< 2 Samuel 21 >

1 Ìyàn kan sì mú lọ́jọ́ Dafidi ní ọdún mẹ́ta, láti ọdún dé ọdún; Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa sì wí pé, “Nítorí ti Saulu ni, àti nítorí ilé rẹ̀ tí ó kún fún ẹ̀jẹ̀, nítorí pé ó pa àwọn ará Gibeoni.”
Davudee paççahiyvalla haa'ane gahıl, xhebille sen çiçiqad qihna q'ittin ıxha. Mançinemee Davudee Rəbbike qidghın ha'a. Rəbbee Davuduk'le eyhen: – Man Şauleeyiy cune nasılen k'yav'uyne ebal-alla vod. Mang'vee Giveonğançenbıniy gyapt'ı.
2 Ọba sì pe àwọn ará Gibeoni, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; àwọn ará Gibeoni kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Israẹli, ṣùgbọ́n wọ́n jẹ́ àwọn tí ó kù nínú àwọn ọmọ Amori; àwọn ọmọ Israẹli sì ti búra fún wọn, Saulu sì ń wá ọ̀nà àti pa wọ́n ní ìtara rẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli àti Juda.
Paççahee Giveonbı qopt'ul, manbışika yuşan ha'ana. Giveonbı İzrailybı deş vuxha. Manbı Emor eyhene milletıke avxuynbı vuxha. İzrailybışe manbı üçübba g'alya'asva k'ın g'assır ıxha. Şaulusmee manbı gyapt'ı avaak'an haa'as vukkiykın. Mang'us mane cigabışee saccu İzrailybıyiy Yahuder avxu vukkan vuxha.
3 Dafidi sì bi àwọn ará Gibeoni léèrè pé, “Kí ni èmi ó ṣe fún un yín? Àti kín ni èmi ó fi ṣe ètùtù, kí ẹ̀yin lè súre fún ilẹ̀ ìní Olúwa?”
Davudee Giveonaaşike qiyghanan: – Zasse vuşdemee hucoo ha'as əxəyee? Şu, Rəbbee g'əyxı'yne milletıs xayir-düə huvuynemee, şi hav'una bınah zasse nəxüb havaakal haa'as vəəxəyee?
4 Àwọn ará Gibeoni sì wí fún un pé, “Kì í ṣe ọ̀rọ̀ fàdákà tàbí wúrà láàrín wa àti Saulu tàbí ìdílé rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fẹ́ kí ẹ pa ẹnìkan ní Israẹli.” Dafidi sì wí pé, “Èyí tí ẹ̀yin bá wí ni èmi ó ṣe?”
Giveonbışe mang'uk'le eyhen: – Şas Şaulıniy cune nasılen k'ınəəğəyiy nuk'ra ıkkan deş. İzrailir şas vuşucar gik'as ıkkan deş. Davudee manbışik'le eyhen: – Şos hucooyiy ıkkan, zı manıd ha'asın.
5 Wọ́n sì wí fún ọba pé, “Ọkùnrin tí ó run wá, tí ó sì rò láti pa wá rẹ́ ki a má kù níbikíbi nínú gbogbo agbègbè Israẹli.
Manbışe paççahık'le eyhen: – Şi İzrailil ımaaxvacenva Şaulee şake öc alyapt'ı, şi gyapt'ı.
6 Mú ọkùnrin méje nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún wá, àwa ó sì so wọ́n rọ̀ fún Olúwa ní Gibeah ti Saulu ẹni tí Olúwa ti yàn.” Ọba sì wí pé, “Èmi ó fi wọ́n fún yín.”
Mang'uke g'arına yighıyre adamiy şasqa hele. Şinab manbı Rəbbee g'əyxı'yne Şaulne Givea eyhene şaharee Rəbbine ögil givaaxanas. Paççahee «Manbı zı şosqa qevlesınbıva» eyhe.
7 Ṣùgbọ́n ọba dá Mefiboṣeti sí, ọmọ Jonatani, ọmọ Saulu, nítorí ìbúra Olúwa tí ó wà láàrín Dafidi àti Jonatani ọmọ Saulu.
Paççah Davudus Şaulne ühatsühat Yonatanna dix Mefiboşet qiykkanna. Mang'us mana qiykkanna Rəbbine ögil Yonatanıs k'ın g'assırva.
8 Ọba sì mú àwọn ọmọkùnrin méjèèjì tí Rispa ọmọbìnrin Aiah bí fún Saulu, àní Ammoni àti Mefiboṣeti àwọn ọmọkùnrin márààrún ti Merabu, ọmọbìnrin Saulu, àwọn tí ó bí fún Adrieli ọmọ Barsillai ará Mehola.
Paççahee Armoniyiy merna Mefiboşet alyabat'a. Manbı Ayyayne yişşee Ritspee Şauluke vuxuyn dixbı vuxha. Sayıb mang'vee Şaulne yişşee Meravee Mexolğançene Barzilayne duxayke Adrielike vuxuyn xhoyre dix alyabat'a.
9 Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Gibeah lọ́wọ́, wọ́n sì so wọ́n rọ̀ lórí òkè níwájú Olúwa: àwọn méjèèjì sì ṣubú lẹ́ẹ̀kan, a sì pa wọ́n ní ìgbà ìkórè, ní ìbẹ̀rẹ̀, ìkórè ọkà barle.
Mang'vee manbı Giveonbışisqa qoole. Giveonbışe manbı Rəbbine ögil suval givaaxananbı. Manbışda yighırsana sacigee habat'anbı. Manbı xhıt'a qiviyşalne ts'eppiyne yiğbışil givaaxan.
10 Rispa ọmọbìnrin Aiah sì mú aṣọ ọ̀fọ̀ kan, ó sì tẹ́ fún ará rẹ̀ lórí àpáta ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè, títí omi fi dà sí wọn lára láti ọ̀run wá, kò sì jẹ́ kí àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run bà lé wọn lọ́sàn, tàbí àwọn ẹranko igbó lóru.
Ayyayne yişşee Ritspee cesva palan alyaat'u, ganzıl gyadaççe. Ritspa xhıt'abı qiyşal gibğılıne yiğbışile, givapxıninbışilqa gyoğiy gyoğasde yiğılqamee maa'ar ayxu. Məng'ee manbışde mayıtbışisqa yiğniyığın xəybışin şit'yar, xəmded çolan həyvanar qeetxhes hassır deş.
11 A sì ro èyí, tí Rispa ọmọbìnrin Aiah obìnrin Saulu ṣe, fún Dafidi.
Şaulne caariyee, Ayyayne yişşee Ritspee ha'ana mana iş Davudulqa hivxhar haa'ana.
12 Dafidi sì lọ ó sì kó egungun Saulu, àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi, àwọn tí ó jí wọn kúrò ní ìta Beti-Ṣani, níbi tí àwọn Filistini gbé so wọ́n rọ̀, nígbà tí àwọn Filistini pa Saulu ní Gilboa.
Davudee hark'ın, Şaulıniy mang'une duxayn Yonatanın bark'vbı Gileadne Yaveşne ç'ak'ınbışike g'eşşenbı. (Filiştinaaşe Gilboa eyhene suval Şaul gik'uyne yiğıl manbışin mayıtbı Bet-Şeane maydama givayxananbı. Yaveşğançene insanaaşeb abı, manbışin mayıtbı qöqənbı.)
13 Ó sì mú egungun Saulu àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ láti ibẹ̀ náà wá; wọ́n sì kó egungun àwọn tí a ti so rọ̀ jọ.
Davudee Şauluniy mang'une duxayn Yonatanın bark'vbı mançe alyaat'anbı, şene givapxınne yıghıng'unud bark'vbı sa'anbı.
14 Wọ́n sì sin egungun Saulu àti ti Jonatani ọmọ rẹ̀ ní ilé Benjamini, ní Ṣela, nínú ibojì Kiṣi baba rẹ̀, wọ́n sì ṣe gbogbo èyí tí ọba paláṣẹ, lẹ́yìn èyí ni Ọlọ́run si gba ẹ̀bẹ̀ nítorí ilẹ̀ náà.
Davudne insanaaşe Şaulıniy mang'une duxayn Yonatanın bark'vbı Benyaminaaşine cigabışeene Tsela eyhene şaharee, Şaulne dekkıne, Gişine, mağareene nyuq'vnesnee k'eyxha. Paççahee manbışik'le uvhuyn gırgın, mane insanaaşe ha'an. Mançile qiyğa Allahee ölkaynemee ha'ane gırgıne düəbışis alidghıniy qelen.
15 Ogun sì tún wà láàrín àwọn Filistini àti Israẹli; Dafidi sì sọ̀kalẹ̀, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì bá àwọn Filistini jà, ó sì rẹ Dafidi.
Meeb Filiştinaaşda İzrailybışika dəv'ə gyooxha. Davud cune insanaaşika Filiştinaaşika səyxəsva ayk'an. Manbı Filiştinaaşika siviyxəmee Davud oyzarna.
16 Iṣbi-Benobu sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn Rafa, ẹni tí ọ̀kọ̀ rẹ̀ wọn ọ̀ọ́dúnrún ṣékélì idẹ, ó sì sán idà tuntun, ó sì gbèrò láti pa Dafidi.
Rafayke g'arıyne İşbi-Benovusus Davud gik'as ıkkiykan. Mang'une nizeyn siv tuncuke xhebıd vəş şekel yı'q'vəlee ıxha. Yı'q'eeqad mang'vee ts'edın g'ılınc qı'ı eyxhe.
17 Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah ràn án lọ́wọ́, ó sì kọlu Filistini náà, ó sì pa á. Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì búra fún un pé, “Ìwọ kì yóò sì tún bá wa jáde lọ sí ibi ìjà mọ́ kí ìwọ má ṣe pa iná Israẹli.”
Tseruyayna dix Avişay Davudusqa kumagıs qarı, Filiştinğançena mang'vee ı'xı', gek'ana. Mane gahıl Davudne insanaaşe mang'us k'ın g'assır, eyhen: – İzrailin işix k'imədəqqəcenva, sayır ğu şaka dəv'eeqa ayres deş.
18 Lẹ́yìn èyí, ìjà kan sì tún wà láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini ní Gobu, nígbà náà ni Sibekai ará Huṣati pa Safu, ẹni tí í ṣe ọ̀kan nínú àwọn Rafa.
Mançile qiyğa Filiştinaaşika Gov eyhene cigee meed səvxiy gexha. Mane gahıl Xuşa eyhene cigeençene Sibbekayee Rafayke g'arına Saf gek'ana.
19 Ìjà kan sì tún wà ní Gobu láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini, Elhanani ọmọ Jairi ará Bẹtilẹhẹmu sì pa arákùnrin Goliati ará Gitti, ẹni tí ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ dàbí ìdábùú apásá ìhunṣọ.
Filiştinaaşika Gov eyhene cigee meed səvxiy gexha. Manke Bet-Lexemğançene Yareyne duxee Elxananee Gatğançena Golyatna çoc gek'ana. Mang'une nizeyn cık'rı qexhvane xhanayn arğacın dal xhinne xətta ıxha.
20 Ìjà kan sì tún wà ní Gati, ọkùnrin kan sì wà tí ó ga púpọ̀, ó sì ní ìka mẹ́fà ní ọwọ́ kan, àti ọmọ ẹsẹ̀ mẹ́fà ní ẹsẹ̀ kan, àpapọ̀ rẹ̀ sì jẹ́ mẹ́rìnlélógún; a sì bí òun náà ní Rafa.
Gat eyhene şaharne k'ane sa menne yəqqees gitxhuyne səvxee, Rafayke g'arına sa axtına canakana insan ıxha. Mane insanne xıleppışilib, g'elybışilib yixhıble t'ubiy. Mang'uqa gırgıba g'ayeyoq'ab t'ub vuxha.
21 Nígbà tí òun sì pe Israẹli ní ìjà. Jonatani ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì pa á.
İzrailybışik'le mang'vee nen qadiy eyhemee, Davudne çocune Şimayne duxee Yonatanee mana gek'ana.
22 Àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ni ìran Rafa ní Gati, wọ́n sì ti ọwọ́ Dafidi ṣubú àti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Mana Rafayke g'arına yoq'uyre insan Gatğançenbı vuxha. Manbı Davudneyiy Davudne insanaaşine xıleke hapt'ı.

< 2 Samuel 21 >