< 2 Samuel 22 >

1 Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu.
I mówił Dawid Panu słowa tej pieśni w on dzień, gdy go wybawił Pan z rąk wszystkich nieprzyjaciół jego i z ręki Saulowej.
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;
I rzekł: Pan opoka moja i twierdza moja, i wybawiciel mój ze mną.
3 Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò, àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi. Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi; ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.
Bóg, skała moja, w nim będę ufał, tarcz moja, róg zbawienia mego, podwyższenie moje, i ucieczka moja, zbawiciel mój, który mię od gwałtu wybawia.
4 “Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn, ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
Wzywałem Pana chwały godnego, a od nieprzyjaciół moich byłem wybawiony.
5 Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri; tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
Albowiem ogarnęły mię były boleści śmierci, potoki niezbożnych przestraszyły mię.
6 Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri; ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí. (Sheol h7585)
Boleści grobu ogarnęły mię, zachwyciły mię sidła śmierci. (Sheol h7585)
7 “Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa, èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi. Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀ igbe mí wọ etí rẹ̀.
W utrapieniu mojem wzywałem Pana, a do Boga mego wołałem, i wysłuchał z kościoła swego głos mój, a wołanie moje przyszło do uszów jego.
8 Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì; ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì, ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
Tedy się wzruszyła, a zadrżała ziemia, a fundamenty nieba zatrząsnęły, i wzruszyły się dla gniewu jego.
9 Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá, iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá, ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
Wystąpił dym z nózdrz jego, a ogień z ust jego pożerający; węgle rozpaliły się od niego.
10 Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀; òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
Nakłonił niebios i zstąpił, a ciemność była pod nogami jego.
11 Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò, a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
I jeździł na Cherubinach, i latał, i widzian jest na skrzydłach wiatrowych.
12 Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi, àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.
Położył ciemność około siebie miasto przybytku, zgromadzenie wód z obłoki niebieskimi.
13 Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀ ẹ̀yín iná ràn.
Od jasności oblicza jego rozpaliły się węgle ogniste.
14 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá, Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.
Zagrzmiał Pan z nieba, a najwyższy wydał głos swój.
15 Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká; ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.
Wypuścił i strzały, a rozproszył je, i błyskawicą potarł je.
16 Ìṣàn ibú òkun sì fi ara hàn, ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn, nípa ìbáwí Olúwa, nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.
I okazały się głębokości morskie, a odkryły się grunty świata na fukanie Pańskie, na tchnienie Ducha z nózdrz jego.
17 “Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi; ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.
Posławszy z wysokości, przyjął mię, wyrwał mię z wód wielkich.
18 Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára, lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.
Wybawił mię od nieprzyjaciela mego potężnego, od tych, którzy mię mieli w nienawiści, choć byli mocniejszymi nad mię.
19 Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi, ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.
Uprzedzili mię w dzień utrapienia mego; ale Pan był podporą moją.
20 Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá, ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.
I wywiódł mię na przestrzeństwo; wybawił mię; bo mię sobie upodobał.
21 “Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.
Oddał mi Pan według sprawiedliwości mojej, według czystości rąk moich oddał mi,
22 Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́, èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
Gdyżem strzegł dróg Pańskich, anim niezbożnie nie odstawał od Boga mego.
23 Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi; àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
Albowiem wszystkie sądy jego są przed obliczem mojem i ustawy jego, nie odstąpiłem od nich.
24 Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í, èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
A będąc doskonały przed nim, wystrzegałem się nieprawości mojej.
25 Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.
Przetoż oddał mi Pan według sprawiedliwości mojej, według czystości mojej przed oblicznością oczu swych.
26 “Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú, àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.
Z miłosiernym miłosiernie postępujesz, z mężem doskonałym doskonałym jesteś.
27 Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun; àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.
Z czystym czysty jesteś, a z przewrotnym surowie się obchodzisz.
28 Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà; ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Ale wybawiasz lud ubogi, a oczy twoje przed wyniosłymi opuszczasz.
29 Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa; Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.
Tyś zaiste pochodnią moją, o Panie, a Pan oświeci ciemności moje.
30 Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá; nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.
Bo w tobie przebiegłem wojsko, w Bogu moim przekroczyłem mur.
31 “Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀; ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò. Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
Droga Boża jest doskonała, wyrok Pański nader czysty, tarczą jest wszystkim, którzy w nim ufają.
32 Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa? Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.
Albowiem któż jest Bogiem oprócz Pana? a kto opoką oprócz Boga naszego?
33 Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára, ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.
Bóg jest mocą moją w wojsku, on czyni doskonałą drogę moję.
34 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín; ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.
Równa nogi moje z jeleniemi, na wysokich miejscach moich stawia mię.
35 Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà; tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.
Ćwiczy ręce me do boju, tak że kruszę łuk miedziany ramiony swemi.
36 Ìwọ sì ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ̀; ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.
Albowiem dałeś mi tarcz zbawienia mego, a w cichości twojej rozmnożyłeś mię.
37 Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi; tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.
Rozszerzyłeś kroki moje podemną, tak iż się nie zachwiały kostki moje.
38 “Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n, èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.
Goniłem nieprzyjacioły moje, i wytraciłem je, a nie wróciłem się, ażem je wyplenił.
39 Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn, wọn kò sì le dìde mọ́, wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.
I wyniszczyłem je, i poprzebijałem je, tak iż nie powstaną: upadli pod nogami mojemi.
40 Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà; àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.
Tyś mię przepasał mocą ku bitwie, a powaliłeś pod mię powstające przeciwko mnie.
41 Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi, èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
Nadto podałeś mi szyję nieprzyjaciół moich, którzy mię mieli w nienawiści, i wykorzeniłem je.
42 Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n; wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.
Poglądali, ale nie był wybawiciel; wołali na Pana, ale ich nie wysłuchał.
43 Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.
I potarłem je jako proch ziemi, jako błoto na ulicach podeptawszy je, rozmiotałem je.
44 “Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi, ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè. Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.
Tyś mię od sporu ludu mego wyrwał; zachowałeś mię, abym był głową narodów; lud, któregom nie znał, służy mi.
45 Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi; bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.
Synowie obcy kłamali mną, a skoro usłyszeli, byli mi posłuszni.
46 Àyà yóò pá àwọn àlejò, wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.
Synowie obcy opadali, a drżeli i w zamknieniu swem.
47 “Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi! Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.
Żyje Pan, i błogosławiona skała moja; niechże będzie wywyższony Bóg, opoka zbawienia mego.
48 Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi, àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.
Bóg jest, który mi dawa pomsty, a podbija narody pod mię.
49 Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi. Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ; ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.
Który mię wywodzi od nieprzyjaciół moich, a nad tymi, którzy powstają przeciwko mnie, wywyższasz mię, od człowieka niepobożnego wybawiasz mię.
50 Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa, láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè, èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.
Przetoż będę cię wyznawał Panie między narodami; a imieniowi twemu śpiewać będę.
51 “Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀; ó sì fi àánú hàn fún ẹni àmì òróró rẹ̀, fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”
On jest wieżą zbawienia króla swego, a czyniący miłosierdzie nad pomazańcem swoim Dawidem, i nad nasieniem jego aż na wieki.

< 2 Samuel 22 >