< 2 Samuel 22 >
1 Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu.
UDavida wasekhuluma eNkosini amazwi alelihubo mhla iNkosi imkhulula esandleni sezitha zakhe zonke lesandleni sikaSawuli.
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;
Wasesithi: INkosi ilidwala lami, lenqaba yami, lomkhululi wami;
3 Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò, àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi. Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi; ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.
uNkulunkulu wedwala lami, ngizaphephela kuye, isihlangu sami, lophondo losindiso lwami, inqaba yami ephakemeyo, lesiphephelo sami, umsindisi wami; ungisindisile odlakeleni.
4 “Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn, ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
Ngizabiza iNkosi edumisekayo, ngakho ngizasindiswa ezitheni zami.
5 Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri; tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
Ngoba izinsizi zokufa zingizingelezele, lezikhukhula zobubi zangethusa.
6 Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri; ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí. (Sheol )
Izibopho zesihogo zangigombolozela, imijibila yokufa yayiphambi kwami. (Sheol )
7 “Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa, èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi. Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀ igbe mí wọ etí rẹ̀.
Ekuhluphekeni kwami ngayibiza iNkosi, ngakhala kuNkulunkulu wami; waselizwa ilizwi lami esethempelini lakhe, lokukhala kwami kwafinyelela endlebeni zakhe.
8 Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì; ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì, ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
Khona umhlaba wazamazama, wanyikinyeka, izisekelo zamazulu zaqhaqhazela, zazamazama, ngoba wayethukuthele.
9 Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá, iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá, ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
Kwenyuka intuthu emakhaleni akhe, lomlilo ophuma emlonyeni wakhe waqothula; amalahle avuthiswa yiwo.
10 Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀; òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
Wasekhothamisa amazulu, wehlela phansi; lomnyama onzima wawungaphansi kwenyawo zakhe.
11 Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò, a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
Wasegada ikherubhi, waphapha, wabonakala phezu kwempiko zomoya.
12 Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi, àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.
Wasemisa umnyama waba ngamadumba inhlangothi zonke zakhe, lokuqoqana kwamanzi, amayezi amnyama omkhathi.
13 Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀ ẹ̀yín iná ràn.
Ekukhazimuleni okuphambi kwakhe kwavuthiswa amalahle omlilo.
14 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá, Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.
INkosi yaduma isemazulwini, loPhezukonke walikhupha ilizwi lakhe.
15 Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká; ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.
Yathuma imitshoko, yabachitha; imibane, yabaphaphathekisa.
16 Ìṣàn ibú òkun sì fi ara hàn, ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn, nípa ìbáwí Olúwa, nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.
Khona kwabonakala imisele yolwandle, kwembulwa izisekelo zomhlaba, ekusoleni kweNkosi, ekuvutheleni komoya wamakhala ayo.
17 “Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi; ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.
Iphezulu yathuma, yangibamba, yangenyula emanzini amanengi.
18 Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára, lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.
Yangophula esitheni sami esilamandla, kwabangizondayo, ngoba babelamandla kulami.
19 Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi, ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.
Babephambi kwami osukwini lwenhlupheko yami, kodwa iNkosi yaba yisisekelo sami.
20 Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá, ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.
Yangikhuphela endaweni ebanzi, yangikhulula, ngoba yayithokoza ngami.
21 “Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.
INkosi yangivuza njengokulunga kwami, yangibuyisela njengokuhlanzeka kwezandla zami.
22 Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́, èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
Ngoba ngizilondolozile indlela zeNkosi, kangisukanga kuNkulunkulu wami ngenkohlakalo.
23 Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi; àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
Ngoba zonke izahlulelo zayo zaziphambi kwami, lezimiso zayo, kangiphambukanga kuzo.
24 Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í, èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Njalo ngangiqondile phambi kwayo, ngizinqandile ebubini bami.
25 Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.
Ngakho iNkosi ingibuyisele njengokulunga kwami, njengokuhlanzeka kwami phambi kwamehlo ayo.
26 “Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú, àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.
Kolesihawu uzaziveza ulesihawu; koqotho uzaziveza uqotho;
27 Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun; àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.
kohlanzekileyo uzaziveza uhlanzekile; lakophambukileyo uzaziveza uphambukile.
28 Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà; ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Labantu abahlutshwayo uzabasindisa, kodwa amehlo akho aphezu kwabaziphakamisayo, uzabehlisela phansi.
29 Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa; Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.
Ngoba uyisibane sami, Nkosi, iNkosi izakhanyisa-ke ubumnyama bami.
30 Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá; nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.
Ngoba ngawe ngigijimile ngadabula phakathi kwebutho, ngoNkulunkulu wami ngeqe umthangala.
31 “Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀; ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò. Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
UNkulunkulu; indlela yakhe iphelele; ilizwi leNkosi lihloliwe; uyisihlangu kubo bonke abaphephela kuye.
32 Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa? Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.
Ngoba ngubani onguNkulunkulu ngaphandle kweNkosi? Njalo ngubani olidwala ngaphandle kukaNkulunkulu wethu?
33 Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára, ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.
UNkulunkulu uyinqaba yami lamandla, owenza indlela yami iphelele.
34 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín; ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.
Owenza inyawo zami zibe njengezezimpala, wangimisa ezingqongeni zami.
35 Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà; tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.
Ofundisela izandla zami impi, ukuze idandili lethusi ligotshiswe zingalo zami.
36 Ìwọ sì ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ̀; ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.
Unginikile lesihlangu sosindiso lwakho, lokuzithoba kwakho kungikhulisile.
37 Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi; tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.
Wenze laba banzi inyathelo lami ngaphansi kwami, ukuze inqagala zami zingatsheleli.
38 “Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n, èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.
Ngixotshene lezitha zami ngazibhubhisa, kangibuyanga ngaze ngaziqeda.
39 Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn, wọn kò sì le dìde mọ́, wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.
Ngaziqeda, ngazigwaza, ukuze zingavuki; kodwa zawa ngaphansi kwenyawo zami.
40 Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà; àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.
Ngoba ungibhincise amandla kusenzelwa impi, wabakhothamisela phansi kwami abangivukelayo.
41 Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi, èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
Unginike intamo yezitha zami, labo abangizondayo ngababhubhisa.
42 Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n; wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.
Bakhangela, kodwa engekho umsindisi; eNkosini, kodwa kayibaphendulanga.
43 Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.
Ngasengibacholisisa njengothuli lomhlaba, ngabagxoba njengodaka lwezitalada, ngabatsahaza.
44 “Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi, ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè. Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.
Wasungikhulula ekuphikiseni kwabantu bami, wangigcina ngiyinhloko yezizwe; abantu engangingabazi bangisebenzela.
45 Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi; bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.
Abezizweni bazazehlisela phansi kimi; bangenela ukuzwa ngendlebe bazangilalela.
46 Àyà yóò pá àwọn àlejò, wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.
Abezizweni bazabuna, baphume ezinqabeni zabo bethuthumela.
47 “Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi! Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.
INkosi iyaphila; njalo kalibusiswe idwala lami, kaphakanyiswe uNkulunkulu, idwala losindiso lwami;
48 Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi, àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.
uNkulunkulu onginika impindiselo, lowehlisela izizwe ngaphansi kwami;
49 Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi. Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ; ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.
longikhupha ezitheni zami; laphezu kwabangivukelayo wena wangiphakamisa; lemuntwini wodlakela wangikhulula.
50 Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa, láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè, èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.
Ngenxa yalokhu ngizakudumisa, Nkosi, phakathi kwezizwe, ngihubele ibizo lakho indumiso.
51 “Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀; ó sì fi àánú hàn fún ẹni àmì òróró rẹ̀, fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”
Ingumphotshongo wosindiso kuyo inkosi yayo, isenzela ogcotshiweyo wayo umusa, kuDavida, lenzalweni yakhe kuze kube nininini.