< 2 Samuel 2 >

1 Lẹ́yìn àkókò yìí, Dafidi wádìí lọ́wọ́ Olúwa. Ó sì béèrè pé, “Ṣé èmi lè gòkè lọ sí ọ̀kan lára àwọn ìlú Juda?” Olúwa sì wí pé, “Gòkè lọ.” Dafidi sì béèrè pé, “Ní ibo ni kí èmi kí ó lọ?” Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Sí Hebroni.”
He hnukah khaw David loh BOEIPA te a dawt tih, “Judah khopuei pakhat la ka cet aya?” a ti nah. Te vaengah anih te BOEIPA loh, “Cet saw,” a ti nah. Te dongah David loh, “Melam ka caeh eh?,” a ti nah. Te vaengah, “Hebron la,” a ti nah.
2 Nígbà náà ni Dafidi gòkè lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ méjì Ahinoamu ará Jesreeli, àti Abigaili obìnrin opó Nabali ti Karmeli.
Te dongah David te a yuu rhoi, Jezreel nu Ahinoam, Karmel Nabal yurho Abigal neh a caeh puei.
3 Dafidi sì mú àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, olúkúlùkù pẹ̀lú ìdílé rẹ̀, wọ́n sì ń gbé ní Hebroni àti ìlú rẹ̀ mìíràn.
Amah taengkah a hlang rhoek khaw David loh a cako neh rhip a caeh puei tih Hebron khopuei rhoek ah kho a sak uh.
4 Nígbà náà àwọn ọkùnrin ará Juda wá sí Hebroni, níbẹ̀ ni wọ́n ti fi àmì òróró yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba lórí ilé Juda. Nígbà tí wọ́n sọ fún Dafidi pé, àwọn ọkùnrin ti Jabesi Gileadi ni ó sin òkú Saulu,
Te vaengah Judah hlang rhoek te ha pawk uh tih David te Judah imkhui kah manghai la pahoi a koelh uh. Te phoeiah Jabesh Gilead hlang rhoek loh Saul a up uh te thui ham David taengla puen uh.
5 Dafidi rán oníṣẹ́ sí àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi láti sọ fún wọn pé, “Olúwa bùkún un yín fún fífi inú rere yín hàn sí Saulu ọ̀gá yín nípa sí sin ín.
Jabesh hlang rhoek taengla David loh puencawn a hlah tih,” Sitlohnah he na boei rhoek taeng neh Saul taengah khaw na saii uh tih anih na up uh dongah BOEIPA rhang neh na yoethen uh.
6 Kí Olúwa kí ó fi inú rere àti òtítọ́ fún un yín, èmi náà yóò sì san oore yìí fún un yín, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí.
BOEIPA loh nangmih ham sitlohnah neh uepomnah han saii saeh. Hekah hno na saii uh dogah kai long khaw nangmih taengah hnothen he ka saii van bitni.
7 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ara yín le, kí ẹ sì ní ìgboyà, nítorí Saulu ọba yín ti kú, ilé Juda sì ti fi àmì òróró yàn mí ní ọba lórí wọn.”
Te dongah na kut te thahuel lamtah hlang tatthai la om laeh. Na boei Saul te duek cakhaw Judah imkhui ah manghai la kai khaw ng'koelh ta,” a ti nah.
8 Lákòókò yìí, Abneri ọmọ Neri olórí ogun Saulu ti mú Iṣboṣeti ọmọ Saulu, ó sì mú un kọjá sí Mahanaimu.
Tedae Saul taengkah caempuei mangpa Ner capa Abner loh Saul capa Ishbosheth a loh tih Mahanaim a paan puei.
9 Ó sì fi jẹ ọba lórí Gileadi Aṣuri àti Jesreeli àti lórí Efraimu àti lórí Benjamini àti lórí gbogbo Israẹli.
Anih te Gilead, Ashuri, Jezreel, Ephraim, Benjamin neh Israel boeih soah a manghai sak.
10 Iṣboṣeti ọmọ Saulu sì jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí ó jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjì. Ilé Juda sì ń tọ Dafidi lẹ́yìn.
Saul capa Ishbosheth te kum sawmli a lo ca vaengah Israel te a manghai thil tih kum nit manghai. Tedae Judah imkhui tah David hnukah bang uh.
11 Gbogbo àkókò tí Dafidi fi jẹ ọba ní Hebroni lórí ilé Juda sì jẹ́ ọdún méje àti oṣù mẹ́fà.
A khohnin he a tarhing la om. Manghai David he Hebron kah Judah imkhui ah kum rhih neh hla rhuk om.
12 Abneri ọmọ Neri pẹ̀lú àwọn ọkùnrin ti Iṣboṣeti ọmọkùnrin Saulu kúrò ní Mahanaimu, wọ́n sì lọ sí Gibeoni.
Ner capa Abner loh Saul capa Ishbosheth kah sal rhoek te Mahanaim lamloh Gibeon la a khuen.
13 Joabu ọmọ Seruiah pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Dafidi jáde lọ láti lọ bá wọn ní adágún Gibeoni. Ẹgbẹ́ kan sì jókòó ní apá kan adágún, àti ẹgbẹ́ kejì ní apá kejì adágún.
Zeruiah capa Joab neh David kah sal rhoek khaw hlah uh tih amih neh Gibeon tuibuem ah tun hum uh. Te vaengah pakhat rhoek te tuibuem khat ben ah, khat ben rhoek khaw tuibuem khat ben ah ngol uh.
14 Nígbà náà, Abneri sọ fún Joabu pé, “Jẹ́ kí díẹ̀ nínú àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yìí ó dìde láti bá ara wọn jà níwájú wa.” Joabu sì dáhùn pé, “Ó dára, jẹ́ kí wọ́n ṣe é.”
Abner loh Joab taengah, “Camoe rhoek he thoo uh saeh lamtah mamih mikhmuh ah nae uh saeh,” a ti nah hatah, Joab loh, “Thoo uh mai saeh,” a ti nah.
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dìde sókè, a sì kà wọ́n sí ọkùnrin méjìlá fún Benjamini àti Iṣboṣeti ọmọ Saulu àti méjìlá fún Dafidi.
Te dongah Benjamin ham neh Saul capa Ishbosheth ham te hlang hlai nit, David sal lamkah hlai nit a tarhing la thoo uh tih cet uh.
16 Nígbà náà olúkúlùkù ọkùnrin gbá ẹnìkejì rẹ̀ mú ní orí, ó sì fi idà gún ẹnìkejì rẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́, wọ́n sì ṣubú lulẹ̀ papọ̀. Bẹ́ẹ̀ ni ibẹ̀ ni Gibeoni ti à ń pè ni Helikatihu Hasurimu.
Te vaengah pakhat loh a hui lu te a kop, a hui long khaw a cunghang te a vae ah a kaelh van dongah darhek cungku uh. Te dongah tekah a hmuen Gibeon ah aka om te Helkathhazzurim la a khue.
17 Ogun náà ní ọjọ́ náà gbóná. Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì ṣẹ́gun Abneri pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Israẹli.
Tekah khohnin ah caemtloek khaw kalthalh la muep om coeng tih Abner neh Israel hlang rhoek tah David sal rhoek kah mikhmuh ah yawk.
18 Àwọn ọmọkùnrin Seruiah mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ni ó wà níbẹ̀: Joabu, Abiṣai àti Asaheli. Nísinsin yìí ẹsẹ̀ Asaheli sì fẹ́rẹ̀ bí ẹsẹ̀ èsúró tí ó wà ní pápá.
Te vaengah Zeruiah ca rhoek Joab, Abishai neh Asahel pathum om uh tih Asahel tah kohong kirhang bangla a kap yanghoep.
19 Asaheli sì ń lépa Abneri, bí òun tí ń lọ kò sì yípadà sí ọ̀tún tàbí sí òsì láti máa tọ́ Abneri lẹ́yìn.
Asahel loh Abner hnuk te a hloem tih Abner hnuk lamkah banvoei, bantang la caeh ham khaw phael tlaih pawh.
20 Abneri bojú wo ẹ̀yìn rẹ̀, Ó sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ Asaheli ni?” Ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni.”
Abner te a hnuk la mael tih, “Asahel te nang a,” a ti nah hatah, “Kai ni ue,” a ti nah.
21 Nígbà náà, Abneri sọ fún un pé, “Yípadà sí ọ̀tún tàbí òsì; mú ọ̀kan lára àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kí o sì bọ́ ìhámọ́ra rẹ.” Ṣùgbọ́n Asaheli kọ̀ láti dẹ́kun lílépa rẹ̀.
Te dongah anih te Abner loh, “Nang te banvoei la bantang la mael lamtah camoe rhoek khuikah pakhat te namah ham tu laeh. A pumoep te khaw namah ham lo,” a ti nah. Tedae anih hnuk lamkah a nong ham tah Asahel loh huem pawh.
22 Abneri tún kìlọ̀ fún Asaheli, “Dẹ́kun lílépa mi! Èéṣe tí èmi yóò fi lù ọ́ bolẹ̀? Báwo ni èmi yóò ti wo arákùnrin rẹ Joabu lójú?”
Abner loh koep a rhaep tih Asahel te, “Nang te kai hnuk lamloh nong, balae tih nang te lai la kan ngawn eh? Na manuca Joab taengah ka mik metlam ka dai eh?,” a ti nah.
23 Ṣùgbọ́n ó sí kọ̀ láti padà, Abneri sì fi òdì ọ̀kọ̀ gún un lábẹ́ inú, ọ̀kọ̀ náà sì jáde ní ẹ̀yìn rẹ̀: òun sì ṣubú lulẹ̀ níbẹ̀, ó sì kú ní ibi kan náà; ó sí ṣe gbogbo ènìyàn tí ó dé ibi tí Asaheli gbé ṣubú si, tí ó sì kú, sì dúró jẹ́.
Tedae nong ham te a aal coeng dongah anih te Abner loh a hnuk longah caai neh a bung ah a thun. Te vaengah caai a nam la pawlh tih pahoi a cungku dongah amah ah duek. Te dongah Asahel cungku tih a duek nah hmuen la aka pawk boeih tah sut pai uh.
24 Joabu àti Abiṣai sì lépa Abneri: oòrùn sì wọ̀, wọ́n sì dé òkè ti Amima tí o wà níwájú Giah lọ́nà ijù Gibeoni.
Tedae Abner hnuk aka hloem Joab neh Abishai tah khomik a tlak daengah Gibeon khosoek longpuei, Giyak imdan kah Ammah som la pawk rhoi.
25 Àwọn ọmọ Benjamini sì kó ara wọn jọ wọ́n tẹ̀lé Abneri, wọ́n sì wá di ẹgbẹ́ kan, wọ́n sì dúró lórí òkè kan.
Abner hnukkah Benjamin koca rhoek khaw coi uh thae tih rhoi at la om uh. Te phoeiah amih te som lu pakhat soah pai uh.
26 Abneri sì pe Joabu, ó sì bi í léèrè pé, “Idà yóò máa parun títí láéláé bí? Ǹjẹ́ ìwọ kò ì tí ì mọ̀ pé yóò korò níkẹyìn? Ǹjẹ́ yóò ha ti pẹ́ tó kí ìwọ tó sọ fún àwọn ènìyàn náà, kí wọ́n dẹ́kun láti máa lépa arákùnrin wọn.”
Te vaengah Joab te Abner loh a khue tih, “Cunghang te a yoeyah la ca ne, hmailong ah hnorhih la a om ham te na ming moenih a? A manuca rhoek hnuk lamkah balkhong ham te pilnam taengah me hil nim na thui pawt ve,” a ti nah.
27 Joabu sì wí pé, “Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, bí kò ṣe bí ìwọ ti wí, nítòótọ́ ní òwúrọ̀ ni àwọn ènìyàn náà ìbá padà lẹ́yìn arákùnrin wọn.”
Te dongah Joab loh, “Pathen kah hingnah vanbangla, mincang duela na thui ngawn pawt koinih, pilnam loh a manuca hnuk te khik a phatawt ni,” a ti nah.
28 Joabu sì fọ́n ìpè, gbogbo ènìyàn sì dúró jẹ́ẹ́, wọn kò sì lépa Israẹli mọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì tún jà mọ́.
Joab loh tuki a ueng vaengah pilnam loh boeih pai uh. Te daengah Israel hnuk te hloem voel pawt tih, vathoh ham khaw khoep voel pawh.
29 Abneri àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì fi gbogbo òru náà rìn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì kọjá Jordani, wọ́n sì rìn ní gbogbo Bitironi, wọ́n sì wá sí Mahanaimu.
Abner neh a hlang rhoek tah khoyin khing Arabah longah khong uh. Jordan a poeng uh phoeiah, Bithron pum te a lan uh tih Mahanaim la pawk uh.
30 Joabu sì dẹ́kun àti máa tọ Abneri lẹ́yìn: ó sì kó gbogbo àwọn ènìyàn náà jọ, ènìyàn mọ́kàndínlógún ni ó kú pẹ̀lú Asaheli nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi.
Joab loh Abner hnuk te a mael tak tih pilnam pum te a coi. Te vaengah David kah hlang sal hlai ko neh Asahel te hma.
31 Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì pa nínú àwọn ènìyàn Benjamini: nínú àwọn ọmọkùnrin Abneri; òjìdínnírinwó ènìyàn.
Tedae David kah sal rhoek loh Benjamin neh Abner kah hlang rhoek te a ngawn uh tih hlang ya thum sawmrhuk duek.
32 Wọ́n si gbé Asaheli wọ́n sì sin ín sínú ibojì baba rẹ̀ tí ó wà ní Bẹtilẹhẹmu. Joabu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ fi gbogbo òru náà rìn, ilẹ̀ sì mọ́ wọn sí Hebroni.
Asahel te a khuen uh tih Bethlehem kah a napa phuel ah a up uh. Joab neh a hlang rhoek khaw khoyin puet cet uh tih Hebron ah khothai uh.

< 2 Samuel 2 >