< 2 Samuel 21 >

1 Ìyàn kan sì mú lọ́jọ́ Dafidi ní ọdún mẹ́ta, láti ọdún dé ọdún; Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa sì wí pé, “Nítorí ti Saulu ni, àti nítorí ilé rẹ̀ tí ó kún fún ẹ̀jẹ̀, nítorí pé ó pa àwọn ará Gibeoni.”
Əmma Dawutning künliridǝ uda üq yil aqarqiliⱪ boldi. Dawut uning toƣruluⱪ Pǝrwǝrdigardin soridi. Pǝrwǝrdigar uningƣa: Aqarqiliⱪ Saul wǝ uning ⱪanhor jǝmǝtidikilǝr sǝwǝbidin, yǝni uning Gibeonluⱪlarni ⱪirƣin ⱪilƣinidin boldi, dedi.
2 Ọba sì pe àwọn ará Gibeoni, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; àwọn ará Gibeoni kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Israẹli, ṣùgbọ́n wọ́n jẹ́ àwọn tí ó kù nínú àwọn ọmọ Amori; àwọn ọmọ Israẹli sì ti búra fún wọn, Saulu sì ń wá ọ̀nà àti pa wọ́n ní ìtara rẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli àti Juda.
Padixaⱨ Gibeonluⱪlarni qaⱪirip, ular bilǝn sɵzlǝxti (Gibeonluⱪlar Israillardin ǝmǝs idi, bǝlki Amoriylarning bir ⱪaldisi idi. Israil ǝslidǝ ular bilǝn ǝⱨdǝ ⱪilip ⱪǝsǝm iqkǝnidi; lekin Saul Israil wǝ Yǝⱨudalarƣa bolƣan ⱪizƣinliⱪi bilǝn ularni ɵltürüxkǝ intilgǝnidi).
3 Dafidi sì bi àwọn ará Gibeoni léèrè pé, “Kí ni èmi ó ṣe fún un yín? Àti kín ni èmi ó fi ṣe ètùtù, kí ẹ̀yin lè súre fún ilẹ̀ ìní Olúwa?”
Dawut Gibeonluⱪlarƣa: Silǝrgǝ nemǝ ⱪilip berǝy? Mǝn ⱪandaⱪ ⱪilip bu gunaⱨni kafarǝt ⱪilip yapsam, andin silǝr Pǝrwǝrdigarning mirasiƣa bǝht-bǝrikǝt tiliyǝlǝysilǝr? — dedi.
4 Àwọn ará Gibeoni sì wí fún un pé, “Kì í ṣe ọ̀rọ̀ fàdákà tàbí wúrà láàrín wa àti Saulu tàbí ìdílé rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fẹ́ kí ẹ pa ẹnìkan ní Israẹli.” Dafidi sì wí pé, “Èyí tí ẹ̀yin bá wí ni èmi ó ṣe?”
Gibeonluⱪlar uningƣa: Bizning Saul wǝ uning jǝmǝtidikilǝrdin altun-kümüx sorax ⱨǝⱪⱪimiz yoⱪ, wǝ bizning sǝwǝbimizdin Israildin bir adǝmnimu ɵlümgǝ mǝⱨkum ⱪildurux ⱨǝⱪⱪimiz yoⱪ, dedi. Dawut: Silǝr nemǝ desǝnglar, mǝn xundaⱪ ⱪilay, dedi.
5 Wọ́n sì wí fún ọba pé, “Ọkùnrin tí ó run wá, tí ó sì rò láti pa wá rẹ́ ki a má kù níbikíbi nínú gbogbo agbègbè Israẹli.
Ular padixaⱨⱪa: Burun bizni yoⱪatmaⱪqi bolƣan, bizni Israilning barliⱪ pasilliri iqidǝ turƣudǝk yeri ⱪalmisun dǝp, bizni ⱨalak ⱪilixⱪa ⱪǝstligǝn ⱨeliⱪi kixining,
6 Mú ọkùnrin méje nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún wá, àwa ó sì so wọ́n rọ̀ fún Olúwa ní Gibeah ti Saulu ẹni tí Olúwa ti yàn.” Ọba sì wí pé, “Èmi ó fi wọ́n fún yín.”
ⱨazir uning ǝrkǝk nǝslidin yǝttisi bizgǝ tapxurup berilsun, biz Pǝrwǝrdigarning talliƣini bolƣan Saulning Gibeaⱨ xǝⱨiridǝ, Pǝrwǝrdigarning aldida ularni ɵltürüp, esip ⱪoyayli, dedi. Padixaⱨ: — Mǝn silǝrgǝ qoⱪum tapxurup berimǝn, dedi.
7 Ṣùgbọ́n ọba dá Mefiboṣeti sí, ọmọ Jonatani, ọmọ Saulu, nítorí ìbúra Olúwa tí ó wà láàrín Dafidi àti Jonatani ọmọ Saulu.
Lekin Dawut bilǝn Saulning oƣli Yonatanning Pǝrwǝrdigar aldida iqixkǝn ⱪǝsimi wǝjidin padixaⱨ Saulning nǝwrisi, Yonatanning oƣli Mǝfiboxǝtni ayidi.
8 Ọba sì mú àwọn ọmọkùnrin méjèèjì tí Rispa ọmọbìnrin Aiah bí fún Saulu, àní Ammoni àti Mefiboṣeti àwọn ọmọkùnrin márààrún ti Merabu, ọmọbìnrin Saulu, àwọn tí ó bí fún Adrieli ọmọ Barsillai ará Mehola.
Padixaⱨ Ayaⱨning ⱪizi Rizpaⱨning Saulƣa tuƣup bǝrgǝn ikki oƣli Armoni wǝ Mǝfiboxǝtni wǝ Saulning ⱪizi Miⱪal Mǝⱨolatliⱪ Barzillayning oƣli Adriǝl üqün beⱪiwalƣan bǝx oƣulni tutup,
9 Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Gibeah lọ́wọ́, wọ́n sì so wọ́n rọ̀ lórí òkè níwájú Olúwa: àwọn méjèèjì sì ṣubú lẹ́ẹ̀kan, a sì pa wọ́n ní ìgbà ìkórè, ní ìbẹ̀rẹ̀, ìkórè ọkà barle.
Gibeonluⱪlarning ⱪoliƣa tapxurdi. Bular ularni dɵngdǝ Pǝrwǝrdigarning aldida esip ⱪoydi. Bu yǝttǝylǝn bir kündǝ ɵltürüldi; ular ɵltürülgǝndǝ arpa ormisi aldidiki künlǝr idi.
10 Rispa ọmọbìnrin Aiah sì mú aṣọ ọ̀fọ̀ kan, ó sì tẹ́ fún ará rẹ̀ lórí àpáta ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè, títí omi fi dà sí wọn lára láti ọ̀run wá, kò sì jẹ́ kí àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run bà lé wọn lọ́sàn, tàbí àwọn ẹranko igbó lóru.
Andin Ayaⱨning ⱪizi Rizpaⱨ bɵz rǝhtni elip, ⱪoram üstigǝ yeyip saldi. U orma baxlanƣandin tartip asmandin yamƣur qüxkǝn waⱪitⱪiqǝ, u yǝrdǝ olturup kündüzi ⱪuxlarning jǝsǝtlǝrning üstigǝ ⱪonuxiƣa, keqisi yirtⱪuqlarning ularni dǝssǝp qǝylixigǝ yol ⱪoymidi.
11 A sì ro èyí, tí Rispa ọmọbìnrin Aiah obìnrin Saulu ṣe, fún Dafidi.
Birsi Saulning keniziki, Ayaⱨning ⱪizi Rizpaⱨning ⱪilƣanlirini Dawutⱪa eytti.
12 Dafidi sì lọ ó sì kó egungun Saulu, àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi, àwọn tí ó jí wọn kúrò ní ìta Beti-Ṣani, níbi tí àwọn Filistini gbé so wọ́n rọ̀, nígbà tí àwọn Filistini pa Saulu ní Gilboa.
Xuning bilǝn Dawut Yabǝx-Gileadtikilǝrning ⱪexiƣa berip, u yǝrdin Saulning wǝ uning oƣli Yonatanning sɵngǝklirini elip kǝldi (Filistiylǝr Gilboada Saulni ɵltürgǝn künidǝ ularning jǝsǝtlirini Bǝyt-Xandiki mǝydanda esip ⱪoyƣanidi; Yabǝx-Gileadtikilǝr ǝslidǝ bularni xu yǝrdin oƣriliⱪqǝ elip kǝtkǝnidi).
13 Ó sì mú egungun Saulu àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ láti ibẹ̀ náà wá; wọ́n sì kó egungun àwọn tí a ti so rọ̀ jọ.
Dawut Saul bilǝn uning oƣli Yonatanning sɵngǝklirini xu yǝrdin elip kǝldi; ular esip ɵltürülgǝn yǝttǝylǝnning sɵngǝklirinimu yiƣip ⱪoydi,
14 Wọ́n sì sin egungun Saulu àti ti Jonatani ọmọ rẹ̀ ní ilé Benjamini, ní Ṣela, nínú ibojì Kiṣi baba rẹ̀, wọ́n sì ṣe gbogbo èyí tí ọba paláṣẹ, lẹ́yìn èyí ni Ọlọ́run si gba ẹ̀bẹ̀ nítorí ilẹ̀ náà.
andin xularni Saul bilǝn oƣli Yonatanning sɵngǝkliri bilǝn Binyamin zeminidiki Zelada, atisi kixning ⱪǝbrisidǝ dǝpnǝ ⱪildi. Ular padixaⱨ ǝmr ⱪilƣandǝk ⱪildi. Andin Huda [hǝlⱪning] zemin toƣruluⱪ dualirini ijabǝt ⱪildi.
15 Ogun sì tún wà láàrín àwọn Filistini àti Israẹli; Dafidi sì sọ̀kalẹ̀, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì bá àwọn Filistini jà, ó sì rẹ Dafidi.
Filistiylǝr bilǝn Israilning ottursida yǝnǝ jǝng boldi, Dawut ɵz adǝmliri bilǝn qüxüp, Filistiylǝr bilǝn soⱪuxti. Əmma Dawut tolimu qarqap kǝtti;
16 Iṣbi-Benobu sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn Rafa, ẹni tí ọ̀kọ̀ rẹ̀ wọn ọ̀ọ́dúnrún ṣékélì idẹ, ó sì sán idà tuntun, ó sì gbèrò láti pa Dafidi.
Rafaⱨning ǝwladliridin bolƣan Ixbi-Binob Dawutni ɵltürmǝkqi idi; uning mis nǝyzisining eƣirliⱪi üq yüz xǝkǝl idi; uningƣa yǝnǝ yengi sawut baƣlaⱪliⱪ idi.
17 Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah ràn án lọ́wọ́, ó sì kọlu Filistini náà, ó sì pa á. Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì búra fún un pé, “Ìwọ kì yóò sì tún bá wa jáde lọ sí ibi ìjà mọ́ kí ìwọ má ṣe pa iná Israẹli.”
Lekin Zǝruiyaning oƣli Abixay uningƣa yardǝmgǝ kelip Filistiyni ⱪiliqlap ɵltürdi. Xu küni Dawutning adǝmliri uningƣa ⱪǝsǝm ⱪilip: Sǝn yǝnǝ biz bilǝn jǝnggǝ qiⱪmiƣin! Bolmisa Israilning qiriƣi ɵqüp ⱪalidu, — dedi.
18 Lẹ́yìn èyí, ìjà kan sì tún wà láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini ní Gobu, nígbà náà ni Sibekai ará Huṣati pa Safu, ẹni tí í ṣe ọ̀kan nínú àwọn Rafa.
Bu ixtin keyin xundaⱪ boldiki, Gobta Filistiylǝr bilǝn yǝnǝ jǝng boldi; u waⱪitta Ⱨuxatliⱪ Sibbikay Rafaⱨning ǝwladidin bolƣan Safni ɵltürdi.
19 Ìjà kan sì tún wà ní Gobu láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini, Elhanani ọmọ Jairi ará Bẹtilẹhẹmu sì pa arákùnrin Goliati ará Gitti, ẹni tí ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ dàbí ìdábùú apásá ìhunṣọ.
Gobta yǝnǝ bir ⱪetim Filistiylǝr bilǝn jǝng boldi; u qaƣda Bǝyt-Lǝⱨǝmlik Yairning oƣli Əl-Ⱨanan Gatliⱪ Goliyatning inisini ɵltürdi. Uning nǝyzisining sepi bapkarning hadisidǝk idi.
20 Ìjà kan sì tún wà ní Gati, ọkùnrin kan sì wà tí ó ga púpọ̀, ó sì ní ìka mẹ́fà ní ọwọ́ kan, àti ọmọ ẹsẹ̀ mẹ́fà ní ẹsẹ̀ kan, àpapọ̀ rẹ̀ sì jẹ́ mẹ́rìnlélógún; a sì bí òun náà ní Rafa.
Yǝnǝ bir jǝng Gatta boldi; u yǝrdǝ egiz boyluⱪ bir adǝm bar idi, ⱪollirining altidin barmaⱪliri, putlirining altidin barmaⱪliri bolup jǝmiy yigirmǝ tɵt barmiⱪi bar idi. U ⱨǝm Rafaⱨning ǝwladi idi.
21 Nígbà tí òun sì pe Israẹli ní ìjà. Jonatani ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì pa á.
U Israillarning aldida turup ularni mazaⱪ ⱪildi; lekin Dawutning akisi Ximiyaning oƣli Yonatan uni ɵltürdi.
22 Àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ni ìran Rafa ní Gati, wọ́n sì ti ọwọ́ Dafidi ṣubú àti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Bu tɵt kixi Gatliⱪ Rafaⱨning ǝwladi bolup, ⱨǝmmisi Dawutning ⱪolida yaki uning hizmǝtkarlirining ⱪolida ɵltürüldi.

< 2 Samuel 21 >