< 2 Samuel 20 >

1 Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé, “Àwa kò ní ipa nínú Dafidi, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jese! Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Israẹli!”
Benjamin miphun Bikhri capa a min teh Sheba tie taran ka thaw e buet touh ao. Ahni ni mongka a ueng teh Oe Isarel miphun maimouh teh Devit koevah, buet touh hai coe hane tawn awh hoeh. Jesi capa koevah râw coe hane kamcu awh hoeh. Isarelnaw namamae rim koe lengkaleng cet awh telah atipouh.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
Isarelnaw ni Devit hnukkâbang awh hoeh toe. Bikhri capa Sheba hnuk a kâbang awh. Judahnaw ni Jordan hoi Jerusalem kho totouh siangpahrang koe a kâhnai awh.
3 Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
Devit ni Jerusalem ama im a pha toteh, siangpahrang ni a yudo 10 touh im ka ring hanelah a hruek e hah a ceikhai teh, a paung. A canei kapoenaw ni canei kawi a poe awh ei teh, amamouh koe kâen awh hoeh. A due hnin totouh a paung awh teh lahmainaw patetlah ao awh.
4 Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
Siangpahrang ni Amasa koevah, hnin thum touh thung Judahnaw hah kamkhueng sak nateh, ahnimouh hoi rei na tho han telah atipouh.
5 Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
Judahnaw kamkhueng sak hanelah Amasa teh a cei. Hatei, Devit teh a hnin a khoe e hlak hnuk a teng.
6 Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
Devit ni Abishai koevah Bikhri capa Sheba ni Absalom hlak hai runae na poe han, na bawipa e sannaw kaw nateh ahnimanaw pâlei awh telah hoehpawiteh, ahni teh kacakpounge kho buetbuet touh kâen vaiteh, maimae kut dawk hoi a hlout han doeh telah Abishai koe a dei pouh.
7 Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Joab e taminaw Kereth tami, Phelet taminaw hoi tami a thakasainaw ni a hnukkâbang awh. Jerusalem hoi Bikhri capa Sheba pâlei hanelah a kamthaw awh.
8 Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
Gideon kho dawk e lungsong onae koe a pha awh toteh, Amasa ni ahnimanaw a dawn. Joab ni puengcang a kâmahrawk teh a keng dawk taisawm hoi tahloi a neng. A cei nalaihoi tahloi a yut teh a bo.
9 Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
Joab ni Amasa koevah, ka nawngha na dam ou telah ati. Joab ni a kâsak teh a paco han a dei teh a pâkhamuen a rang lae kut hoi a kuet.
10 Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Joab ni avoilae kut dawk sarai a sin e hah Amasa ni a pouk hoeh dawkvah, a von dawk a thut pouh teh a ruen hah talai dawk a bo. Bout thun hoeh toe. Amasa teh a due. Joab hoi a nawngha Abishai ni Bikhri capa Sheba hah a pâlei roi.
11 Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
Ahni e a teng Joab e tami buet touh a kangdue teh, Joab hoi Devit koelah ka kampang e pueng ni Joab heh pou ring naseh telah a ti.
12 Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
Amasa teh lam dawkvah a thi hoi pukkâkaawk. Ka tho pueng ni a hmu awh teh a kangdue awh. Joab e tami ni taminaw a kangdue e a hmu awh toteh, Amasa e a ro hah lam dawk hoi a la awh teh, kahrawng vah a puen awh teh hni hoi a ramuk awh.
13 Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Haw e lam dawk hoi a puen awh hnukkhu, Bikhri capa Sheba pâlei hanelah taminaw ni, Joab e hnuk a kâbang awh.
14 Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
Joab ni Bethmaakha ram Abel kho totouh Isarel ram pueng koe a cei. Bere taminaw koehai a cei teh taminaw a pâkhueng teh, Sheba hnuk a kâbang awh.
15 Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
Sheba a luennae Bethmaakha ram Abel kho hah a kalup awh. A kho teng vah talai avoivang lah a paten awh. Rapan raphoe hanelah thouk a phom awh.
16 Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’”
Hatnavah, a lungkaang e napui buet touh ni khothung hoi a hram teh a dei e teh, thai awh haw, thai awh. Kai ni Joab hoi lawk ka dei thai nahanelah tho loe telah Joab koe dei pouh awh telah a ti.
17 Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi náà ni.” Obìnrin náà sì wí fún un pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi ń gbọ́.”
Joab rek a hnai teh napui ni nang hah Joab vai khe, telah a pacei. Oe kai doeh atipouh. Napui ni kaie lawk thai haw atipouh navah, Joab ni ka thai doeh telah atipouh.
18 Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
Ayan teh Abel kho vah kho a khang awh han rah, ouk ati awh. Hottelah laidei pou a tâtueng awh.
19 Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
Kai teh Isarelnaw dawk roumnae ka ngai e hoi yuemkamcu e lah ka o. Nang teh Isarel kho koung raphoe hanelah na kâcai. Bangkongmaw BAWIPA e râw hah he pahma hanelah na kâcai telah a dei.
20 Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
Joab ni he pâhma hane, raphoe hane kâcainae awm hoeh bo.
21 Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.” Obìnrin náà sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, orí rẹ̀ ni a ó sì sọ láti inú odi wá.”
Hottelah nahoeh bo, Ephraim mon dawk e Bikhri capa a min teh Sheba ni amae siangpahrang hah a taran toe. Ahni hah na poe awh haw. Na poe awh pawiteh kho dawk hoi ka tâco han telah ati. Napui ni Joab koevah, khenhaw! a lû teh rapan hloilah ka tâkhawng han telah a ti.
22 Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
Hote napui teh a lungang e patetlah taminaw koe a cei hnukkhu, Bikhri capa Sheba lû a tâtueng awh teh Joab koelah alawilah a tâkhawng pouh awh. Joab ni mongka a ueng teh taminaw teh hote kho dawk hoi amamouh onae koe bout a ban awh. Hahoi, Joab teh Jerusalem siangpahrang koe a ban.
23 Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli; Benaiah ọmọ Jehoiada sì jẹ́ olórí àwọn Kereti, àti ti àwọn Peleti.
Joab teh Isarel ransanaw e ransabawi lah ao. Jehoiada capa Benaiah teh Kereth tami hoi Pelet taminaw kaukkung lah ao.
24 Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.
Adoram teh tamuk thaw ka kuen e lah ao. Ahilud capa Jehoshaphat teh kamthang kathutkung lah ao.
25 Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé; Sadoku àti Abiatari sì ni àwọn àlùfáà.
Sheva teh ca kathunkung lah ao. Zadok hoi Abiathar teh vaihma lah ao.
26 Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.
Jair tami teh Devit e ram kaukkung bawi lah ao.

< 2 Samuel 20 >