< 2 Samuel 22 >

1 Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu.
I izgovori David Gospodu rijeèi ove pjesme, kad ga izbavi Gospod iz ruku svijeh neprijatelja njegovijeh i iz ruke Saulove;
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;
I reèe: Gospod je moja stijena i grad moj i izbavitelj moj.
3 Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò, àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi. Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi; ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.
Bog je stijena moja, u njega æu se uzdati, štit moj i rog spasenja mojega, zaklon moj i utoèište moje, spasitelj moj, koji me izbavlja od sile.
4 “Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn, ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
Prizivljem Gospoda, kojega valja hvaliti, i opraštam se neprijatelja svojih.
5 Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri; tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
Jer obuzeše me smrtni bolovi, potoci nevaljalijeh ljudi uplašiše me.
6 Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri; ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí. (Sheol h7585)
Bolovi grobni opkoliše me, stegoše me zamke smrtne. (Sheol h7585)
7 “Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa, èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi. Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀ igbe mí wọ etí rẹ̀.
U tjeskobi svojoj prizvah Gospoda, i k Bogu svojemu povikah, on èu iz dvora svojega glas moj, i vika moja doðe mu do ušiju.
8 Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì; ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì, ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
Zatrese se i pokoleba se zemlja, temelji nebesima zadrmaše se i pomjeriše se, jer se on razgnjevi.
9 Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá, iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá, ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
Podiže se dim iz nozdara njegovijeh i iz usta njegovijeh oganj koji proždire, živo ugljevlje otskakaše od njega.
10 Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀; òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
Savi nebesa i siðe; a mrak bijaše pod nogama njegovijem.
11 Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò, a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
I sjede na heruvima i poletje, i pokaza se na krilima vjetrnijem.
12 Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi, àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.
Od mraka naèini oko sebe šator, od mraènijeh voda, oblaka vazdušnijeh.
13 Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀ ẹ̀yín iná ràn.
Od sijevanja pred njim goraše živo ugljevlje.
14 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá, Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.
Zagrmje s nebesa Gospod, i višnji pusti glas svoj.
15 Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká; ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.
Pusti strijele svoje, i razmetnu ih; munje, i razasu ih.
16 Ìṣàn ibú òkun sì fi ara hàn, ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn, nípa ìbáwí Olúwa, nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.
Pokazaše se dubine morske, i otkriše se temelji vasiljenoj od prijetnje Gospodnje, od dihanja duha iz nozdara njegovijeh.
17 “Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi; ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.
Tada pruži s visine ruku i uhvati me, izvuèe me iz vode velike.
18 Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára, lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.
Izbavi me od neprijatelja mojega silnoga i od mojih nenavidnika, kad bijahu jaèi od mene.
19 Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi, ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.
Ustaše na me u dan nevolje moje, ali mi Gospod bi potpora.
20 Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá, ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.
I izvede me na prostrano mjesto, izbavi me, jer sam mu mio.
21 “Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.
Dade mi Gospod po pravdi mojoj, po èistoti ruku mojih dariva me.
22 Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́, èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
Jer se držah putova Gospodnjih, i ne odmetnuh se Boga svojega.
23 Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi; àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
Nego su svi zakoni njegovi preda mnom, i zapovijesti njegovijeh ne uklanjam od sebe.
24 Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í, èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
I bih mu vjeran, i èuvah se od bezakonja svojega.
25 Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.
Dade mi Gospod po pravdi mojoj, po èistoti mojoj pred oèima njegovima.
26 “Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú, àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.
Sa svetima postupaš sveto, s èovjekom vjernijem vjerno;
27 Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun; àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.
S èistijem èisto postupaš, a s nevaljalijem nasuprot njemu.
28 Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà; ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Jer pomažeš narodu nevoljnom, a na ponosite spuštaš oèi svoje i ponižavaš ih.
29 Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa; Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.
Ti si vidjelo moje, Gospode, i Gospod prosvjetljuje tamu moju.
30 Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá; nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.
S tobom razbijam vojsku, s Bogom svojim skaèem preko zida.
31 “Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀; ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò. Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
Put je Božji vjeran, rijeè Gospodnja èista. On je štit svjema koji se uzdaju u nj.
32 Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa? Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.
Jer ko je Bog osim Gospoda? i ko je stijena osim Boga našega?
33 Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára, ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.
Bog je krjepost moja i sila moja, i èini da mi je put bez mane.
34 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín; ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.
Daje mi noge kao u jelena, i na visine moje stavlja me.
35 Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà; tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.
Uèi ruke moje boju, te lome luk mjedeni mišice moje.
36 Ìwọ sì ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ̀; ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.
Ti mi daješ štit spasenja svojega, i milost tvoja èini me velika.
37 Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi; tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.
Širiš korake moje poda mnom, te se ne omièu gležnji moji.
38 “Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n, èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.
Tjeram neprijatelje svoje, i potirem ih, i ne vraæam se dokle ih ne istrijebim.
39 Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn, wọn kò sì le dìde mọ́, wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.
I istrebljujem ih, i obaram ih da ne mogu ustati, nego padaju pod noge moje.
40 Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà; àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.
Jer me ti opasuješ snagom za boj: koji ustanu na me, obaraš ih poda me.
41 Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi, èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
Neprijatelja mojih pleæi ti mi obraæaš, i potirem nenavidnike svoje.
42 Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n; wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.
Obziru se, ali nema pomagaèa: vièu ka Gospodu, ali ih ne sluša.
43 Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.
Satirem ih kao prah zemaljski, kao blato po ulicama gazim ih i razmeæem.
44 “Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi, ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè. Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.
Ti me izbavljaš od bune naroda mojega, èuvaš me da sam glava narodima; narod kojega ne poznavah služi mi.
45 Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi; bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.
Tuðini laskaju mi, èujuæi pokoravaju mi se.
46 Àyà yóò pá àwọn àlejò, wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.
Tuðini blijede, dršæu u gradovima svojim.
47 “Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi! Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.
Živ je Gospod, i da je blagoslovena stijena moja. Da se uzvisi Bog, stijena spasenja mojega.
48 Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi, àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.
Bog, koji mi daje osvetu, i pokorava mi narode,
49 Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi. Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ; ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.
Koji me izvodi iz neprijatelja mojih, i podiže me nad one koji ustaju na me, i od èovjeka žestoka izbavlja me.
50 Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa, láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè, èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.
Toga radi hvalim te, Gospode, po narodima, i pojem imenu tvojemu,
51 “Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀; ó sì fi àánú hàn fún ẹni àmì òróró rẹ̀, fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”
Koji slavno izbavljaš cara svojega, i èiniš milost pomazaniku svojemu Davidu i sjemenu njegovu dovijeka.

< 2 Samuel 22 >