< 2 Samuel 20 >

1 Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé, “Àwa kò ní ipa nínú Dafidi, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jese! Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Israẹli!”
Zgodilo se je, da je bil tam Beliálov mož, katerega ime je bilo Ševá, Bihríjev sin, Benjaminovec. Ta je zatrobil na šofar in rekel: »Mi nimamo deleža v Davidu niti nimamo dediščine v Jesejevem sinu. Vsak mož k svojim šotorom, oh Izrael.«
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
Tako je vsak mož iz Izraela odšel gor izza Davida in sledil Bihríjevem sinu Ševáju; toda Judovi možje, od Jordana, celo do Jeruzalema, so se trdno pridružili njihovemu kralju.
3 Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
David je prišel k svoji hiši v Jeruzalemu in kralj je vzel deset žensk, svojih priležnic, ki jih je pustil, da varujejo hišo in jih zaprl v ječo in jih hranil, toda ni šel noter k njim. Tako so bile zaprte do dneva svoje smrti, živeče v vdovstvu.
4 Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
Potem je kralj rekel Amasáju: »V treh dneh mi zberi može iz Juda in ti bodi tu prisoten.«
5 Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
Tako je Amasá odšel, da zbere Judove može, toda zadržal se je dlje kakor postavljen čas, ki mu je bil določen.
6 Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
David je rekel Abišáju: »Sedaj nam bo Bihríjev sin Ševá storil več škode, kakor jo je storil Absalom. Vzemi služabnike svojega gospoda in ga zasleduj, da si ne pridobi utrjenih mest in nam pobegne.«
7 Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Tam so odšli ven za njim Joábovi možje, Keretéjci, Péletovci in vsi mogočni možje. Odšli so iz Jeruzalema, da zasledujejo Bihríjevega sina Ševája.
8 Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
Ko so bili pri velikem kamnu, ki je v Gibeónu, je Amasá šel pred njimi. Joábova obleka, ki jo je oblekel, je bila opasana k njemu in na njej pas s pritrjenim mečem na svojih ledjih, v svoji nožnici in ko je šel naprej, je ta padel ven.
9 Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
Joáb je rekel Amasáju: » Ali si pri zdravju, moj brat?« Joáb je z desnico prijel Amasája za brado, da ga poljubi.
10 Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Toda Amasá ni pazil na meč, ki je bil v Joábovi roki. Tako ga je z njim udaril v peto rebro in njegovo notranjost prelil na tla in ni ga ponovno udaril in je umrl. Tako sta Joáb in njegov brat Abišáj zasledovala Bihríjevega sina Ševája.
11 Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
Eden izmed Joábovih mož je stal poleg njega ter rekel: »Kdor je naklonjen Joábu in kdor je za Davida, ta naj gre za Joábom.«
12 Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
Amasá se je valjal v krvi na sredi glavne ceste. In ko je mož videl, da je vse ljudstvo obstalo, je Amasája odstranil z glavne ceste na polje in nanj vrgel oblačilo, ko je videl, da je vsak, kdor je prišel mimo, mirno obstal.
13 Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Ko je bil odstranjen z glavne ceste, je vse ljudstvo odšlo naprej za Joábom, da zasledujejo Bihríjevega sina Ševája.
14 Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
Ta je šel skozi vse Izraelove rodove do Abéle in do Bet Maáhe in do vseh Bihríjevcev in zbrani so bili skupaj ter šli tudi za njim.
15 Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
Prišli so in ga oblegali v Abél Bet Maáhi in nasuli so nasip zoper mesto in le-ta je stal v jarku. In vse ljudstvo, ki je bilo z Joábom, je uničevalo obzidje, da ga zrušijo.
16 Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’”
Potem je modra ženska iz mesta zaklicala: »Poslušajte, poslušajte. Recite, prosim vas, Joábu: ›Pridi blizu sèm, da lahko govorim s teboj.‹«
17 Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi náà ni.” Obìnrin náà sì wí fún un pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi ń gbọ́.”
Ko je ta prišel bliže k njej, je ženska rekla: » Ali si ti Joáb?« Odgovoril je: »Jaz sem.« Potem mu je rekla: »Poslušaj besede svoje pomočnice.« Odgovoril je: »Poslušam.«
18 Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
Potem je spregovorila, rekoč: »V starih časih so bili navajeni govoriti, rekoč: ›Zagotovo bodo vprašali za nasvet v Abélu, ‹ in tako so končali zadevo.
19 Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
Jaz sem ena izmed tistih, ki so v Izraelu mirni in zvesti, ti pa si prizadevaš, da uničiš mesto in mater v Izraelu. Zakaj hočeš pogoltniti Gospodovo dediščino?«
20 Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
Joáb je odgovoril in rekel: »Daleč bodi to, daleč bodi to od mene, da bi pogoltnil ali uničil.
21 Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.” Obìnrin náà sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, orí rẹ̀ ni a ó sì sọ láti inú odi wá.”
Zadeva ni takšna, temveč človek z gore Efrájim, po imenu Bihríjev sin Ševá, je vzdignil svojo roko zoper kralja, celó zoper Davida. Samo njega izročite in odšel bom od mesta.« Ženska je rekla Joábu: »Glej, njegova glava ti bo vržena čez obzidje.«
22 Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
Potem je ženska, v svoji modrosti, odšla k vsemu ljudstvu. Odsekali so glavo Bihríjevega sina Ševája in jo vrgli ven k Joábu. Ta je zatrobil na šofar in umaknili so se od mesta, vsak mož k svojemu šotoru. In Joáb se je vrnil h kralju v Jeruzalem.
23 Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli; Benaiah ọmọ Jehoiada sì jẹ́ olórí àwọn Kereti, àti ti àwọn Peleti.
Torej Joáb je bil nad vso Izraelovo vojsko. Jojadájev sin Benajá je bil nad Keretéjci in nad Péletovci;
24 Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.
Adorám je bil nad davkom; Ahilúdov sin Józafat je bil letopisec;
25 Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé; Sadoku àti Abiatari sì ni àwọn àlùfáà.
Ševá je bil pisar; Cadók in Abjatár sta bila duhovnika;
26 Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.
in tudi Jaírovec Irá je bil glavni častnik pri Davidu.

< 2 Samuel 20 >