< 2 Samuel 19 >

1 A sì rò fún Joabu pe, “Wò ó, ọba ń sọkún, ó sì ń gbààwẹ̀ fún Absalomu.”
I oznajmino Joabowi: Oto król płacze i żałuje Absaloma.
2 Ìṣẹ́gun ọjọ́ náà sì di àwẹ̀ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, nítorí àwọn ènìyàn náà gbọ́ ní ọjọ́ náà bí inú ọba ti bàjẹ́ nítorí ọmọ rẹ̀.
Przetoż się ono zwycięstwo dnia onego obróciło w płacz wszystkiemu ludowi; albowiem usłyszawszy lud dnia onego, że mówiono: Żałośny jest król dla syna swego.
3 Àwọn ènìyàn náà sì yọ́ lọ sí ìlú ní ọjọ́ náà gẹ́gẹ́ bí àwọn bí ènìyàn tí a dójútì ṣe máa ń yọ́ lọ nígbà tí wọ́n bá sá lójú ìjà.
Zaczem wkradł się lud onego dnia wchodząc do miasta, jako się więc wkrada lud, który się wstydzi, uciekając z bitwy.
4 Ọba sì bo ojú rẹ̀, ọba sì kígbe ní ohùn rara pé, “Á à! Ọmọ mi Absalomu! Absalomu ọmọ mi, ọmọ mi!”
A król nakrywszy oblicze swoje, wołał głosem wielkim: Synu mój Absalomie, Absalomie, synu mój, synu mój!
5 Joabu sì wọ inú ilé tọ ọba lọ, ó sì wí pé, “Ìwọ dójúti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ lónìí, àwọn tí ó gba ẹ̀mí rẹ̀ là lónìí, àti ẹ̀mí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti ti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, àti àwọn aya rẹ̀, àti ẹ̀mí àwọn obìnrin rẹ.
Tedy wszedł Joab do króla w dom, i rzekł: Shańbiłeś dziś oblicze wszystkich sług twoich, którzy wybawili duszę twoję dzisiaj, i duszę synów twoich, i córek twoich, i duszę żon twoich, i duszę nałożnic twoich.
6 Nítorí pé ìwọ fẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ sì kórìíra àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Nítorí tí ìwọ wí lónìí pé, Ìwọ kò náání àwọn ọmọ ọba tàbí àwọn ìránṣẹ́; èmi sì rí lónìí pé, ìbá ṣe pé Absalomu wà láààyè, kí gbogbo wa sì kú lónìí, ǹjẹ́ ìbá dùn mọ́ ọ gidigidi.
Miłując te, którzy cię mają w nienawiści, a nienawidząc tych, którzy cię miłują. Albowiem pokazałeś dziś, że sobie nie poważasz hetmanów, i sług twoich; bom doznał tego dziś, że gdyby Absalom był żyw, choćbyśmy my wszyscy dziś byli pobici, tedyć by się to bardzo podobało.
7 Sì dìde nísinsin yìí, lọ, kí o sì sọ̀rọ̀ ìtùnú fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, nítorí pé èmi fi Olúwa búra, bí ìwọ kò bá lọ, ẹnìkan kì yóò bá ọ dúró ni alẹ́ yìí, èyí ni yóò sì burú fún ọ ju gbogbo ibi tí ojú rẹ ti ń rí láti ìgbà èwe rẹ wá títí ó fi di ìsinsin yìí.”
Przetoż teraz wstań, wynijdź, a mów łagodnie do sług twoich. Boć przez Pana przysięgam, jeźli ty nie wynijdziesz, że nie zostanie żaden z tobą tej nocy, a będzieć to gorzej, niżli wszystko złe, którekolwiek na cię przychodziło od młodości twojej aż dotąd.
8 Ọba sì dìde, ó sì jókòó ní ẹnu-ọ̀nà, wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Wò ó, ọba jókòó ní ẹnu-ọ̀nà.” Gbogbo ènìyàn sì wá sí iwájú ọba. Nítorí pé, Israẹli ti sá, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀.
Wstał tedy król, i siadł w bramie; i opowiedziano to wszystkiemu ludowi, mówiąc: Oto król siedzi w bramie. I przyszedł wszystek lud przed oblicze królewskie; ale Izraelczycy uciekli byli, każdy do namiotu swego.
9 Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì ń bà ara wọn jà nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, pé, “Ọba ti gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, ó sì ti gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini; òun sì wá sá kúrò ní ìlú nítorí Absalomu.
I stało się, że się wszystek lud sprzeczał z sobą we wszystkich pokoleniach Izraelskich, mówiąc: Król wyrwał nas z rąk nieprzyjaciół naszych, tenże nas też wyrwał z rąk Filistyńskich, a teraz uciekł z ziemi przed Absalomem.
10 Absalomu, tí àwa fi jẹ ọba lórí wa sì kú ní ogun, ǹjẹ́ èéṣe tí ẹ̀yin fi dákẹ́ tí ẹ̀yin kò sì sọ̀rọ̀ kan láti mú ọba padà wá?”
Lecz Absalom, któregośmy byli pomazali nad sobą, zginął w bitwie; a teraz przeczże wy zaniedbywacie przyprowadzić zasię króla?
11 Dafidi ọba sì ránṣẹ́ sí Sadoku, àti sí Abiatari àwọn àlùfáà pé, “Sọ fún àwọn àgbàgbà Juda, pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi kẹ́yìn láti mú ọba padà wá sí ilé rẹ̀? Ọ̀rọ̀ gbogbo Israẹli sì ti dé ọ̀dọ̀ ọba àní ní ilé rẹ̀.
Przetoż król Dawid posłał do Sadoka i do Abijatara, kapłanów, z temi słowy: Powiedzcie starszym Judzkim, mówiąc: Przeczże macie być pośledniejszymi w przyprowadzeniu zasię króla do domu jego? Albowiem słowa wszystkiego Izraela dochodziły króla do domu jego.
12 Ẹ̀yin ni ara mi, ẹ̀yin ni egungun mi, àti ẹran-ara mi: èéṣì ti ṣe tí ẹ̀yin fi kẹ́yìn láti mú ọba padà wá.’
Braciaście moi, kość moja, a ciałoście moje; przeczże tedy macie być pośledniejszymi w przywróceniu króla?
13 Kí ẹ̀yin sì wí fún Amasa pé, ‘Egungun àti ẹran-ara mi kọ́ ni ìwọ jẹ́ bí? Kí Ọlọ́run ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí ìwọ kò ba ṣe olórí ogun níwájú mi títí, ní ipò Joabu.’”
Amazie także powiedzcie: Izaliś ty nie jest kość moja, i ciało moje? To niech mi uczyni Bóg, i to niech przyczyni, jeźli hetmanem wojska nie będziesz przedemną po wszystkie dni, miasto Joaba.
14 Òun sì yí gbogbo àwọn ọkùnrin Juda lọ́kàn padà àní bí ọkàn ènìyàn kan; wọ́n sì ránṣẹ́ sí ọba, pé, “Ìwọ padà àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ.”
A tak nakłonił serce wszystkich mężów Judzkich jako męża jednego, że posłali do króla mówiąc: Nawróć się ty, i wszyscy słudzy twoi.
15 Ọba sì padà, o sì wá sí odò Jordani. Juda sì wá sí Gilgali láti lọ pàdé ọba, àti láti mú ọba kọjá odò Jordani.
Wrócił się tedy król, i przyszedł aż do Jordanu; a lud Judzki wyszedł był do Galgal, aby zaszedł w drodze królowi, a przeprowadził króla przez Jordan.
16 Ṣimei ọmọ Gera, ará Benjamini ti Bahurimu, ó yára ó sì bá àwọn ọkùnrin Juda sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Dafidi ọba.
Pospieszył się także Semej, syn Giery, syna Jemini, który był z Bachurym, i wyszedł z mężami Judzkimi przeciwko królowi Dawidowi.
17 Ẹgbẹ̀rún ọmọkùnrin sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nínú àwọn ọmọkùnrin Benjamini, Ṣiba ìránṣẹ́ ilé Saulu, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́ sì pẹ̀lú rẹ̀; wọ́n sì gòkè odò Jordani ṣáájú ọba.
A było tysiąc mężów z nim z Benjamitów; Syba także, sługa domu Saulowego, i piętnaście synów jego, i dwadzieścia sług jego z nim, i szczęśliwie się przeprawili za Jordan do króla.
18 Ọkọ̀ èrò kan ti rékọjá láti kó àwọn ènìyàn ilé ọba sí òkè, àti láti ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ̀. Ṣimei ọmọ Gera wólẹ̀. Ó sì dojúbolẹ̀ níwájú ọba, bí ó tí gòkè odò Jordani.
Przeprawili też prom, aby przewieziono czeladź królewską, a iżby uczyniono, coby mu się najlepiej podobało; a Semej, syn Giery, upadł przed królem, gdy się przeprawił przez Jordan,
19 Ó sì wí fún ọba pé, “Kí olúwa mi ó má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ sí mi lọ́rùn, má sì ṣe rántí àfojúdi tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣe ni ọjọ́ tí olúwa mi ọba jáde ní Jerusalẹmu, kí ọba má sì fi sí inú.
I rzekł do króla: Nie przyczytaj mi, panie mój, nieprawości, ani wspominaj, co lekkomyślnie uczynił sługa twój onegoż dnia, gdy wyszedł król, pan mój, z Jeruzalemu, aby to miał przypuszczać król do serca swego;
20 Nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ mọ̀ pé èmi ti ṣẹ̀; sì wò ó, mo wá lónìí yìí, ẹni àkọ́kọ́ ní gbogbo ìdílé Josẹfu tí yóò sọ̀kalẹ̀ wá pàdé olúwa mi ọba.”
Albowiem zna sługa twój, żem zgrzeszył; a otom dziś przyszedł pierwej niż kto ze wszystkiego domu Józefowego, abym zajechał drogę królowi, panu memu.
21 Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah dáhùn ó sì wí pé, “Kò ha tọ́ kí a pa Ṣimei nítorí èyí? Nítorí pé òun ti bú ẹni àmì òróró Olúwa.”
Tedy odpowiedział Abisaj, syn Sarwii, i rzekł: Izaż dla tego nie ma być zabity Semej, że złorzeczył pomazańcowi Pańskiemu?
22 Dafidi sì wí pé, “Kí ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah tí ẹ dàbí ọ̀tá fún mi lónìí? A ha lè pa ènìyàn kan lónìí ní Israẹli? Tàbí èmi kò ha mọ̀ pé lónìí èmi ni ọba Israẹli.”
Ale mu rzekł Dawid: Cóż wam do tego, synowie Sarwii, żeście mi dziś przeciwnymi? Izali dziś ma być zabity kto w Izraelu? Bo azaż nie wiem, żem ja dziś został królem nad Izraelem?
23 Ọba sì wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ kì yóò kú!” Ọba sì búra fún un.
I rzekł król do Semeja: Nie umrzesz; i przysiągł mu król.
24 Mefiboṣeti ọmọ Saulu sì sọ̀kalẹ̀ láti wá pàdé ọba, kò wẹ ẹsẹ̀ rẹ̀, kò sí tọ́ irùngbọ̀n rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fọ aṣọ rẹ̀ láti ọjọ́ tí ọba ti jáde títí ó fi di ọjọ́ tí ó fi padà ní àlàáfíà.
Mefiboset także, wnuk Saula, wyjechał przeciw królowi; który ani obmył nóg swoich, ani czesał brody swojej, ani prał szat swoich, ode dnia, którego był wyszedł król aż do dnia, którego się wrócił w pokoju.
25 Nígbà tí òun sì wá sí Jerusalẹmu láti pàdé ọba, ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ kò fi bá mi lọ, Mefiboṣeti?”
I stało się, gdy zabieżał w Jeruzalemie królowi, rzekł mu król: przeczżeś nie szedł ze mną, Mefibosecie?
26 Òun sì dáhùn wí pé, “Olúwa mi, ọba, ìránṣẹ́ mi ni ó tàn mí, nítorí ìránṣẹ́ rẹ wí fún un pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi èmi ó gùn ún, èmi ó sì tọ ọba lọ.’ Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ yarọ.
A on mu odpowiedział: Królu, panie mój, zdradził mię sługa mój; bo rzekł był sługa twój, osiodłam sobie osła, żebym siadłszy nań, jechał z królem, gdyż jest chromy sługa twój.
27 Ó sì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí ìránṣẹ́ rẹ, fún olúwa mi ọba, ṣùgbọ́n bí angẹli Ọlọ́run ni olúwa mi ọba rí, nítorí náà ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ.
I oskarżył sługę twego przed królem, panem moim; ale król, pan mój, jest jako Anioł Boży; przetoż czyń, co dobrego jest w oczach twoich.
28 Nítorí pé gbogbo ilé baba mi bí òkú ènìyàn ni wọ́n sá à rí níwájú olúwa mi ọba, ìwọ sì fi ipò fún ìránṣẹ́ rẹ láàrín àwọn tí ó ń jẹun ní ibi oúnjẹ. Nítorí náà àre kín ni èmi ní tí èmi yóò fi máa ké pe ọba síbẹ̀.”
Albowiem wszyscy z domu ojca mego byliśmy godni śmierci przed królem, panem moim, a przecięś ty posadził sługę twego między tymi, którzy jadają u stołu twego: I cóż jeszcze za sprawiedliwość moja, abym się miał więcej uskarżać na króla?
29 Ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń sọ ọ̀ràn ara rẹ fún mi èmi sá à ti wí pé, kí ìwọ àti Ṣiba pín ilẹ̀ náà.”
Rzekł mu tedy król: Cóż masz więcej mówić w sprawie twojej? Jużem rzekł, ty i Syba, podzielcie się majętnością.
30 Mefiboṣeti sì wí fún ọba pé, “Jẹ́ kí ó mú gbogbo rẹ̀, kí olúwa mi ọba sá à ti padà bọ̀ wá ilé rẹ̀ ni àlàáfíà.”
A Mefiboset rzekł do króla: I wszystko niech weźmie, gdy się tylko wrócił król, pan mój, w pokoju do domu swego.
31 Barsillai ará Gileadi sì sọ̀kalẹ̀ láti Rogelimu wá, ó sì bá ọba gòkè odò Jordani, láti ṣe ìkẹ́ rẹ̀ sí ìkọjá odò Jordani.
Barsylaj też Galaatczyk wyszedłszy z Rogielim, przeprawił się z królem przez Jordan, aby go prowadził za Jordan.
32 Barsillai sì jẹ́ arúgbó ọkùnrin gidigidi, ẹni ogbó ọgọ́rin ọdún sì ni, ó sì pèsè ohun jíjẹ fún ọba nígbà tí ó ti wà ní Mahanaimu; nítorí pé ọkùnrin ọlọ́lá ni òun ń ṣe.
A Barsylaj był bardzo stary, mając osiemdziesiąt lat, który podejmował króla, póki mieszkał w Mahanaim; bo był człowiekiem bogatym bardzo.
33 Ọba sì wí fún Barsillai pé, “Ìwọ wá bá mi gòkè odò, èmi ó sì máa pèsè fún ọ ní Jerusalẹmu.”
I rzekł król do Barsylajego: Pójdź ze mną, a będę cię chował przy sobie w Jeruzalemie.
34 Barsillai sì wí fún ọba pé, “Ọjọ́ mélòó ni ọdún ẹ̀mí mi kù, tí èmi ó fi bá ọba gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
Ale Barsylaj odpowiedział królowi: Wieleż jest dni lat żywota mego, żebym miał iść z królem do Jeruzalemu?
35 Ẹni ogbó ọgọ́rin ọdún sá à ni èmi lónìí, ǹjẹ́ èmi mọ ìyàtọ̀ nínú rere àti búburú? Ǹjẹ́ ìránṣẹ́ rẹ le mọ adùn ohun tí òun ń jẹ tàbí ohun ti òun ń mu bí? Èmi tún lè mọ adùn ohùn àwọn ọkùnrin tí ń kọrin àti àwọn obìnrin tí ń kọrin bí, ǹjẹ́ nítorí kín ni ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe jẹ́ ìyọnu síbẹ̀ fún olúwa mi ọba.
Osiemdziesiąt lat mi dzisiaj; izali mogę rozeznać między dobrem a złem? izali poczuje smak sługa twój w tem, cobym jadł, albo cobym pił? izali słuchać mogę więcej głosu śpiewaków i śpiewaczek? a przeczżeby miał być sługa twój jeszcze ciężarem królowi, panu memu?
36 Ìránṣẹ́ rẹ yóò sì sin ọba lọ díẹ̀ gòkè odò Jordani; èéṣì ṣe tí ọba yóò fi san ẹ̀san yìí fún mi.
Jeszcze trochę pójdzie sługa twój za Jordan z królem: bo czemużby mi miał dawać król takową nagrodę?
37 Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ padà, èmi ó sì kú ní ìlú mi, a ó sì sin mí ní ibojì baba àti ìyá mi. Sì wo Kimhamu ìránṣẹ́ rẹ, yóò bá olúwa mi ọba gòkè; ìwọ ó sì ṣe ohun tí ó bá tọ́ lójú rẹ fún un.”
Niech się wróci proszę sługa twój, abym umarł w mieście mojem, przy grobie ojca mego i matki mojej; ale oto sługa twój Chymham pójdzie z królem, panem moim: uczyńże mu, co dobrego jest w oczach twoich.
38 Ọba sì dáhùn wí pé, “Kimhamu yóò bá mi gòkè, èmi ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ̀ fún un; ohunkóhun tí ìwọ bá sì béèrè lọ́wọ́ mi, èmi ó ṣe é fún ọ.”
I rzekł król: Niechże ze mną idzie Chymham, a ja mu uczynię, co dobrego będzie w oczach twoich; nadto, cokolwiek żądać będziesz ode mnie, toć uczynię.
39 Gbogbo àwọn ènìyàn sì gòkè odò Jordani ọba sì gòkè; ọba sì fi ẹnu ko Barsillai lẹ́nu, ó sì súre fún un; òun sì padà sí ilé rẹ̀.
A gdy się przeprawił wszystek lud przez Jordan, król się też przeprawił. Tedy pocałował król Barsylajego, i błogosławił mu; który się wrócił do miejsca swego.
40 Ọba sì ń lọ́ sí Gilgali, Kimhamu sì ń bà a lọ, gbogbo àwọn ènìyàn Juda sì ń ṣe ìkẹ́ ọba, àti ààbọ̀ àwọn ènìyàn Israẹli.
Potem przyszedł król do Galgal, przyszedł też z nim Chymham. Wszystek też lud Judzki prowadził króla, także i połowa ludu Izraelskiego.
41 Sì wò ó, gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì tọ ọba wá, wọ́n sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí àwọn arákùnrin wa àwọn ọkùnrin Juda fi jí ọ kúrò, tí wọ́n sì fi mú ọba àti àwọn ará ilé rẹ̀ gòkè odò Jordani, àti gbogbo àwọn ènìyàn Dafidi pẹ̀lú rẹ?”
A oto, wszyscy mężowie Izraelscy, zszedłszy się do króla, mówili do niego: Czemuż cię wykradli bracia nasi, mężowie Judzcy, i przeprowadzili króla i dom jego przez Jordan, i wszystkie męże Dawidowe z nim?
42 Gbogbo ọkùnrin Juda sì dá àwọn ọkùnrin Israẹli lóhùn pé, “Nítorí pé ọba bá wa tan ni; èéṣe tí ẹ̀yin fi bínú nítorí ọ̀ràn yìí? Àwa jẹ nínú oúnjẹ ọba rárá bí? Tàbí ó fi ẹ̀bùn kan fún wa bí?”
I odpowiedzieli wszyscy mężowie Judzcy mężom Izraelskim: Przeto, iż nam powinny jest król. A przeczże się gniewać macie o to? izali nam za to jeść król dawa, albo nam jakie dary rozdał?
43 Àwọn ọkùnrin Israẹli náà sì dá àwọn ọkùnrin Juda lóhùn pé, “Àwa ní ipá mẹ́wàá nínú ọba, àwa sì ní nínú Dafidi jù yín lọ, èéṣì ṣe tí ẹ̀yin kò fi kà wá sí, tí ìmọ̀ wa kò fi ṣáájú láti mú ọba wa padà?” Ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Juda sì le ju ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Israẹli.
Tedy odpowiedzieli mężowie Izraelscy mężom Judzkim, i rzekli: Dziesięć kroć więcej mamy do króla; przetoż i Dawid więcej do nas należy, niż do was. Przeczżeście nas lekce poważali? Azażeśmy my o to pierwej nie mówili, abyśmy przywrócili króla swe go? Ale sroższa była mowa mężów Judzkich, niż mowa mężów Izraelskich.

< 2 Samuel 19 >