< 2 Samuel 21 >

1 Ìyàn kan sì mú lọ́jọ́ Dafidi ní ọdún mẹ́ta, láti ọdún dé ọdún; Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa sì wí pé, “Nítorí ti Saulu ni, àti nítorí ilé rẹ̀ tí ó kún fún ẹ̀jẹ̀, nítorí pé ó pa àwọn ará Gibeoni.”
I za czasów Dawida panował głód przez trzy lata, rok po roku. Dawid szukał więc oblicza PANA, a PAN odpowiedział: To z powodu Saula i jego krwawego domu, ponieważ wymordował Gibeonitów.
2 Ọba sì pe àwọn ará Gibeoni, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; àwọn ará Gibeoni kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Israẹli, ṣùgbọ́n wọ́n jẹ́ àwọn tí ó kù nínú àwọn ọmọ Amori; àwọn ọmọ Israẹli sì ti búra fún wọn, Saulu sì ń wá ọ̀nà àti pa wọ́n ní ìtara rẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli àti Juda.
Wtedy król wezwał Gibeonitów i przemówił do nich. A Gibeonici nie wywodzili się z synów Izraela, ale z resztki Amorytów. I chociaż synowie Izraela przysięgli im, Saul jednak usiłował wytępić ich w swej gorliwości względem synów Izraela i Judy.
3 Dafidi sì bi àwọn ará Gibeoni léèrè pé, “Kí ni èmi ó ṣe fún un yín? Àti kín ni èmi ó fi ṣe ètùtù, kí ẹ̀yin lè súre fún ilẹ̀ ìní Olúwa?”
Dawid zapytał więc Gibeonitów: Cóż mam dla was uczynić? A czym was ułagodzić, abyście błogosławili dziedzictwo PANA?
4 Àwọn ará Gibeoni sì wí fún un pé, “Kì í ṣe ọ̀rọ̀ fàdákà tàbí wúrà láàrín wa àti Saulu tàbí ìdílé rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fẹ́ kí ẹ pa ẹnìkan ní Israẹli.” Dafidi sì wí pé, “Èyí tí ẹ̀yin bá wí ni èmi ó ṣe?”
I odpowiedzieli mu Gibeonici: Nie chodzi nam o srebro ani o złoto od Saula i jego domu, ani o to, żeby zabito kogoś w Izraelu. A [on] odpowiedział: Cokolwiek powiecie, to dla was uczynię.
5 Wọ́n sì wí fún ọba pé, “Ọkùnrin tí ó run wá, tí ó sì rò láti pa wá rẹ́ ki a má kù níbikíbi nínú gbogbo agbègbè Israẹli.
Oni powiedzieli do króla: [Co do] mężczyzny, który nas wygubił i zmierzał do tego, aby nas wytępić, żeby nikt z nas nie pozostał we wszystkich granicach Izraela;
6 Mú ọkùnrin méje nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún wá, àwa ó sì so wọ́n rọ̀ fún Olúwa ní Gibeah ti Saulu ẹni tí Olúwa ti yàn.” Ọba sì wí pé, “Èmi ó fi wọ́n fún yín.”
Wydajcie nam siedmiu z jego synów, a my powiesimy ich przed PANEM w Gibea Saula, [który był] wybrańcem PANA. Król odpowiedział: Wydam [ich].
7 Ṣùgbọ́n ọba dá Mefiboṣeti sí, ọmọ Jonatani, ọmọ Saulu, nítorí ìbúra Olúwa tí ó wà láàrín Dafidi àti Jonatani ọmọ Saulu.
Lecz król oszczędził Mefiboszeta, syna Jonatana, syna Saula, z powodu przysięgi PANA, która [była] między nimi, między Dawidem a Jonatanem, synem Saula.
8 Ọba sì mú àwọn ọmọkùnrin méjèèjì tí Rispa ọmọbìnrin Aiah bí fún Saulu, àní Ammoni àti Mefiboṣeti àwọn ọmọkùnrin márààrún ti Merabu, ọmọbìnrin Saulu, àwọn tí ó bí fún Adrieli ọmọ Barsillai ará Mehola.
Ale król wziął dwóch synów Rispy, córki Aji, których urodziła Saulowi, Armoniego i Mefiboszeta, i pięciu synów [siostry] Mikal, córki Saula, których urodziła Adrielowi, synowi Barzillaja z Mecholi;
9 Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Gibeah lọ́wọ́, wọ́n sì so wọ́n rọ̀ lórí òkè níwájú Olúwa: àwọn méjèèjì sì ṣubú lẹ́ẹ̀kan, a sì pa wọ́n ní ìgbà ìkórè, ní ìbẹ̀rẹ̀, ìkórè ọkà barle.
I wydał ich w ręce Gibeonitów, a oni powiesili ich na górze przed PANEM. Razem umarło ich siedmiu, zostali zabici w pierwsze dni żniw, na początku żniw jęczmienia.
10 Rispa ọmọbìnrin Aiah sì mú aṣọ ọ̀fọ̀ kan, ó sì tẹ́ fún ará rẹ̀ lórí àpáta ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè, títí omi fi dà sí wọn lára láti ọ̀run wá, kò sì jẹ́ kí àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run bà lé wọn lọ́sàn, tàbí àwọn ẹranko igbó lóru.
Wtedy Rispa, córka Aji, wzięła wór i rozciągnęła go na skale, na początku żniw, aż do czasu, gdy spadł na nich deszcz z nieba, i nie pozwalała, aby ptactwo powietrzne zbliżało się do nich za dnia, ani zwierzęta polne – nocą.
11 A sì ro èyí, tí Rispa ọmọbìnrin Aiah obìnrin Saulu ṣe, fún Dafidi.
Potem doniesiono Dawidowi o tym, co uczyniła Rispa, córka Aji, nałożnica Saula.
12 Dafidi sì lọ ó sì kó egungun Saulu, àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi, àwọn tí ó jí wọn kúrò ní ìta Beti-Ṣani, níbi tí àwọn Filistini gbé so wọ́n rọ̀, nígbà tí àwọn Filistini pa Saulu ní Gilboa.
Dawid poszedł więc i wziął kości Saula i kości Jonatana, jego syna, od starszych Jabesz-Gilead, którzy ukradli je z placu Bet-Szan, gdzie ich zawiesili Filistyni w dniu zabicia Saula przez Filistynów w Gilboa.
13 Ó sì mú egungun Saulu àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ láti ibẹ̀ náà wá; wọ́n sì kó egungun àwọn tí a ti so rọ̀ jọ.
Wziął więc stamtąd kości Saula i kości Jonatana, jego syna; zebrano też kości powieszonych;
14 Wọ́n sì sin egungun Saulu àti ti Jonatani ọmọ rẹ̀ ní ilé Benjamini, ní Ṣela, nínú ibojì Kiṣi baba rẹ̀, wọ́n sì ṣe gbogbo èyí tí ọba paláṣẹ, lẹ́yìn èyí ni Ọlọ́run si gba ẹ̀bẹ̀ nítorí ilẹ̀ náà.
I pogrzebali kości Saula i Jonatana, jego syna, w ziemi Beniamina w Sela, w grobie Kisza, jego ojca. Uczynili wszystko, co król nakazał. Potem Bóg dał się ubłagać co do ziemi.
15 Ogun sì tún wà láàrín àwọn Filistini àti Israẹli; Dafidi sì sọ̀kalẹ̀, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì bá àwọn Filistini jà, ó sì rẹ Dafidi.
Później znowu doszło do wojny między Filistynami a Izraelem. I Dawid wyruszył wraz ze swymi sługami i walczyli z Filistynami, a Dawid był znużony.
16 Iṣbi-Benobu sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn Rafa, ẹni tí ọ̀kọ̀ rẹ̀ wọn ọ̀ọ́dúnrún ṣékélì idẹ, ó sì sán idà tuntun, ó sì gbèrò láti pa Dafidi.
Wtedy Iszbibenob, który wywodził się z synów pewnego olbrzyma, a którego włócznia ważyła trzysta syklów brązu i który miał przepasany nowy [miecz], postanowił, że zabije Dawida.
17 Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah ràn án lọ́wọ́, ó sì kọlu Filistini náà, ó sì pa á. Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì búra fún un pé, “Ìwọ kì yóò sì tún bá wa jáde lọ sí ibi ìjà mọ́ kí ìwọ má ṣe pa iná Israẹli.”
Lecz Abiszaj, syn Serui, przyszedł mu z pomocą, uderzył Filistyna i zabił go. Wtedy ludzie Dawida przysięgli mu: Nie będziesz już wyruszał z nami do bitwy, abyś nie zgasił pochodni Izraela.
18 Lẹ́yìn èyí, ìjà kan sì tún wà láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini ní Gobu, nígbà náà ni Sibekai ará Huṣati pa Safu, ẹni tí í ṣe ọ̀kan nínú àwọn Rafa.
Potem znowu była bitwa z Filistynami w Gob. Wtedy Sibbekaj Chuszatyta zabił Safa, który pochodził z synów tego olbrzyma.
19 Ìjà kan sì tún wà ní Gobu láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini, Elhanani ọmọ Jairi ará Bẹtilẹhẹmu sì pa arákùnrin Goliati ará Gitti, ẹni tí ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ dàbí ìdábùú apásá ìhunṣọ.
Była też jeszcze inna wojna z Filistynami w Gob, podczas której Elchanan, syn Jaara Oregima z Betlejem, zabił [brata] Goliata Gittyty, którego drzewce włóczni były jak wał tkacki.
20 Ìjà kan sì tún wà ní Gati, ọkùnrin kan sì wà tí ó ga púpọ̀, ó sì ní ìka mẹ́fà ní ọwọ́ kan, àti ọmọ ẹsẹ̀ mẹ́fà ní ẹsẹ̀ kan, àpapọ̀ rẹ̀ sì jẹ́ mẹ́rìnlélógún; a sì bí òun náà ní Rafa.
Ponadto toczyła się jeszcze wojna w Gat, gdzie był człowiek [wysokiego] wzrostu, mający po sześć palców u rąk i po sześć palców u nóg, razem dwadzieścia cztery. On także był synem tego olbrzyma.
21 Nígbà tí òun sì pe Israẹli ní ìjà. Jonatani ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì pa á.
Gdy urągał on Izraelowi, zabił go Jonatan, syn Szimei, brata Dawida.
22 Àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ni ìran Rafa ní Gati, wọ́n sì ti ọwọ́ Dafidi ṣubú àti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Ci czterej byli synami [tego] olbrzyma z Gat, a polegli z ręki Dawida i z ręki jego sług.

< 2 Samuel 21 >