< 2 Samuel 23 >

1 Wọ̀nyí sì ni ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi. “Dafidi ọmọ Jese, àní ọkùnrin tí a ti gbéga, ẹni àmì òróró Ọlọ́run Jakọbu, àti olórin dídùn Israẹli wí pé,
And these [are] the last words of David: “A declaration of David son of Jesse, And a declaration of the man raised up—Concerning the anointed of the God of Jacob, And the sweetness of the songs of Israel:
2 “Ẹ̀mí Olúwa sọ ọ̀rọ̀ nípa mi, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ ní ahọ́n mi.
The Spirit of YHWH has spoken by me, And His word [is] on my tongue.
3 Ọlọ́run Israẹli ni, àpáta Israẹli sọ fún mi pé, ‘Ẹnìkan ti ń ṣe alákòóso ènìyàn lódodo, tí ń ṣàkóso ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
He said—the God of Israel—to me, He spoke—the Rock of Israel: He who is ruling over man [is] righteous, He is ruling in the fear of God.
4 Yóò sì dàbí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nígbà tí oòrùn bá là, òwúrọ̀ tí kò ní ìkùùkuu, nígbà tí koríko tútù bá hù wá láti ilẹ̀ lẹ́yìn òjò.’
And he rises as the light of morning, A morning sun [with] no clouds! By the shining, by the rain, Tender grass of the earth!
5 “Lóòtítọ́ ilé mi kò rí bẹ́ẹ̀ níwájú Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ó ti bá mi dá májẹ̀mú àìnípẹ̀kun, tí a túnṣe nínú ohun gbogbo, tí a sì pamọ́; nítorí pé gbogbo èyí ni ìgbàlà, àti gbogbo ìfẹ́ mi, ilé mi kò lè ṣe kí ó má dàgbà.
For though my house [is] not so with God; So He made a perpetual covenant with me, Arranged in all things, and kept; For all my salvation, and all desire, For He has not caused [it] to spring up.
6 Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọ Beliali yóò dàbí ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n tí a ṣá tì, nítorí pé a kò lè fi ọwọ́ kó wọn.
As for the worthless—All of them [are] driven away as a thorn, For they are not taken away by hand;
7 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí yóò tọ́ wọn yóò fi irin àti ọ̀pá ọ̀kọ̀ ṣagbára yí ara rẹ̀ ká; wọ́n ó jóná lúúlúú níbìkan náà.”
And the man who comes against them Is filled with iron and the staff of a spear, And they are utterly burned with fire In the cessation.”
8 Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn akọni ọkùnrin tí Dafidi ní: Joṣebu-Basṣebeti ará Takemoniti ni olórí àwọn balógun, òun sì ni akọni rẹ̀ tí ó pa ẹgbẹ̀rin ènìyàn lẹ́ẹ̀kan náà.
These [are] the names of the mighty ones whom David has: sitting in the seat [is] the Tachmonite, head of the captains—he [is] Adino, who hardened himself against eight hundred—wounded at one time.
9 Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Eleasari ọmọ Dodo ará Ahohi, ọ̀kan nínú àwọn alágbára ọkùnrin mẹ́ta ti ó wà pẹ̀lú Dafidi, nígbà tí wọ́n pe àwọn Filistini ní ìjà, àwọn ọkùnrin Israẹli sì ti lọ kúrò.
And after him [is] Eleazar son of Dodo, son of Ahohi, of the three mighty men with David; in their exposing themselves among the Philistines—they have been gathered there to battle, and the men of Israel go up—
10 Òun sì dìde, ó sì kọlu àwọn Filistini títí ọwọ́ fi kún un, ọwọ́ rẹ̀ sì lẹ̀ mọ́ idà; Olúwa sì ṣiṣẹ́ ìgbàlà ńlá lọ́jọ́ náà, àwọn ènìyàn sì padà bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ láti kó ìkógun.
he has arisen, and strikes among the Philistines until his hand has been weary, and his hand cleaves to the sword, and YHWH works a great salvation on that day, and the people turn back after him only to strip off.
11 Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Ṣamma ọmọ Agee ará Harari, àwọn Filistini sì kó ara wọn jọ láti piyẹ́, oko kan sì wà níbẹ̀ tí ó kún fun lẹntili, àwọn ọmọ-ogun Israẹli sì sá kúrò níwájú àwọn Filistini.
And after him [is] Shammah son of Agee the Hararite, and the Philistines are gathered into a company, and there is a portion of the field full of lentils there, and the people have fled from the presence of the Philistines,
12 Ṣamma sì dúró láàrín méjì ilẹ̀ náà, ó sì gbà á sílẹ̀, ó sì pa àwọn Filistini Olúwa sì ṣe ìgbàlà ńlá.
and he stations himself in the midst of the portion, and delivers it, and strikes the Philistines, and YHWH works a great salvation.
13 Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀, wọ́n sì tọ Dafidi wá ní àkókò ìkórè nínú ihò Adullamu, ọ̀wọ́ àwọn Filistini sì dó sí àfonífojì Refaimu.
And three of the thirty heads go down and come to the harvest, to David, to the cave of Adullam, and the company of the Philistines are encamping in the Valley of Rephaim,
14 Dafidi sì wà nínú odi, ibùdó àwọn Filistini sì wà ní Bẹtilẹhẹmu nígbà náà.
and David [is] then in a fortress, and the station of the Philistines [is] then in Beth-Lehem,
15 Dafidi sì ń pòǹgbẹ, ó wí báyìí pé, “Ta ni yóò fún mi mu nínú omí kànga tí ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu-bodè.”
and David longs and says, “Who gives me a drink of the water of the well of Beth-Lehem, which [is] by the gate?”
16 Àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta sì la ogún àwọn Filistini lọ, wọ́n sì fa omi láti inú kànga Bẹtilẹhẹmu wá, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu-bodè, wọ́n sì mú tọ Dafidi wá, òun kò sì fẹ́ mu nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tú u sílẹ̀ fún Olúwa.
And the three mighty ones cleave through the camp of the Philistines, and draw water out of the well of Beth-Lehem, which [is] by the gate, and take [it] up, and bring [it] to David; and he was not willing to drink it, and pours it out to YHWH,
17 Òun sì wí pé, “Kí a má rí, Olúwa, tí èmi ó fi ṣe èyí; ṣé èyí ni ẹ̀jẹ̀ àwọn ọkùnrin tí ó lọ tí àwọn tí ẹ̀mí wọn lọ́wọ́?” Nítorí náà òun kò sì fẹ́ mú un. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ṣe.
and says, “Far be it from me, O YHWH, to do this; is it the blood of the men who are going with their lives?” And he was not willing to drink it; the three mighty ones did these [things].
18 Abiṣai, arákùnrin Joabu, ọmọ Seruiah, òun náà ni pàtàkì nínú àwọn mẹ́ta. Òun ni ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè sí ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, ó sì pa wọ́n, ó sì ní orúkọ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta.
And Abishai brother of Joab, son of Zeruiah, he [is] head of three, and he is lifting up his spear against three hundred—wounded, and he has a name among three.
19 Ọlọ́lá jùlọ ni òun jẹ́ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, ó sì jẹ́ olórí fún wọn, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ìṣáájú.
Is he not the honored of the three? And he becomes their head; and he has not come to the [first] three.
20 Benaiah, ọmọ Jehoiada, ọmọ akọni ọkùnrin kan tí Kabṣeeli, ẹni tí ó pọ̀ ní iṣẹ́ agbára, òun pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu; ó sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ó sì pa kìnnìún kan nínú ihò lákoko òjò-dídì.
And Benaiah son of Jehoiada (son of a man of valor, great in deeds from Kabzeel), has struck two lion-like men of Moab, and he has gone down and struck the lion in the midst of the pit in a day of snow.
21 Ó sì pa ará Ejibiti kan, ọkùnrin tí ó dára láti wò, ará Ejibiti náà sì ní ọ̀kọ̀ kan ní ọwọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n Benaiah sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ, pẹ̀lú ọ̀pá ní ọwọ́, ó sì gba ọ̀kọ̀ náà lọ́wọ́ ará Ejibiti náà, ó sì fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ pa á.
And he has struck the Egyptian man, a man of appearance, and a spear [is] in the hand of the Egyptian, and he goes down to him with a rod, and takes the spear violently away out of the hand of the Egyptian, and slays him with his own spear.
22 Nǹkan wọ̀nyí ní Benaiah ọmọ Jehoiada ṣe, ó sì ní orúkọ nínú àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta náà.
Benaiah son of Jehoiada has done these [things], and has a name among the three mighty ones.
23 Nínú àwọn ọgbọ̀n náà, òun ní ọlá jùlọ, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ti ìṣáájú. Dafidi sì fi í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀.
He is honored more than the thirty, but he did not come to the three; and David sets him over his guard.
24 Ọ̀kan nínú àwọn ọgbọ̀n náà: Asaheli arákùnrin Joabu sì Jásí Elhanani ọmọ Dodo ti Bẹtilẹhẹmu;
Asahel brother of Joab [is] of the thirty; Elhanan son of Dodo of Beth-Lehem,
25 Ṣamma ará Haroditi, Elika ará Harodi.
Shammah the Harodite, Elika the Harodite,
26 Helesi ará Palti, Ira ọmọ Ikẹsi ará Tekoa;
Helez the Paltite, Ira son of Ikkesh the Tekoite,
27 Abieseri ará Anatoti, Sibekai ará Huṣati;
Abiezer the Annethothite, Mebunnai the Hushathite,
28 Salmoni ará Ahohi, Maharai ará Netofa;
Zalmon the Ahohite, Maharai the Netophathite,
29 Heledi ọmọ Baanah, ará Netofa, Ittai ọmọ Ribai to Gibeah ti àwọn ọmọ Benjamini;
Heleb son of Baanah the Netophathite, Ittai son of Ribai from Gibeah of the sons of Benjamin,
30 Benaiah ará Piratoni, Hiddai ti àfonífojì Gaaṣi,
Benaiah the Pirathonite, Hiddai of the brooks of Gaash,
31 Abi-Alboni ará Arbati, Asmafeti Barhumiti;
Abi-Albon the Arbathite, Azmaveth the Barhumite,
32 Eliaba ará Ṣaalboni, àwọn ọmọ Jaṣeni, Jonatani;
Eliahba the Shaalbonite, of the sons of Jashen, Jonathan,
33 ọmọ Ṣamma ará Harari, Ahiamu ọmọ Ṣarari ará Harari;
Shammah the Hararite, Ahiam son of Sharar the Hararite,
34 Elifeleti ọmọ Ahasbai, ọmọ ará Maakati, Eliamu ọmọ Ahitofeli ará Giloni;
Eliphelet son of Ahasbai, son of the Maachathite, Eliam son of Ahithophel the Gilonite,
35 Hesro ará Karmeli, Paarai ará Arba;
Hezrai the Carmelite, Paarai the Arbite,
36 Igali ọmọ Natani ti Soba, Bani ará Gadi;
Igal son of Nathan from Zobah, Bani the Gadite,
37 Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beeroti, ẹni tí ń ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah;
Zelek the Ammonite, Naharai the Beerothite, bearer of the weapons of Joab son of Zeruiah,
38 Ira ará Itri, Garebu ará Itri.
Ira the Ithrite, Gareb the Ithrite,
39 Uriah ará Hiti. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́tàdínlógójì.
Uriah the Hittite: thirty-seven in all.

< 2 Samuel 23 >