< 2 Samuel 20 >
1 Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé, “Àwa kò ní ipa nínú Dafidi, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jese! Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Israẹli!”
Aconteceu que estava ali um malvado, cujo nome era Sheba, filho de Bichri, um benjamita; e ele tocou a trombeta, e disse: “Não temos parte em David, nem herdamos no filho de Jesse. Cada homem para suas tendas, Israel”!
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
Assim, todos os homens de Israel passaram a seguir Davi, e seguiram Sabá, filho de Bicri; mas os homens de Judá se uniram ao seu rei, desde o Jordão até Jerusalém.
3 Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
David veio a sua casa em Jerusalém; e o rei levou as dez concubinas, que ele havia deixado para manter a casa, e as colocou sob custódia e lhes deu sustento, mas não as acolheu. Então elas ficaram fechadas até o dia de sua morte, vivendo na viuvez.
4 Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
Então o rei disse a Amasa: “Chame-me os homens de Judá juntos dentro de três dias, e esteja aqui presente”.
5 Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
Então Amasa foi chamar os homens de Judá juntos, mas ele ficou mais tempo do que o tempo estabelecido que lhe havia sido designado.
6 Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
David disse a Abishai: “Agora Sheba, o filho de Bichri, nos fará mais mal do que Absalom”. Pegue os servos de seu senhor e o persiga, para que ele não se transforme em cidades fortificadas, e escape de nossa vista”.
7 Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Os homens de Joab saíram atrás dele com os queretitas, os peletitas e todos os homens poderosos; e saíram de Jerusalém para perseguir Sebá, o filho de Bichri.
8 Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
Quando eles estavam na grande pedra que está em Gibeon, Amasa veio ao seu encontro. Joabe estava vestido com seu traje de guerra que havia colocado, e sobre ele estava uma faixa com uma espada presa na cintura em sua bainha; e enquanto ele ia junto, caiu para fora.
9 Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
Joab disse a Amasa: “Está tudo bem contigo, meu irmão?” Joab pegou Amasa pela barba com sua mão direita para beijá-lo.
10 Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Mas Amasa não deu atenção à espada que estava na mão de Joab. Então ele o golpeou com ela no corpo e derramou suas entranhas no chão, e não o golpeou novamente; e ele morreu. Joab e Abishai seu irmão perseguiram Sheba, o filho de Bichri.
11 Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
Um dos jovens de Joab ficou ao seu lado, e disse: “Aquele que favorece Joab, e aquele que é por David, que siga Joab!
12 Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
Amasa estava chafurdando em seu sangue no meio da rodovia. Quando o homem viu que todo o povo estava parado, ele levou Amasa para fora da rodovia e jogou uma roupa sobre ele quando viu que todos que passavam por ele estavam parados.
13 Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Quando ele foi retirado da rodovia, todas as pessoas foram atrás de Joab para perseguir Sheba, o filho de Bichri.
14 Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
Ele passou por todas as tribos de Israel até Abel, até Beth Maacah, e todos os beritas. Eles se reuniram e foram também atrás dele.
15 Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
Eles vieram e o cercaram em Abel de Beth Maacah, e levantaram um monte contra a cidade, e ele ficou contra a muralha; e todas as pessoas que estavam com Joabe bateram no muro para jogá-lo abaixo.
16 Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’”
Então uma mulher sábia gritou para fora da cidade: “Ouçam, ouçam! Por favor, diga a Joab: “Chegue aqui, para que eu possa falar com você”.
17 Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi náà ni.” Obìnrin náà sì wí fún un pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi ń gbọ́.”
Ele se aproximou dela; e a mulher disse: “Você é Joab?” Ele respondeu: “Eu sou”. Então ela lhe disse: “Ouça as palavras de seu servo”. Ele respondeu: “Estou ouvindo”.
18 Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
Então ela falou, dizendo: “Antigamente diziam: 'Certamente pedirão conselho na Abel', e assim resolveram um assunto.
19 Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
Eu estou entre os que são pacíficos e fiéis em Israel. Procura-se destruir uma cidade e uma mãe em Israel. Por que você engolirá a herança de Javé”?
20 Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
Joab respondeu: “Longe de mim, longe de mim, que eu deva engolir ou destruir”.
21 Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.” Obìnrin náà sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, orí rẹ̀ ni a ó sì sọ láti inú odi wá.”
O assunto não é assim. Mas um homem da região montanhosa de Efraim, Sabá, o filho de Bichri, levantou a mão contra o rei, até mesmo contra Davi. Basta entregá-lo, e eu irei embora da cidade”. A mulher disse a Joab: “Eis que sua cabeça será jogada sobre a parede”.
22 Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
Então a mulher foi a todas as pessoas em sua sabedoria. Eles cortaram a cabeça de Sheba, o filho de Bichri, e a jogaram fora para Joab. Ele tocou a trombeta, e eles foram dispersos da cidade, cada homem para sua tenda. Então Joabe voltou para Jerusalém, para o rei.
23 Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli; Benaiah ọmọ Jehoiada sì jẹ́ olórí àwọn Kereti, àti ti àwọn Peleti.
Now Joab estava sobre todo o exército de Israel, Benaiah, filho de Jehoiada, sobre os queretitas e sobre os peletitas,
24 Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.
Adoram estava sobre os homens sujeitos ao trabalho forçado, Jehosafá, filho de Ahilud, era o registrador,
25 Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé; Sadoku àti Abiatari sì ni àwọn àlùfáà.
Sheva era escriba, Zadok e Abiathar eram sacerdotes,
26 Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.
e Ira, o jairite, era ministro-chefe de Davi.