< 2 Samuel 20 >

1 Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé, “Àwa kò ní ipa nínú Dafidi, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jese! Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Israẹli!”
Ahora, por casualidad, estaba presente un hombre perverso llamado Seba, el hijo de Bicri, un Benjamita, y él, sonando el cuerno, dijo: No tenemos parte en David, ni ningún interés en el Hijo de Isaí, que cada uno vaya a su tienda, oh Israel.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
Entonces todos los hombres de Israel, apartándose de David, fueron tras Seba, el hijo de Bicri, pero los hombres de Judá fueron fieles a su rey, y lo acompañaron desde el Jordán hasta Jerusalén.
3 Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
Y vino David a su casa en Jerusalén; y el rey llevó a las diez concubinas a quienes había dejado el cuidado de la casa, las encerró bajo custodia y les dio las necesidades de la vida, pero no volvió a tener relaciones con ellas. Así que fueron encerradas hasta el día de su muerte, viviendo como viudas.
4 Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
Entonces el rey dijo a Amasa: Reúne a todos los hombres de Judá, y tu también preséntate en tres días aquí.
5 Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
Entonces Amasa fue a reunir a todos los hombres de Judá, pero él tomó más tiempo del que David le había dado.
6 Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
Entonces David dijo a Abisai: Seba, el hijo de Bicri, nos hará más daño que Absalón; así que toma algunos de los sirvientes de tu señor y ve tras él, antes de que se ponga a salvo en las ciudades amuralladas y se escape ante nuestros ojos.
7 Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Y fueron después Abisai, Joab y los cereteos, los peleteos y todos los combatientes; Salieron de Jerusalén para alcanzar a Seba, el hijo de Bicri.
8 Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
Cuando estaban en la gran piedra que está en Gabaón, Amasa se encontró cara a cara con ellos. Ahora Joab llevaba puesto su traje de guerra, y alrededor de él un cinturón de la que colgaba su espada en su cubierta; y mientras caminaba, se le salió, cayendo al suelo.
9 Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
Y Joab dijo a Amasa: ¿Está bien, hermano mío? Y con su mano derecha lo tomó por el pelo de su barbilla para darle un beso.
10 Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Pero Amasa no vio peligro por la espada que estaba ahora en la mano izquierda de Joab, y Joab se la pasó por el estómago y todos sus intestinos se derramaron en el suelo, y no le dio otro golpe. Entonces Joab y su hermano Abisai siguieron a Seba, el hijo de Bicri.
11 Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
Y uno de los jóvenes de Joab, tomando su lugar al lado de Amasa, dijo: Quienquiera que sea para Joab y para David, ¡que vaya tras Joab!
12 Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
Y Amasa estaba tendido en un charco de sangre en medio de la carretera. Y cuando el hombre vio que toda la gente se estaba deteniendo, sacó a Amasa de la carretera y lo puso en un campo, con un paño sobre él, cuando vio que todos los que iban se detuvieron parados junto a él.
13 Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Cuando lo sacaron del camino, todas las personas siguieron a Joab en busca de Seba, el hijo de Bicri.
14 Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
Y Seba pasó por todas las tribus de Israel a Abel de Bet-maaca; Y todos los descendientes de Bicri se juntaron y entraron tras él.
15 Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
Y Joab y sus hombres lo encerraron en Abel de Bet-maaca, y levantaron un rampa de tierra contra la ciudad: y todos los hombres de Joab hicieron todo lo posible por derribar el muro.
16 Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’”
Entonces una mujer sabia se levantó en la pared y, gritando desde el pueblo, dijo: Oye, oye; Di ahora a Joab: acércate, para que pueda hablar contigo.
17 Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi náà ni.” Obìnrin náà sì wí fún un pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi ń gbọ́.”
Y él se acercó, y la mujer dijo: ¿Eres tú Joab? Y él respondió: Yo soy. Entonces ella dijo: Escucha las palabras de tu sierva. Y él dijo: Estoy escuchando.
18 Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
Entonces ella dijo: En los viejos tiempos, hubo un dicho: Pongan la pregunta en Abel y en Dan, diciendo: ¿Ha llegado a su fin lo que los hombres de buena fe en Israel han ordenado?
19 Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
Tu propósito es la destrucción de una ciudad madre en Israel: ¿por qué pondrías fin a la herencia del Señor?
20 Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
Y respondiendo Joab, le dijo: Lejos, lejos de mí, sea causa de muerte o destrucción;
21 Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.” Obìnrin náà sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, orí rẹ̀ ni a ó sì sọ láti inú odi wá.”
No es así, pero un hombre de la región montañosa de Efraín, Seba, hijo de Bicri, por su nombre, ha tomado las armas contra el rey, contra David: abandone a este hombre solamente, y me iré del pueblo. Y la mujer le dijo a Joab: Su cabeza caerá sobre la pared hacia ti.
22 Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
Entonces la mujer en su sabiduría había hablado con todo el pueblo. Y le cortaron la cabeza a Seba y la enviaron a Joab. Y él hizo sonar el cuerno de retirada, y los envió a todos lejos de la ciudad, cada hombre a su tienda. Y Joab volvió a Jerusalén al rey.
23 Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli; Benaiah ọmọ Jehoiada sì jẹ́ olórí àwọn Kereti, àti ti àwọn Peleti.
Y Joab estaba sobre todo el ejército; y Benaía, el hijo de Joiada, estaba al mando de los cereteos y los peleteos;
24 Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.
Y Adoram era el supervisor del trabajo forzado; y Josafat, el hijo de Ahilud, fue el registrador;
25 Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé; Sadoku àti Abiatari sì ni àwọn àlùfáà.
Y Seva era el escriba, y Sadoc y Abiatar eran sacerdotes;
26 Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.
Y además, Ira él Jaireo era sacerdote de David.

< 2 Samuel 20 >