< 2 Samuel 19 >

1 A sì rò fún Joabu pe, “Wò ó, ọba ń sọkún, ó sì ń gbààwẹ̀ fún Absalomu.”
To je bilo povedano Joábu: »Glej, kralj joka in žaluje za Absalomom.«
2 Ìṣẹ́gun ọjọ́ náà sì di àwẹ̀ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, nítorí àwọn ènìyàn náà gbọ́ ní ọjọ́ náà bí inú ọba ti bàjẹ́ nítorí ọmọ rẹ̀.
Zmaga tega dne je bila obrnjena v žalovanje vsemu ljudstvu, kajti ljudstvo je tisti dan slišalo govoriti, kako je bil kralj užaloščen zaradi svojega sina.
3 Àwọn ènìyàn náà sì yọ́ lọ sí ìlú ní ọjọ́ náà gẹ́gẹ́ bí àwọn bí ènìyàn tí a dójútì ṣe máa ń yọ́ lọ nígbà tí wọ́n bá sá lójú ìjà.
Ljudstvo se je tisti dan skrivoma spravilo v mesto, kakor se ljudstvo, ki je osramočeno, odplazi, ko v boju zbeži.
4 Ọba sì bo ojú rẹ̀, ọba sì kígbe ní ohùn rara pé, “Á à! Ọmọ mi Absalomu! Absalomu ọmọ mi, ọmọ mi!”
Toda kralj je pokril svoj obraz in kralj je jokal z močnim glasom: »Oh moj sin Absalom, oh Absalom, moj sin, moj sin!«
5 Joabu sì wọ inú ilé tọ ọba lọ, ó sì wí pé, “Ìwọ dójúti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ lónìí, àwọn tí ó gba ẹ̀mí rẹ̀ là lónìí, àti ẹ̀mí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti ti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, àti àwọn aya rẹ̀, àti ẹ̀mí àwọn obìnrin rẹ.
Joáb je prišel v hišo h kralju in rekel: »Ta dan si osramotil obraze vseh svojih služabnikov, ki so ta dan rešili tvoje življenje in življenja tvojih sinov in tvojih hčera in življenja tvojih soprog in življenja tvojih priležnic,
6 Nítorí pé ìwọ fẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ sì kórìíra àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Nítorí tí ìwọ wí lónìí pé, Ìwọ kò náání àwọn ọmọ ọba tàbí àwọn ìránṣẹ́; èmi sì rí lónìí pé, ìbá ṣe pé Absalomu wà láààyè, kí gbogbo wa sì kú lónìí, ǹjẹ́ ìbá dùn mọ́ ọ gidigidi.
v tem, da ti ljubiš svoje sovražnike in sovražiš svoje prijatelje. Kajti ta dan si oznanil, da se ne oziraš niti na prince niti na služabnike, kajti ta dan zaznavam, da če bi Absalom živel in bi ta dan mi vsi umrli, potem bi ti to dobro ugajalo.
7 Sì dìde nísinsin yìí, lọ, kí o sì sọ̀rọ̀ ìtùnú fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, nítorí pé èmi fi Olúwa búra, bí ìwọ kò bá lọ, ẹnìkan kì yóò bá ọ dúró ni alẹ́ yìí, èyí ni yóò sì burú fún ọ ju gbogbo ibi tí ojú rẹ ti ń rí láti ìgbà èwe rẹ wá títí ó fi di ìsinsin yìí.”
Zdaj torej vstani, pojdi naprej in tolažilno govori svojim služabnikom, kajti prisegam pri Gospodu, če ne greš naprej, to noč nobeden ne bo ostal s teboj in huje ti bo kakor vse zlo, ki te je zadelo od tvoje mladosti do sedaj.«
8 Ọba sì dìde, ó sì jókòó ní ẹnu-ọ̀nà, wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Wò ó, ọba jókòó ní ẹnu-ọ̀nà.” Gbogbo ènìyàn sì wá sí iwájú ọba. Nítorí pé, Israẹli ti sá, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀.
Potem je kralj vstal in se usedel pri velikih vratih. In vsemu ljudstvu so povedali, rekoč: »Glejte, kralj sedi pri velikih vratih.« Vse ljudstvo je prišlo pred kralja, kajti Izrael je zbežal vsak mož k svojemu šotoru.
9 Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì ń bà ara wọn jà nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, pé, “Ọba ti gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, ó sì ti gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini; òun sì wá sá kúrò ní ìlú nítorí Absalomu.
Vse ljudstvo je bilo nesložno po vseh Izraelovih rodovih, rekoč: »Kralj nas je rešil iz roke naših sovražnikov in nas osvobodil iz roke Filistejcev; sedaj pa je zaradi Absaloma pobegnil iz dežele.
10 Absalomu, tí àwa fi jẹ ọba lórí wa sì kú ní ogun, ǹjẹ́ èéṣe tí ẹ̀yin fi dákẹ́ tí ẹ̀yin kò sì sọ̀rọ̀ kan láti mú ọba padà wá?”
Absalom, ki smo ga mazilili nad seboj, je mrtev v bitki. Zdaj torej, zakaj ne spregovorite besedo o privedbi kralja nazaj?«
11 Dafidi ọba sì ránṣẹ́ sí Sadoku, àti sí Abiatari àwọn àlùfáà pé, “Sọ fún àwọn àgbàgbà Juda, pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi kẹ́yìn láti mú ọba padà wá sí ilé rẹ̀? Ọ̀rọ̀ gbogbo Israẹli sì ti dé ọ̀dọ̀ ọba àní ní ilé rẹ̀.
Kralj David je poslal k duhovnikoma Cadóku in Abjatárju, rekoč: »Govorita Judovim starešinam, rekoč: ›Zakaj ste zadnji, da bi privedli kralja nazaj v njegovo hišo, glede na to, da je govor vsega Izraela prišel do kralja, celó k njegovi hiši.
12 Ẹ̀yin ni ara mi, ẹ̀yin ni egungun mi, àti ẹran-ara mi: èéṣì ti ṣe tí ẹ̀yin fi kẹ́yìn láti mú ọba padà wá.’
Vi ste moji bratje, vi ste moje kosti in moje meso. Zakaj ste potem zadnji, da kralja pripeljete nazaj?‹
13 Kí ẹ̀yin sì wí fún Amasa pé, ‘Egungun àti ẹran-ara mi kọ́ ni ìwọ jẹ́ bí? Kí Ọlọ́run ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí ìwọ kò ba ṣe olórí ogun níwájú mi títí, ní ipò Joabu.’”
In Amasáju recite: › Ali nisi ti od moje kosti in od mojega mesa? Bog naj mi tako stori in še več, če ne boš nenehno pred menoj poveljnik vojske na Joábovem položaju.‹«
14 Òun sì yí gbogbo àwọn ọkùnrin Juda lọ́kàn padà àní bí ọkàn ènìyàn kan; wọ́n sì ránṣẹ́ sí ọba, pé, “Ìwọ padà àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ.”
In nagnil je srce vseh Judovih mož, celo kakor srce enega človeka, tako da so kralju poslali to besedo: »Vrni se ti in vsi tvoji služabniki.«
15 Ọba sì padà, o sì wá sí odò Jordani. Juda sì wá sí Gilgali láti lọ pàdé ọba, àti láti mú ọba kọjá odò Jordani.
Tako se je kralj vrnil in prišel k Jordanu. In Juda je prišel v Gilgál, da gre, da sreča kralja, da spremi kralja čez Jordan.
16 Ṣimei ọmọ Gera, ará Benjamini ti Bahurimu, ó yára ó sì bá àwọn ọkùnrin Juda sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Dafidi ọba.
In Šimí, Gerájev sin, Benjaminovec, ki je bil iz Bahuríma, je pohitel in prišel dol z Judovimi možmi, da sreča kralja Davida.
17 Ẹgbẹ̀rún ọmọkùnrin sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nínú àwọn ọmọkùnrin Benjamini, Ṣiba ìránṣẹ́ ilé Saulu, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́ sì pẹ̀lú rẹ̀; wọ́n sì gòkè odò Jordani ṣáájú ọba.
Tam je bilo z njim tisoč mož iz Benjamina in Cibá, služabnik Savlove hiše in njegovih petnajst sinov in njegovih dvajset služabnikov z njim in pred kraljem so šli čez Jordan.
18 Ọkọ̀ èrò kan ti rékọjá láti kó àwọn ènìyàn ilé ọba sí òkè, àti láti ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ̀. Ṣimei ọmọ Gera wólẹ̀. Ó sì dojúbolẹ̀ níwájú ọba, bí ó tí gòkè odò Jordani.
Tam je šla čez rečna ladja, da prenese čez kraljevo družino in da stori, kar se mu je zdelo dobro. Gerájev sin Šimí pa je padel dol pred kraljem, ko je ta hotel iti čez Jordan
19 Ó sì wí fún ọba pé, “Kí olúwa mi ó má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ sí mi lọ́rùn, má sì ṣe rántí àfojúdi tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣe ni ọjọ́ tí olúwa mi ọba jáde ní Jerusalẹmu, kí ọba má sì fi sí inú.
in kralju rekel: »Naj moj gospod krivičnosti ne pripiše meni niti se ne spominjaj tega, kar je tvoj služabnik sprevrženo storil tistega dne, ko je moj gospod kralj odšel iz Jeruzalema, da bi si to kralj vzel k srcu.
20 Nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ mọ̀ pé èmi ti ṣẹ̀; sì wò ó, mo wá lónìí yìí, ẹni àkọ́kọ́ ní gbogbo ìdílé Josẹfu tí yóò sọ̀kalẹ̀ wá pàdé olúwa mi ọba.”
Kajti tvoj služabnik ve, da sem grešil. Glej, zato sem ta dan prvi prišel iz vse Jožefove hiše, da grem dol, da srečam svojega gospoda kralja.«
21 Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah dáhùn ó sì wí pé, “Kò ha tọ́ kí a pa Ṣimei nítorí èyí? Nítorí pé òun ti bú ẹni àmì òróró Olúwa.”
Toda Cerújin sin Abišáj je odgovoril in rekel: »Ali ne bo Šimí usmrčen zaradi tega, ker je preklinjal Gospodovega maziljenca?«
22 Dafidi sì wí pé, “Kí ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah tí ẹ dàbí ọ̀tá fún mi lónìí? A ha lè pa ènìyàn kan lónìí ní Israẹli? Tàbí èmi kò ha mọ̀ pé lónìí èmi ni ọba Israẹli.”
David pa je rekel: »Kaj imam z vama, vidva, Cerújina sinova, da bi mi bila ta dan nasprotnika? Ali naj bo ta dan kdorkoli usmrčen v Izraelu? Kajti ali ne vem, da sem ta dan kralj nad Izraelom?«
23 Ọba sì wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ kì yóò kú!” Ọba sì búra fún un.
Zato je kralj rekel Šimíju: »Ne boš umrl.« In kralj mu je prisegel.
24 Mefiboṣeti ọmọ Saulu sì sọ̀kalẹ̀ láti wá pàdé ọba, kò wẹ ẹsẹ̀ rẹ̀, kò sí tọ́ irùngbọ̀n rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fọ aṣọ rẹ̀ láti ọjọ́ tí ọba ti jáde títí ó fi di ọjọ́ tí ó fi padà ní àlàáfíà.
Savlov sin Mefibóšet je prišel dol, da sreča kralja in niti ni obul svojih stopal, niti ni postrigel svoje brade, niti ni umil svojih oblačil od dneva, ko je kralj odpotoval, do dneva, ko je ponovno prišel v miru.
25 Nígbà tí òun sì wá sí Jerusalẹmu láti pàdé ọba, ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ kò fi bá mi lọ, Mefiboṣeti?”
Pripetilo se je, ko je prišel v Jeruzalem, da sreča kralja, da mu je kralj rekel: »Zakaj nisi šel z menoj, Mefibóšet?«
26 Òun sì dáhùn wí pé, “Olúwa mi, ọba, ìránṣẹ́ mi ni ó tàn mí, nítorí ìránṣẹ́ rẹ wí fún un pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi èmi ó gùn ún, èmi ó sì tọ ọba lọ.’ Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ yarọ.
Ta je odgovoril: »Moj gospod, oh kralj, moj služabnik me je zavedel, kajti tvoj služabnik je rekel: ›Osedlal si bom osla, da bom lahko jahal na njem in šel h kralju, ker je tvoj služabnik hrom.‹
27 Ó sì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí ìránṣẹ́ rẹ, fún olúwa mi ọba, ṣùgbọ́n bí angẹli Ọlọ́run ni olúwa mi ọba rí, nítorí náà ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ.
In ta je obrekoval tvojega služabnika mojemu gospodu kralju, toda moj gospod kralj je kakor angel od Boga. Stôri torej, kar je dobro v tvojih očeh.
28 Nítorí pé gbogbo ilé baba mi bí òkú ènìyàn ni wọ́n sá à rí níwájú olúwa mi ọba, ìwọ sì fi ipò fún ìránṣẹ́ rẹ láàrín àwọn tí ó ń jẹun ní ibi oúnjẹ. Nítorí náà àre kín ni èmi ní tí èmi yóò fi máa ké pe ọba síbẹ̀.”
Kajti vsi iz hiše mojega očeta so bili le kot mrtvi možje pred mojim gospodom kraljem, vendar si svojega služabnika postavil med tiste, ki so jedli pri tvoji lastni mizi. Kakšno pravico imam torej, da še kakorkoli kličem h kralju?«
29 Ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń sọ ọ̀ràn ara rẹ fún mi èmi sá à ti wí pé, kí ìwọ àti Ṣiba pín ilẹ̀ náà.”
Kralj mu je rekel: »Zakaj še govoriš o svojih zadevah? Rekel sem: ›Ti in Cibá si razdelita deželo.‹«
30 Mefiboṣeti sì wí fún ọba pé, “Jẹ́ kí ó mú gbogbo rẹ̀, kí olúwa mi ọba sá à ti padà bọ̀ wá ilé rẹ̀ ni àlàáfíà.”
Mefibóšet je rekel kralju: »Da, naj on vzame vse, potem ko se je moj gospod kralj v miru ponovno vrnil v svojo lastno hišo.«
31 Barsillai ará Gileadi sì sọ̀kalẹ̀ láti Rogelimu wá, ó sì bá ọba gòkè odò Jordani, láti ṣe ìkẹ́ rẹ̀ sí ìkọjá odò Jordani.
Gileádec Barziláj je prišel dol iz Roglíma in s kraljem odšel čez Jordan, da ga spremi čez Jordan.
32 Barsillai sì jẹ́ arúgbó ọkùnrin gidigidi, ẹni ogbó ọgọ́rin ọdún sì ni, ó sì pèsè ohun jíjẹ fún ọba nígbà tí ó ti wà ní Mahanaimu; nítorí pé ọkùnrin ọlọ́lá ni òun ń ṣe.
Torej Barziláj je bil zelo ostarel mož, star celó osemdeset let. Kralju je priskrbel oskrbo, medtem ko je ta ležal pri Mahanájimu, kajti bil je zelo izjemen človek.
33 Ọba sì wí fún Barsillai pé, “Ìwọ wá bá mi gòkè odò, èmi ó sì máa pèsè fún ọ ní Jerusalẹmu.”
Kralj je rekel Barziláju: »Z menoj pridi čez in hranil te bom v Jeruzalemu.«
34 Barsillai sì wí fún ọba pé, “Ọjọ́ mélòó ni ọdún ẹ̀mí mi kù, tí èmi ó fi bá ọba gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
Barziláj pa je kralju rekel: »Doklej bom še živel, da bi s kraljem šel gor v Jeruzalem?
35 Ẹni ogbó ọgọ́rin ọdún sá à ni èmi lónìí, ǹjẹ́ èmi mọ ìyàtọ̀ nínú rere àti búburú? Ǹjẹ́ ìránṣẹ́ rẹ le mọ adùn ohun tí òun ń jẹ tàbí ohun ti òun ń mu bí? Èmi tún lè mọ adùn ohùn àwọn ọkùnrin tí ń kọrin àti àwọn obìnrin tí ń kọrin bí, ǹjẹ́ nítorí kín ni ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe jẹ́ ìyọnu síbẹ̀ fún olúwa mi ọba.
Ta dan sem star osemdeset let in ali lahko razločim med dobrim in zlom? Ali lahko tvoj služabnik okuša, kar jem ali kar pijem? Ali še lahko slišim glas prepevajočih mož in prepevajočih žensk? Zakaj bi bil torej tvoj služabnik še breme mojemu gospodu kralju?
36 Ìránṣẹ́ rẹ yóò sì sin ọba lọ díẹ̀ gòkè odò Jordani; èéṣì ṣe tí ọba yóò fi san ẹ̀san yìí fún mi.
Tvoj služabnik bo s kraljem šel krajšo pot čez Jordan. Zakaj bi me kralj poplačal s takšno nagrado?
37 Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ padà, èmi ó sì kú ní ìlú mi, a ó sì sin mí ní ibojì baba àti ìyá mi. Sì wo Kimhamu ìránṣẹ́ rẹ, yóò bá olúwa mi ọba gòkè; ìwọ ó sì ṣe ohun tí ó bá tọ́ lójú rẹ fún un.”
Naj se tvoj služabnik, prosim te, obrne nazaj, da lahko umrem v svojem lastnem mestu in pokopan bom poleg groba svojega očeta in svoje matere. Toda poglej svojega služabnika Kimháma. Naj gre on preko z mojim gospodom kraljem in stôri mu, kakor se ti zdi dobro.«
38 Ọba sì dáhùn wí pé, “Kimhamu yóò bá mi gòkè, èmi ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ̀ fún un; ohunkóhun tí ìwọ bá sì béèrè lọ́wọ́ mi, èmi ó ṣe é fún ọ.”
Kralj je odgovoril: »Kimhám bo z menoj šel preko in storil mu bom to, kar se ti zdi dobro in karkoli boš zahteval od mene, to bom storil zate.«
39 Gbogbo àwọn ènìyàn sì gòkè odò Jordani ọba sì gòkè; ọba sì fi ẹnu ko Barsillai lẹ́nu, ó sì súre fún un; òun sì padà sí ilé rẹ̀.
In vse ljudstvo je šlo čez Jordan. Ko je kralj prišel čez, je kralj poljubil Barzilája in ga blagoslovil, in ta se je vrnil na svoj lasten kraj.
40 Ọba sì ń lọ́ sí Gilgali, Kimhamu sì ń bà a lọ, gbogbo àwọn ènìyàn Juda sì ń ṣe ìkẹ́ ọba, àti ààbọ̀ àwọn ènìyàn Israẹli.
Potem je kralj odšel naprej h Gilgálu in Kimhám je z njim odšel naprej in vse Judovo ljudstvo je spremilo kralja in tudi polovica Izraelovega ljudstva.
41 Sì wò ó, gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì tọ ọba wá, wọ́n sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí àwọn arákùnrin wa àwọn ọkùnrin Juda fi jí ọ kúrò, tí wọ́n sì fi mú ọba àti àwọn ará ilé rẹ̀ gòkè odò Jordani, àti gbogbo àwọn ènìyàn Dafidi pẹ̀lú rẹ?”
Glej, vsi Izraelovi možje so prišli h kralju in kralju rekli: »Zakaj so te naši bratje, Judovi možje, ukradli in privedli kralja, njegovo družino in vse Davidove može z njim, čez Jordan?«
42 Gbogbo ọkùnrin Juda sì dá àwọn ọkùnrin Israẹli lóhùn pé, “Nítorí pé ọba bá wa tan ni; èéṣe tí ẹ̀yin fi bínú nítorí ọ̀ràn yìí? Àwa jẹ nínú oúnjẹ ọba rárá bí? Tàbí ó fi ẹ̀bùn kan fún wa bí?”
In vsi možje iz Juda so Izraelovim možem odgovorili: »Ker nam je kralj bližnji sorodnik. Zakaj ste potem jezni zaradi te zadeve? Ali smo sploh jedli na kraljeve stroške? Ali nam je dal kakršnokoli darilo?«
43 Àwọn ọkùnrin Israẹli náà sì dá àwọn ọkùnrin Juda lóhùn pé, “Àwa ní ipá mẹ́wàá nínú ọba, àwa sì ní nínú Dafidi jù yín lọ, èéṣì ṣe tí ẹ̀yin kò fi kà wá sí, tí ìmọ̀ wa kò fi ṣáájú láti mú ọba wa padà?” Ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Juda sì le ju ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Israẹli.
Izraelovi možje so odgovorili Judovim možem in rekli: »V kralju imamo deset delov in mi imamo več pravice do Davida kakor vi. Čemu nas potem prezirate, da naš nasvet ne bi bil prvi v tem, da smo svojega kralja privedli nazaj?« In besede mož iz Juda so bile trše kakor besede mož iz Izraela.

< 2 Samuel 19 >