< 2 Samuel 20 >

1 Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé, “Àwa kò ní ipa nínú Dafidi, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jese! Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Israẹli!”
Te vaengah hlang muen pakhat om, a ming tah Benjamin hlang, Bikhri capa Sheba ni. Tuki te a ueng tih, “Mamih kah hamsum he David ham moenih, mamih kah rho he Jesse capa taengah a om ham moenih. Israel rhoek te amah kah dap la boeih cet saeh,” a ti.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
Te dongah Israel hlang boeih tah David hnuk lamloh Bikhri capa Sheba hnuk la cet uh. Tedae Judah hlang tah Jordan lamloh Jerusalem duela a manghai nen ni a kibaeng uh.
3 Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
David te Jerusalem kah amah im la a pawk vaengah im tawt la a paih a yula huta parha te manghai loh a loh tih im hloeh ah a khueh. Amih te a cangbam van ngawn dae amih taengla moe pah voel pawh. Amih te a duek hnin duela a daengdaeh dongah a khosaknah he nuhmai la om uh.
4 Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
Manghai loh Amasa taengah, “Hnin thum khuiah Judah hlang te kamah taengla hueh lamtah namah khaw pahoi om,” a ti nah.
5 Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
Amasa loh Judah rhoek te hueh hamla cet ngawn dae uelh, uelh tih tingtunnah te a khueh.
6 Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
Te dongah David loh Abishai taengah, “Absalom lakah Bikhri capa Sheba loh mamih taengah thae a huet pawn ni. Namah loh na boeipa kah sal rhoek ke khuen lamtah a hnukah hloem laeh. Khopuei vong cak te anih loh hmuh vetih mamih mikhmuh ah huul uh ve,” a ti nah.
7 Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Te dongah Joab kah hlang rhoek, Kerethi, Phelethi neh hlangrhalh boeih tah anih hnukah cet uh tih, Bikhri capa Sheba hnuk hloem hamla Jerusalem lamloh khoong uh.
8 Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
Amih te Gibeon lungnu ah a om uh vaengah Amasa te amih mikhmuh ah a pawk pah. Te dongah Joab loh a himbai neh a pueinak te a muk. Capang dongkah cunghang te cihin neh a cinghen ah a sol dae a khuen vaengah vik a colh pah.
9 Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
Joab loh Amasa te, “Ka manuca na sading a?” a ti nah. Te phoeiah anih te mok hamla Amasa hnapae te Joab kah bantang kut neh a tuuk.
10 Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Te vaengah Joab kut dongkah cunghang te Amasa loh hmuethmat pawh. Te dongah Amasa te tumca neh a bung ah a laih tih a bung te diklai la pawk a sop pah. Anih te a talh mueh la duek. Te phoeiah Joab neh a mana Abishai loh Bikhri capa Sheba te a hloem.
11 Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
Te vaengah Joab kah tueihyoeih khui lamkah hlang pakhat te a taengah pai tih, “U khaw Joab taengla aka naep tih u khaw David ham aka ti te tah Joab hnukah bat saeh,” a ti.
12 Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
Amasa tah long lung ah a thii neh a bol vaengah hlang pakhat loh a hmuh. Te dongah pilnam te boeih a hloh tih Amasa te longpuei lamloh lohma la a thoeih uh. Anih taengla aka thoeng boeih loh a hmuh vaengah a pai thil tih anih te himbai a khuk thil.
13 Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
Long lamloh a khoe van nen tah hlang boeih loh Bikhri capa Sheba hnuk hloem hamla Joab te a paan.
14 Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
Te vaengah Israel koca boeih te Abel lungnu neh Bethmaakha due, Beree boeih te khaw a hil. Te dongah coi tih, tingtun uh tih a hnukah bang uh.
15 Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
Abelbethmaakah a pha uh vaengah anih te koep a dum uh. Khopuei te tanglung malh a lun thil uh tih rhalmahvong te a pai thil. Joab neh a pilnam pum loh vongtung te cungku sak ham a thuk.
16 Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’”
Te vaengah khopuei lamkah huta aka cueih te pang tih, “Hnatun, hnatun uh mai lah, Joab te, ‘Hela ha mop lamtah namah taengah ka thui eh,’ ti nah dae,” a ti.
17 Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi náà ni.” Obìnrin náà sì wí fún un pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi ń gbọ́.”
A taengla a thoeng pah vaengah huta loh, “Joab nang a,” a ti nah. Te dongah, “Kai ni ue,” a ti nah. Te phoeiah, “Na salnu kah ol he hnatun lah,” a ti nah hatah, “Ka hnatun ngawn,” a ti nah.
18 Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
Te phoeiah, “A thui lam khaw thui pah. Hlamat ah a thui uh tih, ‘Abel ah toem la toem uh tih cing uh,’ a ti lah ko.
19 Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
Kai long tah Israel he oltak la ka thuung vaengah nang long tah khopuei neh Israel khuikah a manu te ngawn ham na mae. Balae tih BOEIPA kah rho na yoop eh?” a ti nah.
20 Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
Joab loh a doo tih, “Savisava la savisava, kai lamloh aka yoop mai tih aka phae mai te.
21 Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.” Obìnrin náà sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, orí rẹ̀ ni a ó sì sọ láti inú odi wá.”
He tah ol voel moenih. Tedae Ephraim tlang kah hlang pakhat, Bikhri capa, a ming ah Sheba loh manghai David te a kut a luklek thil. Anih bueng mah han tloeng lamtah khopuei lamloh ka nong bitni,” a ti nah. Te vaengah huta loh Joab taengah, “A lu te vongtung lamloh namah taengla ham voeih coeng te,” a ti nah.
22 Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
Huta loh pilnam boeih te a cueihnah neh a paan dongah Bikhri capa Sheba kah a lu te a rhaih pa uh tih Joab taengla a voeih uh. Te daengah tuki te a ueng tih, hlang khopuei lamloh amah kah dap duela taekyak uh. Te phoeiah Joab te Jerusalem kah manghai taengla koep mael.
23 Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli; Benaiah ọmọ Jehoiada sì jẹ́ olórí àwọn Kereti, àti ti àwọn Peleti.
Te dongah Israel caempuei boeih te Joab loh, Kerethi neh Phelethi te Jehoiada capa Benaiah loh,
24 Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.
Adoram loh saldong boei, Ahilud capa Jehoshaphat loh khokhuen cabu,
25 Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé; Sadoku àti Abiatari sì ni àwọn àlùfáà.
Sheva te cadaek, Zadok neh Abiathar loh khosoih te a ngol thil.
26 Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.
Jairi Ira khaw David taengah khosoih la om van.

< 2 Samuel 20 >