< 2 Samuel 2 >
1 Lẹ́yìn àkókò yìí, Dafidi wádìí lọ́wọ́ Olúwa. Ó sì béèrè pé, “Ṣé èmi lè gòkè lọ sí ọ̀kan lára àwọn ìlú Juda?” Olúwa sì wí pé, “Gòkè lọ.” Dafidi sì béèrè pé, “Ní ibo ni kí èmi kí ó lọ?” Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Sí Hebroni.”
Après cela, David consulta le Seigneur, disant: Irai-je en l'une des villes de Juda? Et le Seigneur lui répondit: Va. Et David demanda: Où irai- je? A Hébron, reprit le Seigneur.
2 Nígbà náà ni Dafidi gòkè lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ méjì Ahinoamu ará Jesreeli, àti Abigaili obìnrin opó Nabali ti Karmeli.
Et David partit pour Hébron, avec ses deux femmes Achinoam la Jezraélite et Abigaïl, femme de Nabal du Carmel,
3 Dafidi sì mú àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, olúkúlùkù pẹ̀lú ìdílé rẹ̀, wọ́n sì ń gbé ní Hebroni àti ìlú rẹ̀ mìíràn.
Et avec ses hommes, chacun emmenant sa famille; ainsi, ils habitèrent les villes d'Hébron.
4 Nígbà náà àwọn ọkùnrin ará Juda wá sí Hebroni, níbẹ̀ ni wọ́n ti fi àmì òróró yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba lórí ilé Juda. Nígbà tí wọ́n sọ fún Dafidi pé, àwọn ọkùnrin ti Jabesi Gileadi ni ó sin òkú Saulu,
Alors, des hommes de la Judée vinrent, et ils sacrèrent David pour qu'il régnât sur la tribu de Juda; ces hommes lui apprirent que ceux de Jabès-Galaad avaient inhumé Saül.
5 Dafidi rán oníṣẹ́ sí àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi láti sọ fún wọn pé, “Olúwa bùkún un yín fún fífi inú rere yín hàn sí Saulu ọ̀gá yín nípa sí sin ín.
Et David envoya des messagers aux chefs de Jabès-Galaad, et il leur dit: Bénis soyez-vous par le Seigneur, parce que vous avez été miséricordieux envers votre maître, envers Saül l'oint du Seigneur, et que vous l'avez inhumé, lui et son fils Jonathan.
6 Kí Olúwa kí ó fi inú rere àti òtítọ́ fún un yín, èmi náà yóò sì san oore yìí fún un yín, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí.
Que le Seigneur vous traite selon sa miséricorde et sa vérité; pour moi, j'en userai bien avec vous, parce que vous avez bien agi.
7 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ara yín le, kí ẹ sì ní ìgboyà, nítorí Saulu ọba yín ti kú, ilé Juda sì ti fi àmì òróró yàn mí ní ọba lórí wọn.”
Et maintenant que vos mains soient fortes; soyez vaillants vous-mêmes; car votre maître Saül n'est plus, et la maison de Juda m'a sacré, afin que je règne sur elle.
8 Lákòókò yìí, Abneri ọmọ Neri olórí ogun Saulu ti mú Iṣboṣeti ọmọ Saulu, ó sì mú un kọjá sí Mahanaimu.
Mais, Abner, fils de Ner, général de Saül, prit Isboseth, fils de Saül, et il l'emmena du camp de Manaam,
9 Ó sì fi jẹ ọba lórí Gileadi Aṣuri àti Jesreeli àti lórí Efraimu àti lórí Benjamini àti lórí gbogbo Israẹli.
Et il le fit reconnaître roi par la contrée de Galaad, par Thasiri, par Jezraël, par Ephrahn, par Benjamin, par tout Israël.
10 Iṣboṣeti ọmọ Saulu sì jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí ó jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjì. Ilé Juda sì ń tọ Dafidi lẹ́yìn.
Isboseth, fils de Saül, avait quarante ans lorsqu'il devint roi d'Israël; il régna deux ans, hormis sur la maison de Juda, qui obéissait à David.
11 Gbogbo àkókò tí Dafidi fi jẹ ọba ní Hebroni lórí ilé Juda sì jẹ́ ọdún méje àti oṣù mẹ́fà.
Et David régna à Hébron sur la maison de Juda, sept ans et demi.
12 Abneri ọmọ Neri pẹ̀lú àwọn ọkùnrin ti Iṣboṣeti ọmọkùnrin Saulu kúrò ní Mahanaimu, wọ́n sì lọ sí Gibeoni.
Cependant, Abner, fils de Ner, et les serviteurs d'Isboseth, fils de Saül, s'en allèrent de Manaam en Gabaon.
13 Joabu ọmọ Seruiah pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Dafidi jáde lọ láti lọ bá wọn ní adágún Gibeoni. Ẹgbẹ́ kan sì jókòó ní apá kan adágún, àti ẹgbẹ́ kejì ní apá kejì adágún.
De son côté, Joab, fils de Sarvia, avec la troupe de David, sortit d'Hébron, et il arriva en même temps qu'eux vers la fontaine de Gabaon; ils campèrent les uns en deçà, les autres au delà de la fontaine.
14 Nígbà náà, Abneri sọ fún Joabu pé, “Jẹ́ kí díẹ̀ nínú àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yìí ó dìde láti bá ara wọn jà níwájú wa.” Joabu sì dáhùn pé, “Ó dára, jẹ́ kí wọ́n ṣe é.”
Et Abner dit à Joab: Que ces jeunes gens se lèvent et qu'ils viennent jouer devant nous; à quoi Joab répondit: Qu'ils se lèvent.
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dìde sókè, a sì kà wọ́n sí ọkùnrin méjìlá fún Benjamini àti Iṣboṣeti ọmọ Saulu àti méjìlá fún Dafidi.
Et douze des serviteurs d'Isboseth, fils de Saül, tous de la tribu de Benjamin, se portèrent à la rencontre de douze serviteurs de David.
16 Nígbà náà olúkúlùkù ọkùnrin gbá ẹnìkejì rẹ̀ mú ní orí, ó sì fi idà gún ẹnìkejì rẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́, wọ́n sì ṣubú lulẹ̀ papọ̀. Bẹ́ẹ̀ ni ibẹ̀ ni Gibeoni ti à ń pè ni Helikatihu Hasurimu.
Et chacun saisit d'une main la tête de celui qui lui faisait face, puis, de l'autre main, il lui enfonça dans le flanc son épée, et ils tombèrent tous en même temps. Et l'on appela ce lieu qui est en Gabaon, le Champ des Traîtres.
17 Ogun náà ní ọjọ́ náà gbóná. Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì ṣẹ́gun Abneri pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Israẹli.
Ce jour-là, il y eut une terrible bataille; Abner et les hommes d'Israël échouèrent devant les serviteurs de David.
18 Àwọn ọmọkùnrin Seruiah mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ni ó wà níbẹ̀: Joabu, Abiṣai àti Asaheli. Nísinsin yìí ẹsẹ̀ Asaheli sì fẹ́rẹ̀ bí ẹsẹ̀ èsúró tí ó wà ní pápá.
Il se trouvait là trois fils de Sarvia, Joab, Abessa et Asaël; or, Asaël avait les pieds légers comme un daim libre dans les champs.
19 Asaheli sì ń lépa Abneri, bí òun tí ń lọ kò sì yípadà sí ọ̀tún tàbí sí òsì láti máa tọ́ Abneri lẹ́yìn.
Et Asaël se lança à la poursuite d'Abner; il s'attacha à ses pas, sans s'écarter à droite ni à gauche.
20 Abneri bojú wo ẹ̀yìn rẹ̀, Ó sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ Asaheli ni?” Ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni.”
Abner regardant derrière lui, s'écria: N'es-tu pas Asaël? l'autre reprit: Je le suis.
21 Nígbà náà, Abneri sọ fún un pé, “Yípadà sí ọ̀tún tàbí òsì; mú ọ̀kan lára àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kí o sì bọ́ ìhámọ́ra rẹ.” Ṣùgbọ́n Asaheli kọ̀ láti dẹ́kun lílépa rẹ̀.
Abner lui dit: Détourne-toi à droite ou à gauche, attaque l'un des jeunes serviteurs, et prends pour toi ses armes. Mais Asaël refusa de s'écarter ni à droite ni à guiche.
22 Abneri tún kìlọ̀ fún Asaheli, “Dẹ́kun lílépa mi! Èéṣe tí èmi yóò fi lù ọ́ bolẹ̀? Báwo ni èmi yóò ti wo arákùnrin rẹ Joabu lójú?”
Abner continua de lui parler, disant: Éloigne-toi donc de moi, de peur que d'un coup je ne t'étende à terre; comment alors oserais-je lever les yeux devant Joab?
23 Ṣùgbọ́n ó sí kọ̀ láti padà, Abneri sì fi òdì ọ̀kọ̀ gún un lábẹ́ inú, ọ̀kọ̀ náà sì jáde ní ẹ̀yìn rẹ̀: òun sì ṣubú lulẹ̀ níbẹ̀, ó sì kú ní ibi kan náà; ó sí ṣe gbogbo ènìyàn tí ó dé ibi tí Asaheli gbé ṣubú si, tí ó sì kú, sì dúró jẹ́.
Où en veux-tu venir? Retourne vers Joab, ton frère. Mais il ne voulut pas s'éloigner, et Abner le frappa du bas de sa javeline au ventre, la pointe ressortit par les reins. Asaël tomba, et il mourut en s'affaissant sur lui-même; tous ceux qui arrivèrent au lieu où il était mort s'arrêtèrent autour de lui.
24 Joabu àti Abiṣai sì lépa Abneri: oòrùn sì wọ̀, wọ́n sì dé òkè ti Amima tí o wà níwájú Giah lọ́nà ijù Gibeoni.
Et Joab et Abessa s'élancèrent à la poursuite d'Abner; le soleil se couchait alors; et ils allèrent jusqu'à la colline d'Amma, qui est en face d'Haï, où monte le chemin du désert de Gabaon.
25 Àwọn ọmọ Benjamini sì kó ara wọn jọ wọ́n tẹ̀lé Abneri, wọ́n sì wá di ẹgbẹ́ kan, wọ́n sì dúró lórí òkè kan.
Mais les fils de Benjamin, s'étant ralliés auprès de la troupe d'Abner, ne formaient plus qu'un seul corps; ils se rangèrent sur la crête d'une colline.
26 Abneri sì pe Joabu, ó sì bi í léèrè pé, “Idà yóò máa parun títí láéláé bí? Ǹjẹ́ ìwọ kò ì tí ì mọ̀ pé yóò korò níkẹyìn? Ǹjẹ́ yóò ha ti pẹ́ tó kí ìwọ tó sọ fún àwọn ènìyàn náà, kí wọ́n dẹ́kun láti máa lépa arákùnrin wọn.”
Et Abner appela Joab, et il lui dit: Est-ce que l'épée dévorera sans relâche? Ne sais-tu pas qu'elle peut devenir amère à la fin? Qu'attends-tu donc pour ordonner aux tiens de ne plus poursuivre nos frères?
27 Joabu sì wí pé, “Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, bí kò ṣe bí ìwọ ti wí, nítòótọ́ ní òwúrọ̀ ni àwọn ènìyàn náà ìbá padà lẹ́yìn arákùnrin wọn.”
Et Joab répondit: Vive le Seigneur! si tu n'avais parlé, aucun des nôtres qui, depuis le matin, poursuivent leurs frères, ne se fût arrêté.
28 Joabu sì fọ́n ìpè, gbogbo ènìyàn sì dúró jẹ́ẹ́, wọn kò sì lépa Israẹli mọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì tún jà mọ́.
Et Joab sonna de la trompette, et toute l'armée s'arrêta; elle ne poursuivit plus Israël, et le combat finit.
29 Abneri àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì fi gbogbo òru náà rìn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì kọjá Jordani, wọ́n sì rìn ní gbogbo Bitironi, wọ́n sì wá sí Mahanaimu.
Partis le soir même, Abner et ses hommes marchèrent toute la nuit; ils traversèrent le Jourdain, le côtoyèrent et rentrèrent dans leur camp.
30 Joabu sì dẹ́kun àti máa tọ Abneri lẹ́yìn: ó sì kó gbogbo àwọn ènìyàn náà jọ, ènìyàn mọ́kàndínlógún ni ó kú pẹ̀lú Asaheli nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi.
Joab revint sur ses pas, laissant partir Abner; il rassembla tout le peuple, et il vit que des serviteurs de David, il manquait dix-neuf hommes outre Asaël.
31 Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì pa nínú àwọn ènìyàn Benjamini: nínú àwọn ọmọkùnrin Abneri; òjìdínnírinwó ènìyàn.
Et les serviteurs de David avaient tué trois cent soixante des fils de Benjamin, qui accompagnaient Abner.
32 Wọ́n si gbé Asaheli wọ́n sì sin ín sínú ibojì baba rẹ̀ tí ó wà ní Bẹtilẹhẹmu. Joabu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ fi gbogbo òru náà rìn, ilẹ̀ sì mọ́ wọn sí Hebroni.
Et ils emportèrent le corps d'Asaël pour l'ensevelir à Bethléem, dans le sépulcre de son père; Joab et ses hommes marchèrent aussi toute la nuit; le jour paraissait quand ils arrivèrent à Hébron.