa sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ fún ilẹ̀ náà, ààrùn náà sì dá kúrò ní Israẹli.
David bâtit là un autel à Yahvé, et il offrit des holocaustes et des sacrifices de prospérité. Il implora Yahvé pour le pays, et la plaie fut retirée d'Israël.

< 2 Samuel 24 >