< 2 Samuel 22 >
1 Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu.
Après cela David prononça à l'Eternel les paroles de ce cantique, le jour que l'Eternel l'eut délivré de la main de tous ses ennemis, et surtout de la main de Saül.
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;
Il dit donc: L'Eternel est ma roche, et ma forteresse, et mon libérateur.
3 Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò, àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi. Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi; ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.
Dieu est mon rocher, je me retirerai vers lui; il est mon bouclier et la corne de mon salut; il est ma haute retraite et mon refuge; mon Sauveur, tu me garantis de la violence.
4 “Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn, ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
Je crierai à l'Eternel, lequel on doit louer, et je serai délivré de mes ennemis.
5 Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri; tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
Car les angoisses de la mort m'avaient environné; les torrents des méchants m'avaient troublé;
6 Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri; ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí. (Sheol )
Les cordeaux du sépulcre m'avaient entouré; les filets de la mort m'avaient surpris. (Sheol )
7 “Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa, èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi. Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀ igbe mí wọ etí rẹ̀.
Quand j'ai été dans l'adversité j'ai crié à l'Eternel; j'ai, [dis-je], crié à mon Dieu, et il a entendu ma voix de son palais, et mon cri est parvenu à ses oreilles.
8 Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì; ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì, ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
Alors la terre fut ébranlée et trembla, les fondements des cieux croulèrent et furent ébranlés, parce qu'il était irrité.
9 Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá, iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá, ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
Une fumée montait de ses narines, et de sa bouche sortait un feu dévorant; les charbons de feu en étaient embrasés.
10 Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀; òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
Il baissa donc les cieux, et descendit, ayant [une] obscurité sous ses pieds.
11 Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò, a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
Et il était monté sur un Chérubin, et volait; et il parut sur les ailes du vent.
12 Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi, àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.
Et il mit tout autour de soi les ténèbres pour tabernacle; [savoir], les eaux amoncelées qui sont les nuées de l'air.
13 Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀ ẹ̀yín iná ràn.
Des charbons de feu étaient embrasés de la splendeur qui était au devant de lui.
14 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá, Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.
L'Eternel tonna des cieux, et le Souverain fit retentir sa voix.
15 Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká; ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.
Il tira ses flèches, et écarta [mes ennemis]; il [fit briller] l'éclair; et les mit en déroute.
16 Ìṣàn ibú òkun sì fi ara hàn, ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn, nípa ìbáwí Olúwa, nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.
Alors le fond de la mer parut, [et] les fondements de la terre habitable furent découverts par l'Eternel qui les tançait, [et] par le souffle du vent de ses narines.
17 “Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi; ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.
Il étendit [la main] d'en haut, [et] m'enleva, [et] me tira des grosses eaux.
18 Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára, lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.
Il me délivra de mon ennemi puissant, [et] de ceux qui me haïssaient, car ils étaient plus forts que moi.
19 Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi, ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.
Ils m'avaient devancé au jour de ma calamité; mais l'Eternel fut mon appui.
20 Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá, ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.
Il m'a mis au large, il m'a délivré, parce qu'il a pris son plaisir en moi.
21 “Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.
L'Eternel m'a rendu selon ma justice; il m'a rendu selon la pureté de mes mains.
22 Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́, èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
Parce que j'ai tenu le chemin de l'Eternel, et que je ne me suis point détourné de mon Dieu.
23 Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi; àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
Car j'ai eu devant moi tous ses droits, et je ne me suis point détourné de ses ordonnances.
24 Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í, èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Et j'ai été intègre envers lui, et je me suis donné garde de mon iniquité.
25 Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.
L'Eternel donc m'a rendu selon ma justice, [et] selon ma pureté, qui a été devant ses yeux.
26 “Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú, àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.
Envers celui qui use de gratuité, tu uses de gratuité; et envers l'homme intègre tu te montres intègre.
27 Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun; àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.
Envers celui qui est pur tu te montres pur; mais envers le pervers tu agis selon sa perversité.
28 Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà; ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Car tu sauves le peuple affligé, et tu [jettes] tes yeux sur les hautains, et les humilies.
29 Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa; Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.
Tu es même ma lampe, ô Eternel! et l'Eternel fera reluire mes ténèbres.
30 Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá; nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.
Et par ton moyen je me jetterai sur [toute] une troupe, [et] par le moyen de mon Dieu je franchirai la muraille.
31 “Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀; ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò. Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
La voie du [Dieu] Fort est parfaite, la parole de l'Eternel [est] affinée; c'est un bouclier à tous ceux qui se retirent vers lui.
32 Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa? Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.
Car qui est [Dieu] Fort, sinon l'Eternel? et qui [est] Rocher, sinon notre Dieu?
33 Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára, ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.
Le [Dieu] Fort, qui est ma force, est la vraie force, et il a aplani ma voie, [qui était une voie] d'intégrité.
34 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín; ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.
Il a rendu mes pieds égaux à ceux des biches, et m'a fait tenir debout sur mes lieux élevés.
35 Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà; tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.
C'est lui qui dresse mes mains au combat, de sorte qu'un arc d'airain a été rompu avec mes bras.
36 Ìwọ sì ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ̀; ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.
Tu m'as aussi donné le bouclier de ton salut, et ta bonté m'a fait devenir plus grand.
37 Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi; tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.
Tu as élargi le chemin sous mes pas, et mes talons n'ont point glissé.
38 “Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n, èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.
J'ai poursuivi mes ennemis, et je les ai exterminés; et je ne m'en suis point retourné jusqu'à ce que je les aie consumés.
39 Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn, wọn kò sì le dìde mọ́, wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.
Je les ai consumés, je les ai transpercés, et ils ne se sont point relevés; mais ils sont tombés sous mes pieds.
40 Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà; àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.
Car tu m'as revêtu de force pour le combat; tu as fait plier sous moi ceux qui s'élevaient contre moi.
41 Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi, èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
Tu as fait aussi que mes ennemis, et ceux qui me haïssaient ont tourné le dos devant moi, et je les ai détruits.
42 Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n; wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.
Ils regardaient çà et là, mais il n'y avait point de libérateur; [ils criaient] à l'Eternel, mais il ne leur a point répondu.
43 Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.
Et je les ai brisés menu comme la poussière de la terre; je les ai écrasés, [et] je les ai foulés comme la boue des rues.
44 “Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi, ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè. Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.
Et tu m'as délivré des dissensions des peuples, tu m'as gardé pour être le chef des nations. Le peuple que je ne connaissais point m'a été assujetti.
45 Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi; bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.
Les étrangers m'ont menti; ayant ouï parler de moi, ils se sont rendus obéissants.
46 Àyà yóò pá àwọn àlejò, wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.
Les étrangers se sont écoulés et ils ont tremblé de peur dans leurs retraites cachées.
47 “Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi! Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.
L'Eternel est vivant, et mon rocher est béni; c'est pourquoi Dieu, le rocher de mon salut, soit exalté.
48 Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi, àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.
Le [Dieu] Fort est celui qui me donne les moyens de me venger, et qui m'assujettit les peuples.
49 Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi. Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ; ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.
C'est lui aussi qui me retire d'entre mes ennemis. Tu m'enlèves d'entre ceux qui s'élèvent contre moi; tu me délivres de l'homme outrageux.
50 Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa, láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè, èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.
C'est pourquoi, ô Eternel! je te célébrerai parmi les nations, et je chanterai des psaumes à ton Nom.
51 “Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀; ó sì fi àánú hàn fún ẹni àmì òróró rẹ̀, fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”
C'est lui qui est la tour des délivrances de son Roi, et qui use de gratuité envers David son Oint, et envers sa postérité à jamais.