< 2 Samuel 20 >

1 Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé, “Àwa kò ní ipa nínú Dafidi, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jese! Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Israẹli!”
Vala pedig ott történetesen egy istentelen ember, kinek neve Séba vala, Bikrinek fia, Benjámin nemzetségéből való férfiú. Ez trombitát fuvata, és monda: Nincsen nékünk semmi közünk Dávidhoz, és semmi örökségünk nincsen az Isai fiában. Azért oh Izráel, oszoljatok el, kiki az ő sátorába.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
Eltávozék azért mind az Izráel népe Dávidtól Séba után, Bikri fia után. A Júda nemzetségéből valók azonban mellette maradának az ő királyoknak, a Jordán vizétől fogva mind Jeruzsálemig.
3 Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
Bemenvén pedig Dávid az ő házába Jeruzsálemben, előhozatá a király azt a tíz ágyasát, a kiket otthon hagyott vala a ház őrzésére; és őrizet alá rekeszté és tápláltatá azokat; de hozzájok be nem méne. És őrizet alatt lőnek haláloknak napjáig, özvegységben élvén.
4 Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
Monda pedig a király Amasának: Gyűjtsd össze nékem a Júda nemzetségét három nap alatt, és magad is itt légy jelen.
5 Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
Elméne azért Amasa, hogy összegyűjtse Júdát, de több ideig késék, mint a hogy a király meghagyta vala néki.
6 Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
Monda akkor Dávid Abisainak: Ímé majd gonoszabbul cselekeszik velünk Séba, Bikrinek fia, Absolonnál: Vedd magad mellé a te uradnak szolgáit, és kergesd meg őt, nehogy erős városokat szerezzen magának, és elmeneküljön előlünk.
7 Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Kimenének azért ő utána a Joáb emberei, és a Kereteusok és Peleteusok és az erősek mindnyájan, és kimenének Jeruzsálemből, hogy üldözzék Sébát, Bikrinek fiát.
8 Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
Mikor pedig ama nagy kősziklánál voltak, mely Gibeonnál van, Amasa jöve eleikbe; Joáb pedig ruhájába öltözvén, az ő ruháján felül derekához övedzett fegyvere a hüvelyében vala, mely mikor Joáb ment, leesék.
9 Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
És monda Joáb Amasának: Egészségben vagy-é atyámfia? És Joáb megfogá jobbkezével az Amasa szakálát, mintha meg akarná csókolni.
10 Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Amasa azonban nem őrizkedék a fegyvertől, mely Joáb kezében vala, és általüté őt az ötödik oldalborda alatt, és kiontá a bélit a földre, és noha többször nem üté által, mindazáltal meghala; Joáb pedig és Abisai, az ő atyjafia, üldözék azután Sébát, a Bikri fiát.
11 Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
Megálla pedig az Amasa teste felett Joábnak egy szolgája, és monda: Valaki Joábbal tart és Dávidnak javát kívánja, Joáb után siessen.
12 Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
Amasa pedig fetreng vala a vérben az útnak közepén; látván pedig egy ember, hogy ott mindenki megálla, kivoná Amasát az útról a mezőre, és ruhát vete ő reá; mivel látta, hogy valaki csak arra ment, mind megállott.
13 Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Minekutána pedig kivonták az útról, minden ember Joáb után siet vala, hogy üldözzék Sébát, Bikrinek fiát.
14 Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
És általméne Séba Izráelnek minden nemzetségein, Abelán és Béth-Maakán, és egész Béreán, kik egybegyűlvén, követik vala őt.
15 Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
És eljövén, körülfogták őt Abelában Béth-Maaka városában, és nagy töltést emelének a város ellen, mely a kőfallal egyenlő volt; és az egész nép, mely Joábbal vala, rombolá, hogy ledöntse a kőfalat,
16 Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’”
Akkor kiálta egy eszes asszony a városból: Halljátok meg, halljátok meg! Mondjátok meg, kérlek, Joábnak: Jőjj ide hozzám, valamit mondok néked!
17 Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi náà ni.” Obìnrin náà sì wí fún un pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi ń gbọ́.”
Ki mikor hozzá ment, monda az asszony: Te vagy-é Joáb? Felele: Én vagyok. Ki monda néki: Hallgasd meg a te szolgálóleányodnak szavát. És felele: Meghallgatom.
18 Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
Akkor monda az asszony: Korábban azt szokták mondani: Kérdezzék meg Abelát, és úgy végeztek.
19 Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
Én Izráel békeszerető hívei közül való vagyok, te pedig el akarsz pusztítani egy várost és anyát Izráelben? Miért akarod elnyelni az Úrnak örökségét?
20 Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
Akkor felele Joáb, és monda: Távol legyen, távol legyen az én tőlem, hogy elnyeljem és elveszessem!
21 Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.” Obìnrin náà sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, orí rẹ̀ ni a ó sì sọ láti inú odi wá.”
Nem úgy van a dolog, hanem egy ember az Efraim hegységéből való, a kinek neve Séba, a Bikri fia, felemelte kezét Dávid király ellen: adjátok kézbe azt egyedül, és elmegyek a város alól. És monda az asszony Joábnak: Ímé majd kivetjük a kőfalon a fejét néked.
22 Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
Elméne azért az asszony nagy eszesen az egész községhez, és elvágatá Sébának, a Bikri fiának fejét, és kiveték Joábnak. Akkor megfuvatá a trombitát, és hazaoszlának a város alól kiki az ő sátorába, Joáb pedig hazaméne Jeruzsálembe, a királyhoz.
23 Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli; Benaiah ọmọ Jehoiada sì jẹ́ olórí àwọn Kereti, àti ti àwọn Peleti.
Joáb pedig Izráel egész serege felett való volt, Benája pedig, Jójadának fia, a Kereteusok és Peleteusok vezére vala.
24 Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.
Adorám pedig adószedő, és Jósafát, Ahiludnak fia, emlékíró vala.
25 Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé; Sadoku àti Abiatari sì ni àwọn àlùfáà.
Séja íródeák, Sádók pedig és Abjátár papok valának.
26 Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.
A Jairból való Ira is Dávidnak fő embere vala.

< 2 Samuel 20 >