< 2 Samuel 24 >

1 Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli, ó sì ti Dafidi sí wọn, pé, “Lọ ka iye Israẹli àti Juda!”
Israel nuiah Angraeng palungphuihaih hmai baktiah angqongh; to pongah Setan mah David khaeah, Caeh loe, Israel hoi Judah kaminawk to kroek ah, tiah pahruek.
2 Ọba sì wí fún Joabu olórí ogun, tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ ní ìsinsin yìí sí gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba, kí ẹ sì ka iye àwọn ènìyàn, kí èmi lè mọ iye àwọn ènìyàn náà!”
To pongah siangpahrang mah Joab hoi anih taengah kaom misatuh angraengnawk khaeah, Kami nazetto maw oh o, tiah ka panoek thai hanah, caeh loe, Dan hoi Beersheba khoek to Israel acaengnawk to kroek boih ah, tiah a naa.
3 Joabu sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi kún iye àwọn ènìyàn náà, iyekíye tí ó wù kí wọn jẹ́, ní ọ̀rọ̀ọ̀rún, ojú olúwa mi ọba yóò sì rí i, ṣùgbọ́n èétiṣe tí olúwa mi ọba fi fẹ́ nǹkan yìí?”
Toe Joab mah siangpahrang khaeah, Na Angraeng Sithaw mah na misatuh kaminawk to alet cumvai khoek to pungsak nasoe; to hmuen to ka Angraeng siangpahrang mah hnu nasoe; toe tipongah ka angraeng siangpahrang mah to baktih hmuen sak hanah na koeh loe? tiah a naa.
4 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí ti Joabu, àti ti àwọn olórí ogun. Joabu àti àwọn olórí ogun sì jáde lọ kúrò níwájú ọba, láti lọ ka àwọn ènìyàn Israẹli.
Toe siangpahrang ih lok mah Joab hoi misatuh angraengnawk ih lok to pazawk. To pongah Joab hoi misatuh angraengnawk loe Israel kaminawk kroek hanah anih hmaa hoiah caeh o.
5 Wọ́n sì kọjá odò Jordani, wọ́n sì pàgọ́ ní Aroeri, ní ìhà apá ọ̀tún ìlú tí ó wà láàrín àfonífojì Gadi, àti sí ìhà Jaseri.
Jordan vapui angkat o pacoengah, Gad azawn thungah kaom, Aroer vangpui ni angyae bang ih, Jazer vangpui taengah atai o;
6 Wọ́n sì wá sí Gileadi, àti sí ilé Tatimi Hodṣi; wọ́n sì wá sí Dani Jaani àti yíkákiri sí Sidoni.
Gilead prae hoi Tahtim Hodshi, tiah kawk ih ohhaih ahmuen kangtha prae ah caeh o tathuk; to ahmuen hoiah Daan-Jaan ah caeh o moe, Sidon prae bangah caeh o poe,
7 Wọ́n sì wá sí ìlú olódi Tire, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hifi, àti ti àwọn ará Kenaani, wọ́n sì jáde lọ síhà gúúsù ti Juda, àní sí Beerṣeba.
to pacoengah Tura misa abuephaih im ah caeh o tathuk moe, Hiv kaminawk, Kanaan kaminawk khaeah doeh caeh o; hnukkhuem koekah Judah prae aloih bangah kaom Beersheba vangpui ah caeh o.
8 Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu ní òpin oṣù kẹsànán àti ogúnjọ́.
Prae thung boih ah caeh o moe, khrah takawtto boenghaih, ni pumphaeto naah Jerusalem to phak o.
9 Joabu sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́. Ó sì jẹ́ ogójì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Israẹli, àwọn onídà, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn.
Joab mah siangpahrang khaeah, kaminawk nazetto maw oh, tiah thuih pae; Israel prae thungah sumsen hoi misatuh thaih kami, sang cumvai tazetto oh o moe, Judah prae thungah sang cumvai pangato oh o.
10 Àyà Dafidi sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dafidi sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe, ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jì ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”
David loe misatuh thaih kami to kroek pacoengah, dawnpakhuem moe, Angraeng khaeah, Kai loe paroeai hmuen sakpazae boeh; Aw Angraeng, vaihi na tamna ih zaehaih takhoe ving hanah, tahmenhaih kang hnik; paroeai amthuhaih hoiah hmuen to ka sak moeng boeh, tiah a naa.
11 Dafidi sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gadi wòlíì wá, aríran Dafidi wí pé,
David mah khawnbang khawnthaw angthawk naah, David ih tahmaa, Gad khaeah Angraeng ih lok to angzoh,
12 “Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
caeh loe David khaeah, Angraeng mah, Qoih hanah hmuen thumto kang paek; na nuiah ka sak han ih hmuen thumto thungah maeto qoi ah, tiah a thuih, tiah thui paeh, tiah a naa.
13 Gadi sì tọ Dafidi wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí ààrùn ìparun ọjọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Rò ó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
To pongah Gad loe David khaeah caeh moe, anih khaeah, Na prae thungah saning sarihto thung khokhaahaih maw na koeh? To tih ai boeh loe saning thumto thung na misanawk mah patom moe cawnh? To tih ai boeh loe na prae thungah ni thumto thung kasae nathaih phaksak? Kai patoehkung khaeah kawbangmaw ka thuih pae han, tiah poek het ah loe, na thui ah, tiah a naa.
14 Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí a fi ara wa lé Olúwa ní ọwọ́; nítorí pé àánú rẹ̀ pọ̀; kí ó má sì ṣe fi mí lé ènìyàn ní ọwọ́.”
David mah Gad khaeah, Paroeai palung ka set; anih tahmenhaih loe, len parai pongah, Angraeng ih ban ah kam timh o halat han boeh; minawk ban thungah amtimsak hmah, tiah a naa.
15 Olúwa sì rán ààrùn ìparun sí Israẹli láti òwúrọ̀ títí dé àkókò tí a dá, ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn sì kú nínú àwọn ènìyàn náà láti Dani títí fi dé Beerṣeba.
To pongah akhawnbang hoi atue khaehhaih ni karoek to, Angraeng mah, Israel kaminawk nuiah kasae nathaih to phaksak; Daan hoi Beersheba karoek to kami sang quisarihto duek o.
16 Nígbà tí angẹli náà sì nawọ́ rẹ̀ sí Jerusalẹmu láti pa á run, Olúwa sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì sọ fún angẹli tí ń pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó tó, dá ọwọ́ rẹ dúró wàyí!” Angẹli Olúwa náà sì wà níbi ìpakà Arauna ará Jebusi.
Jerusalem vangpui phraek hanah, a nuiah van kami mah ban phok naah, to patangkhanghaih pongah, Angraeng to dawnpakhuem moe, kami hum van kami khaeah, Khawt boeh! Na ban pakhuem duem lai ah! tiah a naa. To naah Angraeng ih van kami loe Jebus acaeng Araunah ih cang atithaih ahmuen ah oh.
17 Dafidi sì wí fún Olúwa nígbà tí ó rí angẹli tí ń kọlu àwọn ènìyàn pé, “Wò ó, èmi ti ṣẹ̀, èmi sì ti hùwà búburú ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn wọ̀nyí, kín ni wọ́n ha ṣe? Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, kí ó wà lára mi àti ìdílé baba mi.”
Kami hum van kami to David mah hnuk naah, Angraeng khaeah, Khenah, Kai loe ka zae boeh, amthuhaih hoiah zaehaih ka sak moeng boeh; toe hae tuunawk loe timaw sakpazaehaih tawnh o? Na ban loe kaimah hoi kampa ih imthung takoh nuiah krah nasoe, tiah a naa.
18 Gadi sì tọ Dafidi wá ní ọjọ́ náà, ó sì wí fún un pé, “Gòkè, tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.”
To na niah Gad mah David khaeah caeh moe, anih khaeah, Caeh loe, Jebus acaeng Araunah ih cang atithaih ahmuen ah, Angraeng han hmaicam maeto sah ah, tiah a naa.
19 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Gadi, Dafidi sì gòkè lọ bí Olúwa ti pa á ní àṣẹ.
To pongah Angraeng mah Gad khaeah thuih ih lok baktih toengah, David loe caeh tahang.
20 Arauna sì wò, ó sì rí ọba àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ wá lọ́dọ̀ rẹ̀, Arauna sì jáde, ó sì wólẹ̀ níwájú ọba ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀.
Araunah mah a taengah angzo siangpahrang hoi a tamnanawk to hnuk naah, Caeh moe, siangpahrang hmaa ah long ah akuep.
21 Arauna sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ọba ṣe tọ ìránṣẹ́ rẹ̀ wá?” Dafidi sì dáhùn pé, “Láti ra ibi ìpakà rẹ lọ́wọ́ rẹ, láti tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa, kí ààrùn ìparun lè dá lára àwọn ènìyàn náà.”
Araunah mah, Tipongah ka Angraeng siangpahrang loe a tamna khaeah angzoh loe? tiah a naa. David mah, Kaminawk khae hoi nathaih kasae anghmat boih thai hanah, Angraeng han hmaicam sak ka koeh pongah, nang ih cang atithaih ahmuen qan hanah kang zoh, tiah a naa.
22 Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba ó mú èyí tí ó dára lójú rẹ̀, kí o sì fi í rú ẹbọ, wò ó, màlúù nìyìí láti fi ṣe ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà, àti ohun èlò mìíràn ti màlúù fún igi.
Araunah mah David khaeah, Ka angraeng siangpahrang mah a koeh ih hmuen to la nasoe loe, paek nasoe; khenah, angbawnhaih sak hanah maitaw taenawk doeh hae ah oh; angbawnhaih sak hanah cang atithaih thing hoi maitaw hmai pakhaem naah patoh ih thingnawk doeh oh.
23 Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Arauna fi fún ọba, bí ọba.” Arauna sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ ó gba ọrẹ rẹ.”
Aw siangpahrang, Araunah mah siangpahrang hanah hae hmuennawk hae paek boih boeh, tiah a naa. Araunah mah, Na Angraeng Sithaw mah talawk nasoe, tiah a naa.
24 Ọba sì wí fún Arauna pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n èmi ó rà á ní iye kan lọ́wọ́ rẹ, bí ó ti wù kí ó ṣe; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi èyí tí èmi kò náwó fún, rú ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run mi.” Dafidi sì ra ibi ìpakà náà, àti àwọn màlúù náà ní àádọ́ta ṣékélì fàdákà.
Toe siangpahrang mah Araunah khaeah, To tiah na ai ni; atho paek han ih ni ka thuih; atho paek ai ah hak ih hmuen hoiah ka Angraeng Sithaw khaeah, angbawnhaih ka sah mak ai, tiah a naa. To pongah cang atithaih ahmuen hoi maitaw ataenawk to David mah phoisa shekel quipangato hoiah qanh.
25 Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ sí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ti ìlàjà. Olúwa sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ fún ilẹ̀ náà, ààrùn náà sì dá kúrò ní Israẹli.
David mah to ahmuen ah hmaicam to sak moe, hmai angbawnhaih hoi angdaeh angbawnhaih to sak. To naah Angraeng mah prae zuengah lawkthuihaih to pathim pae pongah, Israel nui ih kasae nathaih to anghmat.

< 2 Samuel 24 >