< 2 Samuel 19 >

1 A sì rò fún Joabu pe, “Wò ó, ọba ń sọkún, ó sì ń gbààwẹ̀ fún Absalomu.”
Și i s-a spus lui Ioab: Iată, împăratul plânge și jelește după Absalom.
2 Ìṣẹ́gun ọjọ́ náà sì di àwẹ̀ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, nítorí àwọn ènìyàn náà gbọ́ ní ọjọ́ náà bí inú ọba ti bàjẹ́ nítorí ọmọ rẹ̀.
Și victoria în acea zi a fost prefăcută în jale pentru tot poporul; fiindcă poporul a auzit spunându-se în acea zi cum împăratul era mâhnit pentru fiul său.
3 Àwọn ènìyàn náà sì yọ́ lọ sí ìlú ní ọjọ́ náà gẹ́gẹ́ bí àwọn bí ènìyàn tí a dójútì ṣe máa ń yọ́ lọ nígbà tí wọ́n bá sá lójú ìjà.
Și poporul s-a furișat în acea zi înăuntrul cetății, cum se furișează un popor care este rușinat când fuge în bătălie.
4 Ọba sì bo ojú rẹ̀, ọba sì kígbe ní ohùn rara pé, “Á à! Ọmọ mi Absalomu! Absalomu ọmọ mi, ọmọ mi!”
Dar împăratul și-a acoperit fața și împăratul striga cu o voce tare: O fiul meu Absalom, O Absalom, fiul meu, fiul meu!
5 Joabu sì wọ inú ilé tọ ọba lọ, ó sì wí pé, “Ìwọ dójúti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ lónìí, àwọn tí ó gba ẹ̀mí rẹ̀ là lónìí, àti ẹ̀mí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti ti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, àti àwọn aya rẹ̀, àti ẹ̀mí àwọn obìnrin rẹ.
Și Ioab a intrat în casă la împărat și a spus: Ai rușinat în această zi fețele tuturor servitorilor tăi, care în această zi ți-au salvat viața ta și viețile fiilor tăi și ale fiicelor tale și viețile soțiilor tale și viețile concubinelor tale;
6 Nítorí pé ìwọ fẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ sì kórìíra àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Nítorí tí ìwọ wí lónìí pé, Ìwọ kò náání àwọn ọmọ ọba tàbí àwọn ìránṣẹ́; èmi sì rí lónìí pé, ìbá ṣe pé Absalomu wà láààyè, kí gbogbo wa sì kú lónìí, ǹjẹ́ ìbá dùn mọ́ ọ gidigidi.
În aceea că tu iubești pe dușmanii tăi și îi urăști pe prietenii tăi. Fiindcă ai declarat în această zi că nu iei aminte nici la prinți nici la servitori, pentru că în această zi pricep că dacă Absalom ar fi trăit, iar noi toți astăzi am fi murit, atunci ți-ar fi plăcut mult.
7 Sì dìde nísinsin yìí, lọ, kí o sì sọ̀rọ̀ ìtùnú fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, nítorí pé èmi fi Olúwa búra, bí ìwọ kò bá lọ, ẹnìkan kì yóò bá ọ dúró ni alẹ́ yìí, èyí ni yóò sì burú fún ọ ju gbogbo ibi tí ojú rẹ ti ń rí láti ìgbà èwe rẹ wá títí ó fi di ìsinsin yìí.”
De aceea acum, ridică-te, ieși și vorbește cu mângâiere servitorilor tăi; fiindcă jur pe DOMNUL, dacă nu ieși, nu va rămâne unul cu tine în această noapte; și aceasta va fi mai rău pentru tine decât tot răul care a venit asupra ta din tinerețea ta până acum.
8 Ọba sì dìde, ó sì jókòó ní ẹnu-ọ̀nà, wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Wò ó, ọba jókòó ní ẹnu-ọ̀nà.” Gbogbo ènìyàn sì wá sí iwájú ọba. Nítorí pé, Israẹli ti sá, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀.
Atunci împăratul s-a ridicat și a șezut la poartă. Și au spus întregului popor, zicând: Iată, împăratul șade la poartă. Și tot poporul a venit înaintea împăratului; fiindcă Israel fugise fiecare om la cortul său.
9 Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì ń bà ara wọn jà nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, pé, “Ọba ti gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, ó sì ti gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini; òun sì wá sá kúrò ní ìlú nítorí Absalomu.
Și tot poporul se certa în toate triburile lui Israel, spunând: Împăratul ne-a salvat din mâna dușmanilor noștri și ne-a eliberat din mâna filistenilor; și acum a fugit din țară din cauza lui Absalom.
10 Absalomu, tí àwa fi jẹ ọba lórí wa sì kú ní ogun, ǹjẹ́ èéṣe tí ẹ̀yin fi dákẹ́ tí ẹ̀yin kò sì sọ̀rọ̀ kan láti mú ọba padà wá?”
Și Absalom, pe care l-am uns peste noi, a murit în bătălie. De aceea acum, de ce nu spuneți un cuvânt pentru aducerea împăratului înapoi?
11 Dafidi ọba sì ránṣẹ́ sí Sadoku, àti sí Abiatari àwọn àlùfáà pé, “Sọ fún àwọn àgbàgbà Juda, pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi kẹ́yìn láti mú ọba padà wá sí ilé rẹ̀? Ọ̀rọ̀ gbogbo Israẹli sì ti dé ọ̀dọ̀ ọba àní ní ilé rẹ̀.
Și împăratul David a trimis la Țadoc și Abiatar, preoții, spunând: Vorbiți bătrânilor lui Iuda, zicând: De ce sunteți voi cei din urmă ca să aduceți pe împărat înapoi acasă? Văzând că vorbirea întregului Israel a venit la împărat, în casa lui.
12 Ẹ̀yin ni ara mi, ẹ̀yin ni egungun mi, àti ẹran-ara mi: èéṣì ti ṣe tí ẹ̀yin fi kẹ́yìn láti mú ọba padà wá.’
Voi sunteți frații mei, voi sunteți oasele mele și carnea mea; pentru ce atunci sunteți cei din urmă ca să aduceți înapoi pe împărat?
13 Kí ẹ̀yin sì wí fún Amasa pé, ‘Egungun àti ẹran-ara mi kọ́ ni ìwọ jẹ́ bí? Kí Ọlọ́run ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí ìwọ kò ba ṣe olórí ogun níwájú mi títí, ní ipò Joabu.’”
Și spuneți lui Amasa: Nu ești tu din osul meu și din carnea mea? Astfel să îmi facă Dumnezeu și încă mai mult, dacă nu vei fi căpetenia oștirii înaintea mea continuu, în locul lui Ioab.
14 Òun sì yí gbogbo àwọn ọkùnrin Juda lọ́kàn padà àní bí ọkàn ènìyàn kan; wọ́n sì ránṣẹ́ sí ọba, pé, “Ìwọ padà àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ.”
Și el a aplecat inima tuturor bărbaților lui Iuda, chiar ca pe inima unui singur om, astfel încât au trimis acest cuvânt la împărat: Întoarce-te tu și toți servitorii tăi.
15 Ọba sì padà, o sì wá sí odò Jordani. Juda sì wá sí Gilgali láti lọ pàdé ọba, àti láti mú ọba kọjá odò Jordani.
Astfel împăratul s-a întors și a venit la Iordan. Și Iuda a venit la Ghilgal, pentru a merge să îl întâmpine pe împărat și să îl conducă pe împărat peste Iordan.
16 Ṣimei ọmọ Gera, ará Benjamini ti Bahurimu, ó yára ó sì bá àwọn ọkùnrin Juda sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Dafidi ọba.
Și Șimei, fiul lui Ghera, un beniamit, care era din Bahurim, s-a grăbit și a coborât cu bărbații lui Iuda să îl întâlnească pe împăratul David.
17 Ẹgbẹ̀rún ọmọkùnrin sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nínú àwọn ọmọkùnrin Benjamini, Ṣiba ìránṣẹ́ ilé Saulu, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́ sì pẹ̀lú rẹ̀; wọ́n sì gòkè odò Jordani ṣáájú ọba.
Și acolo erau o mie de oameni din Beniamin cu el și Țiba, servitorul casei lui Saul, și cei cincisprezece fii ai lui și cei douăzeci de servitori ai lui cu el; și au trecut Iordanul înaintea împăratului.
18 Ọkọ̀ èrò kan ti rékọjá láti kó àwọn ènìyàn ilé ọba sí òkè, àti láti ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ̀. Ṣimei ọmọ Gera wólẹ̀. Ó sì dojúbolẹ̀ níwájú ọba, bí ó tí gòkè odò Jordani.
Și a trecut un bac ca să treacă dincolo casa împăratului și să facă ce i se părea bine. Și Șimei, fiul lui Ghera, a căzut înaintea împăratului, pe când el trecea Iordanul.
19 Ó sì wí fún ọba pé, “Kí olúwa mi ó má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ sí mi lọ́rùn, má sì ṣe rántí àfojúdi tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣe ni ọjọ́ tí olúwa mi ọba jáde ní Jerusalẹmu, kí ọba má sì fi sí inú.
Și a spus împăratului: Să nu îmi impute nelegiuire domnul meu, nici să nu îți amintești ceea ce servitorul tău a făcut cu strâmbătate în acea zi când a ieșit domnul meu împăratul din Ierusalim; ca împăratul să pună aceasta la inimă.
20 Nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ mọ̀ pé èmi ti ṣẹ̀; sì wò ó, mo wá lónìí yìí, ẹni àkọ́kọ́ ní gbogbo ìdílé Josẹfu tí yóò sọ̀kalẹ̀ wá pàdé olúwa mi ọba.”
Pentru că servitorul tău știe că eu am păcătuit; de aceea, iată, am venit cel dintâi în această zi din toată casa lui Iosif pentru a coborî să îl întâmpin pe domnul meu, împăratul.
21 Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah dáhùn ó sì wí pé, “Kò ha tọ́ kí a pa Ṣimei nítorí èyí? Nítorí pé òun ti bú ẹni àmì òróró Olúwa.”
Dar Abișai, fiul Țeruiei, a răspuns și a zis: Să nu fie Șimei dat la moarte pentru aceasta, deoarece a blestemat pe unsul DOMNULUI?
22 Dafidi sì wí pé, “Kí ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah tí ẹ dàbí ọ̀tá fún mi lónìí? A ha lè pa ènìyàn kan lónìí ní Israẹli? Tàbí èmi kò ha mọ̀ pé lónìí èmi ni ọba Israẹli.”
Și David a spus: Ce am eu a face cu voi, fii ai Țeruiei, ca în această zi să îmi fiți potrivnici? Să fie dat cineva la moarte în această zi în Israel? Oare nu știu eu că sunt astăzi împărat peste Israel?
23 Ọba sì wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ kì yóò kú!” Ọba sì búra fún un.
De aceea împăratul i-a spus lui Șimei: Nu vei muri. Și împăratul i-a jurat.
24 Mefiboṣeti ọmọ Saulu sì sọ̀kalẹ̀ láti wá pàdé ọba, kò wẹ ẹsẹ̀ rẹ̀, kò sí tọ́ irùngbọ̀n rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fọ aṣọ rẹ̀ láti ọjọ́ tí ọba ti jáde títí ó fi di ọjọ́ tí ó fi padà ní àlàáfíà.
Și Mefiboșet, fiul lui Saul, a coborât să îl întâlnească pe împărat și nu își îngrijise picioarele, nici nu își pregătise barba, nici nu își spălase hainele, din ziua în care împăratul plecase până în ziua când s-a întors în pace.
25 Nígbà tí òun sì wá sí Jerusalẹmu láti pàdé ọba, ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ kò fi bá mi lọ, Mefiboṣeti?”
Și s-a întâmplat, după ce a venit la Ierusalim să îl întâlnească pe împărat, că împăratul i-a spus: Pentru ce nu ai mers cu mine, Mefiboșet?
26 Òun sì dáhùn wí pé, “Olúwa mi, ọba, ìránṣẹ́ mi ni ó tàn mí, nítorí ìránṣẹ́ rẹ wí fún un pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi èmi ó gùn ún, èmi ó sì tọ ọba lọ.’ Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ yarọ.
Și el a răspuns: Domnul meu, o împărate, servitorul meu m-a înșelat; fiindcă servitorul tău a spus: îmi voi înșeua un măgar, ca să călăresc pe el și să merg la împărat, pentru că servitorul tău este șchiop.
27 Ó sì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí ìránṣẹ́ rẹ, fún olúwa mi ọba, ṣùgbọ́n bí angẹli Ọlọ́run ni olúwa mi ọba rí, nítorí náà ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ.
Și el a defăimat pe servitorul tău înaintea domnului meu împăratul; dar domnul meu împăratul este ca un înger al lui Dumnezeu; fă de aceea ce este bine în ochii tăi.
28 Nítorí pé gbogbo ilé baba mi bí òkú ènìyàn ni wọ́n sá à rí níwájú olúwa mi ọba, ìwọ sì fi ipò fún ìránṣẹ́ rẹ láàrín àwọn tí ó ń jẹun ní ibi oúnjẹ. Nítorí náà àre kín ni èmi ní tí èmi yóò fi máa ké pe ọba síbẹ̀.”
Pentru că toți ai casei tatălui meu nu erau decât oameni morți înaintea domnului meu, împăratul; totuși tu ai pus pe servitorul tău printre cei care mănâncă la masa ta. Ce drept am eu să mai strig către împărat?
29 Ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń sọ ọ̀ràn ara rẹ fún mi èmi sá à ti wí pé, kí ìwọ àti Ṣiba pín ilẹ̀ náà.”
Și împăratul i-a spus: De ce mai vorbești încă de lucrurile tale? Eu am spus: Tu și Țiba împărțiți câmpul.
30 Mefiboṣeti sì wí fún ọba pé, “Jẹ́ kí ó mú gbogbo rẹ̀, kí olúwa mi ọba sá à ti padà bọ̀ wá ilé rẹ̀ ni àlàáfíà.”
Și Mefiboșet a spus împăratului: Da, să ia el totul, pentru că domnul meu împăratul a venit în pace în casa lui.
31 Barsillai ará Gileadi sì sọ̀kalẹ̀ láti Rogelimu wá, ó sì bá ọba gòkè odò Jordani, láti ṣe ìkẹ́ rẹ̀ sí ìkọjá odò Jordani.
Și Barzilai galaaditul a coborât de la Roghelim și a trecut Iordanul cu împăratul, pentru a-l conduce peste Iordan.
32 Barsillai sì jẹ́ arúgbó ọkùnrin gidigidi, ẹni ogbó ọgọ́rin ọdún sì ni, ó sì pèsè ohun jíjẹ fún ọba nígbà tí ó ti wà ní Mahanaimu; nítorí pé ọkùnrin ọlọ́lá ni òun ń ṣe.
Acum, Barzilai era un om foarte bătrân, de optzeci de ani; și el s-a îngrijit de susținerea împăratului în timp ce era în Mahanaim, pentru că era un om foarte mare.
33 Ọba sì wí fún Barsillai pé, “Ìwọ wá bá mi gòkè odò, èmi ó sì máa pèsè fún ọ ní Jerusalẹmu.”
Și împăratul i-a spus lui Barzilai: Treci cu mine și te voi hrăni cu mine în Ierusalim.
34 Barsillai sì wí fún ọba pé, “Ọjọ́ mélòó ni ọdún ẹ̀mí mi kù, tí èmi ó fi bá ọba gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
Și Barzilai a spus împăratului: Cât mai am de trăit, ca să urc cu împăratul la Ierusalim?
35 Ẹni ogbó ọgọ́rin ọdún sá à ni èmi lónìí, ǹjẹ́ èmi mọ ìyàtọ̀ nínú rere àti búburú? Ǹjẹ́ ìránṣẹ́ rẹ le mọ adùn ohun tí òun ń jẹ tàbí ohun ti òun ń mu bí? Èmi tún lè mọ adùn ohùn àwọn ọkùnrin tí ń kọrin àti àwọn obìnrin tí ń kọrin bí, ǹjẹ́ nítorí kín ni ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe jẹ́ ìyọnu síbẹ̀ fún olúwa mi ọba.
Eu am în această zi optzeci de ani; și pot eu discerne între bine și rău? Poate servitorul tău să guste ce mănânc și ce beau? Pot eu să mai aud vocea cântăreților și a cântărețelor? Pentru ce atunci să mai fie servitorul tău o povară domnului meu împăratul?
36 Ìránṣẹ́ rẹ yóò sì sin ọba lọ díẹ̀ gòkè odò Jordani; èéṣì ṣe tí ọba yóò fi san ẹ̀san yìí fún mi.
Servitorul tău va merge puțin peste Iordan cu împăratul; și de ce să mă răsplătească împăratul cu o astfel de răsplată?
37 Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ padà, èmi ó sì kú ní ìlú mi, a ó sì sin mí ní ibojì baba àti ìyá mi. Sì wo Kimhamu ìránṣẹ́ rẹ, yóò bá olúwa mi ọba gòkè; ìwọ ó sì ṣe ohun tí ó bá tọ́ lójú rẹ fún un.”
Lasă, te rog, să se întoarcă servitorul tău, ca să mor în propria mea cetate și să fiu îngropat lângă mormântul tatălui meu și al mamei mele. Dar iată, pe servitorul tău, Chimham; să treacă el cu domnul meu, împăratul; și să îi faci ce ți se va părea bine.
38 Ọba sì dáhùn wí pé, “Kimhamu yóò bá mi gòkè, èmi ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ̀ fún un; ohunkóhun tí ìwọ bá sì béèrè lọ́wọ́ mi, èmi ó ṣe é fún ọ.”
Și împăratul a răspuns: Chimham să treacă împreună cu mine și îi voi face ce ți se va părea bine; și orice vei cere de la mine, aceea voi face pentru tine.
39 Gbogbo àwọn ènìyàn sì gòkè odò Jordani ọba sì gòkè; ọba sì fi ẹnu ko Barsillai lẹ́nu, ó sì súre fún un; òun sì padà sí ilé rẹ̀.
Și tot poporul a trecut Iordanul. Și după ce împăratul a trecut, împăratul l-a sărutat pe Barzilai și l-a binecuvântat; și el s-a întors la locul său.
40 Ọba sì ń lọ́ sí Gilgali, Kimhamu sì ń bà a lọ, gbogbo àwọn ènìyàn Juda sì ń ṣe ìkẹ́ ọba, àti ààbọ̀ àwọn ènìyàn Israẹli.
Atunci împăratul a mers la Ghilgal și Chimham a mers cu el; și tot poporul lui Iuda l-a condus pe împărat și de asemenea jumătate din poporul lui Israel.
41 Sì wò ó, gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì tọ ọba wá, wọ́n sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí àwọn arákùnrin wa àwọn ọkùnrin Juda fi jí ọ kúrò, tí wọ́n sì fi mú ọba àti àwọn ará ilé rẹ̀ gòkè odò Jordani, àti gbogbo àwọn ènìyàn Dafidi pẹ̀lú rẹ?”
Și, iată, toți bărbații lui Israel au venit la împărat și i-au spus: De ce te-au furat frații noștri, bărbații lui Iuda, și au adus pe împărat și casa lui și pe toți oamenii lui David cu el, peste Iordan?
42 Gbogbo ọkùnrin Juda sì dá àwọn ọkùnrin Israẹli lóhùn pé, “Nítorí pé ọba bá wa tan ni; èéṣe tí ẹ̀yin fi bínú nítorí ọ̀ràn yìí? Àwa jẹ nínú oúnjẹ ọba rárá bí? Tàbí ó fi ẹ̀bùn kan fún wa bí?”
Și toți bărbații lui Iuda au răspuns bărbaților lui Israel: Pentru că împăratul ne este rudă apropiată; de ce atunci v-ați mâniat din cauza acestui lucru? Am mâncat noi ceva pe cheltuiala împăratului? Sau ne-a dat el vreun dar?
43 Àwọn ọkùnrin Israẹli náà sì dá àwọn ọkùnrin Juda lóhùn pé, “Àwa ní ipá mẹ́wàá nínú ọba, àwa sì ní nínú Dafidi jù yín lọ, èéṣì ṣe tí ẹ̀yin kò fi kà wá sí, tí ìmọ̀ wa kò fi ṣáájú láti mú ọba wa padà?” Ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Juda sì le ju ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Israẹli.
Și bărbații lui Israel au răspuns bărbaților lui Iuda și au spus: Noi avem zece părți la împărat și de asemenea mai mult drept în David decât voi; de ce atunci ne-ați disprețuit, încât sfatul nostru să nu fie cel dintâi în aducerea înapoi a împăratului nostru? Și cuvintele bărbaților lui Iuda au fost mai aspre decât cuvintele bărbaților lui Israel.

< 2 Samuel 19 >