< 2 Samuel 22 >

1 Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu.
David adressa à Yahvé les paroles de ce cantique, le jour où Yahvé le délivra de la main de tous ses ennemis et de la main de Saül,
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;
et il dit: « Yahvé est mon rocher, ma forteresse, et mon libérateur, même le mien;
3 Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò, àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi. Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi; ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.
Dieu est mon rocher, en qui je trouve refuge; mon bouclier, et la corne de mon salut, ma haute tour et mon refuge. Mon sauveur, tu me sauves de la violence.
4 “Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn, ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
J'invoque Yahvé, qui est digne d'être loué; Ainsi je serai sauvé de mes ennemis.
5 Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri; tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
Car les vagues de la mort m'ont entouré. Les flots de l'impiété m'ont fait peur.
6 Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri; ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí. (Sheol h7585)
Les cordes du séjour des morts m'entouraient. Les pièges de la mort m'ont attrapé. (Sheol h7585)
7 “Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa, èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi. Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀ igbe mí wọ etí rẹ̀.
Dans ma détresse, j'ai invoqué Yahvé. Oui, j'ai appelé mon Dieu. Il a entendu ma voix hors de sa tempe. Mon cri est parvenu à ses oreilles.
8 Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì; ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì, ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
Alors la terre trembla et s'ébranla. Les fondations du ciel ont tremblé et ont été ébranlées, parce qu'il était en colère.
9 Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá, iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá, ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
De la fumée sortait de ses narines. Un feu dévorant est sorti de sa bouche. Des charbons ont été allumés par elle.
10 Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀; òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
Il a aussi incliné les cieux, et il est descendu. Une obscurité épaisse était sous ses pieds.
11 Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò, a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
Il était monté sur un chérubin, et il volait. Oui, il a été vu sur les ailes du vent.
12 Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi, àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.
Il a fait des ténèbres un abri autour de lui, le rassemblement des eaux, et les nuages épais des cieux.
13 Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀ ẹ̀yín iná ràn.
A la clarté devant lui, des charbons ardents ont été allumés.
14 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá, Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.
Yahvé tonna du ciel. Le Très-Haut a fait entendre sa voix.
15 Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká; ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.
Il envoya des flèches et les dispersa, des éclairs et les a rendus confus.
16 Ìṣàn ibú òkun sì fi ara hàn, ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn, nípa ìbáwí Olúwa, nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.
Alors les canaux de la mer apparurent. Les fondations du monde ont été mises à nu par la réprimande de Yahvé, au souffle de ses narines.
17 “Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi; ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.
Il a envoyé d'en haut et il m'a pris. Il m'a tiré de nombreuses eaux.
18 Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára, lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.
Il m'a délivré de mon ennemi puissant, de ceux qui me haïssaient, car ils étaient trop puissants pour moi.
19 Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi, ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.
Ils sont venus sur moi au jour de ma calamité, mais Yahvé était mon soutien.
20 Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá, ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.
Il m'a aussi fait sortir dans un grand lieu. Il m'a délivré, car il s'est réjoui de moi.
21 “Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.
L'Éternel m'a récompensé selon ma justice. Il m'a récompensé selon la propreté de mes mains.
22 Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́, èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
Car j'ai gardé les voies de l'Éternel, et je ne me suis pas éloigné de mon Dieu par méchanceté.
23 Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi; àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
Car toutes ses ordonnances étaient devant moi. Quant à ses statuts, je ne m'en suis pas écarté.
24 Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í, èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
J'étais aussi parfait envers lui. Je me suis gardé de mon iniquité.
25 Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.
C'est pourquoi Yahvé m'a récompensé selon ma justice, Selon ma propreté dans sa vue.
26 “Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú, àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.
Avec les miséricordieux, tu te montreras miséricordieux. Avec l'homme parfait, vous vous montrerez parfaite.
27 Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun; àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.
Avec les purs, tu te montreras pur. Avec les tordus, vous vous montrerez astucieux.
28 Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà; ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Tu sauveras le peuple affligé, mais tes yeux sont sur les arrogants, pour les faire tomber.
29 Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa; Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.
Car tu es ma lampe, Yahvé. Yahvé va éclairer mes ténèbres.
30 Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá; nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.
Car par toi, je cours contre une troupe. Par mon Dieu, je saute par-dessus un mur.
31 “Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀; ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò. Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
Quant à Dieu, sa voie est parfaite. La parole de Yahvé est mise à l'épreuve. Il est un bouclier pour tous ceux qui se réfugient en lui.
32 Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa? Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.
Car qui est Dieu, en dehors de Yahvé? Qui est un rocher, à part notre Dieu?
33 Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára, ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.
Dieu est ma forte forteresse. Il rend mon chemin parfait.
34 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín; ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.
Il rend ses pieds semblables à ceux des biches, et me place sur mes hauts lieux.
35 Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà; tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.
Il apprend à mes mains à combattre, pour que mes bras fassent un arc de bronze.
36 Ìwọ sì ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ̀; ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.
Tu m'as aussi donné le bouclier de ton salut. Votre gentillesse m'a rendu grand.
37 Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi; tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.
Tu as élargi mes pas sous moi. Mes pieds n'ont pas glissé.
38 “Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n, èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.
J'ai poursuivi mes ennemis et je les ai détruits. Je ne me suis pas retourné jusqu'à ce qu'ils soient consommés.
39 Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn, wọn kò sì le dìde mọ́, wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.
Je les ai consumés, et les a transpercés, pour qu'ils ne puissent pas surgir. Oui, ils sont tombés sous mes pieds.
40 Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà; àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.
Car tu m'as armé de force pour le combat. Tu as soumis à moi ceux qui s'élevaient contre moi.
41 Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi, èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
Tu as aussi fait en sorte que mes ennemis me tournent le dos, afin d'exterminer ceux qui me haïssent.
42 Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n; wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.
Ils regardèrent, mais il n'y avait personne à sauver; même à Yahvé, mais il ne leur a pas répondu.
43 Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.
Puis je les ai battus comme de la poussière de la terre. Je les ai écrasés comme la boue des rues, et je les ai répandus.
44 “Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi, ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè. Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.
C'est toi aussi qui m'as délivré de l'oppression de mon peuple. Tu m'as gardé pour être le chef des nations. Un peuple que je n'ai pas connu me servira.
45 Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi; bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.
Les étrangers se soumettront à moi. Dès qu'ils entendront parler de moi, ils m'obéiront.
46 Àyà yóò pá àwọn àlejò, wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.
Les étrangers disparaîtront, et sortiront en tremblant de leurs lieux clos.
47 “Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi! Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.
Yahvé est vivant! Béni soit mon rocher! Exalté soit Dieu, le rocher de mon salut,
48 Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi, àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.
même le Dieu qui exécute la vengeance pour moi, qui fait tomber les peuples sous mes ordres,
49 Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi. Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ; ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.
qui m'emmène loin de mes ennemis. Oui, tu me soulèves au-dessus de ceux qui s'élèvent contre moi. Tu me délivres de l'homme violent.
50 Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa, láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè, èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.
C'est pourquoi je te louerai, Yahvé, parmi les nations, et chanteront les louanges de ton nom.
51 “Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀; ó sì fi àánú hàn fún ẹni àmì òróró rẹ̀, fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”
Il accorde une grande délivrance à son roi, et fait preuve de bonté envers ses oints, à David et à sa descendance, pour toujours. »

< 2 Samuel 22 >