< 2 Samuel 23 >
1 Wọ̀nyí sì ni ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi. “Dafidi ọmọ Jese, àní ọkùnrin tí a ti gbéga, ẹni àmì òróró Ọlọ́run Jakọbu, àti olórin dídùn Israẹli wí pé,
And these [are] [the] words of David last [the] utterance of David [the] son of Jesse and [the] utterance of the man [who] he was raised up height [the] [one] anointed of [the] God of Jacob and [the] pleasant [one] of [the] songs of Israel.
2 “Ẹ̀mí Olúwa sọ ọ̀rọ̀ nípa mi, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ ní ahọ́n mi.
[the] spirit of Yahweh he has spoken by me and speech his [is] on tongue my.
3 Ọlọ́run Israẹli ni, àpáta Israẹli sọ fún mi pé, ‘Ẹnìkan ti ń ṣe alákòóso ènìyàn lódodo, tí ń ṣàkóso ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
He said [the] God of Israel to me he spoke [the] rock of Israel [one who] rules over humankind righteous [one who] rules [the] fear of God.
4 Yóò sì dàbí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nígbà tí oòrùn bá là, òwúrọ̀ tí kò ní ìkùùkuu, nígbà tí koríko tútù bá hù wá láti ilẹ̀ lẹ́yìn òjò.’
And like [the] light of morning [when] it dawns [the] sun morning not clouds from brightness from rain vegetation from [the] earth.
5 “Lóòtítọ́ ilé mi kò rí bẹ́ẹ̀ níwájú Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ó ti bá mi dá májẹ̀mú àìnípẹ̀kun, tí a túnṣe nínú ohun gbogbo, tí a sì pamọ́; nítorí pé gbogbo èyí ni ìgbàlà, àti gbogbo ìfẹ́ mi, ilé mi kò lè ṣe kí ó má dàgbà.
For not thus [is] house? my with God for a covenant of perpetuity he has made to me arranged in everything and preserved for all salvation my and every desire for not will he make grow?
6 Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọ Beliali yóò dàbí ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n tí a ṣá tì, nítorí pé a kò lè fi ọwọ́ kó wọn.
And a worthless person [is] like thorn[s] [which is] chased away all of them for not in a hand people will take.
7 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí yóò tọ́ wọn yóò fi irin àti ọ̀pá ọ̀kọ̀ ṣagbára yí ara rẹ̀ ká; wọ́n ó jóná lúúlúú níbìkan náà.”
And anyone [who] he will touch them he will arm himself iron and [the] wood of a spear and with fire certainly they will be burned at the dwelling.
8 Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn akọni ọkùnrin tí Dafidi ní: Joṣebu-Basṣebeti ará Takemoniti ni olórí àwọn balógun, òun sì ni akọni rẹ̀ tí ó pa ẹgbẹ̀rin ènìyàn lẹ́ẹ̀kan náà.
These [are] [the] names of the warriors who [belonged] to David Josheb-Basshebeth a Tahkemonite - [the] chief of the three he Adino (the Eznite *Q(K)*) on eight hundred [one] slain at a time (one. *Q(K)*)
9 Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Eleasari ọmọ Dodo ará Ahohi, ọ̀kan nínú àwọn alágbára ọkùnrin mẹ́ta ti ó wà pẹ̀lú Dafidi, nígbà tí wọ́n pe àwọn Filistini ní ìjà, àwọn ọkùnrin Israẹli sì ti lọ kúrò.
(And [was] after him *Q(k)*) Eleazar [the] son of (Dodo *Q(K)*) [the] son of Ahoah among three (the warriors *Q(K)*) with David when defied they the Philistines [who] they were gathered there for battle and they went up [the] man of Israel.
10 Òun sì dìde, ó sì kọlu àwọn Filistini títí ọwọ́ fi kún un, ọwọ́ rẹ̀ sì lẹ̀ mọ́ idà; Olúwa sì ṣiṣẹ́ ìgbàlà ńlá lọ́jọ́ náà, àwọn ènìyàn sì padà bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ láti kó ìkógun.
He he arose and he struck down among the Philistines until - for it was weary hand his and it cleaved hand his to the sword and he did Yahweh a deliverance great on the day that and the people they returned after him only to strip.
11 Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Ṣamma ọmọ Agee ará Harari, àwọn Filistini sì kó ara wọn jọ láti piyẹ́, oko kan sì wà níbẹ̀ tí ó kún fun lẹntili, àwọn ọmọ-ogun Israẹli sì sá kúrò níwájú àwọn Filistini.
And [was] after him Shamma [the] son of Agee [the] Hararite and they were gathered [the] Philistines to Lehi and it was there [the] portion of the field full of lentils and the people it fled from before [the] Philistines.
12 Ṣamma sì dúró láàrín méjì ilẹ̀ náà, ó sì gbà á sílẹ̀, ó sì pa àwọn Filistini Olúwa sì ṣe ìgbàlà ńlá.
And he took his stand in [the] middle of the portion and he delivered it and he struck down [the] Philistines and he did Yahweh a deliverance great.
13 Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀, wọ́n sì tọ Dafidi wá ní àkókò ìkórè nínú ihò Adullamu, ọ̀wọ́ àwọn Filistini sì dó sí àfonífojì Refaimu.
And they went down (three *Q(K)*) from the thirty leader[s] and they came to [the] harvest to David to [the] cave of Adullam and a community of Philistines [was] encamped in [the] valley of [the] Rephaites.
14 Dafidi sì wà nínú odi, ibùdó àwọn Filistini sì wà ní Bẹtilẹhẹmu nígbà náà.
And David then [was] in the stronghold and a garrison of Philistines then [was] Beth-lehem.
15 Dafidi sì ń pòǹgbẹ, ó wí báyìí pé, “Ta ni yóò fún mi mu nínú omí kànga tí ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu-bodè.”
And he desired David and he said who? will he give to drink me water from [the] well of Beth-lehem which [is] at the gate.
16 Àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta sì la ogún àwọn Filistini lọ, wọ́n sì fa omi láti inú kànga Bẹtilẹhẹmu wá, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu-bodè, wọ́n sì mú tọ Dafidi wá, òun kò sì fẹ́ mu nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tú u sílẹ̀ fún Olúwa.
And they broke through [the] three the warriors in [the] camp of [the] Philistines and they drew water from [the] well of Beth-lehem which [was] at the gate and they carried [it] and they brought [it] to David and not he was willing to drink them and he poured out them to Yahweh.
17 Òun sì wí pé, “Kí a má rí, Olúwa, tí èmi ó fi ṣe èyí; ṣé èyí ni ẹ̀jẹ̀ àwọn ọkùnrin tí ó lọ tí àwọn tí ẹ̀mí wọn lọ́wọ́?” Nítorí náà òun kò sì fẹ́ mú un. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ṣe.
And he said far be it to me O Yahweh than to do I this [thing] ¿ [the] blood of the men who went with lives their and not he was willing to drink them these [things] they did [the] three the warriors.
18 Abiṣai, arákùnrin Joabu, ọmọ Seruiah, òun náà ni pàtàkì nínú àwọn mẹ́ta. Òun ni ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè sí ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, ó sì pa wọ́n, ó sì ní orúkọ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta.
And Abishai [the] brother of - Joab [the] son of Zeruiah he [was] [the] chief (of the three *Q(K)*) and he he wielded spear his on three hundred [one] slain and [belonged] to him a name among the three.
19 Ọlọ́lá jùlọ ni òun jẹ́ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, ó sì jẹ́ olórí fún wọn, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ìṣáájú.
More than the three ¿ for [was he] honored and he became to them a commander and to the three not he came.
20 Benaiah, ọmọ Jehoiada, ọmọ akọni ọkùnrin kan tí Kabṣeeli, ẹni tí ó pọ̀ ní iṣẹ́ agbára, òun pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu; ó sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ó sì pa kìnnìún kan nínú ihò lákoko òjò-dídì.
And Benaiah [the] son of Jehoiada [was] a son of a man (of strength *Q(K)*) great of deeds from Kabzeel he he struck down [the] two [the] lion-like men of Moab and he he went down and he struck down (the lion *Q(K)*) in [the] midst of the pit on [the] day of the snow.
21 Ó sì pa ará Ejibiti kan, ọkùnrin tí ó dára láti wò, ará Ejibiti náà sì ní ọ̀kọ̀ kan ní ọwọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n Benaiah sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ, pẹ̀lú ọ̀pá ní ọwọ́, ó sì gba ọ̀kọ̀ náà lọ́wọ́ ará Ejibiti náà, ó sì fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ pa á.
And he he struck down a man Egyptian (a man of *Q(K)*) appearance and [was] in [the] hand of the Egyptian a spear and he went down to him with the staff and he seized the spear from [the] hand of the Egyptian and he killed him with own spear his.
22 Nǹkan wọ̀nyí ní Benaiah ọmọ Jehoiada ṣe, ó sì ní orúkọ nínú àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta náà.
These [things] he did Benaiah [the] son of Jehoiada and [belonged] to him a name among three the warriors.
23 Nínú àwọn ọgbọ̀n náà, òun ní ọlá jùlọ, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ti ìṣáájú. Dafidi sì fi í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀.
More than the thirty [he was] honored and to the three not he came and he appointed him David to bodyguard his.
24 Ọ̀kan nínú àwọn ọgbọ̀n náà: Asaheli arákùnrin Joabu sì Jásí Elhanani ọmọ Dodo ti Bẹtilẹhẹmu;
Asah-el [the] brother of Joab [was] among the thirty Elhanan [the] son of Dodo Beth-lehem.
25 Ṣamma ará Haroditi, Elika ará Harodi.
Shammah the Harodite Elika the Harodite.
26 Helesi ará Palti, Ira ọmọ Ikẹsi ará Tekoa;
Helez the Paltite Ira [the] son of Ikkesh the Tekoite.
27 Abieseri ará Anatoti, Sibekai ará Huṣati;
Abiezer the Anathothite Mebunnai the Hushathite.
28 Salmoni ará Ahohi, Maharai ará Netofa;
Zalmon the Ahohite Maharai the Netophathite.
29 Heledi ọmọ Baanah, ará Netofa, Ittai ọmọ Ribai to Gibeah ti àwọn ọmọ Benjamini;
Heleb [the] son of Baanah the Netophathite. Ittai [the] son of Ribai from Gibeah of [the] descendants of Benjamin.
30 Benaiah ará Piratoni, Hiddai ti àfonífojì Gaaṣi,
Benaiah [the] Pirathonite Hiddai from [the] wadis of Gaash.
31 Abi-Alboni ará Arbati, Asmafeti Barhumiti;
Abi-Albon the Arbathite Azmaveth the Barhumite.
32 Eliaba ará Ṣaalboni, àwọn ọmọ Jaṣeni, Jonatani;
Eliahba the Shaalbonite [the] sons of Jashen Jonathan.
33 ọmọ Ṣamma ará Harari, Ahiamu ọmọ Ṣarari ará Harari;
([the] son of *X*) Shammah the Hararite Ahiam [the] son of Sharar the Hararite.
34 Elifeleti ọmọ Ahasbai, ọmọ ará Maakati, Eliamu ọmọ Ahitofeli ará Giloni;
Eliphelet [the] son of Ahasbai [the] son of the Maacathite. Eliam [the] son of Ahithophel the Gilonite.
35 Hesro ará Karmeli, Paarai ará Arba;
(Hezrai *Q(K)*) the Carmelite Paarai the Arbite.
36 Igali ọmọ Natani ti Soba, Bani ará Gadi;
Igal [the] son of Nathan from Zobah. Bani the Gadite.
37 Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beeroti, ẹni tí ń ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah;
Zelek the Ammonite. Naharai the Beerothite ([the] bearer of *Q(K)*) [the] armor of Joab [the] son of Zeruiah.
38 Ira ará Itri, Garebu ará Itri.
Ira the Ithrite Gareb the Ithrite.
39 Uriah ará Hiti. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́tàdínlógójì.
Uriah the Hittite all [were] thirty and seven.