< 2 Samuel 20 >

1 Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé, “Àwa kò ní ipa nínú Dafidi, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jese! Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Israẹli!”
Na rĩrĩ, kwarĩ mũndũ wa ngũĩ wetagwo Sheba mũrũ wa Bikiri, Mũbenjamini, nake agĩkorwo aarĩ hau. Akĩhuha karumbeta, akĩanĩrĩra, akiuga atĩrĩ, “Ithuĩ tũtirĩ na igai harĩ Daudi, tũtirĩ na handũ harĩ mũrũ wa Jesii! O mũndũ nĩacooke hema-inĩ yake, inyuĩ andũ a Isiraeli!”
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
Nĩ ũndũ ũcio andũ othe a Isiraeli magĩtiganĩria Daudi, makĩrũmĩrĩra Sheba mũrũ wa Bikiri. No andũ a Juda makĩrũmĩrĩra mũthamaki wao kuuma Jorodani nginya Jerusalemu.
3 Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
Rĩrĩa Daudi aacookire gĩikaro kĩa nyũmba yake ya ũthamaki kũu Jerusalemu-rĩ, akĩoya thuriya iria ikũmi aatigĩte imenyagĩrĩre nyũmba ya ũthamaki, makĩigwo nyũmba marangagĩrwo. Nĩamaheaga irio, no ndaakomire nao. Maatũũraga marĩ ahingĩre na matariĩ ta atumia a ndigwa nginya mũthenya wa gũkua.
4 Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
Nake mũthamaki akĩĩra Amasa atĩrĩ, “Tũmanĩra andũ a Juda moke kũrĩ niĩ mũira wa matukũ matatũ mataanathira, nawe mwene ũgaakorwo ho.”
5 Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
No rĩrĩa Amasa aathiire gwĩta andũ a Juda, agĩikara ihinda iraaya kũrĩ rĩrĩa mũthamaki aamwĩrĩte.
6 Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
Daudi akĩĩra Abishai atĩrĩ, “Rĩu Sheba mũrũ wa Bikiri nĩegũtũgera ngero nene kũrĩ ĩrĩa twagerirwo nĩ Abisalomu. Oya andũ a mwathi waku mũmũtengʼerie, kwaga ũguo aahota kuona matũũra mairigĩre oorĩre kuo, na ithuĩ twage kũmuona.”
7 Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Nĩ ũndũ ũcio andũ a Joabu, na Akerethi, na Apelethi, na njamba ciothe iria ciarĩ hinya makiumagara matongoretio nĩ Abishai. Nao magĩthiĩ moimĩte Jerusalemu, matengʼeretie Sheba mũrũ wa Bikiri.
8 Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
Rĩrĩa maarĩ ihiga-inĩ rĩrĩa inene kũu Gibeoni, Amasa agĩũka kũmatũnga. Joabu eehumbĩte nguo ciake cia mbaara, na akehotora mũcibi na rũhiũ rũrĩ njora thĩinĩ. Rĩrĩa aathiire mbere, rũhiũ rũu rũkiuma njora-inĩ.
9 Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
Joabu akĩĩra Amasa atĩrĩ, “Ũrĩ mwega, mũrũ wa baba?” Hĩndĩ ĩyo Joabu akĩnyiita Amasa nderu na guoko gwake kwa ũrĩo nĩguo amũmumunye.
10 Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Amasa ndaatindanĩrĩire na rũhiũ rũrĩa Joabu aanyiitĩte na guoko, nake Joabu akĩmũtheeca nda naruo, namo mara make makiuma makĩgũa thĩ, na ndaigana kũmũtheeca rĩngĩ, nake Amasa agĩkua. Ningĩ Joabu na mũrũ wa nyina Abishai magĩtengʼeria Sheba mũrũ wa Bikiri.
11 Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
Ũmwe wa andũ a Joabu akĩrũgama mwena-inĩ wa Amasa, akiuga atĩrĩ, “Mũndũ ũrĩa wothe ũrĩ mwena wa Joabu na mwena wa Daudi, nĩarũmĩrĩre Joabu!”
12 Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
Nake Amasa eegaragaragia thakame-inĩ yake arĩ njĩra gatagatĩ, nake mũndũ ũcio akĩona atĩ mbũtũ ciothe cia ita nĩciarũgamaga hau. Rĩrĩa aamenyire atĩ o mũndũ aakinyaga harĩ Amasa akarũgama-rĩ, akĩmũkururia kuuma njĩra-inĩ, akĩmũiga gĩthaka-inĩ, na akĩmũhumbĩra na nguo.
13 Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Amasa aarĩkia kweherio njĩra-inĩ, andũ othe makĩrũmĩrĩra Joabu, magĩtengʼeria Sheba mũrũ wa Bikiri.
14 Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
Sheba akĩhĩtũkĩra mĩhĩrĩga-inĩ yothe ya Isiraeli, agĩkinya Abeli-Bethi-Maaka, akĩhĩtũkĩra bũrũri-inĩ wothe wa Aberi, arĩa moonganire hamwe na makĩmũrũmĩrĩra.
15 Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
Nacio mbũtũ ciothe cia ita hamwe na Joabu igĩũka na ikĩrigiicĩria Sheba kũu Abeli-Bethi-Maaka. Magĩthondeka kĩhumbu gĩa tĩĩri kũrigania na itũũra, nakĩo gĩkĩambatio nginya rũthingo rwa na nja rwa ũgitĩri wa itũũra. Na rĩrĩa maahũũraga rũthingo nĩguo marũmomore-rĩ,
16 Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’”
mũndũ-wa-nja ũmwe mũũgĩ agĩĩtana arĩ thĩinĩ wa itũũra rĩu, akiuga atĩrĩ, “Ta thikĩrĩriai! Ta thikĩrĩriai! Ĩrai Joabu oke haha nĩguo njarie nake.”
17 Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi náà ni.” Obìnrin náà sì wí fún un pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi ń gbọ́.”
Nake agĩthiĩ erekeire harĩ we; nake mũndũ-wa-nja ũcio akĩmũũria atĩrĩ, “Wee nĩwe Joabu?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Ĩĩ nĩ niĩ.” Nake akiuga atĩrĩ, “Gĩthikĩrĩrie ũrĩa ndungata yaku ĩkuuga.” Nake akiuga atĩrĩ, “Nĩ thikĩrĩirie.”
18 Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
Mũndũ-wa-nja ũcio agĩthiĩ na mbere kwaria, akiuga atĩrĩ, “Tene-rĩ, ciugo ici nĩciaragio, gũkeerwo atĩrĩ ‘Andũ makaahooyaga kĩrĩra kũu Abeli.’ Naguo ũhoro ũgaathirĩra kuo.
19 Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
Ithuĩ-rĩ, tũrĩ andũ a thayũ na ehokeku thĩinĩ wa Isiraeli. Wee ũrageria kwananga itũũra rĩĩrĩ, na nĩrĩo nyina wa Isiraeli. Nĩ kĩĩ gĩgũtũma wende kũniina igai rĩa Jehova?”
20 Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
Joabu agĩcookia atĩrĩ, “Ũhoro ũcio ũrondaihĩrĩria! Ũhoro wa kũniina na kwananga ũrondaihĩrĩria!
21 Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.” Obìnrin náà sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, orí rẹ̀ ni a ó sì sọ láti inú odi wá.”
Ũguo tiguo ũhoro ũtariĩ. Mũndũ wĩtagwo Sheba mũrũ wa Bikiri, kuuma bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma wa Efiraimu, nĩarĩkĩtie kwambararia guoko ookĩrĩre mũthamaki, ookĩrĩre Daudi. Tũnengerei mũndũ ũcio ũmwe tu, na nĩngũtigana na itũũra rĩĩrĩ.” Mũndũ-wa-nja ũcio akĩĩra Joabu atĩrĩ, “Nĩũgũikĩrio mũtwe wake kuuma rũthingo-inĩ.”
22 Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
Hĩndĩ ĩyo mũtumia ũcio agĩthiĩ kũrĩ andũ othe arĩ na mataaro macio make ma ũũgĩ, nao magĩtinia mũtwe wa Sheba mũrũ wa Bikiri, makĩũikĩria Joabu. Nĩ ũndũ ũcio Joabu akĩhuha karumbeta, nao andũ ake makĩharagana kuuma itũũra-inĩ, o mũndũ agĩcooka gwake mũciĩ. Nake Joabu agĩcooka kũrĩ mũthamaki kũu Jerusalemu.
23 Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli; Benaiah ọmọ Jehoiada sì jẹ́ olórí àwọn Kereti, àti ti àwọn Peleti.
Joabu nĩwe warĩ mũnene wa mbũtũ ciothe cia ita cia Isiraeli; nake Benaia mũrũ wa Jehoiada aarĩ mũnene wa Akerethi, o na Apelethi;
24 Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.
Adoniramu aarĩ mũtongoria wa kũrutithia wĩra wa hinya; nake Jehoshafatu mũrũ wa Ahiludu nĩwe warĩ mwandĩki wa maũndũ ma ihinda rĩu;
25 Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé; Sadoku àti Abiatari sì ni àwọn àlùfáà.
nake Sheva nĩwe warĩ mwandĩki-marũa; Zadoku na Abiatharu maarĩ athĩnjĩri-Ngai;
26 Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.
nake Ira, ũrĩa Mũnjairi, aarĩ mũthĩnjĩri-Ngai wa Daudi.

< 2 Samuel 20 >